诗篇 19 – CCB & YCB

Chinese Contemporary Bible (Simplified)

诗篇 19:1-14

第 19 篇

上帝的作为和律法

大卫的诗,交给乐长。

1诸天述说上帝的荣耀,

穹苍传扬祂的作为。

2它们日复一日地诉说,

夜复一夜地宣扬,

3无言无语,无声无息。

4它们的声音传遍天下,

它们的话语传到地极。

上帝在天上为太阳设立居所。

5太阳出来时,如步出洞房的新郎,

又如欢然奔跑赛程的健儿。

6它滑过长空,

从天这边绕到天那边,

热量广及万物。

7耶和华的律法完美,

能更新生命;

耶和华的法度可靠,

让愚人有智慧。

8耶和华的法则公正,

使人充满喜乐;

耶和华的命令纯全,

让人眼目明亮。

9要以纯洁的心敬畏耶和华,

直到永远;

耶和华的法令可靠,

全然公义。

10这些比纯金还宝贵,

比蜂房的蜜更甘甜。

11你仆人从中受到警戒,

遵守的人必得大赏赐。

12谁能知道自己的过失呢?

求你赦免我心中隐藏的过错。

13求你拦阻我,

别让我明知故犯,

别让罪恶辖制我。

这样,我才纯全正直,

免犯大过。

14耶和华——我的磐石、我的救赎主啊,

愿你喜悦我口中的言语、心中的意念。

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Saamu 19:1-14

Saamu 19

Fún adarí orin. Saamu ti Dafidi.

1Àwọn ọ̀run ń sọ nípa ti ògo Ọlọ́run;

Àwọsánmọ̀ ń sọ nípa ti iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀.

2Wọ́n ń fọhùn ní ọjọ́ dé ọjọ́;

wọ́n ń fi ìmọ̀ hàn ní alẹ́ dé alẹ́.

3Kò sí ohùn tàbí èdè

níbi tí a kò gbé gbọ́ ìró wọn

419.4: Ro 10.18.Ohùn wọn jáde lọ sí gbogbo orílẹ̀ ayé,

ọ̀rọ̀ wọn títí dé òpin ilẹ̀ ayé.

Ó ti kọ́ àgọ́ fún oòrùn nínú àwọn ọ̀run.

5Tí ó dàbí ọkọ ìyàwó tí ó ń jáde ti yàrá rẹ̀ wá,

òun yọ bí alágbára ọkùnrin tí ó ń sáré ìje.

6Ìjáde lọ rẹ̀ ni láti òpin ọ̀run wá

àti àyíká rẹ̀ sì dé ìpínlẹ̀ rẹ̀;

kò sì sí ohun tí ó pamọ́ kúrò nínú oore rẹ̀.

7Pípé ni òfin Olúwa,

ó ń yí ọkàn padà.

Ẹ̀rí Olúwa dánilójú,

ó sọ òpè di ọlọ́gbọ́n.

8Ìlànà Olúwa tọ̀nà,

ó ń fi ayọ̀ fún ọkàn.

Àṣẹ Olúwa ni mímọ́,

ó ń fi ìmọ́lẹ̀ fún ojú.

9Ìbẹ̀rù Olúwa mọ́,

ó ń faradà títí láéláé.

Ìdájọ́ Olúwa dájú

òdodo ni gbogbo wọn.

10Wọn ṣọ̀wọ́n ju wúrà lọ,

ju wúrà tí o dára jùlọ,

wọ́n dùn ju oyin lọ,

àti ju afárá oyin lọ.

11Nípa wọn ni a ti ṣí ìránṣẹ́ rẹ̀ létí;

nípa pípa wọ́n mọ́, èrè púpọ̀ ń bẹ.

12Ta ni ó lè mọ àṣìṣe rẹ̀?

Dáríjì mí nínú àṣìṣe mi tí ó pamọ́.

13Wẹ ìránṣẹ́ rẹ mọ́ kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ àmọ̀ọ́n-mọ̀-dá;

má ṣe jẹ kí wọn kí ó jẹ ọba lórí mi.

Nígbà náà ní èmi yóò dúró ṣinṣin,

èmi yóò sì ṣe aláìlẹ́bi kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ ńlá.

14Jẹ́ kí ọ̀rọ̀ ẹnu mi àti àṣàrò ọkàn mi

kí ó jẹ́ ìtẹ́wọ́gbà ní ojú rẹ,

Ìwọ Olúwa àpáta mi, àti Olùdáǹdè mi.