约伯记 11 – CCB & YCB

Chinese Contemporary Bible (Simplified)

约伯记 11:1-20

琐法的回答

1拿玛琐法回答说:

2“难道滔滔不绝就无人反驳?

难道唠唠叨叨就证明有理?

3你喋喋不休,人们岂能缄默不言?

你嘲笑讥讽,岂不该有人使你羞愧?

4你自以为信仰纯全,

在上帝眼中清白。

5唯愿上帝发言,

开口驳斥你,

6告诉你智慧的奥秘,

因为真智慧深奥难懂。

要知道,上帝对你的惩罚比你该受的还轻。

7“你能测度上帝的深奥,

探索全能者的极限吗?

8那可比诸天还高,你能做什么?

那可比阴间还深,你能知道什么?

9那可比大地还宽广,

比海洋还辽阔。

10祂若来囚禁你,

开庭审判,

谁能阻拦?

11祂洞悉诡诈之人,

看见罪恶,

岂会不理?

12愚蠢人若能变得聪明,

野驴驹也可生成人样。

13“你若把心安正,

向祂举手祷告;

14你若除去自己的罪恶,

不容帐篷里有任何不义,

15就必能无愧地仰起脸,

站立得稳,无所畏惧。

16你必忘记自己的苦楚,

它从你记忆中如流水逝去。

17你的人生将比正午还光明,

生命中的黑暗也必像黎明。

18你必充满盼望,感到安稳,

你必得到保护,安然入睡。

19你睡觉时必无人惊扰,

许多人必求你施恩。

20但恶人必眼目失明,无路可逃,

他们的指望只有死亡。”

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Jobu 11:1-20

Sofari fi ẹ̀sùn irọ́ pípa àti àìṣòótọ́ kan Jobu

1Ìgbà náà ni Sofari, ará Naama, dáhùn, ó sì wí pé:

2“A ha lè ṣe kí a máa dáhùn sí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọ̀rọ̀?

A ha lè fi gbogbo ọ̀rọ̀ wọ̀nyí da ènìyàn láre?

3Ṣé àmọ̀tán rẹ le mú ènìyàn pa ẹnu wọn mọ́ bí?

Ṣé ẹnikẹ́ni kò ní bá ọ wí bí ìwọ bá yọ ṣùtì sí ni?

4Ìwọ sá à ti wí fún Ọlọ́run pé,

‘ìṣe mi jẹ́ aláìléérí, èmi sì mọ́ ní ojú rẹ.’

5Ṣùgbọ́n Ọlọ́run ìbá jẹ́ sọ̀rọ̀,

kí ó sì ya ẹnu rẹ̀ sí ọ;

6Kí ó sì fi àṣírí ọgbọ́n hàn ọ́ pé, ó pọ̀ ju òye ènìyàn lọ;

Nítorí náà, mọ̀ pé Ọlọ́run ti

gbàgbé àwọn ẹ̀ṣẹ̀ rẹ kan.

7“Ìwọ ha le ṣe àwárí ohun ìjìnlẹ̀ Ọlọ́run bí?

Ìwọ ha le ṣe àwárí ibi tí Olódùmarè dé bi?

8Ó ga ju àwọn ọ̀run lọ; kí ni ìwọ le è ṣe?

Ó jì ju jíjìn isà òkú lọ; kí ni ìwọ le mọ̀?

9Ìwọ̀n rẹ̀ gùn ju ayé lọ,

ó sì ní ibú ju Òkun lọ.

10“Bí òun bá rékọjá, tí ó sì sé ọnà,

tàbí tí ó sì mú ni wá sí ìdájọ́, ǹjẹ́, ta ni ó lè dí i lọ́wọ́?

11Òun sá à mọ ẹlẹ́tàn ènìyàn;

àti pé ṣé bí òun bá rí ohun búburú, ṣé òun kì i fi iyè sí i?

12Ṣùgbọ́n òmùgọ̀ ènìyàn ki yóò di ọlọ́gbọ́n,

bi ko ti rọrùn fún ọmọ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ igbó láti bí ènìyàn.

13“Bí ìwọ bá fi ọkàn rẹ fún un,

tí ìwọ sì na ọwọ́ rẹ sí ọ̀dọ̀ rẹ̀,

14Bí ìwọ bá gbé ẹ̀ṣẹ̀ tí ń bẹ ní ọwọ́ rẹ jù sọnù,

tí ìwọ kò sì jẹ́ kí aburú gbé nínú àgọ́ rẹ.

15Nígbà náà ni ìwọ ó gbé ojú rẹ sókè láìní àbàwọ́n,

àní ìwọ yóò dúró ṣinṣin, ìwọ kì yóò sì bẹ̀rù,

16Nítorí pé ìwọ ó gbàgbé ìṣòro rẹ,

ìwọ ó sì rántí rẹ̀ bí omi tí ó ti sàn kọjá lọ.

17Ọjọ́ ayé rẹ yóò sì mọ́lẹ̀ ju ọ̀sán gangan lọ,

bí òkùnkùn tilẹ̀ bò ọ́ mọ́lẹ̀ nísinsin yìí, ìwọ ó dàbí òwúrọ̀.

18Ìwọ ó sì wà láìléwu, nítorí pé ìrètí wà;

àní ìwọ ó rin ilé rẹ wò, ìwọ ó sì sinmi ní àlàáfíà.

19Ìwọ ó sì dùbúlẹ̀ pẹ̀lú, kì yóò sì sí ẹni tí yóò dẹ́rùbà ọ́,

àní ènìyàn yóò máa wá ojúrere rẹ.

20Ṣùgbọ́n ojú ìkà ènìyàn yóò mófo;

gbogbo ọ̀nà àbáyọ ni yóò nù wọ́n,

ìrètí wọn a sì dàbí ẹni tí ó jọ̀wọ́ ẹ̀mí rẹ̀ lọ́wọ́.”