箴言 13 – CCB & YCB

Chinese Contemporary Bible (Simplified)

箴言 13:1-25

1智慧儿听从父训,

嘲讽者不听责备。

2口出良言尝善果,

奸徒贪行残暴事13:2 奸徒贪行残暴事”或译“奸徒必饱受虐待”。

3说话谨慎,可保性命;

口无遮拦,自取灭亡。

4懒惰人空有幻想,

勤快人心想事成。

5义人憎恶虚谎,

恶人行事可耻。

6公义守卫正直的人,

邪恶倾覆犯罪之徒。

7有人强充富有,

其实身无分文;

有人假装贫穷,

却是腰缠万贯。

8富人用财富赎命,

穷人却免受惊吓。

9义人的光灿烂,

恶人的灯熄灭。

10自高自大招惹纷争,

虚心受教才是睿智。

11不义之财必耗尽,

勤俭积蓄财富增。

12盼望无期,使人忧伤;

夙愿得偿,带来生机13:12 带来生机”希伯来文是“使人像棵生命树”。

13蔑视训言,自招灭亡;

敬畏诫命,必得赏赐。

14智者的训言是生命之泉,

可使人避开死亡的网罗。

15睿智使人蒙恩惠,

奸徒之路通灭亡。

16明哲知而后行,

愚人炫耀愚昧。

17奸恶的使者陷入灾祸,

忠诚的使者带来医治。

18不受管教的贫穷羞愧,

接受责备的受到尊崇。

19愿望实现使心甘甜,

远离恶事为愚人憎恶。

20与智者同行必得智慧,

与愚人结伴必受亏损。

21祸患追赶罪人,

义人必得善报。

22善人为子孙留下产业,

罪人给义人积聚财富。

23穷人的田地出产丰富,

因不公而被抢掠一空。

24不用杖管教儿女是憎恶他们,

疼爱儿女的随时管教他们。

25义人丰衣足食,

恶人食不果腹。

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Òwe 13:1-25

1Ọlọ́gbọ́n ọmọ gba ẹ̀kọ́ baba rẹ̀,

ṣùgbọ́n ẹlẹ́gàn kò gbọ́ ìbáwí.

2Láti inú èso ẹnu rẹ̀ ènìyàn ń gbádùn ohun rere

ṣùgbọ́n, ìfẹ́ ọkàn aláìṣòótọ́ ní ìwà ipá.

3Ẹnikẹ́ni tí ó ṣọ́ ẹnu rẹ̀ pa ẹnu ara rẹ̀ mọ́,

ṣùgbọ́n ẹni tí ó ń sọ̀rọ̀ gbàù gbàù yóò parun.

4Ọkàn ọ̀lẹ ń fẹ́, ṣùgbọ́n kò rí nǹkan kan,

ṣùgbọ́n ọkàn àwọn ti kì í ṣe ọ̀lẹ rí ìtẹ́lọ́rùn.

5Olódodo kórìíra ohun tí í ṣe irọ́

Ṣùgbọ́n ènìyàn búburú hu ìwà ìríra àti ìtìjú.

6Òdodo ń ṣamọ̀nà ènìyàn olóòtítọ́ inú,

ṣùgbọ́n ìwà búburú ṣí ẹlẹ́ṣẹ̀ ní ipò.

7Ènìyàn kan díbọ́n bí ẹni tí ó ní ọrọ̀ síbẹ̀ kò ní nǹkan kan

ẹlòmíràn díbọ́n bí i tálákà, síbẹ̀ ó ní ọrọ̀ púpọ̀.

8Ọrọ̀ ènìyàn le è ra ẹ̀mí rẹ̀

ṣùgbọ́n tálákà kì í gbọ́ ìdẹ́rùbà.

9Ìmọ́lẹ̀ olódodo tàn roro,

ṣùgbọ́n fìtílà ènìyàn búburú ni a pa kú.

10Ìgbéraga máa ń dá ìjà sílẹ̀ ni

ṣùgbọ́n ọgbọ́n wà nínú àwọn tí ń gba ìmọ̀ràn.

11Owó tí a fi ọ̀nà èrú kójọ yóò ṣí lọ,

ṣùgbọ́n ẹni tí ń kó owó jọ díẹ̀díẹ̀ yóò pọ̀ sí i.

12Ìrètí tí ń falẹ̀ máa ń mú kí ọkàn ṣàárẹ̀

ṣùgbọ́n ìrètí tí a rí gbà jẹ́ igi ìyè.

13Ẹni tí ó kẹ́gàn ẹ̀kọ́ yóò jìyà rẹ̀

ṣùgbọ́n ẹni tí ó pa àṣẹ mọ́ gba èrè rẹ̀.

14Ìkọ́ni ọlọ́gbọ́n jẹ́ orísun ìyè,

tí ń yí ènìyàn padà kúrò nínú ìdẹ̀kùn ikú.

15Òye pípé ń mú ni rí ojúrere

Ṣùgbọ́n ọ̀nà aláìṣòótọ́ kì í tọ́jọ́.

16Gbogbo olóye ènìyàn máa ń hùwà pẹ̀lú ìmọ̀

Ṣùgbọ́n aláìgbọ́n a fi ìwà òmùgọ̀ rẹ̀ hàn.

17Ìránṣẹ́ búburú bọ́ sínú ìdààmú

ṣùgbọ́n aṣojú olóòtítọ́ mú ìwòsàn wá.

18Ẹni tí ó kọ ìbáwí yóò di tálákà yóò sì rí ìtìjú,

ṣùgbọ́n ẹni tí ó gbọ́ ìbáwí ni yóò rí ọlá.

19Ìfẹ́ tí a mú ṣẹ dùn mọ́ ọkàn

ṣùgbọ́n ìríra ni fún aṣiwèrè láti kúrò nínú ibi.

20Ẹni tí ó ń bá ọlọ́gbọ́n rìn yóò gbọ́n

ṣùgbọ́n ẹni tí ń bá aláìgbọ́n kẹ́gbẹ́ ń pa ara rẹ̀ lára.

21Òsì a máa ta ẹlẹ́ṣẹ̀,

ṣùgbọ́n ọrọ̀ ni èrè fún olódodo.

22Ènìyàn rere a máa fi ogún sílẹ̀ fún àwọn ọmọ ọmọ rẹ̀,

ṣùgbọ́n, a kó ọrọ̀ àwọn tó dẹ́ṣẹ̀ pamọ́ fún àwọn olódodo.

23Ilẹ̀ ẹ tálákà le è mú ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìre oko wá

ṣùgbọ́n àìṣòdodo gbá gbogbo rẹ̀ lọ.

24Ẹni tí ó fa ọwọ́ ìbáwí sẹ́yìn kórìíra ọmọ rẹ̀

ṣùgbọ́n ẹni tí ó fẹ́ràn ọmọ rẹ̀ yóò máa bá a wí.

25Olódodo jẹ́wọ́ títí ó fi tẹ́ ọkàn rẹ̀ lọ́rùn

ṣùgbọ́n ebi yóò máa pa ikùn ènìyàn búburú.