1智慧儿听从父训,
嘲讽者不听责备。
2口出良言尝善果,
奸徒贪行残暴事13:2 “奸徒贪行残暴事”或译“奸徒必饱受虐待”。。
3说话谨慎,可保性命;
口无遮拦,自取灭亡。
4懒惰人空有幻想,
勤快人心想事成。
5义人憎恶虚谎,
恶人行事可耻。
6公义守卫正直的人,
邪恶倾覆犯罪之徒。
7有人强充富有,
其实身无分文;
有人假装贫穷,
却是腰缠万贯。
8富人用财富赎命,
穷人却免受惊吓。
9义人的光灿烂,
恶人的灯熄灭。
10自高自大招惹纷争,
虚心受教才是睿智。
11不义之财必耗尽,
勤俭积蓄财富增。
12盼望无期,使人忧伤;
夙愿得偿,带来生机13:12 “带来生机”希伯来文是“使人像棵生命树”。。
13蔑视训言,自招灭亡;
敬畏诫命,必得赏赐。
14智者的训言是生命之泉,
可使人避开死亡的网罗。
15睿智使人蒙恩惠,
奸徒之路通灭亡。
16明哲知而后行,
愚人炫耀愚昧。
17奸恶的使者陷入灾祸,
忠诚的使者带来医治。
18不受管教的贫穷羞愧,
接受责备的受到尊崇。
19愿望实现使心甘甜,
远离恶事为愚人憎恶。
20与智者同行必得智慧,
与愚人结伴必受亏损。
21祸患追赶罪人,
义人必得善报。
22善人为子孙留下产业,
罪人给义人积聚财富。
23穷人的田地出产丰富,
因不公而被抢掠一空。
24不用杖管教儿女是憎恶他们,
疼爱儿女的随时管教他们。
25义人丰衣足食,
恶人食不果腹。
1Ọlọ́gbọ́n ọmọ gba ẹ̀kọ́ baba rẹ̀,
ṣùgbọ́n ẹlẹ́gàn kò gbọ́ ìbáwí.
2Láti inú èso ẹnu rẹ̀ ènìyàn ń gbádùn ohun rere
ṣùgbọ́n, ìfẹ́ ọkàn aláìṣòótọ́ ní ìwà ipá.
3Ẹnikẹ́ni tí ó ṣọ́ ẹnu rẹ̀ pa ẹnu ara rẹ̀ mọ́,
ṣùgbọ́n ẹni tí ó ń sọ̀rọ̀ gbàù gbàù yóò parun.
4Ọkàn ọ̀lẹ ń fẹ́, ṣùgbọ́n kò rí nǹkan kan,
ṣùgbọ́n ọkàn àwọn ti kì í ṣe ọ̀lẹ rí ìtẹ́lọ́rùn.
5Olódodo kórìíra ohun tí í ṣe irọ́
Ṣùgbọ́n ènìyàn búburú hu ìwà ìríra àti ìtìjú.
6Òdodo ń ṣamọ̀nà ènìyàn olóòtítọ́ inú,
ṣùgbọ́n ìwà búburú ṣí ẹlẹ́ṣẹ̀ ní ipò.
7Ènìyàn kan díbọ́n bí ẹni tí ó ní ọrọ̀ síbẹ̀ kò ní nǹkan kan
ẹlòmíràn díbọ́n bí i tálákà, síbẹ̀ ó ní ọrọ̀ púpọ̀.
8Ọrọ̀ ènìyàn le è ra ẹ̀mí rẹ̀
ṣùgbọ́n tálákà kì í gbọ́ ìdẹ́rùbà.
9Ìmọ́lẹ̀ olódodo tàn roro,
ṣùgbọ́n fìtílà ènìyàn búburú ni a pa kú.
10Ìgbéraga máa ń dá ìjà sílẹ̀ ni
ṣùgbọ́n ọgbọ́n wà nínú àwọn tí ń gba ìmọ̀ràn.
11Owó tí a fi ọ̀nà èrú kójọ yóò ṣí lọ,
ṣùgbọ́n ẹni tí ń kó owó jọ díẹ̀díẹ̀ yóò pọ̀ sí i.
12Ìrètí tí ń falẹ̀ máa ń mú kí ọkàn ṣàárẹ̀
ṣùgbọ́n ìrètí tí a rí gbà jẹ́ igi ìyè.
13Ẹni tí ó kẹ́gàn ẹ̀kọ́ yóò jìyà rẹ̀
ṣùgbọ́n ẹni tí ó pa àṣẹ mọ́ gba èrè rẹ̀.
14Ìkọ́ni ọlọ́gbọ́n jẹ́ orísun ìyè,
tí ń yí ènìyàn padà kúrò nínú ìdẹ̀kùn ikú.
15Òye pípé ń mú ni rí ojúrere
Ṣùgbọ́n ọ̀nà aláìṣòótọ́ kì í tọ́jọ́.
16Gbogbo olóye ènìyàn máa ń hùwà pẹ̀lú ìmọ̀
Ṣùgbọ́n aláìgbọ́n a fi ìwà òmùgọ̀ rẹ̀ hàn.
17Ìránṣẹ́ búburú bọ́ sínú ìdààmú
ṣùgbọ́n aṣojú olóòtítọ́ mú ìwòsàn wá.
18Ẹni tí ó kọ ìbáwí yóò di tálákà yóò sì rí ìtìjú,
ṣùgbọ́n ẹni tí ó gbọ́ ìbáwí ni yóò rí ọlá.
19Ìfẹ́ tí a mú ṣẹ dùn mọ́ ọkàn
ṣùgbọ́n ìríra ni fún aṣiwèrè láti kúrò nínú ibi.
20Ẹni tí ó ń bá ọlọ́gbọ́n rìn yóò gbọ́n
ṣùgbọ́n ẹni tí ń bá aláìgbọ́n kẹ́gbẹ́ ń pa ara rẹ̀ lára.
21Òsì a máa ta ẹlẹ́ṣẹ̀,
ṣùgbọ́n ọrọ̀ ni èrè fún olódodo.
22Ènìyàn rere a máa fi ogún sílẹ̀ fún àwọn ọmọ ọmọ rẹ̀,
ṣùgbọ́n, a kó ọrọ̀ àwọn tó dẹ́ṣẹ̀ pamọ́ fún àwọn olódodo.
23Ilẹ̀ ẹ tálákà le è mú ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìre oko wá
ṣùgbọ́n àìṣòdodo gbá gbogbo rẹ̀ lọ.
24Ẹni tí ó fa ọwọ́ ìbáwí sẹ́yìn kórìíra ọmọ rẹ̀
ṣùgbọ́n ẹni tí ó fẹ́ràn ọmọ rẹ̀ yóò máa bá a wí.
25Olódodo jẹ́wọ́ títí ó fi tẹ́ ọkàn rẹ̀ lọ́rùn
ṣùgbọ́n ebi yóò máa pa ikùn ènìyàn búburú.