撒母耳记上 7 – CCB & YCB

Chinese Contemporary Bible (Simplified)

撒母耳记上 7:1-17

1基列·耶琳人就下来把耶和华的约柜抬到山上,放在亚比拿达的家里,派他的儿子以利亚撒看守耶和华的约柜。

撒母耳征服非利士人

2约柜在基列·耶琳停留了二十年。那时,全体以色列人都痛悔地寻求耶和华。 3撒母耳对他们说:“如果你们全心归向耶和华,就要除掉你们那些外族的神明,包括亚斯她录神像,一心归向耶和华,单单事奉祂,祂必从非利士人手中救你们。” 4于是,他们除掉了巴力亚斯她录神像,单单事奉耶和华。

5撒母耳又说:“你们全体以色列人到米斯巴来,我会为你们向耶和华祈求。” 6他们就在那里聚集,打水倒在耶和华面前,并在当天禁食。他们说:“我们得罪了耶和华。”于是,撒母耳米斯巴以色列人的士师。 7非利士人听说以色列人在米斯巴聚集,他们的首领就率领军队来攻打以色列人。以色列人听见消息后,非常害怕。 8他们对撒母耳说:“请你为我们不停地呼求我们的上帝耶和华,求祂从非利士人手中拯救我们。” 9撒母耳把一只还在吃奶的羊献给耶和华作全牲燔祭。他为以色列人呼求耶和华,耶和华垂听了他的祈求。 10撒母耳正在献燔祭的时候,非利士人已经逼近了。那天,耶和华向非利士人发出雷霆之声,使他们陷入一片恐慌,败在了以色列人手下。 11以色列人从米斯巴一路追杀他们,直到伯·甲附近。

12撒母耳拿了一块石头放在米斯巴的中间,称之为以便以谢7:12 以便以谢”意思是“援助之石”。,说:“耶和华到如今都帮助我们。”

13这样非利士人被征服了,没有再侵犯以色列人。在撒母耳有生之年,耶和华一直严厉地对付非利士人。 14以色列人收复了从以革伦迦特之间被非利士人夺去的城邑,并夺回了这些城邑的周边地区。那时以色列人与亚摩利人和平共处。

15撒母耳一生做以色列人的士师。 16他每年都到伯利恒吉甲米斯巴各地巡回,审理以色列人的案件。 17之后,他才回到拉玛自己的家中,也在那里审理以色列人的案件,并为耶和华筑了一座祭坛。

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

1 Samuẹli 7:1-17

1Nígbà náà àwọn ará Kiriati-Jearimu wá, wọ́n sì gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa. Wọ́n gbé e lọ sí ilé Abinadabu lórí òkè, wọ́n sì ya Eleasari ọmọ rẹ̀ sí mímọ́ láti ṣọ́ àpótí ẹ̀rí Olúwa.

Samuẹli ṣẹ́gun àwọn ará Filistini ní Mispa

2Ó sì jẹ́ ní ìgbà pípẹ́, ogún ọdún ni àpótí ẹ̀rí Olúwa fi wà ní Kiriati-Jearimu. Gbogbo ilé Israẹli ṣọ̀fọ̀ wọ́n sì pohùnréré ẹkún sí Olúwa. 3Samuẹli sọ fún gbogbo ilé Israẹli pé, “Tí ẹ bá ń padà sí ọ̀dọ̀ Olúwa pẹ̀lú gbogbo ọkàn yín, Ẹ yẹra kúrò lọ́dọ̀ ọlọ́run àjèjì àti Aṣtoreti kí ẹ sì fi ara yín jì fún Olúwa kí ẹ sì sin òun nìkan ṣoṣo, òun yóò sì gbà yín kúrò lọ́wọ́ àwọn ará Filistini” 4Nígbà náà ni àwọn ọmọ Israẹli yẹra fún Baali àti Aṣtoreti, wọ́n sì sin Olúwa nìkan ṣoṣo.

5Nígbà náà ni, Samuẹli wí pé, “Ẹ kó gbogbo àwọn ọmọ Israẹli jọ sí Mispa, èmi yóò bẹ̀bẹ̀ fún un yín lọ́dọ̀ Olúwa.” 6Nígbà tí wọ́n sì ti péjọpọ̀ ní Mispa, wọ́n pọn omi, wọ́n sì dà á sílẹ̀ níwájú Olúwa. Ní ọjọ́ náà, wọ́n gbààwẹ̀, wọ́n sì jẹ́wọ́ pé, “Àwa ti ṣẹ̀ sí Olúwa.” Samuẹli sì jẹ́ olórí àwọn ọmọ Israẹli ní Mispa.

7Nígbà tí àwọn Filistini gbọ́ pé àwọn Israẹli ti péjọ ní Mispa, àwọn aláṣẹ Filistini gòkè wá láti kọlù wọ́n. Nígbà tí àwọn ọmọ Israẹli gbọ́ èyí, Ẹ̀rù bà wọ́n nítorí àwọn Filistini. 8Wọ́n sọ fún Samuẹli pé, “Má ṣe dákẹ́ kíké pe Olúwa Ọlọ́run wa fún wa, ké pè é kí ó lè gbà wá kúrò lọ́wọ́ àwọn Filistini.” 9Nígbà náà ni Samuẹli mú ọ̀dọ́-àgùntàn tí ó jẹ́ ọmọ ọmú, ó sì fi rú ẹbọ sísun sí Olúwa. Ó sí ké pe Olúwa nítorí ilé Israẹli, Olúwa sì dá a lóhùn.

10Nígbà tí Samuẹli ń ṣe ìrúbọ ẹbọ sísun, àwọn Filistini súnmọ́ tòsí láti bá Israẹli ja ogun. Ṣùgbọ́n ní ọjọ́ náà, Olúwa sán àrá ńlá lu àwọn Filistini, ó sì mú jìnnìjìnnì bá wọn, a sì lé wọn níwájú àwọn ọmọ Israẹli. 11Àwọn ọkùnrin Israẹli tú jáde láti Mispa. Wọ́n sì ń lépa àwọn Filistini, wọ́n sì pa wọ́n ní àpá rìn títí dé abẹ́ Beti-Kari.

12Samuẹli mú òkúta kan ó sì fi lélẹ̀ láàrín Mispa àti Ṣeni, ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Ebeneseri, wí pé, “Ibí ni Olúwa ràn wá lọ́wọ́ dé.” 13Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n ṣẹ́gun Filistini, wọn kò sì wá sí agbègbè àwọn ọmọ Israẹli mọ́.

Ní gbogbo ìgbésí ayé Samuẹli, ọwọ́ Olúwa lòdì sí àwọn Filistini. 14Àwọn ìlú láti Ekroni dé Gati tí àwọn Filistini ti gbà lọ́wọ́ Israẹli ni ó ti gbà padà fún Israẹli, ó sì gba gbogbo ilẹ̀ agbègbè rẹ̀ kúrò lọ́wọ́ ìṣàkóso àwọn Filistini. Ìrẹ́pọ̀ sì wà láàrín Israẹli àti àwọn Amori.

15Samuẹli tẹ̀síwájú gẹ́gẹ́ bí adájọ́ lórí Israẹli. Ní ọjọ́ ayé e rẹ̀. 16Láti ọdún dé ọdún, ó lọ yíká láti Beteli dé Gilgali dé Mispa, ó sì ń ṣe ìdájọ́ Israẹli ní gbogbo ibi wọ̀nyí. 17Ṣùgbọ́n ó máa ń padà sí ilé rẹ̀ ní Rama, níbí tí ilé rẹ̀ wà, ó sì túnṣe ìdájọ́ Israẹli níbẹ̀, ó sì kọ́ pẹpẹ kan síbẹ̀ fún Olúwa.