撒母耳记上 4 – CCB & YCB

Chinese Contemporary Bible (Simplified)

撒母耳记上 4:1-22

约柜被掳

1那时,以色列人去迎战非利士人,他们在以便以谢扎营,非利士人在亚弗扎营。 2非利士人列阵与以色列人交战,大败以色列人,杀了他们四千人。 3军队回营后,以色列的长老说:“为什么今天耶和华使我们败在非利士人手下?我们从示罗把耶和华的约柜抬来吧,让它4:3 ”或作“祂”。与我们同去,好从仇敌手中救我们。”

4于是,他们派人去示罗把那坐在基路伯天使上的万军之耶和华的约柜抬来。以利的两个儿子何弗尼非尼哈也随上帝的约柜同来。 5以色列人看见耶和华的约柜到了营中,就高声欢呼,声音震天动地。 6非利士人听见了喊声就说:“希伯来人在营中喊什么?”后来他们知道是耶和华的约柜到了营中, 7就害怕起来,说:“有神明到了他们营中,我们大祸临头了,我们从来没有遇过这种事情! 8我们大祸临头了!谁能从这些大能的神明手中救我们?在旷野用各种灾祸毁灭埃及人的就是这些神明。 9非利士人啊,要刚强,做大丈夫。不然,我们就会成为希伯来人的奴隶,像他们做我们的奴隶一样。我们要做大丈夫,奋力征战。”

10非利士人和以色列人交战,以色列人败下阵来,纷纷逃回家中。他们伤亡惨重,损失了三万步兵。 11上帝的约柜被掳走了,以利的两个儿子何弗尼非尼哈被杀身亡。

以利之死

12当天有一个便雅悯人逃出了战场,他撕烂衣服,头蒙灰尘,来到示罗13以利正坐在路旁的座位上观望,因为他心里为上帝的约柜担忧。那个从战场回来的人进城报信后,全城的人都放声大哭。 14以利听见哭喊声,就问:“人们为何喊叫?”那人赶忙告诉他。 15那时,以利已经九十八岁,眼睛因为年老而失明。 16报信的人对以利说:“我今天是从战场逃回来的。”以利问:“我的孩子,情况怎么样?” 17报信的答道:“以色列人被非利士人击溃,伤亡惨重,你的两个儿子何弗尼非尼哈都死了,上帝的约柜也被掳走了。” 18以利年老体胖,听到约柜被掳去,就从门边的座位上向后跌倒,颈断身亡。他做士师审理以色列人的事务共四十年。

19以利的儿媳妇、非尼哈的妻子当时怀孕在身,接近产期。她听说上帝的约柜被掳、公公和丈夫都死了,就突然阵痛,生下了孩子。 20在她弥留之际,身旁的妇人对她说:“不要怕,你生了一个男孩。”但她既不理会,也不回答。 21她给孩子取名叫以迦博,意思是:“荣耀离开以色列了”。这是因为上帝的约柜被掳走,她的公公和丈夫都死了。 22她说:“荣耀离开了以色列,因为上帝的约柜已经被掳走了。”

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

1 Samuẹli 4:1-22

1Ọ̀rọ̀ Samuẹli tọ gbogbo àwọn ọmọ Israẹli wá.

Àwọn Filistini gba àpótí ẹ̀rí

Nísinsin yìí àwọn ọmọ Israẹli jáde láti lọ bá àwọn Filistini jà. Àwọn ọmọ Israẹli sì pàgọ́ sí Ebeneseri àti àwọn Filistini ní Afeki. 2Àwọn Filistini mú ogun wọn sọ̀kalẹ̀ láti pàdé Israẹli, nígbà tí ogun náà bẹ̀rẹ̀, àwọn Filistini ṣẹ́gun Israẹli wọ́n pa ẹgbàajì ọkùnrin nínú ogun náà (4,000). 3Nígbà tí àwọn ọmọ-ogun náà padà sí ibùdó, àwọn àgbàgbà Israẹli sì béèrè pé, “Èéṣe ti Olúwa fi mú kí àwọn Filistini ṣẹ́gun wa lónìí? Ẹ jẹ́ kí a gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa láti Ṣilo wá, kí ó ba à le lọ pẹ̀lú wa kí ó sì gbà wá là kúrò lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá wa.”

4Nítorí náà a rán àwọn ènìyàn lọ sí Ṣilo, wọ́n sì gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa àwọn ọmọ-ogun wá, ẹni tí ń wà láàrín àwọn Kérúbù àti àwọn ọmọ Eli méjèèjì Hofini àti Finehasi wà níbẹ̀ pẹ̀lú àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run.

5Nígbà tí àpótí ẹ̀rí Olúwa wá sí ibùdó, gbogbo àwọn ọmọ Israẹli sì dìde láti kígbe tó bẹ́ẹ̀ tí ilẹ̀ sì mì tìtì. 6Ní ìgbà tí àwọn Filistini gbọ́ ariwo náà wọ́n béèrè pé, “Kí ni gbogbo ariwo yìí ní ibùdó Heberu?”

Nígbà tí wọ́n mọ̀ wí pé àpótí ẹ̀rí Olúwa ti wá sí ibùdó, 7Àwọn Filistini sì bẹ̀rù pé, Ọlọ́run kékeré ti wọ ibùdó, wọ́n wí pé, “A wọ wàhálà, irú èyí kò tí ì ṣẹlẹ̀ rí. 8Àwa gbé! Ta ni yóò gbà wá kúrò lọ́wọ́ Ọlọ́run alágbára yìí? Àwọn ni Ọlọ́run tí ó fi ìpọ́njú pa àwọn ará Ejibiti pẹ̀lú gbogbo àjàkálẹ̀-ààrùn ní aginjù. 9Ẹ jẹ́ alágbára Filistini, ẹ ṣe bí ọkùnrin, bí bẹ́ẹ̀ kọ́, ẹ̀yin yóò di ẹrú àwọn Heberu, bí wọ́n ti jẹ́ sí i yín: Ẹ jẹ́ alágbára ọkùnrin, kí ẹ sì jagun!”

10Nígbà náà àwọn Filistini jà, wọ́n sì ṣẹ́gun àwọn Israẹli olúkúlùkù sì sá padà sínú àgọ́ rẹ̀, wọ́n pa ọ̀pọ̀ ènìyàn; Àwọn ará Israẹli tí ó kú sí ogun sì jẹ́ ẹgbàá-mẹ́dógún àwọn ọmọ-ogun orí ilẹ̀ (30,000). 11Wọ́n gba àpótí ẹ̀rí Olúwa, àwọn ọmọkùnrin Eli méjèèjì sì kú, Hofini àti Finehasi.

Ikú Eli

12Lọ́jọ́ kan náà tí ará Benjamini kan sá wá láti ojú ogun tí ó sì lọ sí Ṣilo, aṣọ rẹ̀ sì fàya pẹ̀lú eruku lórí rẹ̀. 13Nígbà tí ó sì dé, Eli sì jókòó sórí àga rẹ̀ ní ẹ̀gbẹ́ ọ̀nà, ó ń wò, ọkàn rẹ̀ kò balẹ̀ nítorí àpótí ẹ̀rí Olúwa. Nígbà tí ọkùnrin náà wọ ìlú tí ó sì sọ ohun tí ó ṣẹlẹ̀, gbogbo ìlú bẹ̀rẹ̀ sí sọkún.

14Eli gbọ́ ìró ohùn ẹkún náà ó sì béèrè pé, “Kí ni ìtumọ̀ ariwo yìí?”

Ọkùnrin náà sì sáré tọ Eli wá 15Eli sì di ẹni méjì-dínlọ́gọ́run ọdún, tí ojú rẹ̀ di bàìbàì, kò sì ríran mọ́. 16Ọkùnrin náà sọ fún Eli, “Mo ṣẹ̀ṣẹ̀ dé láti ibi ogun náà ni: mo sá láti ibi ogun náà wá lónìí.”

Eli sì béèrè pé, “Kí ni ó ṣẹlẹ̀ ọmọ mi?”

17Ọkùnrin tí ó mú ìròyìn náà wá dáhùn pé, “Israẹli sá níwájú àwọn Filistini, ìṣubú àwọn ọmọ-ogun náà sì pọ̀ lọ́pọ̀lọpọ̀ pẹ̀lú àwọn ọmọ rẹ méjèèjì, Hofini àti Finehasi, wọ́n kú, wọ́n sì ti gba àpótí ẹ̀rí Olúwa lọ.”

18Nígbà tí ó dárúkọ àpótí ẹ̀rí Olúwa, Eli sì ṣubú sẹ́yìn kúrò lórí àga ní ẹ̀gbẹ́ bodè, ọrùn rẹ̀ ṣẹ́, ó sì kú, nítorí tí ó jẹ́ arúgbó ọkùnrin, ó sì tóbi, ó ti darí àwọn Israẹli fún ogójì ọdún.

19Aya ọmọ rẹ̀, ìyàwó Finehasi, ó lóyún ó súnmọ́ àkókò àti bí. Nígbà tí ó gbọ́ ìròyìn náà wí pé wọ́n ti gba àpótí ẹ̀rí Olúwa lọ àti wí pé baba ọkọ rẹ̀ àti ọkọ rẹ̀ ti kú, ó rọbí ó sì bímọ, ó sì borí ìrora ìrọbí náà. 20Bí ó ti ń kú lọ, obìnrin tí ó dúró tì í wí pé, “Má ṣe bẹ̀rù; nítorí o ti bí ọmọ ọkùnrin.” Ṣùgbọ́n kò sọ̀rọ̀ tàbí kọ ibi ara sí i.

21Ó sì pe ọmọ náà ní Ikabodu, wí pé, “Kò sí ògo fún Israẹli mọ́” nítorí tí wọ́n ti gba àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run àti ikú baba ọkọ rẹ̀ àti ti ọkọ rẹ̀. 22Ó si wí pé, “Ògo kò sí fún Israẹli mọ́, nítorí ti a ti gbá àpótí Ọlọ́run.”