利未记 2 – CCB & YCB

Chinese Contemporary Bible (Simplified)

利未记 2:1-16

献素祭的条例

1“如果有人献素祭给耶和华,要用细面粉作祭物。要在细面粉上浇油、加乳香, 2带到祭司——亚伦的子孙那里。祭司要抓一把浇了油的细面粉,连同所有乳香,作为象征放在坛上焚烧。这是蒙耶和华悦纳的馨香火祭。 3剩下的素祭要归亚伦及其子孙,这在献给耶和华的火祭中是至圣的。

4“如果献用炉子烤的素祭,要献调油的无酵细面饼,或涂油的无酵薄饼。

5“如果献用平底锅烤的素祭,要献调油的无酵细面饼。 6要把饼掰成碎块,浇上油。这是素祭。

7“如果献用煎锅煎的素祭,要献用细面粉和油做的祭物。

8“要把做好的素祭带到耶和华面前,交给祭司献在祭坛上。 9祭司要从中取出一部分,作为象征放在祭坛上焚烧。这是蒙耶和华悦纳的馨香火祭。 10剩下的素祭要归亚伦及其子孙。在献给耶和华的火祭中,这是至圣之物。

11“献给耶和华的任何素祭都不可含酵,因为你们不可把酵或蜜当作火祭献给耶和华。 12你们可以把酵和蜜作为初熟之祭献给耶和华,但不可作为馨香之祭烧在祭坛上。 13所有素祭中都要放盐,借此提醒你们与上帝所立的约。所有祭物中都要放盐。

14“如果将初熟的谷物献给耶和华作素祭,要用烘好后压碎的新麦穗, 15加上油和乳香。这是素祭。 16祭司要将一些压碎的麦穗、油及所有乳香作为象征焚烧。这是献给耶和华的火祭。”

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Lefitiku 2:1-16

Ọrẹ ohun jíjẹ

1“ ‘Bí ẹnìkan bá mú ọrẹ ẹbọ ohun jíjẹ wá fún Olúwa ọrẹ rẹ̀ gbọdọ̀ jẹ́ ìyẹ̀fun dáradára, kí ó da òróró sí i, kí o sì fi tùràrí sí i, 2kí ó sì gbé lọ fún àwọn ọmọ Aaroni tí í ṣe àlùfáà. Àlùfáà yóò bu ẹ̀kúnwọ́ kan nínú ìyẹ̀fun àti òróró náà, pẹ̀lú gbogbo tùràrí kí ó sì sun ún gẹ́gẹ́ bí ẹbọ ìrántí lórí pẹpẹ, ọrẹ tí a fi iná ṣe, àní òórùn dídùn sí Olúwa. 3Ìyókù nínú ọrẹ ohun jíjẹ náà jẹ́ ti Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀, ó jẹ́ ìpín tí ó mọ́ jùlọ nínú ọrẹ tí a fi iná sun sí Olúwa.

4“ ‘Bí ẹ bá mú ọrẹ ohun jíjẹ, èyí tí a yan lórí ààrò iná, kí ó jẹ́ ìyẹ̀fun kíkúnná dáradára, àkàrà tí a ṣe láìní ìwúkàrà, tí a sì fi òróró pò àti àkàrà fẹ́lẹ́fẹ́lẹ́ tí a ṣe láìní ìwúkàrà èyí tí a fi òróró pò. 5Bí ọrẹ ẹbọ rẹ bá jẹ́ inú àwo pẹẹrẹ ni o ti ṣe ohun jíjẹ rẹ, kí ó jẹ́ ìyẹ̀fun dáradára tí a fi òróró pò, kò sì gbọdọ̀ ní ìwúkàrà. 6Rún un kí o sì da òróró sí i lórí, ọrẹ ohun jíjẹ ni. 7Bí ọrẹ ẹbọ rẹ bá jẹ́ ẹbọ ohun jíjẹ, tí a yan nínú apẹ, ìyẹ̀fun dáradára ni kí o fi ṣè é pẹ̀lú òróró. 8Mú ọrẹ ohun jíjẹ tí a fi àwọn nǹkan wọ̀nyí ṣe wá fún Olúwa gbé e fún àlùfáà, ẹni tí yóò gbe e lọ sí ibi pẹpẹ, 9Àlùfáà yóò sì mú ẹbọ ìrántí nínú ọrẹ ohun jíjẹ yìí, yóò sì sun ún lórí pẹpẹ gẹ́gẹ́ bí ọrẹ tí a fi iná sun, àní òórùn dídùn sí Olúwa. 10Ìyókù nínú ọrẹ ohun jíjẹ yìí jẹ́ ti Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀, ó jẹ́ èyí tí ó mọ́ jùlọ nínú ọrẹ tí a fi iná sun sí Olúwa.

11“ ‘Gbogbo ọrẹ ohun jíjẹ tí ẹ bá mú wá fún Olúwa kò gbọdọ̀ ní ìwúkàrà nínú, nítorí pé ẹ kò gbọdọ̀ sun ohun wíwú tàbí oyin nínú ọrẹ tí ẹ fi iná sun sí Olúwa. 12Ẹ lè mú wọn wá fún Olúwa gẹ́gẹ́ bí ọrẹ àkọ́so ṣùgbọ́n ẹ kò gbọdọ̀ mú wọn wá sórí pẹpẹ gẹ́gẹ́ bí òórùn dídùn. 13Ẹ fi iyọ̀ dun gbogbo ọrẹ ohun jíjẹ yín. Ẹ má ṣe aláìfi iyọ̀ májẹ̀mú Ọlọ́run yín sínú àwọn ọrẹ ohun jíjẹ yín, ẹ fi iyọ̀ sí gbogbo ọrẹ yín.

14“ ‘Bí ẹ bá mú ọrẹ ohun jíjẹ ti àkọ́so oko yín wá fún Olúwa kí ẹ mú ọkà tuntun tí a fi iná yan. 15Kí ẹ da òróró lé e lórí, kí ẹ sì fi tùràrí sí i, ó jẹ́ ọrẹ ohun jíjẹ. 16Àlùfáà yóò sun ẹbọ ìrántí lára ọkà àti òróró náà, pẹ̀lú gbogbo tùràrí gẹ́gẹ́ bí ọrẹ tí a fi iná sun sí Olúwa.