以赛亚书 32 – CCB & YCB

Chinese Contemporary Bible (Simplified)

以赛亚书 32:1-20

公义的君王

1看啊,必有一位君王以公义治国,

官员们必秉公施政。

2每人都像躲避狂风暴雨的庇护所,

如荒漠中的溪流,

又似干旱之地遮荫的大磐石。

3人们的眼睛必不再迷蒙,

耳朵必能听见。

4急躁的人必慎思明辨,

口吃的人必说话清楚流利。

5愚昧人必不再被奉为尊贵之人,

恶棍必不再受尊重。

6因为愚昧人说愚昧话,

心里邪恶,行事不义,

亵渎耶和华,

使饥饿的人没饭吃,

使口渴的人没水喝。

7恶棍们手段邪恶,

用阴谋诡计和谎言毁灭困苦的人,

即使穷人的诉求有理也是枉然。

8高尚的人计划高尚的事,

在高尚的事上持之以恒。

9生活安逸的妇女啊,

来听我的声音!

无忧无虑的女子啊,

要侧耳听我的言语!

10无忧无虑的女子啊,

再过一年多,

你们必因恐惧而战抖。

那时,必没有葡萄可摘,

没有果子可收。

11生活安逸的妇女啊,战抖吧!

无忧无虑的女子啊,颤栗吧!

你们要脱下衣服,

腰束麻布,

12为美好的田地和硕果累累的葡萄树捶胸痛哭吧!

13为我百姓那长满荆棘和蒺藜的土地,

为那曾经充满欢乐的城邑和家庭哀哭吧!

14王宫必被遗弃,

繁荣的城邑必荒芜,

山冈和瞭望塔必永远成为野驴的乐园、羊群的草场。

15等到圣灵从上面浇灌我们的时候,

旷野要变为沃野,

沃野上庄稼茂密如林。

16那时,公平必充满旷野,

公义必遍布沃野。

17公义必带来平安,

公义所结的果子是永远的和平与安宁。

18我的子民必住在平安之地、

安稳之处、平静之所。

19但冰雹必扫平森林,荡平城邑。

20你们这些在河边撒种、自由地牧放牛驴的人有福了!

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Isaiah 32:1-20

Ìjọba òdodo náà

1Wò ó, ọba kan yóò jẹ nínú òdodo

àwọn olórí yóò máa fi ìdájọ́ ṣe àkóso.

2Ẹnìkọ̀ọ̀kan yóò jẹ́ bí ibi ìṣápamọ́ kúrò lọ́wọ́ afẹ́fẹ́

àti ààbò kúrò lọ́wọ́ ìjì,

gẹ́gẹ́ bí odò omi ní ilẹ̀ aṣálẹ̀,

àti bí òjìji àpáta ńlá ní ilẹ̀ gbígbẹ.

3Nígbà náà ni ojú àwọn tí ó rí kò ní padé mọ́,

àti etí àwọn tí ó gbọ́ yóò tẹ́tí sílẹ̀.

4Ọkàn àwọn oníwàdùwàdù ni yóò là tí yóò sì yè,

àti ahọ́n tí ń kólòlò ni yóò là geerege.

5A kò ní pe òmùgọ̀ ní ọlọ́lá mọ́

tàbí kí a fi ọ̀wọ̀ tí ó ga jù fún aláìlóòótọ́ ènìyàn.

6Nítorí òmùgọ̀ sọ̀rọ̀ òmùgọ̀,

ọkàn rẹ̀ kún fún ìwà ibi:

òun hùwà àìwà-bí-Ọlọ́run

ó sì ń tan àṣìṣe tí ó kan Olúwa kalẹ̀;

ẹni ebi ń pa ló fi sílẹ̀ lófo

àti fún àwọn tí òǹgbẹ ń gbẹ

ni ó mú omi kúrò.

7Ibi ni gbogbo ọgbọ́n àwọn ìkà ènìyàn jẹ́,

ó ń gba èrò búburú

láti fi ọ̀rọ̀ èké pa tálákà run,

bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ẹ̀bẹ̀ aláìní sì tọ̀nà.

8Ṣùgbọ́n ọlọ́lá ènìyàn a máa pète ohun ńlá

àti nípa èrò rere ni yóò dúró.

Àwọn obìnrin Jerusalẹmu

9Ẹ̀yin obìnrin tí ẹ ti gba ìtẹ́lọ́rùn gidi

ẹ dìde kí ẹ tẹ́tí sí mi,

ẹ̀yin ọ̀dọ́mọbìnrin tí ọkàn yín ti balẹ̀,

ẹ gbọ́ ohun tí mo fẹ́ sọ!

10Ní ó lé díẹ̀ ní ọdún kan

ẹ̀yin tí ọkàn an yín balẹ̀ yóò wárìrì;

ìkórè àjàrà kò ní múnádóko,

bẹ́ẹ̀ ni ìkórè èso kò ní sí.

11Wárìrì, ẹ̀yin obìnrin onítẹ̀lọ́rùn

bẹ̀rù, ẹ̀yin ọ̀dọ́mọbìnrin tí ẹ rò pé ọkàn yín balẹ̀!

Ẹ bọ́ aṣọ yín kúrò,

ẹ ró aṣọ ọ̀fọ̀ mọ́ ẹ̀gbẹ́ yín.

12Ẹ lu ọmú yín fún pápá ìgbádùn náà,

fún àwọn àjàrà eléso

13àti fún ilẹ̀ àwọn ènìyàn mi

ilẹ̀ tí ó ti kún fún ẹ̀gún àti ẹ̀wọ̀n—

bẹ́ẹ̀ ni, kẹ́dùn fún gbogbo ilé ìtura

àti fún ìlú àríyá yìí.

14Ilé olódi ni a ó kọ̀sílẹ̀,

ìlù aláriwo ni a ó kọ̀ tì;

ilé olódi àti ilé ìṣọ́ ni yóò di ihò títí láéláé,

ìdùnnú àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ àti pápá

oko fún àwọn ẹran ọ̀sìn,

15títí a ó fi tú Ẹ̀mí sí wa lórí láti òkè wá,

àti ti aṣálẹ̀ tí yóò dí pápá oko ọlọ́ràá

àti tí pápá ọlọ́ràá yóò dàbí ẹgàn.

16Ẹ̀tọ́ yóò máa gbé ní inú aṣálẹ̀

àti òdodo yóò sì máa gbé ní pápá oko ọlọ́ràá.

17Èso òdodo náà yóò sì jẹ́ àlàáfíà;

àbájáde òdodo yóò sì jẹ́ ìdákẹ́ jẹ́ẹ́ àti ìgbẹ́kẹ̀lé títí láé.

18Àwọn ènìyàn mi yóò máa gbé ní ibùgbé àlàáfíà,

ní ibùgbé ìdánilójú,

ní àwọn ibi ìsinmi tí ó parọ́rọ́.

19Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé yìnyín ti tẹ́jú igbó pẹrẹsẹ

àti tí ojú ìlú ti tẹ́ pẹrẹsẹ pátápátá,

20báwo ni ẹ ó ti jẹ́ alábùkún tó,

nípa gbígbin irúgbìn sí ipa odò gbogbo,

àti nípa jíjẹ́ kí àwọn màlúù yín àti

àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ jẹ láìsí ìdíwọ́.