Titu 1 – YCB & SZ-PL

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Titu 1:1-16

1Paulu, ìránṣẹ́ Ọlọ́run àti aposteli Jesu Kristi, gẹ́gẹ́ bí ìgbàgbọ́ àwọn àyànfẹ́ Ọlọ́run àti ìmọ̀ òtítọ́ irú èyí tí í máa darí ènìyàn sí ìgbé ayé ìwà-bí-Ọlọ́run— 2ìgbàgbọ́ àti ìmọ̀ tí ó dúró lórí ìrètí iyè àìnípẹ̀kun, èyí tí Ọlọ́run tí kì í purọ́ ti ṣe ìlérí rẹ̀ ṣáájú kí ayé tó bẹ̀rẹ̀, 3àti pé ní àkókò tirẹ̀, òun ti fi ọ̀rọ̀ rẹ̀ hàn nínú ìwàásù tí a fi lé mi lọ́wọ́ nípa àṣẹ Ọlọ́run Olùgbàlà wa,

41.4: 2Kọ 8.23; Ga 2.3; 2Tm 4.10.Sí Titu, ọmọ mi tòótọ́ nínú ìgbàgbọ́ wa kan náà:

Oore-ọ̀fẹ́ àti àlàáfíà láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run Baba àti Kristi Jesu Olùgbàlà wa.

Iṣẹ́ Titu sí Krete

5Ìdí tí mo fi fi ọ́ sílẹ̀ ní Krete ni pé kí o lè ṣe àṣepé àwọn iṣẹ́ tó ṣẹ́kù. Mo sì ń rọ̀ ọ́ kí o yan àwọn alàgbà ní ìlú kọ̀ọ̀kan gẹ́gẹ́ bí mo ṣe darí rẹ̀. 6Ẹni tí yóò jẹ́ alàgbà gbọdọ̀ jẹ́ aláìlábùkù, wọ́n gbọdọ̀ jẹ́ onìyàwó kan, ọmọ wọn náà gbọdọ̀ jẹ́ onígbàgbọ́ tí kò ní ẹ̀sùn ìwà ipá tàbí ẹ̀sùn àìgbọ́ràn kankan. 7Alábojútó jẹ́ ẹni tí a gbé iṣẹ́ Ọlọ́run lé lọ́wọ́, nítorí náà, kò gbọdọ̀ ní àbùkù kankan tàbí agbéraga, oníjà, kò gbọdọ̀ jẹ́ ọ̀mùtí tàbí alágídí tàbí olójúkòkòrò. 8Wọ́n ní láti jẹ́ olùfẹ́ àlejò ṣíṣe, olùfẹ́ ohun tí ó dára. Wọ́n ní láti jẹ́ ẹni tí ó kò ara rẹ̀ ní ìjánu, ẹni dúró ṣinṣin, ọlọ́kàn mímọ́, àti ẹni oníwàtítọ́. 9Ó gbọdọ̀ di ẹ̀kọ́ nípa ìdúró ṣinṣin mú dáradára gẹ́gẹ́ bí ó ti kọ́ ọ, kí ó lè fi ẹ̀kọ́ tí ó yè kooro kọ́ àwọn ẹlòmíràn. Nípa èyí, yóò lè fi ìdí òtítọ́ múlẹ̀ fún àwọn alátakò.

10Nítorí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn ni ọlọ̀tẹ̀, asọ̀rọ̀ asán àti ẹlẹ́tàn pàápàá jùlọ láàrín àwọn onílà. 11Ó gbọdọ̀ pa wọ́n lẹ́nu mọ́, nítorí wí pé wọ́n ń pa agbo Ọlọ́run run, nípasẹ̀ àwọn ẹ̀kọ́ tí kò jẹ́ èyí tí wọ́n ń kọ́ni. Èyí ni wọ́n ń ṣe fún ère àìṣòdodo. 12Ọ̀kan nínú àwọn wòlíì wọn pàápàá sọ wí pé. “Òpùrọ́ ní àwọn ará Krete, wọ́n jẹ́ ẹranko búburú tí kò sé tù lójú, ọ̀lẹ, àti oníwọra”. 13Òtítọ́ ni ẹ̀rí yìí. Nítorí náà, bá wọn wí gidigidi, kí wọn ba à lè yè koro nínú ìgbàgbọ́ 14kí àwọn má ṣe fiyèsí ìtàn lásán ti àwọn Júù, àti òfin àwọn ènìyàn tí wọ́n yípadà kúrò nínú òtítọ́. 15Sí ọlọ́kàn mímọ́, ohun gbogbo ló jẹ́ mímọ́, ṣùgbọ́n àwọn tó ti díbàjẹ́ tí wọ́n kò sí ka ohunkóhun sí mímọ́. Nítòótọ́, àti ọkàn àti ẹ̀rí ọkàn wọn ló ti díbàjẹ́. 16Wọ́n ń fẹnu sọ wí pé àwọn mọ Ọlọ́run, ṣùgbọ́n wọ́n sẹ́ ẹ nípa ìṣe wọn. Wọ́n díbàjẹ́, wọn si jẹ aláìgbọ́ràn, bẹ́ẹ̀ ni wọ́n kò wúlò lọ́nàkọnà ní ti iṣẹ́ rere gbogbo.

Słowo Życia

Tytusa 1:1-16

Pozdrowienie

1Ja, Paweł, piszę do ciebie jako sługa Boga i apostoł Jezusa Chrystusa. Zostałem bowiem powołany do tego, aby głosić wiarę ludziom wybranym przez Boga i pomóc im poznać prawdę. Dlatego nauczam ich, jak mają żyć, aby podobać się Bogu. 2Wiara ta daje ludziom niepodważalną nadzieję na życie wieczne, które Bóg obiecał już przed wiekami—a On nigdy nie kłamie. 3Teraz zaś, w ustalonym przez siebie czasie, Bóg—nasz Zbawiciel—objawił światu dobrą nowinę i zlecił mi głoszenie jej.

4Tytusie, dzięki naszej wspólnej wierze, jesteś mi jak rodzony syn. Niech Bóg Ojciec i Chrystus Jezus, nasz Zbawiciel, obdarzają cię swoją łaską i pokojem!

Zadanie Tytusa na Krecie

5Zostawiłem cię na Krecie, abyś dokończył to, co jeszcze zostało do zrobienia, i byś we wszystkich miastach wyznaczył spośród wierzących starszych, którzy będą kierować miejscowymi kościołami. Jak już ci wcześniej powiedziałem, 6muszą to być ludzie nienaganni: wierni swoim żonom i mający wierzące dzieci, którym nie można zarzucić niemoralności i nieposłuszeństwa. 7Przywódca, który w imieniu Boga zarządza Jego kościołem, musi być bowiem bez zarzutu. Nie może to być człowiek zarozumiały, impulsywny, pijak, awanturnik ani ktoś, kto jest zachłanny. 8Przeciwnie, powinien być gościnny, kochający dobro, rozsądny, prawy, pobożny i opanowany. 9Powinien wiernie trzymać się prawdy i umieć—poprzez zdrową naukę—zachęcać innych wierzących, a także wykazywać błędy tym, którzy się jej sprzeciwiają.

10Wielu jest bowiem takich, którzy nie okazują posłuszeństwa, a poprzez bezsensowne dyskusje zwodzą innych ludzi, szczególnie tych, którzy wywodzą się z judaizmu. 11Takich trzeba zdecydowanie uciszać, bo swoim złym nauczaniem przynoszą szkodę całym rodzinom. Tym, co ich naprawdę interesuje, są pieniądze. 12Nawet ich własny prorok powiedział o nich: „Kreteńczycy to kłamcy, złe bestie i lenie”. 13I miał rację! Dlatego zwracaj Kreteńczykom uwagę na ich grzechy i prowadź ich do zdrowej wiary, 14aby nie słuchali żydowskich opowiadań i przykazań wymyślonych przez ludzi, którzy odrzucają prawdę.

15Dla tych, którzy mają czyste serce, wszystko jest czyste i dobre. Dla tych zaś, którzy mają w sercach zło i nie wierzą w prawdę, nie ma nic czystego. Ich sumienie i umysł są bowiem pogrążone w grzechu. 16Twierdzą, że znają Boga, ale ich życie zdecydowanie temu zaprzecza. Ludzie ci budzą odrazę, nie są bowiem zdolni do okazania posłuszeństwa Bogu i czynienia jakiegokolwiek dobra.