Sekariah 9 – YCB & BPH

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Sekariah 9:1-17

Ìdájọ́ lórí àwọn ọ̀tá Israẹli

1Ọ̀rọ̀-ìmọ̀.

Ọ̀rọ̀ Olúwa kọjú ìjà sí Hadiraki,

Damasku ni yóò sì jẹ́ ibi ìsinmi rẹ̀;

nítorí ojú Olúwa ń bẹ lára ènìyàn,

àti lára gbogbo ẹ̀yà Israẹli.

2Àti Hamati pẹ̀lú yóò ṣe ààlà rẹ̀

Tire àti Sidoni bí o tilẹ̀ ṣe ọlọ́gbọ́n gidigidi.

3Tire sì mọ odi líle fún ara rẹ̀,

ó sì kó fàdákà jọ bí eruku,

àti wúrà dáradára bí ẹrẹ̀ ìgboro.

4Ṣùgbọ́n, Olúwa yóò kó gbogbo ohun ìní rẹ̀ lọ,

yóò sì pa agbára rẹ̀ run ní ojú Òkun,

a ó sì fi iná jó o run.

5Aṣkeloni yóò rí í, yóò sì bẹ̀rù;

Gasa pẹ̀lú yóò rí í, yóò sì káàánú gidigidi,

àti Ekroni: nítorí tí ìrètí rẹ̀ yóò ṣákì í.

Gasa yóò pàdánù ọba rẹ̀,

Aṣkeloni yóò sì di ahoro.

6Ọmọ àlè yóò sì gbé inú Aṣdodu,

Èmi yóò sì gé ìgbéraga àwọn Filistini kúrò.

7Èmi yóò sì mu ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ kúrò ni ẹnu rẹ̀,

àti àwọn ohun èèwọ̀ kúrò láàrín eyín rẹ̀:

ṣùgbọ́n àwọn tó ṣẹ́kù yóò jẹ́ tí Ọlọ́run wa,

wọn yóò sì jẹ baálẹ̀ ní Juda,

àti Ekroni ni yóò rí bí Jebusi.

8Èmi yóò sì dó yí ilẹ̀ mi ká

nítorí ogun àwọn tí wọ́n ń wá ohun tí wọn yóò bàjẹ́ kiri,

kò sí aninilára tí yóò bori wọn mọ́:

nítorí ni ìsinsin yìí ni mo fi ojú ṣọ́ wọn.

Ọba sioni ń bọ̀

99.9: Mt 21.5; Jh 12.15.Kún fún ayọ̀, ìwọ ọmọbìnrin Sioni,

hó ìhó ayọ̀, ìwọ ọmọbìnrin Jerusalẹmu.

Wò ó, ọba rẹ ń bọ̀ wá sọ́dọ̀ rẹ:

òdodo ni òun, ó sì ní ìgbàlà;

ó ní ìrẹ̀lẹ̀, ó sì ń gun kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́,

àní ọmọ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́.

10Èmi ó sì gbé kẹ̀kẹ́ kúrò ni Efraimu,

àti ẹṣin ogun kúrò ni Jerusalẹmu,

a ó sì ṣẹ́ ọrun ogun.

Òun yóò sì kéde àlàáfíà sí àwọn kèfèrí.

Ìjọba rẹ̀ yóò sì gbilẹ̀ láti Òkun dé Òkun,

àti láti odò títí de òpin ayé.

11Ní tìrẹ, nítorí ẹ̀jẹ̀ májẹ̀mú mi pẹ̀lú rẹ,

Èmi ó dá àwọn ìgbèkùn rẹ̀ sílẹ̀ kúrò nínú ọ̀gbun.

12Ẹ padà sínú odi agbára yín, ẹ̀yin òǹdè ti o ni ìrètí:

àní lónìí yìí èmi sọ pé, èmi o san án fún ọ ni ìlọ́po méjì.

13Èmi ó fa Juda le bí mo ṣe fa ọrun mi le,

mo sì fi Efraimu kún un,

Èmi yóò gbé àwọn ọmọ rẹ ọkùnrin dìde, ìwọ Sioni,

sí àwọn ọmọ rẹ̀ ọkùnrin, ìwọ Giriki,

mo ṣe ọ́ bí idà alágbára.

Olúwa yóò farahàn

14Olúwa yóò sì fi ara hàn ní orí wọn;

ọfà rẹ̀ yóò sì jáde lọ bí mọ̀nàmọ́ná.

Olúwa Olódùmarè yóò sì fọn ìpè,

Òun yóò sì lọ nínú atẹ́gùn ìjì gúúsù.

15Olúwa àwọn ọmọ-ogun yóò dáàbò bò wọ́n;

wọn ó sì jẹ ni run,

wọn ó sì tẹ òkúta kànnàkànnà mọ́lẹ̀;

wọn ó sì mu ẹ̀jẹ̀ wọn bí wáìnì,

wọn ó sì kún bí ọpọ́n,

wọn ó sì rin ṣinṣin bí àwọn igun pẹpẹ.

16Olúwa Ọlọ́run wọn yóò sì gbà wọ́n là ni ọjọ́ náà

bí agbo ènìyàn rẹ̀:

nítorí wọn ó dàbí àwọn òkúta adé,

tí a gbé sókè bí àmì lórí ilẹ̀ rẹ̀.

17Nítorí oore rẹ̀ tí tóbi tó, ẹwà rẹ̀ sì tí pọ̀!

Ọkà yóò mú ọ̀dọ́mọkùnrin dárayá,

àti ọtí wáìnì tuntun yóò mú àwọn ọ̀dọ́mọbìnrin ṣe bẹ́ẹ̀ pẹ̀lú.

Bibelen på hverdagsdansk

Zakariasʼ Bog 9:1-17

Dommen over Israels fjender

1Det følgende er et profetisk ord om landet Hadrak9,1 Et symbolsk navn, der betyder „stærk-svag”. Det er uklart, om der tænkes på Syrien eller det medisk-persiske rige. og specielt om byen Damaskus, for hele menneskeheden og specielt Israels stammer står til ansvar over for Herren. 2Hans straf vil ramme Hamat ved grænsen til Damaskus, og han vil slå ned på Tyrus og Sidon på trods af deres dygtighed. 3Selvom Tyrus har bygget sig en stærk fæstning og samlet sig sølv og guld i massevis, 4vil Herren ødelægge byen, skubbe dens fæstning i havet, og lade ilden opæde resten.

5„Ashkalon vil høre om det og ryste af skræk,” siger Herren. „Gaza og Ekron vil vånde sig i fortvivlelse og håbløshed. Gaza vil miste sin konge, Ashkalon vil blive folketom, 6og et fremmed folk vil overtage Ashdod. Sådan gør jeg ende på filistrenes hovmod. 7Jeg sætter en stopper for deres afgudsdyrkelse og river det blodige offerkød ud af munden på dem. Men en rest af dem skal vende sig til Gud og indlemmes som en slægt i Judas folk, ligesom jebusitterne for længe siden blev det. 8Og jeg vil slå lejr omkring mit folk og forhindre, at fremmede hære kommer ind i landet. Jeg vil selv stå vagt om min ejendom.”

Kongen kommer

9„Fryd jer og råb af glæde, Jerusalems indbyggere! Se, jeres konge er på vej. Han kommer med retfærdighed og frelse, og han er ydmyg og rider på et hanæsel—det er et æselføl. 10Jeg vil fjerne stridsvognene fra Israel og krigshestene fra Jerusalem, og jeg vil afvæbne de stridende grupper. Kongen vil bringe fred til alle folkeslag, og han skal herske overalt, fra hav til hav, og fra Eufratfloden til jordens ende.

11På grund af den pagt, jeg indgik med jer, og som blev beseglet med blod, vil jeg befri jer fra jeres fangehuller. 12Kom hjem i sikkerhed, for nu er der håb. Jeg lover i dag at give jer dobbelt så meget tilbage, som I har mistet. 13Juda, du er min bue! Israel, du er min pil! Jerusalem, du er mit sværd, hvormed jeg skal besejre fjenderne.”

Kongen leder sit folk i det endelige slag

14Herren selv vil lede sit folk i kampen. Hans pile farer af sted som lyn. Den Almægtige blæser alarm, stormer frem som en hvirvelvind fra ørkenen i syd. 15Han beskytter sit folk, mens de slår fjenderne ned og træder dem under fode. De bliver som berusede af sejren og hugger fjenden ned i et stort blodbad. 16Til den tid skal Herren, deres Gud, frelse dem, som hyrden, der redder sin hjord, og de skal stråle i det land, han har givet dem, som juveler i en kongekrone. 17Hvilken vidunderlig fremtid. De unge mænd og piger vil være sunde og stærke, for der skal være rigeligt med korn og vin.