Sefaniah 3 – YCB & NIRV

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Sefaniah 3:1-20

Ọjọ́ iwájú Jerusalẹmu

1Ègbé ni fún ìlú aninilára,

ọlọ̀tẹ̀ àti aláìmọ́.

2Òun kò gbọ́rọ̀ sí ẹnikẹ́ni,

òun kò gba ìtọ́ni,

òun kò gbẹ́kẹ̀lé Olúwa,

bẹ́ẹ̀ ni òun kò súnmọ́ ọ̀dọ̀ Ọlọ́run rẹ̀.

3Àwọn olórí rẹ̀ jẹ́ kìnnìún tí ń ké ramúramù,

àwọn onídàájọ́ rẹ̀, ìkookò àṣálẹ́ ni wọn,

wọn kò sì fi nǹkan kan kalẹ̀ fún òwúrọ̀.

4Àwọn wòlíì rẹ̀ gbéraga,

wọ́n sì jẹ́ alárékérekè ènìyàn.

Àwọn àlùfáà rẹ̀ ti ba ibi mímọ́ jẹ́,

wọ́n sì rú òfin.

5Olúwa ni àárín rẹ̀ jẹ́ olódodo;

kì yóò ṣe ohun tí kò tọ̀nà.

Àràárọ̀ ni ó máa ń mú ìdájọ́ rẹ̀ wá sí ìmọ́lẹ̀,

kì í sì kùnà ní gbogbo ọjọ́ tuntun,

síbẹ̀ àwọn aláìṣòótọ́ kò mọ ìtìjú.

6“Èmi ti ké àwọn orílẹ̀-èdè kúrò,

ilé gíga wọn sì ti bàjẹ́.

Mo ti fi ìgboro wọn sílẹ̀ ní òfo

tó bẹ́ẹ̀ tí ẹnìkankan kò kọjá níbẹ̀.

Ìlú wọn parun tó bẹ́ẹ̀ tí kò sí

ẹnìkan tí yóò ṣẹ́kù,

kò sì ní sí ẹnìkan rárá.

7Èmi wí fún ìlú náà wí pé,

‘Nítòótọ́, ìwọ yóò bẹ̀rù mi,

ìwọ yóò sì gba ìtọ́ni!’

Bẹ́ẹ̀ ni, a kì yóò ké ibùgbé rẹ̀ kúrò

bí ó ti wù kí ń jẹ wọ́n ní yà tó.

Ṣùgbọ́n síbẹ̀ wọ́n sì tún ní ìtara

láti ṣe ìbàjẹ́.

8Nítorí náà ẹ dúró dè mí,” ni Olúwa wí,

“títí di ọjọ́ náà tí èmi yóò fi jẹ́rìí sí yin.

Nítorí ìpinnu mi ni láti kó orílẹ̀-èdè jọ

kí èmi kí ó lè kó ilẹ̀ ọba jọ

àti láti da ìbínú mi jáde sórí wọn,

àní gbogbo ìbínú gbígbóná mi.

Nítorí gbogbo ayé

ni a ó fi iná owú mi jẹ run.

Ìràpadà àwọn ènìyàn tókù

9“Nígbà náà ni èmi yóò yí èdè àwọn ènìyàn padà sí èdè mímọ́,

nítorí kí gbogbo wọn bá a lè máa pe orúkọ Olúwa,

láti fi ọkàn kan sìn ín.

10Láti òkè odò Etiopia,

àwọn olùjọsìn mi, àwọn ènìyàn mi tí ó ti fọ́nká,

yóò mú ọrẹ wá fún mi.

11Ní ọjọ́ náà ni a kì yóò sì dójútì

nítorí gbogbo iṣẹ́ ibi ni tí ó ti ṣẹ̀ sí mi,

nígbà náà ni èmi yóò mu

kúrò nínú ìlú yìí, àwọn tí ń yọ̀ nínú ìgbéraga wọn.

Ìwọ kì yóò sì gbéraga mọ́

ní òkè mímọ́ mi.

12Ṣùgbọ́n Èmi yóò fi àwọn ọlọ́kàn tútù

àti onírẹ̀lẹ̀ sílẹ̀ pẹ̀lú ni àárín rẹ̀,

wọn yóò sì gbẹ́kẹ̀lé orúkọ Olúwa.

13Àwọn ìyókù Israẹli kì yóò hùwà ibi,

wọn kì yóò sọ̀rọ̀ èké.

Bẹ́ẹ̀ ni a kì yóò rí

ahọ́n àrékérekè ní ẹnu wọn.

Àwọn yóò jẹun, wọn yóò sì dùbúlẹ̀,

bẹ́ẹ̀ ni ẹnikẹ́ni kì yóò dẹ́rùbà wọ́n.”

14Kọrin, ìwọ ọmọbìnrin Sioni,

kígbe sókè, ìwọ Israẹli!

Fi gbogbo ọkàn yọ̀, kí inú rẹ kí ó sì dùn,

ìwọ ọmọbìnrin Jerusalẹmu.

15Olúwa ti mú ìdájọ́ rẹ wọ̀n-ọn-nì kúrò,

ó sì ti ti àwọn ọ̀tá rẹ padà sẹ́yìn.

Olúwa, ọba Israẹli wà pẹ̀lú rẹ;

ìwọ kì yóò sì bẹ̀rù ibi kan mọ́.

16Ní ọjọ́ náà, wọn yóò sọ fún Jerusalẹmu pé,

“Má ṣe bẹ̀rù Sioni;

má sì ṣe jẹ́ kí ọwọ́ rẹ kí ó dẹ̀.

17Olúwa Ọlọ́run rẹ wà pẹ̀lú rẹ,

Ó ní agbára láti gbà ọ là.

Yóò yọ̀ ni orí rẹ fún ayọ̀;

Yóò tún ọ ṣe nínú ìfẹ́ rẹ̀,

Yóò sì fi orin yọ̀ ní orí rẹ.”

18“Èmi ó kó àwọn tí ó ń banújẹ́ fún àjọ̀dún tí a yàn jọ,

àwọn tí ó jẹ́ tirẹ̀;

àwọn tí ẹ̀gàn rẹ̀ jásí ẹ̀rù.

19Ní àkókò náà

ni èmi yóò dojúkọ àwọn

tí ń ni yín lára,

èmi yóò gba àtiro là,

èmi yóò sì ṣa àwọn tí ó ti fọ́nká jọ,

èmi yóò fi ìyìn àti ọlá fún wọn ní

gbogbo ilẹ̀ tí a bá ti dójútì wọ́n.

20Ní àkókò náà ni èmi yóò ṣà yín jọ;

nígbà náà ni èmi yóò mú un yín padà wá sílé.

Èmi yóò fi ọlá àti ìyìn fún un yín

láàrín gbogbo ènìyàn àgbáyé,

nígbà tí èmi yóò yí ìgbèkùn yín

padà bọ sípò ní ojú ara yín,”

ni Olúwa wí.

New International Reader’s Version

Zephaniah 3:1-20

A Message About Jerusalem

1How terrible it will be for Jerusalem!

Its people crush others.

They refuse to obey the Lord.

They are “unclean.”

2They don’t obey anyone.

They don’t accept the Lord’s warnings.

They don’t trust in him.

They don’t ask their God for his help.

3Jerusalem’s officials are like roaring lions.

Their rulers are like wolves that hunt in the evening.

They don’t leave anything to eat in the morning.

4Their prophets care about nothing.

They can’t be trusted.

Their priests make the temple “unclean.”

They break the law they teach others to obey.

5In spite of that, the Lord is good to Jerusalem.

He never does anything that is wrong.

Every morning he does what is fair.

Each new day he does the right thing.

But those who do what is wrong

aren’t even ashamed of it.

Jerusalem Remains Unrepentant

6The Lord says to his people,

“I have destroyed other nations.

I have wiped out their forts.

I have left their streets deserted.

No one walks along them.

Their cities are destroyed.

They are deserted and empty.

7Here is what I thought about Jerusalem.

‘Surely you will have respect for me.

Surely you will accept my warning.’

Then the city you think is safe would not be destroyed.

And I would not have to punish you so much.

But they still wanted to go on sinning

in every way they could.

8So wait for me to come as judge,”

announces the Lord.

“Wait for the day I will stand up

to witness against all sinners.

I have decided to gather the nations.

I will bring the kingdoms together.

And I will pour out all my burning anger on them.

The fire of my jealous anger

will burn the whole world up.

Israel Will Trust in the Lord

9“But then I will purify what all the nations say.

And they will use their words to worship me.

They will serve me together.

10My scattered people will come to me

from beyond the rivers of Cush.

They will worship me.

They will bring me offerings.

11Jerusalem, you have done many wrong things to me.

But at that time you will not be put to shame anymore.

That’s because I will remove from this city

those who think so highly of themselves.

You will never be proud again

on my holy mountain of Zion.

12But inside your city I will leave

those who are not proud at all.

Those who are still left alive will trust in the Lord.

13They will not do anything wrong.

They will not tell any lies.

They will not say anything to fool other people.

They will eat and lie down in peace.

And no one will make them afraid.”

14People of Zion, sing!

Israel, shout loudly!

People of Jerusalem, be glad!

Let your hearts be full of joy.

15The Lord has stopped punishing you.

He has made your enemies turn away from you.

The Lord is the King of Israel.

He is with you.

You will never again be afraid

that others will harm you.

16The time is coming when people will say to Jerusalem,

“Zion, don’t be afraid.

Don’t give up.

17The Lord your God is with you.

He is the Mighty Warrior who saves.

He will take great delight in you.

In his love he will no longer punish you.

Instead, he will sing for joy because of you.”

18The Lord says to his people,

“You used to celebrate my appointed feasts in Jerusalem.

You are sad because you can’t do that anymore.

Other people make fun of you because of that.

That sadness was a heavy load for you to carry.

But I will remove that load from you.

19At that time I will punish

all those who crushed you.

I will save those among you who are disabled.

I will gather those who have been taken away.

I will give them praise and honor

in every land where they have been put to shame.

20At that time I will gather you together.

And I will bring you home.

I will give you honor and praise

among all the nations on earth.

I will bless you with great success again,”

says the Lord.