Ìpè si Ìrònúpìwàdà
1Ẹ kó ara yín jọ pọ̀, àní ẹ kó ra yín jọ pọ̀
orílẹ̀-èdè tí kò ní ìtìjú,
2kí a tó pa àṣẹ náà, kí ọjọ́ náà tó kọjá bí ìyàngbò ọkà,
kí gbígbóná ìbínú Olúwa tó dé bá a yín,
kí ọjọ́ ìbínú Olúwa kí ó tó dé bá a yín.
3Ẹ wá Olúwa, gbogbo ẹ̀yin onírẹ̀lẹ̀ ilẹ̀ náà,
ẹ̀yin tí ń ṣe ohun tí ó bá pàṣẹ.
Ẹ wá òdodo, ẹ wá ìrẹ̀lẹ̀ pẹ̀lú,
bóyá á ó pa yín mọ́ ní ọjọ́ ìbínú Olúwa.
Ìlòdì sí Filistia
42.4-7: Isa 14.29-31; Jr 47; El 25.15-17; Jl 3.4-8; Am 1.6-8; Sk 9.5-7.Nítorí pé, a ó kọ Gasa sílẹ̀,
Aṣkeloni yóò sì dahoro.
Ní ọ̀sán gangan ni a ó lé Aṣdodu jáde,
a ó sì fa Ekroni tu kúrò.
5Ègbé ni fún ẹ̀yin tí ń gbé etí Òkun,
ẹ̀yin ènìyàn ara Kereti;
ọ̀rọ̀ Olúwa dojúkọ ọ́, ìwọ Kenaani,
ilẹ̀ àwọn ara Filistini.
“Èmi yóò pa yín run,
ẹnìkan kò sì ní ṣẹ́kù nínú yín.”
6Ilẹ̀ náà ní etí Òkun, ni ibùgbé àwọn ará Kereti,
ni yóò jẹ́ ibùjókòó fún àwọn olùṣọ́-àgùntàn àti agbo àgùntàn.
7Agbègbè náà yóò sì jẹ́ ti ìyókù àwọn ilé Juda,
níbẹ̀ ni wọn yóò sì ti rí koríko fún ẹran.
Ní ilé Aṣkeloni ni wọn yóò
dùbúlẹ̀ ni àṣálẹ́.
Olúwa Ọlọ́run wọn yóò bẹ̀ wọn wò,
yóò sì yí ìgbèkùn wọn padà.
Ìlòdì sí Moabu àti Ammoni
82.8-11: Isa 15–16; 25.10-12; Jr 48; El 25.8-11; Am 2.1-3.“Èmi ti gbọ́ ẹ̀gàn Moabu,
àti ẹlẹ́yà àwọn Ammoni,
àwọn tó kẹ́gàn àwọn ènìyàn mi,
tí wọ́n sì ti gbé ara wọn ga sí agbègbè wọn.
9Nítorí náà, bí Èmi tí wà,”
ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun,
Ọlọ́run àwọn Israẹli wí,
“nítòótọ́ Moabu yóò dàbí Sodomu,
àti Ammoni yóò sì dàbí Gomorra,
ibi tí ó kún fún yèrèpè,
àti ìhó iyọ̀ àti ìdahoro títí láéláé.
Ìyókù àwọn ènìyàn mi yóò kó wọn;
àwọn tí ó sì yọ nínú ewu ní orílẹ̀-èdè mi ni yóò jogún ilẹ̀ wọn.”
10Èyí ni ohun tí wọn yóò gbà padà nítorí ìgbéraga wọn,
nítorí wọ́n kẹ́gàn, wọn sì ti fi àwọn ènìyàn Olúwa àwọn ọmọ-ogun ṣe ẹlẹ́yà.
11Olúwa yóò jẹ́ ìbẹ̀rù fún wọn;
nígbà tí Òun bá pa gbogbo òrìṣà ilẹ̀ náà run.
Orílẹ̀-èdè láti etí odò yóò máa sìn,
olúkúlùkù láti ilẹ̀ rẹ̀ wá.
12“Ẹ̀yin Etiopia pẹ̀lú,
a ó fi idà mi pa yín.”
Asiria
13Òun yóò sì na ọwọ́ rẹ̀ sí apá àríwá,
yóò sì pa Asiria run,
yóò sì sọ Ninefe di ahoro,
àti di gbígbẹ bí aginjù.
14Agbo ẹran yóò sì dùbúlẹ̀ ni àárín rẹ̀,
àti gbogbo ẹranko àwọn orílẹ̀-èdè.
Òwìwí aginjù àti ti n kígbe ẹyẹ òwìwí
yóò wọ bí ẹyẹ ni ọwọ̀n rẹ̀.
Ohùn wọn yóò kọrin ni ojú fèrèsé,
ìdahoro yóò wà nínú ìloro ẹnu-ọ̀nà,
òun yóò sì ṣẹ́ ọ̀pá kedari sílẹ̀.
15Èyí ni ìlú aláyọ̀ tí ó ń gbé láìléwu.
Ó sì sọ fun ara rẹ̀ pé,
“Èmi ni, kò sì sí ẹnìkan tí ó ń bẹ lẹ́yìn mi.”
Irú ahoro wo ni òun ha ti jẹ́,
ibùgbé fún àwọn ẹranko igbó!
Gbogbo ẹni tí ó bá kọjá ọ̀dọ̀ rẹ̀
yóò fi rẹ́rìn-ín ẹlẹ́yà,
wọ́n yóò sì gbọn ẹsẹ̀ wọn.
Judah and Jerusalem Judged Along With the Nations
Judah Summoned to Repent
1Gather together, gather yourselves together,
you shameful nation,
2before the decree takes effect
and that day passes like windblown chaff,
before the Lord’s fierce anger
comes upon you,
before the day of the Lord’s wrath
comes upon you.
3Seek the Lord, all you humble of the land,
you who do what he commands.
Seek righteousness, seek humility;
perhaps you will be sheltered
on the day of the Lord’s anger.
Philistia
4Gaza will be abandoned
and Ashkelon left in ruins.
At midday Ashdod will be emptied
and Ekron uprooted.
5Woe to you who live by the sea,
you Kerethite people;
the word of the Lord is against you,
Canaan, land of the Philistines.
He says, “I will destroy you,
and none will be left.”
6The land by the sea will become pastures
having wells for shepherds
and pens for flocks.
7That land will belong
to the remnant of the people of Judah;
there they will find pasture.
In the evening they will lie down
in the houses of Ashkelon.
The Lord their God will care for them;
he will restore their fortunes.2:7 Or will bring back their captives
Moab and Ammon
8“I have heard the insults of Moab
and the taunts of the Ammonites,
who insulted my people
and made threats against their land.
9Therefore, as surely as I live,”
declares the Lord Almighty,
the God of Israel,
“surely Moab will become like Sodom,
the Ammonites like Gomorrah—
a place of weeds and salt pits,
a wasteland forever.
The remnant of my people will plunder them;
the survivors of my nation will inherit their land.”
10This is what they will get in return for their pride,
for insulting and mocking
the people of the Lord Almighty.
11The Lord will be awesome to them
when he destroys all the gods of the earth.
Distant nations will bow down to him,
all of them in their own lands.
Cush
12“You Cushites,2:12 That is, people from the upper Nile region too,
will be slain by my sword.”
Assyria
13He will stretch out his hand against the north
and destroy Assyria,
leaving Nineveh utterly desolate
and dry as the desert.
14Flocks and herds will lie down there,
creatures of every kind.
The desert owl and the screech owl
will roost on her columns.
Their hooting will echo through the windows,
rubble will fill the doorways,
the beams of cedar will be exposed.
15This is the city of revelry
that lived in safety.
She said to herself,
“I am the one! And there is none besides me.”
What a ruin she has become,
a lair for wild beasts!
All who pass by her scoff
and shake their fists.