1Ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó tọ Sefaniah ọmọ Kuṣi, ọmọ Gedaliah, ọmọ Amariah, ọmọ Hesekiah, ní ìgbà Josiah ọmọ Amoni ọba Juda.
Ìkìlọ̀ fún ìparun tí ń bọ̀
2“Èmi yóò mú gbogbo nǹkan kúrò
lórí ilẹ̀ náà pátápátá,”
ni Olúwa wí.
3“Èmi yóò mú ènìyàn àti ẹranko
kúrò; èmi yóò mú àwọn ẹyẹ ojú
ọ̀run kúrò àti ẹja inú Òkun, àti
ohun ìdìgbòlù pẹ̀lú àwọn
ènìyàn búburú; èmi yóò ké ènìyàn kúrò lórí ilẹ̀ ayé,”
ni Olúwa wí.
Ìlòdì sí Juda
4“Èmi yóò na ọwọ́ mi sórí Juda
àti sórí gbogbo àwọn ènìyàn tí ń gbé ní Jerusalẹmu.
Èmi yóò sì ké kúrò níhìn-ín-yìí ìyókù àwọn Baali, àti orúkọ àwọn abọ̀rìṣà
pẹ̀lú àwọn àlùfáà abọ̀rìṣà,
5àti àwọn tí ń foríbalẹ̀ lórí òrùlé,
àwọn tí ń sin ogun ọ̀run,
àwọn tó ń foríbalẹ̀, tí wọ́n sì ń fi Olúwa búra,
tí wọ́n sì ń fi Moleki búra.
6Àwọn tí ó yípadà kúrò lọ́dọ̀ Olúwa;
Àti àwọn tí kò tí wá Olúwa, bẹ́ẹ̀ ni wọn kò sì béèrè rẹ̀.”
71.7: Hk 2.20; Sk 2.13.Ẹ dákẹ́ jẹ́ẹ́ níwájú Olúwa Olódùmarè,
nítorí tí ọjọ́ Olúwa kù sí dẹ̀dẹ̀.
Olúwa ti pèsè ẹbọ kan sílẹ̀,
ó sì ti ya àwọn alápèjẹ rẹ̀ sí mímọ́.
8“Ní ọjọ́ ẹbọ Olúwa,
Èmi yóò bẹ àwọn olórí wò, àti àwọn
ọmọ ọba ọkùnrin,
pẹ̀lú gbogbo
àwọn tí ó wọ àjèjì aṣọ.
9Ní ọjọ́ náà, èmi yóò fi ìyà jẹ
gbogbo àwọn tí ó yẹra láti rìn lórí ìloro ẹnu-ọ̀nà,
tí wọ́n sì kún tẹmpili àwọn ọlọ́run wọn
pẹ̀lú ìwà ipá àti ẹ̀tàn.
10“Ní ọjọ́ náà,” ni Olúwa wí,
“Ohùn ẹkún yóò wà láti ìhà Ibodè ẹja,
híhu láti ìhà kejì wá àti
ariwo ńlá láti òkè kékeré wá.
11Ẹ hu, ẹ̀yin tí ń gbé ní (Maktẹsi) agbègbè ọjà,
gbogbo àwọn oníṣòwò rẹ̀ ni a ó mú kúrò,
gbogbo àwọn ẹni tí ó ń ra fàdákà ni a ó sì parun.
12Ní àkókò wọ̀n-ọn-nì, èmi yóò wá Jerusalẹmu kiri pẹ̀lú fìtílà,
èmi ó sì fi ìyà jẹ àwọn tí kò ní ìtẹ́lọ́rùn,
tí wọn sì dàbí àwọn ènìyàn tí ó sinmi sínú gẹ̀dẹ̀gẹ́dẹ̀ wọn,
àwọn tí wọn sì ń wí ní ọkàn wọn pé, ‘Olúwa kì yóò ṣe nǹkan kan
tí ó jẹ́ rere tàbí tí ó jẹ́ búburú.’
13Nítorí náà, ọrọ̀ wọn yóò di ìkógun,
àti ilé wọn yóò sì run.
Àwọn yóò sì kọ́ ilé pẹ̀lú, ṣùgbọ́n
wọn kì yóò gbé nínú ilé náà,
wọn yóò gbin ọgbà àjàrà,
ṣùgbọ́n wọn kì yóò mu ọtí
wáìnì láti inú rẹ̀.”
Ọjọ́ ńlá Olúwa
14“Ọjọ́ ńlá Olúwa kù sí dẹ̀dẹ̀,
ó kù sí dẹ̀dẹ̀ ó sì ń yára bọ̀
kánkán. Ẹ tẹ́tí sílẹ̀, ohùn ẹkún
àwọn alágbára ní ọjọ́ Olúwa yóò korò púpọ̀,
15Ọjọ́ náà yóò jẹ́ ọjọ́ ìbínú,
ọjọ́ ìrora àti ìpọ́njú,
ọjọ́ òfò àti idà ọjọ́ ìdahoro
ọjọ́ òkùnkùn àti ìtẹ̀ba,
ọjọ́ kurukuru àti òkùnkùn biribiri,
16ọjọ́ ìpè àti ìpè ogun
sí àwọn ìlú olódi
àti sí àwọn ilé ìṣọ́ gíga.
17“Èmi yóò sì mú ìpọ́njú wá sórí
ènìyàn, wọn yóò sì máa rìn gẹ́gẹ́ bí afọ́jú,
nítorí àwọn ti dẹ́ṣẹ̀ sí Olúwa.
Ẹ̀jẹ̀ wọn ni a ó sì tú jáde bí eruku
àti ẹran-ara wọn bí ìgbẹ́.
18Bẹ́ẹ̀ ni fàdákà tàbí wúrà wọn
kì yóò sì le gbà wọ́n là
ní ọjọ́ ìbínú Olúwa.”
Ṣùgbọ́n gbogbo ayé ni a ó fi iná
ìjowú rẹ̀ parun,
nítorí òun yóò fi ìyára fi òpin sí
gbogbo àwọn tí ń gbé ní ilẹ̀ ayé.
1Herrens ord kom till Sefanja, son till Kushi, son till Gedalja, son till Amarja, son till Hiskia, under Juda kung Josias, Amons sons, regeringstid.
Vredens dag
2”Jag ska fullständigt utplåna allt
från jordens yta, säger Herren.
3Jag ska utplåna både människor och djur,
jag ska utplåna himlens fåglar och havets fiskar,
och ruinhögarna tillsammans med de gudlösa.
Jag ska utrota människorna från jordens yta, säger Herren.
4Jag ska sträcka ut min hand mot Juda
och mot alla som bor i Jerusalem.
Jag ska utrota från denna plats
det som finns kvar av Baal,
avgudaprästernas namn
tillsammans med prästerna,
5dem som på taken böjer sig
i tillbedjan för himlens här,
dem som böjer sig ner för Herren
men också svär vid Milkom1:5 Om ordet inte tolkas som ett avgudanamn utan översätts, betyder det deras kung.,
6dessa som vänt sig bort från Herren
och inte söker eller frågar efter Herren.”
7Var stilla inför Herren, Herren,
för Herrens dag är nära!
Herren har förberett en offerhögtid
och helgat sina inbjudna.
8”På Herrens offerdag
ska jag straffa furstarna och prinsarna
och alla som bär främmande kläder.
9På den dagen ska jag straffa dem
som hoppar över tröskeln
och fyller sina herrars hus
med våld och svek.1:9 Grundtextens innebörd är osäker. Jfr 1 Sam 5:5.
10Den dagen, säger Herren,
ska rop höras från Fiskporten,
klagan från Nya staden,
väldigt dån från höjderna.
11Jämra er, ni som bor i Mortelkvarteret,
för skaran av köpmän är borta,
och utplånade är de
som handlar med silver.
12Vid den tiden ska jag med ljus och lykta
söka igenom Jerusalem
och straffa de män som sitter där
liknöjda på sin drägg,
och tänker:
’Herren gör ingenting, vare sig gott eller ont.’
13Men deras rikedom ska plundras
och deras hus läggas öde.
De ska bygga hus,
men inte få bo i dem,
plantera vingårdar,
men inte få dricka vinet från dem.”
14Herrens stora dag är nära,
ja, den är nära och kommer mycket snabbt.
Det kommer att höras rop på Herrens dag,
starka män ska då gråta bittert.1:14 Grundtextens innebörd är osäker.
15Den dagen är en vredens dag,
en dag av nöd och ångest,
en dag av förödelse och ödeläggelse,
en dag av mörker och dimma,
en dag av moln och dunkel,
16en dag med hornstötar och krigsrop
mot befästa städer och höga torn.
17”Jag ska låta människorna drabbas av ångest,
så att de går omkring som blinda,
för de har syndat mot Herren.
Deras blod ska hällas ut som stoft
och deras inälvor som dynga.
18Varken deras silver eller guld
kan rädda dem på Herrens vredes dag.”
Hans lidelses eld
ska förtära hela jorden.
Han ska göra ett snabbt slut
på alla dess invånare.