Sefaniah 1 – YCB & NRT

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Sefaniah 1:1-18

1Ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó tọ Sefaniah ọmọ Kuṣi, ọmọ Gedaliah, ọmọ Amariah, ọmọ Hesekiah, ní ìgbà Josiah ọmọ Amoni ọba Juda.

Ìkìlọ̀ fún ìparun tí ń bọ̀

2“Èmi yóò mú gbogbo nǹkan kúrò

lórí ilẹ̀ náà pátápátá,”

ni Olúwa wí.

3“Èmi yóò mú ènìyàn àti ẹranko

kúrò; èmi yóò mú àwọn ẹyẹ ojú

ọ̀run kúrò àti ẹja inú Òkun, àti

ohun ìdìgbòlù pẹ̀lú àwọn

ènìyàn búburú; èmi yóò ké ènìyàn kúrò lórí ilẹ̀ ayé,”

ni Olúwa wí.

Ìlòdì sí Juda

4“Èmi yóò na ọwọ́ mi sórí Juda

àti sórí gbogbo àwọn ènìyàn tí ń gbé ní Jerusalẹmu.

Èmi yóò sì ké kúrò níhìn-ín-yìí ìyókù àwọn Baali, àti orúkọ àwọn abọ̀rìṣà

pẹ̀lú àwọn àlùfáà abọ̀rìṣà,

5àti àwọn tí ń foríbalẹ̀ lórí òrùlé,

àwọn tí ń sin ogun ọ̀run,

àwọn tó ń foríbalẹ̀, tí wọ́n sì ń fi Olúwa búra,

tí wọ́n sì ń fi Moleki búra.

6Àwọn tí ó yípadà kúrò lọ́dọ̀ Olúwa;

Àti àwọn tí kò tí wá Olúwa, bẹ́ẹ̀ ni wọn kò sì béèrè rẹ̀.”

71.7: Hk 2.20; Sk 2.13.Ẹ dákẹ́ jẹ́ẹ́ níwájú Olúwa Olódùmarè,

nítorí tí ọjọ́ Olúwa kù sí dẹ̀dẹ̀.

Olúwa ti pèsè ẹbọ kan sílẹ̀,

ó sì ti ya àwọn alápèjẹ rẹ̀ sí mímọ́.

8“Ní ọjọ́ ẹbọ Olúwa,

Èmi yóò bẹ àwọn olórí wò, àti àwọn

ọmọ ọba ọkùnrin,

pẹ̀lú gbogbo

àwọn tí ó wọ àjèjì aṣọ.

9Ní ọjọ́ náà, èmi yóò fi ìyà jẹ

gbogbo àwọn tí ó yẹra láti rìn lórí ìloro ẹnu-ọ̀nà,

tí wọ́n sì kún tẹmpili àwọn ọlọ́run wọn

pẹ̀lú ìwà ipá àti ẹ̀tàn.

10“Ní ọjọ́ náà,” ni Olúwa wí,

“Ohùn ẹkún yóò wà láti ìhà Ibodè ẹja,

híhu láti ìhà kejì wá àti

ariwo ńlá láti òkè kékeré wá.

11Ẹ hu, ẹ̀yin tí ń gbé ní (Maktẹsi) agbègbè ọjà,

gbogbo àwọn oníṣòwò rẹ̀ ni a ó mú kúrò,

gbogbo àwọn ẹni tí ó ń ra fàdákà ni a ó sì parun.

12Ní àkókò wọ̀n-ọn-nì, èmi yóò wá Jerusalẹmu kiri pẹ̀lú fìtílà,

èmi ó sì fi ìyà jẹ àwọn tí kò ní ìtẹ́lọ́rùn,

tí wọn sì dàbí àwọn ènìyàn tí ó sinmi sínú gẹ̀dẹ̀gẹ́dẹ̀ wọn,

àwọn tí wọn sì ń wí ní ọkàn wọn pé, ‘Olúwa kì yóò ṣe nǹkan kan

tí ó jẹ́ rere tàbí tí ó jẹ́ búburú.’

13Nítorí náà, ọrọ̀ wọn yóò di ìkógun,

àti ilé wọn yóò sì run.

Àwọn yóò sì kọ́ ilé pẹ̀lú, ṣùgbọ́n

wọn kì yóò gbé nínú ilé náà,

wọn yóò gbin ọgbà àjàrà,

ṣùgbọ́n wọn kì yóò mu ọtí

wáìnì láti inú rẹ̀.”

Ọjọ́ ńlá Olúwa

14“Ọjọ́ ńlá Olúwa kù sí dẹ̀dẹ̀,

ó kù sí dẹ̀dẹ̀ ó sì ń yára bọ̀

kánkán. Ẹ tẹ́tí sílẹ̀, ohùn ẹkún

àwọn alágbára ní ọjọ́ Olúwa yóò korò púpọ̀,

15Ọjọ́ náà yóò jẹ́ ọjọ́ ìbínú,

ọjọ́ ìrora àti ìpọ́njú,

ọjọ́ òfò àti idà ọjọ́ ìdahoro

ọjọ́ òkùnkùn àti ìtẹ̀ba,

ọjọ́ kurukuru àti òkùnkùn biribiri,

16ọjọ́ ìpè àti ìpè ogun

sí àwọn ìlú olódi

àti sí àwọn ilé ìṣọ́ gíga.

17“Èmi yóò sì mú ìpọ́njú wá sórí

ènìyàn, wọn yóò sì máa rìn gẹ́gẹ́ bí afọ́jú,

nítorí àwọn ti dẹ́ṣẹ̀ sí Olúwa.

Ẹ̀jẹ̀ wọn ni a ó sì tú jáde bí eruku

àti ẹran-ara wọn bí ìgbẹ́.

18Bẹ́ẹ̀ ni fàdákà tàbí wúrà wọn

kì yóò sì le gbà wọ́n là

ní ọjọ́ ìbínú Olúwa.”

Ṣùgbọ́n gbogbo ayé ni a ó fi iná

ìjowú rẹ̀ parun,

nítorí òun yóò fi ìyára fi òpin sí

gbogbo àwọn tí ń gbé ní ilẹ̀ ayé.

New Russian Translation

Софония 1:1-18

1Слово Господа, которое было к Софонии, сыну Кушия, сына Гедалии, сына Амарии, сына Езекии, во время правления иудейского царя Иосии, сына Амона1:1 Царь Иосия правил в 640–610 гг. до н. э..

Суд над землей

2– Я все смету с лица земли, –

возвещает Господь. –

3Погублю и людей, и скот;

погублю и птиц в небесах,

и рыбу в морях.

Я повергну нечестивцев в прах1:3 Смысл этого места в еврейском тексте неясен.

и сотру человека с лица земли, –

говорит Господь.

Суд над Иудеей

4– Я воздену руку над Иудеей

и над жителями Иерусалима

и сотру здесь последний след Баала1:4 Баал – ханаанский бог плодородия и бог-громовержец.,

имена его жрецов и священников:

5и тех, кто поклоняется на крышах

небесному воинству,

и тех, кто поклоняется и клянется в верности

как Господу, так и Молоху1:5 Или: «своему царю». Молох – аммонитский бог, в жертвы которому приносились дети. По Закону за поклонение Молоху израильтянам грозила смертная казнь (см. Лев. 18:21; 20:2-5).,

6и тех, кто отвернулся от Господа

и не ищет Господа и не вопрошает Его.

7Умолкни перед Владыкой Господом,

так как близок день Господа.

Он приготовил жертву

и уже созвал1:7 Букв.: «освятил». гостей.

8– В день жертвы Господней

Я накажу вождей, и сыновей царя,

и всех, кто наряжается в чужеземное платье1:8 Или: «следуют обычаям других народов». Это был обычай, когда люди при поклонении Баалу наряжались в специальную одежду (см. 4 Цар. 10:22)..

9Я накажу в тот день всех,

кто прыгает через порог1:9 Или: «порог святилища». Вероятно, иудеи подражали некоторым религиозным обычаям филистимлян (см. 1 Цар. 5:5).,

кто наполняет дом своих владык1:9 Или: «Владыки своего»; или: «своих богов».

насилием и обманом.

10– В тот день,

– говорит Господь, –

поднимется крик от Рыбных ворот,

плач из новой части города1:10 Рыбные ворота и новый район города находились в северной части Иерусалима. И именно с севера должен был прийти враг.

и страшный грохот с холмов.

11Плачьте, жители торгового района,

потому что погибнут купцы

и будут истреблены торгующие за серебро.

12Тогда Я обойду Иерусалим со светильниками

в поисках самодовольных и накажу их –

тех, кто подобен вину на дрожжах1:12 Образное сравнение с долго стоявшим вином, в котором образовался осадок, говорит о том, что люди, наслаждающиеся жизнью, полной изобилия, становятся равнодушными и самодовольными и полагают, что и Господь должен с безразличием относиться к добру и злу в мире (см. Иер. 48:11).,

кто думает: «Господь не сделает нам ничего:

ни плохого, ни хорошего».

13Их богатства будут расхищены,

и дома придут в запустение.

Они построят дома,

а жить в них не будут;

посадят они виноградники,

но вина пить не будут.

День Господень

14– Близок великий день Господень,

близок и очень спешит.

Страшный шум поднимется в день Господа,

даже храбрые воины будут кричать.

15Тот день будет днем гнева,

днем скорби и муки,

днем гибели и разрушения,

днем мглы и мрака,

днем туч и тьмы,

16днем звука рога и клича к битве

против укрепленных городов

и высоких башен.

17– Я пошлю на людей такую беду,

что они станут бродить, как слепые,

за то, что согрешили перед Господом.

Их кровь прольется, как вода,

и плоть их будет выброшена, как навоз.

18Ни серебро, ни золото

не смогут спасти их в день гнева Господа.

В пламени Его ревности

сгорит вся земля;

внезапный конец положит Он всем,

кто живет на земле.