Saamu 9 – YCB & AKCB

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Saamu 9:1-20

Saamu 9

Fún adarí orin. Ní ti ohun orin. “Ní ti ikú ọmọ.” Saamu ti Dafidi.

1Èmi ó yìn ọ́, Olúwa, pẹ̀lú gbogbo ọkàn mi;

èmi ó sọ ti ìyanu rẹ gbogbo.

2Inú mi yóò dùn, èmi yóò sì yọ̀ nínú rẹ;

èmi ó kọrin ìyìn sí orúkọ rẹ, Ìwọ Ọ̀gá-Ògo jùlọ.

3Àwọn ọ̀tá mi pẹ̀yìndà;

wọ́n kọsẹ̀ wọn sì ṣègbé níwájú rẹ.

4Nítorí ìwọ ti di òtítọ́ àti ọ̀ràn mi mú;

ìwọ ti jókòó lórí ìtẹ́ rẹ, láti ṣe ìdájọ́ òdodo.

5Ìwọ ti bá orílẹ̀-èdè wí, Ìwọ sì ti pa ẹni búburú run;

Ìwọ ti yọ orúkọ wọn kúrò láé àti láéláé.

6Ìparun àìlópin ti borí àwọn ọ̀tá,

ìwọ ti fa àwọn ìlú wọn tu;

àní ìrántí wọn sì ti ṣègbé.

7Olúwa jẹ ọba títí láé;

ó ti gbé ìtẹ́ rẹ̀ kalẹ̀ fún ìdájọ́.

89.8: Ap 17.31.Òun yóò sì ṣe ìdájọ́ ayé ní òdodo;

yóò ṣe àkóso ènìyàn pẹ̀lú òdodo.

9Olúwa ni ààbò fún àwọn tí a ni lára,

ibi ìsádi ní àkókò ìpọ́njú.

10Àwọn tí ó mọ orúkọ rẹ yóò gbẹ́kẹ̀lé ọ,

nítorí, Olúwa, kò kọ àwọn tó ń wá a sílẹ̀.

11Kọ orin ìyìn sí Olúwa, tí o ń jẹ ọba ní Sioni;

kéde láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, ohun tí ó ṣe.

12Nítorí ẹni tí ó ń gbẹ̀san ẹ̀jẹ̀ rántí;

òun kò kọ ẹkún àwọn tí a pọ́n lójú.

13Olúwa, wo bí àwọn ọ̀tá ṣe ń ṣe inúnibíni sí mi!

Ṣàánú, kí o sì gbé mí sókè kúrò ní ẹnu-ọ̀nà ikú,

14kí èmi kí ó lè sọ ti ìyìn rẹ

ni ẹnu-ọ̀nà àwọn ọmọbìnrin Sioni

àti láti máa yọ̀ nínú ìgbàlà rẹ.

15Àwọn orílẹ̀-èdè ti jì sí kòtò tí wọn ti gbẹ́;

ẹsẹ̀ wọn ni àwọ̀n tí wọ́n dẹ sílẹ̀ kọ́.

16A mọ Olúwa nípa òdodo rẹ̀;

àwọn ènìyàn búburú ni a dẹ́kun mú nípa iṣẹ́ ọwọ́ wọn.

17Àwọn ènìyàn búburú ni a ó dà sí isà òkú,

àti gbogbo orílẹ̀-èdè tí ó gbàgbé Ọlọ́run.

18Ṣùgbọ́n àwọn aláìní ni a kò ní gbàgbé láéláé,

ìrètí àwọn ti ó tálákà ni a kì yóò gbàgbé láéláé.

19Dìde, Olúwa, má ṣe jẹ́ kí ènìyàn borí;

jẹ́ kí a ṣe ìdájọ́ àwọn orílẹ̀-èdè ni iwájú rẹ.

20Lù wọ́n pẹ̀lú ìpayà, Olúwa;

jẹ́ kí àwọn orílẹ̀-èdè mọ̀ pé ènìyàn lásán ni wọ́n. Sela.

Akuapem Twi Contemporary Bible

Nnwom 9:1-20

Dwom 9

Dawid dwom.

1Awurade, mefi me koma nyinaa mu ada wo ase.

Mɛka wʼanwonwade no nyinaa.

2Mɛma mʼani agye na madi ahurusi wɔ wo mu.

Mɛto ayeyi dwom ama wo din, Ɔsorosoroni.

3Mʼatamfo san wɔn akyi;

wɔtetew hwe, na wowuwu wɔ wʼanim.

4Woadi mʼasɛm ama me, na menya mʼahofadi;

woatena wʼahengua so, abu atɛntrenee.

5Woatwe amanaman no aso, na woasɛe amumɔyɛfo.

Woapepa wɔn din a wɔrenkae wɔn bio.

6Ɔsɛe a enni awiei ato ɔtamfo no,

woatutu wɔn nkuropɔn;

na wɔnkae wɔn bio mpo.

7Awurade di hene daa daa;

wasi nʼatemmu ahengua.

8Ɔde trenee bebu wiase atɛn;

ɔde atɛntrenee bedi nnipa no so.

9Awurade yɛ guankɔbea ma wɔn a wodi wɔn nya no,

ɔyɛ abandennen wɔ ahohia mmere mu.

10Wɔn a wonim wo din no de wɔn ho bɛto wo so,

efisɛ, wo Awurade, wunnyaw obiara a ɔhwehwɛ wo no mu da.

11Monto ayeyi dwom mma Awurade a ɔte ahengua so wɔ Sion;

mompae mu nka nea wayɛ wɔ amanaman no mu.

12Na ɔkae nea ɔtɔ mogya so were no;

ommu nʼani ngu ɔbrɛfo sufrɛ so.

13Awurade, hwɛ sɛnea mʼatamfo teetee me!

Hu me mmɔbɔ na yi me fi owu apon ano,

14na matumi apae mu aka wʼayeyi

wɔ Ɔbabea Sion apon ano,

na madi ahurusi wɔ wo nkwagye no mu hɔ.

15Amanaman mufo atɔ amoa a wɔatu no mu;

afiri a wosum hintaw no ayi wɔn anan.

16Awurade atɛntrenee da no adi;

amumɔyɛfo nsa ano adwuma ayi wɔn.

17Amumɔyɛfo san kɔ ɔda mu,

amanaman a wɔn werɛ fi Onyankopɔn nyinaa.

18Nanso ɛnyɛ daa na ne werɛ befi ohiani,

anaasɛ mmɔborɔni anidaso bɛyera korakora.

19Sɔre! Awurade, mma ɔdesani nni nkonim,

bu amanaman no atɛn wɔ wʼanim.

20Bɔ wɔn hu, Awurade;

na ma wonhu sɛ, wɔyɛ adesa bi kɛkɛ.