Saamu 20 – YCB & ASCB

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Saamu 20:1-9

Saamu 20

Fún adarí orin. Saamu ti Dafidi.

1Olúwa kí ó gbóhùn rẹ ní ọjọ́ ìpọ́njú;

kí orúkọ Ọlọ́run Jakọbu kí ó dáàbò bò ọ́.

2Kí ó rán ìrànlọ́wọ́ sí ọ, láti ibi mímọ́

kí ó sì tì ọ́ lẹ́yìn láti Sioni wá.

3Kí ó sì rántí gbogbo ẹbọ rẹ

kí ó sì gba ẹbọ sísun rẹ. Sela.

4Kí ó fi fún ọ gẹ́gẹ́ bi ti èrò ọkàn rẹ

kí ó sì mú gbogbo ìmọ̀ rẹ ṣẹ.

5Àwa yóò hó fún ayọ̀ nígbà tí o bá di aṣẹ́gun

àwa yóò gbé àsíá wa sókè ní orúkọ Ọlọ́run wa.

Olúwa kí ó mú gbogbo ìbéèrè rẹ̀ ṣẹ.

6Nísinsin yìí, èmi mọ̀ wí pé,

Olúwa pa ẹni àmì òróró rẹ̀ mọ́.

Yóò gbọ́ láti ọ̀run mímọ́ rẹ̀ wá

pẹ̀lú agbára ìgbàlà ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀.

7Àwọn mìíràn gbẹ́kẹ̀ wọn lé kẹ̀kẹ́, àwọn mìíràn gbẹ́kẹ̀ wọn lé ẹṣin,

ṣùgbọ́n àwa gbẹ́kẹ̀lé orúkọ Olúwa Ọlọ́run wa.

8Wọ́n wólẹ̀, ní eékún, wọ́n sì ṣubú,

ṣùgbọ́n àwa dìde, a sì dúró ṣinṣin.

9Olúwa, fi ìṣẹ́gun fún ọba!

Dá wa lóhùn nígbà tí a bá ń kígbe pè!

Asante Twi Contemporary Bible

Nnwom 20:1-9

Dwom 20

Dawid dwom.

1Awurade ntie wo wɔ wʼahohia mu;

Yakob Onyankopɔn din mmɔ wo ho ban.

2Ɔmfa mmoa mfiri kronkronbea hɔ mmrɛ wo

na ɔmfiri Sion mmɛhyɛ wo den.

3Ɔnkae wʼafɔrebɔ nyinaa

na ɔmma wo hyeɛ afɔdeɛ nsɔ nʼani.

4Ɔmma wo deɛ wʼakoma pɛ,

na wo nhyehyɛeɛ nyinaa nyɛ yie.

5Yɛbɛbɔ ose ɛberɛ a woadi nkonim

na yɛama yɛn frankaa so wɔ yɛn Onyankopɔn din mu.

Awurade nyɛ wʼabisadeɛ nyinaa mma wo.

6Afei mahunu sɛ Awurade gye deɛ wasra no no nkwa;

ɔgye no so wɔ ne soro kronkron hɔ

ɔde tumi a ɛfiri ne nsa nifa mu no ma no nkwagyeɛ.

7Ebinom de wɔn ho to wɔn nteaseɛnam so

na afoforɔ nso, wɔn apɔnkɔ so,

nanso yɛn deɛ, yɛde yɛn ho to Awurade yɛn Onyankopɔn din so.

8Saa nkurɔfoɔ no, wɔbrɛ wɔn ase ma wɔhwehwe ase,

na yɛn deɛ, yɛsɔre gyina pintinn.

9Ao Awurade gye ɔhene nkwa!

Na sɛ yɛfrɛ nso a, gye yɛn so.