Saamu 139 – YCB & AKCB

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Saamu 139:1-24

Saamu 139

Fún adarí orin. Ti Dafidi. Saamu.

1Olúwa, ìwọ tí wádìí mi,

ìwọ sì ti mọ̀ mí.

2Ìwọ mọ̀ ìjókòó mi àti ìdìde mi,

ìwọ mọ̀ èrò mi ní ọ̀nà jíjìn réré.

3Ìwọ yí ipa ọ̀nà mi ká àti ìdùbúlẹ̀ mi,

gbogbo ọ̀nà mi sì di mí mọ̀ fún ọ.

4Nítorí tí kò sí ọ̀rọ̀ kan ní ahọ́n mi,

kíyèsi i, Olúwa, ìwọ mọ̀ ọ́n pátápátá.

5Ìwọ sé mi mọ́ lẹ́yìn àti níwájú,

ìwọ sì fi ọwọ́ rẹ lé mi.

6Irú ìmọ̀ yìí jẹ ohun ìyanu fún mi jù;

ó ga, èmi kò le mọ̀ ọ́n.

7Níbo ní èmi yóò gbé lọ kúrò ni ọwọ́ ẹ̀mí rẹ?

Tàbí níbo ni èmi yóò sáré kúrò níwájú rẹ?

8Bí èmi bá gòkè lọ sí ọ̀run, ìwọ wà níbẹ̀;

bí èmí ba sì tẹ́ ẹní mi ní ipò òkú,

kíyèsi i, ìwọ wà níbẹ̀ pẹ̀lú.

9Èmi ìbá mú ìyẹ́ apá òwúrọ̀,

kí èmi sì lọ jókòó ní ìhà òpin Òkun,

10àní, níbẹ̀ náà ni ọwọ́ rẹ̀ yóò fà mí

ọwọ́ ọ̀tún rẹ yóò sì dì mímú.

11Bí mo bá wí pé, “Ǹjẹ́ kí òkùnkùn kí ó bò mí mọ́lẹ̀;

kí ìmọ́lẹ̀ kí ó di òru yí mi ká.”

12Nítòótọ́ òkùnkùn kì í ṣú lọ́dọ̀ rẹ;

ṣùgbọ́n òru tan ìmọ́lẹ̀ bí ọ̀sán;

àti òkùnkùn àti ọ̀sán, méjèèjì bákan náà ní fún ọ.

13Nítorí ìwọ ni ó dá ọkàn mi;

ìwọ ni ó bò mí mọ́lẹ̀ nínú ìyá mi.

14Èmi yóò yìn ọ, nítorí tẹ̀rù tẹ̀rù àti tìyanu tìyanu ní a dá mi;

ìyanu ní iṣẹ́ rẹ;

èyí nì ni ọkàn mi sì mọ̀ dájúdájú.

15Ẹ̀dá ara mi kò pamọ́ kúrò lọ́dọ̀ rẹ,

nígbà tí a dá mi ní ìkọ̀kọ̀.

Tí a sì ń ṣiṣẹ́ ní àràbarà ní ìhà ìsàlẹ̀ ilẹ̀ ayé,

16ojú rẹ ti rí ohun ara mi

nígbà tí a kò tí ì ṣe mí pé,

àti nínú ìwé rẹ ni a ti kọ ọ̀kọ̀ọ̀kan wọn sí,

ní ọjọ́ tí a dá wọn,

nígbà tí wọn kò tilẹ̀ tí ì sí.

17Ọlọ́run, èrò inú rẹ tí ṣe iyebíye tó fún mi,

iye wọn ti pọ̀ tó!

18Èmi ìbá kà wọ́n,

wọ́n ju iyanrìn lọ ní iye:

nígbà tí mo bá jí,

èmi yóò wà lọ́dọ̀ rẹ síbẹ̀.

19Ọlọ́run ìbá jẹ́ pa àwọn ènìyàn búburú nítòótọ́;

nítorí náà kúrò lọ́dọ̀ mi ẹ̀yin ọkùnrin ẹlẹ́jẹ̀.

20Ẹni tí ń fi inú búburú sọ̀rọ̀ sí ọ,

àwọn ọ̀tá rẹ ń pe orúkọ rẹ ní asán!

21Olúwa, ǹjẹ́ èmi kò kórìíra àwọn tó kórìíra rẹ?

Ǹjẹ́ inú mi kò a sì bàjẹ́ sí àwọn tí ó dìde sí ọ?

22Èmi kórìíra wọn ní àkótán;

èmi kà wọ́n sí ọ̀tá mi.

23Ọlọ́run, wádìí mi, kí o sì mọ ọkàn mí;

dán mi wò, kí o sì mọ ìrò inú mi.

24Kí ó sì wò ó bí ipa ọ̀nà búburú

kan bá wà nínú mi kí ó sì

fi ẹsẹ̀ mi lé ọ̀nà àìnípẹ̀kun.

Akuapem Twi Contemporary Bible

Nnwom 139:1-24

Dwom 139

Dawid dwom.

1Awurade, woahwehwɛ me mu

na woahu me.

2Wunim mʼasetena ne me sɔre;

wufi akyirikyiri hu mʼadwene mu.

3Wunim mʼadifi ne me nnae mu;

wunim mʼakwan nyinaa mu.

4Ansa na mebue mʼano akasa no

Awurade, na wunim ne nyinaa dedaw.

5Woakata me ho nyinaa ahyia

na wobɔ me ho ban.

6Saa nimdeɛ yi yɛ me nwonwa dodo,

ɛkɔ soro dodo ma me sɛ medu ho.

7Ɛhe na metumi afi wo honhom anim akɔ?

Ɛhe na metumi aguan afi wʼanim akɔ?

8Sɛ meforo soro a, wowɔ hɔ.

Na mekɔsɛw me kɛtɛ wɔ asaman a, wo ni.

9Sɛ mede adekyee ntaban tu

na mekɔtena po akyi nohɔ a,

10mpo hɔ na wo nsa begya me akɔ,

na wo nsa nifa beso me mu.

11Na meka se, “Ampa ara sum mmɛkata me so

na hann nnan adesae ntwa me ho nhyia a,”

12sum mpo nyɛ sum mma wo;

na anadwo bɛhyerɛn sɛ awia;

sum ne hann yɛ wo pɛ.

13Na wo na wobɔɔ me honhom

wonwen me wɔ me na awotwaa mu.

14Mekamfo wo, efisɛ woyɛɛ me anwonwakwan so a ɛyɛ hu;

wo nnwuma yɛ nwonwa.

Minim ɛno yiye pa ara.

15Wɔamfa me bɔbea anhintaw wo

bere a wɔyɛɛ me kokoa mu no;

bere a wɔnwenee me wɔ asase bun mu no,

16wʼani huu me, bere a meyɛ mogyatɔw no.

Nna dodow a woatwa ama me no,

wɔakyerɛw ne nyinaa wɔ wo nhoma mu

ansa na mu baako reba mu.

17Onyankopɔn, wo nsusuwii som bo ma me!

woka ne nyinaa bɔ mu a, ɛtrɛw dodo!

18Sɛ mise mɛkan a,

ne dodow bɛboro mpoano nwea,

sɛ minyan a,

me ne wo wɔ hɔ ara.

19Sɛ anka, Onyankopɔn, wubekunkum amumɔyɛfo ɛ!

Mumfi me so, mo a moyɛ mogyapɛfo!

20Wɔde adwemmɔne ka wo ho asɛm;

wʼatamfo mmmɔ wo din pa.

21Awurade, metan wɔn a wɔtan wo,

na mikyi wɔn a wɔsɔre tia wo no ana?

22Minni hwee sɛ ɔtan a mewɔ ma wɔn;

mefa wɔn sɛ mʼatamfo.

23Hwehwɛ me mu, Onyankopɔn, na hu me koma;

sɔ me hwɛ, na hu mʼadwene.

24Hwɛ sɛ bɔne bi wɔ me mu a,

na di mʼanim fa daa nkwa kwan so.