Saamu 126 – YCB & NVI-PT

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Saamu 126:1-6

Saamu 126

Orin fún ìgòkè.

1Nígbà tí Olúwa mú ìkólọ Sioni padà,

àwa dàbí ẹni tí ó ń lá àlá.

2Nígbà náà ni ẹnu wa kún fún ẹ̀rín,

àti ahọ́n wa kọ orin;

nígbà náà ni wọ́n wí nínú àwọn kèfèrí pé,

Olúwa ṣe ohun ńlá fún wọn.

3Olúwa ṣe ohun ńlá fún wa;

nítorí náà àwa ń yọ̀.

4Olúwa mú ìkólọ wa padà,

bí ìṣàn omi ní gúúsù.

5Àwọn tí ń fi omijé fún irúgbìn

yóò fi ayọ̀ ka.

6Ẹni tí ń fi ẹkún rìn lọ,

tí ó sì gbé irúgbìn lọ́wọ́,

lóòtítọ́, yóò fi ayọ̀ padà wá,

yóò sì ru ìtí rẹ̀.

Nova Versão Internacional

Salmos 126:1-6

Salmo 126

Cântico de Peregrinação.

1Quando o Senhor trouxe os cativos

de volta a Sião126.1 Ou trouxe restauração a Sião, foi como um sonho.

2Então a nossa boca encheu-se de riso

e a nossa língua de cantos de alegria.

Até nas outras nações se dizia:

“O Senhor fez coisas grandiosas por este povo”.

3Sim, coisas grandiosas fez o Senhor por nós,

por isso estamos alegres.

4Senhor, restaura-nos126.4 Ou traze nossos cativos de volta,

assim como enches o leito dos ribeiros no deserto126.4 Ou Neguebe.

5Aqueles que semeiam com lágrimas,

com cantos de alegria colherão.

6Aquele que sai chorando

enquanto lança a semente,

voltará com cantos de alegria,

trazendo os seus feixes.