Saamu 104 – YCB & HOF

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Saamu 104:1-35

Saamu 104

1Yin Olúwa, ìwọ ọkàn mi.

Olúwa Ọlọ́run mi, ìwọ tóbi jọjọ;

ọlá àti ọláńlá ni ìwọ wọ̀ ní aṣọ.

2Ìwọ fi ìmọ́lẹ̀ bo ara rẹ gẹ́gẹ́ bí aṣọ;

ó tẹ ọ̀run bí títẹ́ ẹní,

3ìwọ tí ó fi omi ṣe ìtì igi àjà ìyẹ̀wù rẹ.

Ìwọ tí o ṣe àwọsánmọ̀ ní kẹ̀kẹ́ ogun rẹ

ìwọ tí ó ń rìn lórí apá ìyẹ́ afẹ́fẹ́.

4104.4: Hb 1.7.Ó fi ẹ̀fúùfù ṣe àwọn ìránṣẹ́ rẹ,

ọ̀wọ́-iná ni àwọn olùránṣẹ́ rẹ.

5O fi ayé gúnlẹ̀ lórí àwọn ìpìlẹ̀;

tí a kò le è mì láéláé.

6Ìwọ fi ibú omi bò ó mọ́lẹ̀ bí aṣọ;

àwọn omi sì dúró lórí àwọn òkè ńlá.

7Ṣùgbọ́n nípa ìbáwí rẹ ni àwọn omi lọ,

nípa ohùn àrá rẹ ni wọ́n sálọ.

8wọ́n sàn kọjá lórí àwọn òkè,

wọ́n sọ̀kalẹ̀ lọ sí àwọn pẹ̀tẹ́lẹ̀,

sí ibi tí ìwọ ti yàn fún wọn.

9Ìwọ gbé òpin tí wọn kò lè kọjá rẹ̀ kálẹ̀;

láéláé ni wọ́n kò ní lè bo ayé mọ́lẹ̀ lẹ́ẹ̀kan sí i.

10Ìwọ mú kí ìsun da omi sí àwọn àfonífojì;

tí ó ń sàn láàrín àwọn òkè.

11Wọ́n fún gbogbo àwọn ẹranko igbó ní omi

àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ń pa òǹgbẹ wọn.

12Àwọn ẹyẹ ojú òfúrufú tẹ́ ìtẹ́ wọn lẹ́gbẹ̀ẹ́ omi

wọ́n ń kọrin láàrín àwọn ẹ̀ka.

13Ó bu omi rin àwọn òkè láti ìyẹ̀wù rẹ̀ wá;

a tẹ́ ayé lọ́rùn nípa èso iṣẹ́ ọwọ́ rẹ.

14Ó mú kí koríko hù jáde fún àwọn ẹranko láti jẹ

àti àwọn ewébẹ̀ fún ènìyàn láti lò,

kí ó lè mú oúnjẹ jáde láti ilẹ̀ wá.

15Ọtí wáìnì tí ó ń mú ọkàn ènìyàn yọ̀,

òróró láti mú ojú rẹ̀ tan,

àti àkàrà láti ra ọkàn rẹ̀ padà.

16Àwọn igi Olúwa ni a bu omi rin dáradára,

kedari ti Lebanoni tí ó gbìn.

17Níbẹ̀ ní àwọn ẹyẹ ṣe ìtẹ́ wọn

bí ó ṣe tí àkọ̀ ni, orí igi gíga ni ilé rẹ̀.

18Àwọn òkè gíga ni ààbò fún àwọn ewúrẹ́ igbó;

àti àwọn àlàpà jẹ́ ààbò fún àwọn ehoro.

19Òṣùpá jẹ́ àmì fún àkókò

oòrùn sì mọ ìgbà tí yóò wọ̀.

20Ìwọ mú òkùnkùn wá, ó sì di òru,

nínú èyí tí gbogbo ẹranko igbó ń rìn kiri.

21Kìnnìún ń bú ramúramù fún ohun ọdẹ wọn

wọ́n sì ń wá oúnjẹ wọn láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run.

22Oòrùn ràn, wọ́n sì kó ara wọn jọ,

wọn padà lọ dùbúlẹ̀ sí ihò wọn.

23Ọkùnrin jáde lọ sí iṣẹ́ wọn,

àti sí làálàá rẹ̀ títí di àṣálẹ́.

24Iṣẹ́ rẹ ti pọ̀ tó, Olúwa!

Nínú ọgbọ́n ni ìwọ ṣe gbogbo wọn:

ayé kún fún àwọn ìṣẹ̀dá á rẹ.

25Bẹ́ẹ̀ ni Òkun yìí tí ó tóbi, tí ó sì ni ìbú,

tí ó kún fún àwọn ẹ̀dá alààyè ní ìsàlẹ̀ láìníye

ohun alààyè tí tóbi àti kékeré.

26Níbẹ̀ ni ọkọ̀ ń lọ síwá sẹ́yìn,

àti Lefitani, tí ìwọ dá láti ṣe àríyá nínú rẹ̀.

27Àwọn wọ̀nyí ń wò ọ́

láti fún wọn ní oúnjẹ wọn lákòókò rẹ̀.

28Nígbà tí ìwọ bá fi fún wọn,

wọn yóò kó jọ;

nígbà tí ìwọ bá la ọwọ́ rẹ̀,

a tẹ́ wọn lọ́rùn pẹ̀lú ohun rere.

29Nígbà tí ìwọ bá pa ojú rẹ mọ́

ara kò rọ̀ wọ́n

nígbà tí ìwọ bá mú ẹ̀mí wọn lọ,

wọn ó kú, wọn ó sì padà sí erùpẹ̀.

30Nígbà tí ìwọ rán ẹ̀mí rẹ,

ni a dá wọn,

ìwọ sì tún ojú ayé ṣe.

31Jẹ́ kí ògo Olúwa wà pẹ́ títí láé;

kí inú Olúwa kí ó dùn ní ti iṣẹ́ rẹ̀,

32ẹni tí ó wo ayé, tí ó sì wárìrì,

ẹni tí ó fọwọ́ tọ́ àwọn òkè, tí wọ́n yọ èéfín.

33Ní gbogbo ayé mi ní n ó kọrin sí Olúwa:

èmi ó kọrin ìyìn sí Olúwa

níwọ̀n ìgbà tí mo wà láààyè.

34Jẹ́ kí ẹ̀kọ́ mi kí ó tẹ́ ọ lọ́rùn

bí mo ti ń yọ̀ nínú Olúwa.

35Ṣùgbọ́n kí ẹlẹ́ṣẹ̀ kúrò láyé

kí ènìyàn búburú má sì sí mọ́.

Yin Olúwa, ìwọ ọkàn mi.

Yin Olúwa.

Hoffnung für Alle

Psalm 104:1-35

Freude an Gottes Schöpfung

1Ich will den Herrn preisen von ganzem Herzen.

Herr, mein Gott, wie groß bist du!

Majestätische Pracht ist dein Festgewand,

2helles Licht umhüllt dich wie ein Mantel.

Du spanntest den Himmel aus wie ein Zeltdach,

3über den Wolken104,3 Wörtlich: in den Wassern. – Vgl. 1. Mose 1,6‒8. hast du deine Wohnung errichtet.

Ja, die Wolken sind dein Wagen,

du fährst auf den Flügeln des Windes dahin.

4Wind und Wetter sind deine Boten,

und feurige Flammen sind deine Diener.

5Die Erde stelltest du auf ein festes Fundament,

niemals gerät sie ins Wanken.

6Wie ein Kleid bedeckte die Urflut ihre Kontinente,

die Wassermassen standen noch über den Bergen.

7Doch vor deinem lauten Ruf wichen sie zurück,

vor deinem Donnergrollen flohen sie.

8Die Berge erhoben sich,

und die Täler senkten sich an den Ort,

den du für sie bestimmt hattest.

9Du hast dem Wasser eine Grenze gesetzt,

die es nicht überschreiten darf,

nie wieder soll es die ganze Erde überschwemmen.

10Du lässt Quellen sprudeln und als Bäche in die Täler fließen,

zwischen den Bergen finden sie ihren Weg.

11Die Tiere der Steppe trinken davon,

Wildesel stillen ihren Durst.

12An ihren Ufern nisten die Vögel,

in dichtem Laub singen sie ihre Lieder.

13Vom Himmel lässt du Regen auf die Berge niedergehen,

die Erde versorgst du und schenkst reiche Frucht.

14Du lässt Gras wachsen für das Vieh

und Pflanzen, die der Mensch anbauen und ernten kann.

15So hat er Wein, der ihn erfreut,

Öl, das seinen Körper pflegt, und Brot, das ihn stärkt.

16Du, Herr, hast die riesigen Zedern

auf dem Libanongebirge gepflanzt und gibst ihnen genügend Regen.

17In ihren Zweigen bauen die Vögel ihre Nester,

und Störche haben in den Zypressen ihren Brutplatz.

18In den hohen Bergen hat der Steinbock sein Revier,

und das Murmeltier104,18 Wörtlich: der Klippdachs. – Der Klippdachs war ein murmeltierähnlicher Pflanzenfresser von gelb-brauner Farbe. Vgl. 3. Mose 11,5; 5. Mose 14,7. findet in den Felsen Zuflucht.

19Du hast den Mond gemacht, um die Monate zu bestimmen,

und die Sonne weiß, wann sie untergehen soll.

20Du lässt die Dunkelheit hereinbrechen, und es wird Nacht –

dann regen sich die Tiere im Dickicht des Waldes.

21Die jungen Löwen brüllen nach Beute;

von dir, o Gott, erwarten sie ihre Nahrung.

22Sobald aber die Sonne aufgeht,

schleichen sie zurück in ihre Schlupfwinkel

und legen sich dort nieder.

23Dann steht der Mensch auf und geht an seine Arbeit,

er hat zu tun, bis es wieder Abend wird.

24O Herr, welch unermessliche Vielfalt zeigen deine Werke!

Sie alle sind Zeugen deiner Weisheit,

die ganze Erde ist voll von deinen Geschöpfen.

25Da ist das Meer – so unendlich groß und weit,

unzählbar sind die Tiere darin, große wie kleine.

26Schiffe ziehen dort vorüber und auch die Seeungeheuer,

die du geschaffen hast, um mit ihnen zu spielen.

27Alle deine Geschöpfe warten auf dich,

dass du ihnen zur rechten Zeit zu essen gibst.

28Sie holen sich die Nahrung, die du ihnen zuteilst.

Du öffnest deine Hand, und sie werden reichlich satt.

29Doch wenn du dich von ihnen abwendest,

müssen sie zu Tode erschrecken.

Ja, sie sterben und werden zu Staub,

wenn du ihnen den Lebensatem nimmst.

30Doch wenn du deinen Geist schickst, wird neues Leben geschaffen,

und die Erde kann sich wieder entfalten.

31Die Herrlichkeit des Herrn möge ewig bestehen!

Er freue sich an dem, was er geschaffen hat!

32Er braucht die Erde nur anzusehen – schon fängt sie an zu beben;

und wenn er die Berge berührt, dann stoßen sie Rauch aus.

33Singen will ich für den Herrn, solange ich bin,

für meinen Gott will ich musizieren mein Leben lang.

34Wie freue ich mich über den Herrn

möge ihm mein Lied gefallen!

35Doch wer sich ihm widersetzt, soll nicht mehr weiterleben,

ja, die Gottlosen sollen vom Erdboden verschwinden.

Ich will den Herrn preisen von ganzem Herzen.

Halleluja – lobt den Herrn!