Romu 15 – YCB & NUB

Yoruba Contemporary Bible

Romu 15:1-33

1Àwa tí a jẹ́ alágbára nínú ìgbàgbọ́ yẹ kí ó máa ru ẹrù àìlera àwọn aláìlera, kí a má sì ṣe ohun tí ó wu ara wa. 2Olúkúlùkù wa gbọdọ̀ máa ṣe ohun tí ó wu ọmọnìkejì rẹ̀ sí rere, láti gbé e ró. 315.3: Sm 69.9.Nítorí Kristi pàápàá kò ṣe ohun tí ó wu ara rẹ̀, ṣùgbọ́n, bí a ti kọ ọ́ pé: “Ẹ̀gàn àwọn ẹni tí ń gàn ọ́ ṣubú lù mi.” 415.4: Ro 4.23-24; 1Kọ 9.10; 2Tm 3.16.Nítorí ohun gbogbo tí a kọ tẹ́lẹ̀, ni a kọ láti fi kọ́ wa pé, nípa sùúrù àti ìtùnú ìwé mímọ́, kí àwa lè ní ìrètí.

515.5: Ro 12.16; 1Kọ 1.10; 2Kọ 13.11; Fp 2.2; 4.2.Kí Ọlọ́run, ẹni tí ń fún ni ní sùúrù àti ìtùnú fún yin láti ní inú kan sí ara yín gẹ́gẹ́ bí i Jesu Kristi, 6kí ẹ̀yin kí ó lè fi ọkàn kan àti ẹnu kan fi ògo fún Ọlọ́run, Baba Olúwa wa Jesu Kristi.

7Nítorí náà ẹ gba ara yín mọ́ra, gẹ́gẹ́ bí Kristi ti gbà wá mọ́ra fún ògo Ọlọ́run. 8Mo sì wí pé, a rán Kristi láti ṣe ìránṣẹ́ ìkọlà àwọn tí ṣe Júù nítorí òtítọ́ Ọlọ́run, láti fi ìdí àwọn ìlérí tí a ti ṣe fún àwọn baba múlẹ̀, 915.9: Sm 18.49; 2Sa 22.50.kí àwọn aláìkọlà kí ó lè yin Ọlọ́run lógo nítorí àánú rẹ̀; gẹ́gẹ́ bí a ti kọ ọ́ pé:

“Nítorí èyí ni èmi ó ṣe yìn ọ́ láàrín àwọn Kèfèrí,

Èmi ó sì kọrin sí orúkọ rẹ.”

1015.10: De 32.43.Ó sì tún wí pé,

“Ẹ̀yin Kèfèrí, ẹ ma yọ̀, pẹ̀lú àwọn ènìyàn rẹ̀.”

1115.11: Sm 117.1.Àti pẹ̀lú,

“Ẹyin Olúwa, gbogbo ẹ̀yin Kèfèrí;

ẹ kọ orin ìyìn sí, ẹ̀yin ènìyàn gbogbo.”

1215.12: Isa 11.10; Mt 12.21.Isaiah sì tún wí pé,

“Gbòǹgbò Jese kan ń bọ̀ wá,

òun ni ẹni tí yóò dìde ṣe àkóso àwọn Kèfèrí;

Àwọn Kèfèrí yóò ní ìrètí nínú rẹ̀.”

13Ǹjẹ́ kí Ọlọ́run ìrètí kí ó fi gbogbo ayọ̀ òun àlàáfíà kún yín bí ẹ̀yin ti gbà á gbọ́, kí ẹ̀yin kí ó lè pọ̀ ní ìrètí nípa agbára Ẹ̀mí Mímọ́.

Paulu wàásù sí àwọn Kèfèrí

14Ẹ̀yin ará, èmi gan alára ti ní ìdánilójú, pé ẹ̀yin pàápàá kún fún oore, a sì fi gbogbo ìmọ̀ kún un yín, ẹ̀yin sì jáfáfá láti máa kọ́ ara yín. 15Síbẹ̀ mo ti fi ìgboyà kọ̀wé sí yín lórí àwọn kókó-ọ̀rọ̀ kan, bí ẹni ti ń rán yín létí àwọn kókó-ọ̀rọ̀ náà, nítorí oore-ọ̀fẹ́ tí a ti fi fún mi láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run 1615.16: Ap 9.15.láti jẹ́ ìránṣẹ́ Kristi Jesu láàrín àwọn Kèfèrí láti polongo ìhìnrere Ọlọ́run gẹ́gẹ́ bí ojúṣe àlùfáà, kí àwọn Kèfèrí lè jẹ́ ẹbọ ọrẹ ìtẹ́wọ́gbà fún Ọlọ́run, èyí tí a ti fi Ẹ̀mí mímọ́ yà sí mímọ́.

17Nítorí náà, mo ní ìṣògo nínú Kristi Jesu nínú iṣẹ́ ìránṣẹ́ mi fún Ọlọ́run. 1815.18: Ro 1.5; Ap 15.12; 21.19.Èmi kò sá à gbọdọ̀ sọ ohun kan bí kò ṣe èyí tí Kristi ti ọwọ́ mi ṣe, ní títọ́ àwọn Kèfèrí ṣọ́nà láti ṣe ìgbọ́ràn sí ọ̀rọ̀ Ọlọ́run nípa ọ̀rọ̀ àti ìṣe mi: 1915.19: Ap 19.11; 2Kọ 12.12.nípa agbára iṣẹ́ ààmì àti iṣẹ́ ìyanu, nípa agbára Ẹ̀mí Ọlọ́run, tó bẹ́ẹ̀ láti Jerusalẹmu àti yíkákiri, àní títí fi dé Illirikoni, mo ti polongo ìhìnrere Kristi ní ẹ̀kúnrẹ́rẹ́. 2015.20: 2Kọ 10.15-16.Ó jẹ́ èrò mi ní gbogbo ìgbà láti wàásù ìhìnrere Kristi ní ibi gbogbo tí wọn kò tí ì mọ̀ ọ́n, kí èmi kí ó má ṣe máa mọ àmọlé lórí ìpìlẹ̀ ẹlòmíràn. 2115.21: Isa 52.15.Ṣùgbọ́n, gẹ́gẹ́ bí a ti kọ ọ́ pé:

“Àwọn ẹni tí a kò tí ì sọ ọ̀rọ̀ rẹ̀ fún yóò rí i,

àti àwọn tí kò tí ì gbọ́, òye yóò sì yé.”

2215.22: Ro 1.13.Ìdí nìyìí tí ààyè fi há pẹ́ tó bẹ́ẹ̀ fún mi kí n tó tọ̀ yín wa.

Paulu ṣètò láti ṣé àbẹ̀wò sí Romu

2315.23: Ap 19.21; Ro 1.10-11; 15.32.Ṣùgbọ́n báyìí tí kò tún sí ibòmíràn fún mi mọ́ láti ṣiṣẹ́ ní ẹkùn yìí, tí èmi sì ti ń pòǹgbẹ láti ọdún púpọ̀ sẹ́yìn láti bẹ́ yín wò, 2415.24: Ro 15.28.mo gbèrò láti ṣe bẹ́ẹ̀ nígbà tí mo bá lọ sí Spania. Èmi yóò rí i yín ní ọ̀nà àjò mi, àti pé ẹ ó mú mi já ọ̀nà níbẹ̀ láti ọ̀dọ̀ yín lọ, lẹ́yìn tí mo bá gbádùn ẹgbẹ́ yín fún ìgbà díẹ̀. 2515.25: Ap 19.21; 24.17; 15.31.Ṣùgbọ́n ní báyìí, mo ń lọ sí Jerusalẹmu láti sé ìránṣẹ́ fún àwọn ènìyàn mímọ́ níbẹ̀. 2615.26: 2Kọ 8.1-5; 9.2; 1Tẹ 1.7-8.Nítorí pé ó wu àwọn tí ó wà ní Makedonia àti Akaia láti kó owó jọ fún àwọn tálákà tí ó wà ní àárín àwọn ènìyàn mímọ́ ní Jerusalẹmu. 2715.27: 1Kọ 9.11.Pẹ̀lú ayọ̀ ni wọ́n ń ṣe èyí, nítorí wọ́n gbà wí pé, wọ́n jẹ́ ajigbèsè fún wọn. Nítorí bí ó bá ṣe pé a fi àwọn Kèfèrí ṣe alájọni nínú ohun ẹ̀mí wọn, ajigbèsè sì ni wọn láti fi ohun ti ara ta wọ́n lọ́rẹ. 2815.28: Ro 15.24.Nítorí náà, nígbà tí mo bá ti ṣe èyí tán, tí mo bá sì di èdìdì èso náà fún wọn tán, èmi yóò ti ọ̀dọ̀ yín lọ sí Spania. 2915.29: Ap 19.21.Mo sì mọ̀ pé nígbà tí mo bá dé ọ̀dọ̀ yín, èmi yóò wà ní ẹ̀kúnrẹ́rẹ́ ìbùkún ìhìnrere Kristi.

30Èmí rọ̀ yín, ẹ̀yin arákùnrin àti arábìnrin, nítorí Olúwa wa Jesu Kristi, àti nítorí ìfẹ́ Ẹ̀mí, kí ẹ̀yin kí ó kún mi láti bá mi làkàkà nínú àdúrà yín sí Ọlọ́run fún mi. 3115.31: 2Tẹ 3.2; Ro 15.25-26; 2Kọ 8.4; 9.1.Kí a lè kó mi yọ kúrò lọ́wọ́ àwọn aláìgbàgbọ́ ní Judea àti kí iṣẹ́ ìránṣẹ́ tí mo ní sí Jerusalẹmu le jẹ́ ìtẹ́wọ́gbà lọ́dọ̀ àwọn ènìyàn mímọ́ níbẹ̀, 3215.32: Ro 1.10; Ap 19.21.kí èmi le fi ayọ̀ tọ̀ yín wa, nípa ìfẹ́ Ọlọ́run, àti kí èmi lè ní ìtura pọ̀ pẹ̀lú yín. 3315.33: 2Kọ 13.11; Fp 4.9.Kí Ọlọ́run àlàáfíà wà pẹ̀lú gbogbo yín. Àmín.

Swedish Contemporary Bible

Romarbrevet 15:1-33

Tänk på andra

1Vi som har en stark tro är skyldiga att hjälpa de svaga med deras problem, och inte bara tänka på oss själva. 2Var och en av oss ska tänka på det som är bäst för andra och bygger upp. 3Kristus tänkte inte på sig själv, utan på andra. Det står ju skrivet: ”Dina förolämpares förolämpningar har fallit över mig.”15:3 Se Ps 69:9.

4Allt som skrivits förut står där för att undervisa oss, för att vi genom uthållighet och tröst från Skriften ska kunna hålla fast vid hoppet. 5Och må Gud, han som ger uthållighet och tröstar, hjälpa er att leva eniga med varandra, i enlighet med Kristus Jesus vilja. 6Då kan ni alla tillsammans hylla vår Herre Jesus Kristus Gud och Fader.

7Acceptera därför varandra på samma sätt som Kristus har accepterat er, för då blir Gud ärad. 8Jag menar att Kristus blev de omskurnas tjänare för att visa Guds sanning och bekräfta de löften som gavs till förfäderna. 9Då skulle också de andra folken hylla Gud för hans barmhärtighet. Det står ju skrivet:

”Därför vill jag prisa dig bland folken,

och sjunga till din ära!”15:9 Se Ps 18:50.

10Det står också:

”Gläd er, ni folk, tillsammans med hans folk!”15:10 Se 5 Mos 32:43.

11Vidare:

”Prisa Herren, alla nationer!

Lova honom, alla folk!”15:11 Se Ps 117:1.

12Jesaja säger också:

”Han som är av Jishajs rot15:12 Dvs. ättlingen till Jishaj, kung Davids far. ska komma,

och han ska resa sig för att härska över alla folk.

De ska hoppas på honom.”15:12 Se Jes 11:10.

13Må hoppets Gud fylla er med all glädje och frid när ni tror på honom, så att den heliga Andens kraft gör ert hopp allt starkare.

Paulus speciella uppdrag

14Jag är själv övertygad om, syskon, att ni är fyllda med godhet och med så mycket kunskap att ni kan vägleda varandra. 15Men jag ville ändå skriva till er för att påminna om allt detta, och ibland har jag varit mycket rakt på sak. Det beror på att Gud i sin nåd gav mig 16uppdraget att tjäna som präst åt Kristus Jesus, för att jag skulle sprida Guds evangelium till andra folk, så att de skulle bli ett offer till Gud, helgat genom den heliga Anden.

17Tack vare Kristus Jesus kan jag vara stolt över det uppdrag Gud har gett mig. 18Något annat än det som Kristus har gjort genom mig för de andra folken vågar jag inte tala om. Han har fått dem att lyda Gud genom mina ord och mina handlingar, 19och genom kraften i tecken och under genom Andens kraft. På detta sätt har jag spridit evangeliet om Kristus, med början i Jerusalem och sedan överallt, ända till Illyrien.15:19 Illyrien var en romersk provins nordost om nuvarande Italien.

20Hela tiden har min målsättning varit att sprida evangelium på platser där man ännu inte känner Kristus, istället för att bygga vidare på en grund som någon annan har lagt, 21så som det står skrivet:

”De ska se något som ingen har berättat för dem,

och förstå något som de inte har hört om.”15:21 Se Jes 52:15.

22Det är på grund av detta som jag har hindrats så länge från att resa till er.

Paulus resplaner

23Men nu är jag äntligen färdig med mitt arbete i det här området och kan efter många år av väntan komma till er. 24Jag planerar nämligen att resa till Spanien, och på vägen dit tänkte jag stanna hos er. När jag sedan har fått vara tillsammans med er en kort tid, hoppas jag att ni ger mig vad jag behöver för min fortsatta resa.

25Men först måste jag resa till Jerusalem för att hjälpa de heliga där. 26Församlingarna i Makedonien och Achaia15:26 Makedonien och Achaia var två romerska provinser i nuvarande Grekland. har nämligen gjort en frivillig insamling till de fattiga bland de heliga i Jerusalem. 27De var glada att få göra detta, eftersom de står i tacksamhetsskuld till judarna. De andra folken har ju fått del av judarnas andliga goda, och därför är det också rätt att de delar med sig av sitt materiella goda. 28Men så snart jag har avslutat detta uppdrag och lämnat över gåvan till dem tänker jag resa till Spanien och hälsa på er på vägen. 29Och jag vet att när jag kommer till er har jag med mig full välsignelse från Kristus.

30Men jag vädjar till er, syskon, för vår Herre Jesus Kristus skull och för den kärleks skull som Anden ger: Hjälp mig i min kamp genom att be till Gud för mig. 31Be att Gud räddar mig från de människor i Judeen som vägrar att tro och att de heliga i Jerusalem ska bli glada över den hjälp jag har med mig. 32Då kan jag, om Gud vill, besöka er, och genom detta bli uppmuntrad och utvilad.

33Må fridens Gud vara med er alla. Amen.