Ọ̀rọ̀ ìkíni Paulu sí àwọn àyànfẹ́
11.1: Ap 9.15; 13.2; 1Kọ 1.1; 2Kọ 1.1; Ga 1.15.Paulu, ìránṣẹ́ Jesu Kristi, ẹni tí a ti pè láti jẹ́ aposteli, tí a sì ti yà sọ́tọ̀ láti wàásù ìhìnrere Ọlọ́run, 2ìhìnrere tí ó ti ṣe ìlérí tẹ́lẹ̀ rí láti ẹnu àwọn wòlíì rẹ̀ nínú ìwé Mímọ́. 3Ní ti Ọmọ rẹ̀, ẹni tí a bí láti inú irú-ọmọ Dafidi nípa ti ara, 4ẹni tí a pinnu rẹ̀ láti jẹ́ Ọmọ Ọlọ́run nínú agbára gẹ́gẹ́ bí Ẹ̀mí ìwà mímọ́, nípa àjíǹde kúrò nínú òkú, àní Jesu Kristi Olúwa wa. 51.5: Ap 26.16-18; Ro 15.18; Ga 2.7,9.Láti ọ̀dọ̀ ẹni tí àwa rí oore-ọ̀fẹ́ àti jíjẹ́ aposteli gbà, fún ìgbọ́ràn ìgbàgbọ́ láàrín gbogbo orílẹ̀-èdè, nítorí orúkọ rẹ̀. 6Ẹ̀yin pẹ̀lú si wa lára àwọn tí a pè sọ́dọ̀ Jesu Kristi.
71.7: 1Kọ 1.3; 2Kọ 1.2; Ga 1.3; Ef 1.2; Fp 1.2; Kl 1.2; 1Tẹ 1.2; 2Tẹ 1.2; 1Tm 1.2; 2Tm 1.2; Tt 1.4; Fm 3; 2Jh 3.Sí gbogbo àwọn àyànfẹ́ Ọlọ́run tí ó wà ní Romu tí a ti pè láti jẹ́ ènìyàn mímọ́:
Oore-ọ̀fẹ́ àti àlàáfíà fún yín láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run Baba wa àti láti ọ̀dọ̀ Olúwa wa Jesu Kristi.
Ìfojúsọ́nà Paulu láti bẹ Romu wò
81.8: Ro 16.19.Ní àkọ́kọ́, mo dúpẹ́ lọ́wọ́ Ọlọ́run nípasẹ̀ Jesu Kristi fún gbogbo yín, nítorí a ń ròyìn ìgbàgbọ́ yin káàkiri gbogbo ayé. 9Ọlọ́run ṣá à ni ẹlẹ́rìí mi, ẹni tí èmí ń fi gbogbo ẹ̀mí mi sìn nínú ìhìnrere Ọmọ rẹ̀, bí ó ti ṣe pé ní àìsimi ni èmí ń rántí yín nígbà gbogbo nínú àdúrà mi 101.10: Ro 15.23,32; Ap 19.21.nínú àdúrà mi ìgbà gbogbo; mo tún ń gbàdúrà wí pé nípa oore-ọ̀fẹ́ Ọlọ́run kí ọ̀nà ó ṣí fún mi láti wá sọ́dọ̀ yín.
11Nítorí èmi ń fẹ́ gidigidi láti tọ̀ yín wá, kí èmi lè fún yín ní ẹ̀bùn ẹ̀mí díẹ̀, kí a bá a le sọ yín di alágbára nínú Olúwa, 12èyí nì ni pé, kí a lè jẹ́ ìwúrí fún ara wa nípa ìgbàgbọ́ ẹnìkọ̀ọ̀kan wa. 131.13: Ro 15.22.Mo fẹ́ kí ẹ mọ èyí, ẹ̀yin ará mi, pé mo ti gbìyànjú lọ́pọ̀ ìgbà láti tọ̀ yín wá, (ṣùgbọ́n ìdíwọ́ wà fún mi), kí èmi ki ó lè jèrè ọkàn díẹ̀ láàrín yín, gẹ́gẹ́ bí mo ti ní láàrín àwọn aláìkọlà yòókù.
141.14: 1Kọ 9.16.Nítorí mo jẹ́ ajigbèsè sí Giriki àti sí àwọn aláìgbédè tí kì í ṣe Giriki, sí àwọn ọlọ́gbọ́n àti sí àwọn aṣiwèrè. 15Nítorí ìdí èyí ni mo ṣe ń làkàkà láti wá sí Romu àti láti fi gbogbo agbára mi wàásù ìhìnrere Ọlọ́run sí i yín.
161.16: 1Kọ 1.18,24.Èmi kò tijú ìhìnrere Jesu, nítorí agbára Ọlọ́run ní ín ṣe láti gba gbogbo àwọn tí ó bá gbàgbọ́ là, ọ̀rọ̀ yìí ni a kọ́kọ́ wàásù sí àwọn Júù nìkan, ṣùgbọ́n nísinsin yìí fún àwọn Helleni pẹ̀lú. 171.17: Ro 3.21; Ga 3.11; Fp 3.9; Hb 10.38; Hk 2.4.Nítorí nínú ìhìnrere ni òdodo Ọlọ́run ti farahàn, òdodo Ọlọ́run nípa ìgbàgbọ́ láti ìbẹ̀rẹ̀ dé òpin gẹ́gẹ́ bí a ti kọ ọ́ nínú ìwé Mímọ́ pé, “Olódodo yóò yè nípa ìgbàgbọ́ rẹ̀.”
Ìbínú Ọlọ́run sí orílẹ̀ ayé
181.18: Ef 5.6; Kl 3.6.Ṣùgbọ́n Ọlọ́run fi ìbínú rẹ̀ hàn láti ọ̀run wá sí gbogbo àìwà-bí-Ọlọ́run àti gbogbo àìṣòdodo ènìyàn, àwọn tí ń fi ìwà búburú dènà ìmọ̀ òtítọ́ lọ́dọ̀ ènìyàn. 19Nítorí pé, nǹkan gbogbo tí a lè mọ nípa Ọlọ́run ni a ti fihàn fún wọn, nítorí Ọlọ́run ti fi í hàn fún wọn. 201.20: Sm 19.1-4.Nítorí pé láti ìgbà dídá ayé, gbogbo ohun àìlèfojúrí rẹ̀: bí agbára ayérayé àti ìwà-bí-Ọlọ́run rẹ̀ ni a rí gbangba tí a sì ń fi òye ohun tí a dá mọ̀ ọ́n kí ènìyàn má ba à wá àwáwí.
211.21: Ef 4.17-18.Lóòótọ́, wọn ní òye nípa Ọlọ́run dáradára, ṣùgbọ́n wọn kò yìn ín lógo bí Ọlọ́run, wọ́n kò sí dúpẹ́ lọ́wọ́ rẹ̀; wọ́n ń ro èrò asán, ọkàn aṣiwèrè wọn sì ṣókùnkùn. 22Níwọ́n bí ó tilẹ̀ jẹ́ wí pé wọ́n pe ara wọn ní ọlọ́gbọ́n ṣùgbọ́n wọ́n di òmùgọ̀ pátápátá, 231.23: Ap 17.29.wọ́n sì yí ògo Ọlọ́run tí kì í díbàjẹ́ sí àwọn àwòrán ère bí i ti ènìyàn tí í díbàjẹ́ àti ti ẹyẹ, àti ti ẹranko ẹlẹ́sẹ̀ mẹ́rin àti ti ẹranko afàyàfà.
24Nítorí náà Ọlọ́run fà wọ́n lé ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ ọkàn wọn lọ́wọ́ láti máa ṣe ohun ìríra pẹ̀lú ara wọn èyí tí kò tọ́. 25Wọ́n yí òtítọ́ Ọlọ́run sí èké, wọ́n sì ń foríbalẹ̀ láti máa sin ẹ̀dá dípò ẹlẹ́dàá—ẹni tí ìyìn tọ́ sí láéláé. Àmín.
26Nítorí èyí yìí ni Ọlọ́run ṣe fi wọ́n fún ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́: nítorí àwọn obìnrin wọn tilẹ̀ ń yí ìṣẹ̀dá ìbáṣepọ̀ tí ó tọ̀nà, sí èyí tí kò tọ̀nà. 27Gẹ́gẹ́ bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọkùnrin pẹ̀lú, wọn a máa fi ìbálòpọ̀ obìnrin nípa ti ẹ̀dá sílẹ̀, wọn a máa fẹ́ ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ sí ara wọn, ọkùnrin ń bá ọkùnrin ṣe èyí tí kò yẹ, wọ́n sì ǹ jẹ èrè ìṣìnà wọn nínú ara wọn bí ó ti yẹ sí.
28Àti gẹ́gẹ́ bí wọ́n ti kọ̀ láti gba Ọlọ́run nínú ìmọ̀ tí ó tọ́, Ọlọ́run fi wọ́n fún iyè ríra láti ṣe ohun tí kò tọ́ fún wọn láti ṣe: 29Wọ́n kún fún onírúurú àìṣòdodo gbogbo, àgbèrè, ìkà, ojúkòkòrò, àrankàn; wọ́n kún fún ìlara, ìpànìyàn, ìjà, ìtànjẹ, ìwà búburú; wọ́n jẹ́ a fi-ọ̀rọ̀-kẹ́lẹ́-banijẹ́. 30Asọ̀rọ̀ ẹni lẹ́yìn, akórìíra Ọlọ́run, aláfojúdi, agbéraga, ahalẹ̀, aláròṣe ohun búburú, aṣàìgbọràn sí òbí, 31aláìníyè nínú, ọ̀dàlẹ̀, aláìnígbàgbọ́, ọ̀dájú, aláìláàánú: 32Bí ó tilẹ̀ jẹ́ wí pé wọ́n mọ ìlànà Ọlọ́run pé, ẹni tí ó bá ṣe irú nǹkan wọ̀nyí yẹ sí ikú, wọn kò ní inú dídùn sí àwọn nǹkan wọ̀nyí nìkan ṣùgbọ́n wọ́n ní inú dídùn sí àwọn tí ń ṣe wọ́n.
1این نامه از طرف پولس، غلام عیسی مسیح است که توسط خدا به رسالت برگزیده شده تا مژدهٔ انجیل او را به همگان برساند. 2همان انجیلی که خدا وعدهاش را از زمانهای دور توسط انبیای خود در کتب مقدّس داده بود. 3این انجیل دربارهٔ اوست، که بهلحاظ زندگی زمینیاش، از نسل داوود پادشاه بود؛ 4اما بهلحاظ قدوسیت الهیاش، با زنده شدنش پس از مرگ، ثابت کرد که پسر نیرومند خداست، یعنی خداوند ما، عیسی مسیح.
5بهواسطۀ مسیح فیض و رسالت یافتهایم تا به همهٔ اقوام غیریهود اعلام کنیم که او چه لطف عظیمی به ایشان نموده است، تا ایشان نیز به او ایمان آورند، از او اطاعت کنند و نام او را جلال دهند 6و این شامل شما نیز میشود که فراخوانده شدهاید تا از آنِ عیسی مسیح باشید.
7این نامه را به همۀ کسانی که در روم محبوب خدا هستند و فراخوانده شدهاند تا قوم مقدّس او باشند، مینویسم.
از پدرمان خدا و خداوندمان عیسی مسیح، طالب فیض و آرامش برای شما هستم.
دعای شکرگزاری برای مسیحیان روم
8پیش از هر چیز، باید بگویم که خبر ایمانتان به تمام دنیا رسیده است. از این رو، برای این خبر و برای وجود هر یک از شما، خدا را بهوسیلۀ عیسی مسیح شکر میکنم. 9خدا شاهد است که من پیوسته برای شما دعا میکنم، و روز و شب احتیاجاتتان را به حضور او میبرم، به حضور خدایی که با تمام توانم او را خدمت میکنم و مژدهٔ انجیل او را که دربارهٔ پسرش عیسی مسیح است، به دیگران اعلام مینمایم.
10دعای دیگرم این است که اگر خدا بخواهد، پس از این همه انتظار، سعادت دیدار شما نصیبم شود. 11زیرا بسیار مشتاق دیدارتان هستم تا بتوانم شما را از برکات خدا برخوردار سازم، و باعث تقویت ایمانتان شوم. 12از این گذشته، من خود نیز نیاز به کمک شما دارم تا بهوسیلۀ ایمانتان تقویت شوم. به این ترتیب، هر یک از ما باعث تقویت ایمان یکدیگر میشویم.
13اما برادران عزیز، مایلم بدانید که بارها خواستهام نزد شما بیایم، اما هر بار مانعی پیش آمده است. قصد من از آمدن، این بود که خدمتی در میان شما انجام دهم و عدهای را به سوی مسیح هدایت کنم، همانطور که در جاهای دیگر نیز کردهام. 14زیرا من خود را مدیون میدانم که این خبر خوش را به همه برسانم، چه به اشخاص متمدن و چه به اشخاص بیتمدن، چه به باسوادان و چه به بیسوادان. 15پس تا آنجا که در توان دارم، خواهم کوشید که به روم، نزد شما بیایم و مژدهٔ انجیل را در میان شما اعلام نمایم. 16زیرا من از انجیل مسیح شرم ندارم چون قدرت خداست برای نجات تمام کسانی که ایمان بیاورند. پیغام انجیل در ابتدا فقط به یهودیان اعلام میشد، اما اکنون همه میتوانند با ایمان آوردن به آن، به حضور خدا راه یابند. 17پیغام این است که خدا فقط در یک صورت از سر تقصیرات ما میگذرد و به ما شایستگی آن را میدهد که به حضور او برویم؛ و آن وقتی است که به عیسی مسیح ایمان آوریم. بله، فقط ایمان لازم است. همانطور که نوشته شده: «عادل به ایمان خواهد زیست.»1:17 حبقوق ۲:۴.
خشم خدا نسبت به گناهان بشر
18اما خدا خشم و غضب خود را از آسمان بر تمام خدانشناسیها و شرارتهای اشخاصی آشکار میسازد که با شرارتهای خود، حقیقت را سرکوب میکنند. 19برای آنان حقیقت وجود خدا کاملاً روشن است، زیرا خدا ایشان را از این حقیقت آگاه ساخته است. 20انسان از ابتدا، آسمان و زمین و چیزهایی را که خدا آفریده، دیده است و با دیدن آنها میتواند به وجود خدا و قدرت ابدی او که نادیدنی هستند پی ببرد. پس وقتی در روز داوری در حضور خدا میایستد، برای بیایمانی خود هیچ عذر و بهانهای ندارد.
21بله، درست است که مردم این حقایق را میدانند، اما هیچگاه حاضر نیستند به آن اعتراف کنند و خدا را بپرستند و سپاس گویند. در عوض دربارهٔ وجود خدا و ارادهٔ او، عقاید احمقانهای ابداع میکنند. به همین علّت ذهن نادانشان، تاریک و مغشوش شده است. 22خود را دانا و خردمند میپنداشتند، اما همگی، نادان و بیخرد شدند. 23به جای اینکه خدای بزرگ و ابدی را بپرستند، بتهایی از چوب و سنگ به شکل انسان فانی، پرندگان، چارپایان و خزندگان ساختند و آنها را پرستیدند.
24بنابراین، خدا نیز ایشان را به حال خود رها کرده تا هر چه میخواهند بکنند و در آتش شهوات گناهآلود خود بسوزند و با بدنهای خود مرتکب گناهان شرمآور شوند. 25ایشان حقایق الهی را با دروغ معاوضه کردند و بدینسان، مخلوقات را به جای خدا پرستش کردند – خدایی که شایستۀ ستایش ابدی است! آمین.
26به همین دلیل، خدا آنها را در شهوات شرمآور رها ساخت. حتی زنانشان نیز روابط جنسی غیرطبیعی را جایگزین روابط طبیعی ساختند. 27به همین شکل، مردان نیز روابط طبیعی با زنها را رها کردند، و در آتش شهوت نسبت به یکدیگر سوختند. مردان با مردان مرتکب اعمال شرمآور شدند، و در وجود خود، به سزای اعمال خود رسیدند.
28پس همانطور که ایشان برای شناخت خدا ارزش قائل نیستند، خدا نیز ایشان را به حال خود رها کرده است تا هر آنچه به ذهن ناپاکشان خطور میکند، به عمل آورند. 29زندگی آنان پر است از هر نوع شرارت و بدی، طمع و نفرت و حسادت، قتل و جدال، دروغ و کینه و سخنچینی. 30غیبت از زبانشان دور نمیشود. ایشان دشمنان خدا هستند. مغرور و گستاخ و خودستایند. همیشه به دنبال راههای تازه میگردند تا بیشتر گناه ورزند و مطیع والدین خود نیستند. 31بیاحساسند و بدقول و بیعاطفه و بیرحم. 32با اینکه میدانند خدا برای چنین اعمالی، مجازات مرگ تعیین کرده است، نه فقط خودشان مرتکب آنها میشوند، بلکه دیگران را نیز به انجام این کارها تشویق میکنند!