Oniwaasu 1 – YCB & ASCB

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Oniwaasu 1:1-18

Asán ni ohun ayé

1Ọ̀rọ̀ Oniwaasu, ọmọ Dafidi, ọba Jerusalẹmu:

2“Asán inú asán!”

oníwàásù náà wí pé,

“Asán inú asán!

Gbogbo rẹ̀ asán ni.”

3Kí ni ènìyàn rí jẹ ní èrè lórí gbogbo iṣẹ́ rẹ̀,

lórí èyí tí ó ń ṣe wàhálà sí lábẹ́ oòrùn?

4Bí ìran kan ti wá ni ìran mìíràn ń kọjá lọ,

síbẹ̀ ayé dúró títí láé.

5Oòrùn ń ràn, oòrùn sì ń wọ̀,

ó sì sáré padà sí ibi tí ó ti yọ.

6Afẹ́fẹ́ ń fẹ́ lọ sí ìhà gúúsù,

Ó sì ń fẹ́ yípo sí ìhà àríwá,

a sì tún padà sí ọ̀nà rẹ̀.

7Gbogbo odò ń sàn sí inú Òkun,

síbẹ̀síbẹ̀ Òkun kò kún.

Níbi tí àwọn odò ti wá,

níbẹ̀ ni wọ́n tún padà sí.

8Ohun gbogbo ni ó ń mú àárẹ̀ wá,

ju èyí tí ẹnu le è sọ.

Ojú kò tí ì rí ìrírí tí ó tẹ́ ẹ lọ́rùn,

bẹ́ẹ̀ ni, etí kò tí ì kún fún gbígbọ́.

9Ohun tí ó ti wà tẹ́lẹ̀ náà ni yóò sì máa wà, ohun tí a ti ṣe sẹ́yìn

òun ni a ó tún máa ṣe padà

kò sí ohun tuntun lábẹ́ oòrùn.

10Ǹjẹ́ ohun kan wà tí ẹnìkan le è sọ wí pé,

“Wò ó! Ohun tuntun ni èyí”?

Ó ti wà tẹ́lẹ̀ rí ní ọjọ́ tó ti pẹ́,

o ti wà ṣáájú tiwa.

11Kò sí ìrántí ohun ìṣáájú

bẹ́ẹ̀ ni ìrántí kì yóò sí fún

ohun ìkẹyìn tí ń bọ̀

lọ́dọ̀ àwọn tí ń bọ̀ ní ìgbà ìkẹyìn.

Asán ni ọgbọ́n ènìyàn

12Èmi, Oniwaasu ti jẹ ọba lórí Israẹli ní Jerusalẹmu rí. 13Mo fi àsìkò mi sílẹ̀ láti kọ́ àti láti ṣe àwárí pẹ̀lú ọgbọ́n, gbogbo ohun tí ó ń ṣẹlẹ̀ lábẹ́ ọ̀run. Háà! Ẹrù wúwo tí Ọlọ́run ti gbé lé àwọn ènìyàn: 14Èmi ti rí ohun gbogbo tí ó ń ṣẹlẹ̀ lábẹ́ oòrùn, gbogbo rẹ̀ kò ní ìtumọ̀ bí ẹní gbìyànjú àti mú afẹ́fẹ́ ni.

15Ohun tí ó ti wọ́ kò le è ṣe é tọ́ mọ́,

ohun tí kò sí kò le è ṣe é kà.

16Mo rò nínú ara mi, “Wò ó, mo ti dàgbà, ọgbọ́n mi sì ti pọ̀ ju ti ẹnikẹ́ni tí ó ti ṣe alákòóso Jerusalẹmu síwájú mi lọ, mo ti ní ìrírí púpọ̀ nípa ọgbọ́n àti ìmọ̀.” 17Nígbà náà ni mo fi ara jì láti ní ìmọ̀ nípa ọgbọ́n, àti pàápàá àìgbọ́n àti òmùgọ̀, ṣùgbọ́n mo rí, wí pé èyí pẹ̀lú bí ẹni ń gbìyànjú àti mú afẹ́fẹ́ ni.

18Nítorí pé ọgbọ́n púpọ̀ ìbànújẹ́ púpọ̀ ní ń mú wá,

bí ìmọ̀ bá sì ṣe pọ̀ tó náà ni ìbànújẹ́ ń pọ̀ tó.

Asante Twi Contemporary Bible

Ɔsɛnkafoɔ 1:1-18

Biribiara Yɛ Adehuhuo

1Yeinom ne nsɛm a Ɔsɛnkafoɔ, ɔhene Dawid babarima a ɔyɛ ɔhene wɔ Yerusalem seɛ:

2“Ahuhudeɛ! Ahuhudeɛ!”

Ɔsɛnkafoɔ no na ɔseɛ.

“Ahuhudeɛ mu ahuhudeɛ

Biribiara yɛ ahuhudeɛ.”

3Ɛdeɛn na onipa nya firi nʼadwumayɛ nyinaa mu?

Deɛn na ɔnya firi deɛ enti ɔkum ne ho yɛ no awia so no?

4Awoɔ ntoatoasoɔ ba na ɛkɔ,

nanso asase tim hɔ daa.

5Owia pue na owia kɔtɔ,

na ɛyɛ ntɛm kɔ deɛ ɛpue firiiɛ hɔ.

6Mframa bɔ kɔ anafoɔ fam

na ɛdane hwɛ atifi fam;

ɛkyinkyini kɔ baabiara

na ɛsane bɔ fa ne kwan so.

7Nsubɔntene nyinaa tene kɔgu ɛpo mu,

nanso ɛpo nyɛ ma da.

Baabi a nsubɔntene no firie no

ɛhɔ na wɔsane kɔ bio.

8Biribiara yɛ ɔbrɛ

a ɛboro deɛ obi bɛka soɔ.

Ani nhwɛ adeɛ nwie da

na aso nso ntie nsɛm mma ɛmmu so da.

9Deɛ aba no bɛba bio,

deɛ wɔayɛ no, wɔbɛyɛ bio;

adeɛ foforɔ biara nni owia yi ase.

10Biribi wɔ hɔ a wɔbɛtumi aka wɔ ho sɛ:

“Hwɛ! Yei yɛ ade foforɔ” anaa?

Ɛwɔ hɔ dada firi tete nteredee;

ɛwɔ hɔ ansa na wɔwoo yɛn.

11Wɔnnkae tetefoɔ no,

na wɔn a wɔnnya nnwoo wɔn no nso

wɔn a wɔbɛdi wɔn akyi no

renkae wɔn.

Nimdeɛ Yɛ Ahuhudeɛ

12Me, Ɔsɛnkafoɔ, na meyɛ Israelhene wɔ Yerusalem. 13Metuu me ho sii hɔ sɛ mede nimdeɛ bɛsua ayɛ nhwehwɛmu wɔ biribiara a wɔyɛ no owia yi ase ho. Adesoa duruduru bɛn na Onyankopɔn de ato adasamma soɔ yi! 14Mahunu biribiara a wɔyɛ no owia yi ase; ne nyinaa nka hwee, ɛte sɛ deɛ obi de mmirika taa mframa.

15Deɛ akyea no, wɔntumi ntene;

na deɛ ɛnni hɔ no, wɔntumi nkan.

16Mekaa wɔ me ho sɛ, “Hwɛ, manyini na manya nimdeɛ bebree asene obiara a watena Yerusalem ahennwa so ansa na merebɛdi adeɛ. Manya nhunumu ne nimdeɛ mu osuahunu.” 17Afei, meyɛɛ mʼadwene sɛ mɛhwehwɛ na mate nimdeɛ ase, ɛne abɔdamsɛm ne nkwaseasɛm. Nanso mehunuu sɛ yei nso te sɛ deɛ obi di mmirika taa mframa.

18Nimdeɛ bebree de awerɛhoɔ na ɛba;

nyansa bebree de ahohiahia bebree ba.