Onidajį» 9 – YCB & NTLR

BĆ­bĆ©lƬ MĆ­mį»Ģ YorĆ¹bĆ” ƒde ƒn

Onidajį» 9:1-57

Abimeleki

1Ní ọjọ́ kan Abimeleki ọmọ Jerubbaali lọ sí ọ̀dọ̀ àwọn arákùnrin ìyá rẹ̀ ní Ṣekemu ó sì bá wọn sọ̀rọ̀ àti gbogbo àwọn ìbátan ìyá rẹ̀ wí pé, 2“Ẹ bi gbogbo àwọn ará Ṣekemu léèrè, ‘Èwo ló sàn fún un yín, ṣé kí gbogbo àwọn àádọ́rin ọmọ Jerubbaali jẹ ọba lórí yín ni tàbí kí ẹnìkan ṣoṣo ṣe àkóso yín?’ Ṣùgbọ́n ẹ rántí pé ẹran-ara yín àti ẹ̀jẹ̀ yín ni èmi ń ṣe.”

3Nígbà tí àwọn arákùnrin rẹ̀ sọ èyí ní etí àwọn ará Ṣekemu, ọkàn wọn fà sí àti tẹ̀lé Abimeleki torí, wọ́n sọ wí pé, “Arákùnrin wa ní í ṣe.” 4Wọ́n fún un ní àádọ́rin ṣékélì fàdákà láti ilé òrìṣà Baali-Beriti, Abimeleki fi owó náà gba àwọn jàǹdùkú àti aláìníláárí ènìyàn tí wọ́n sì di olùtẹ̀lé rẹ̀. 5Ó kó wọn lọ sí ilé baba rẹ̀ ní Ofira, níbẹ̀ ní orí òkúta kan ṣoṣo ni ó ti pa àádọ́rin nínú àwọn arákùnrin rẹ̀, àwọn Jerubbaali, ṣùgbọ́n Jotamu, àbíkẹ́yìn nínú àwọn ọmọ Jerubbaali, bọ́ yọ nítorí pé ó sá pamọ́. 6Gbogbo àwọn ará Ṣekemu àti àwọn ará Beti-Milo pàdé pọ̀ ní ẹ̀bá igi óákù ní ibi òpó ní Ṣekemu láti fi Abimeleki jẹ ọba.

7Nígbà tí wọ́n sọ ohun tí ó ń ṣẹlẹ̀ yìí fún Jotamu, ó gun orí ṣóńṣó òkè Gerisimu lọ, ó sì ké lóhùn rara pé, “Ẹ tẹ́tí sí mi, ẹ̀yin àgbàgbà Ṣekemu, kí Ọlọ́run le tẹ́tí sí yín. 8Ní ọjọ́ kan àwọn igi jáde lọ láti fi òróró yan ọba fún ara wọn. Wọ́n pe igi Olifi pé, ‘Wá ṣe ọba wa.’

9“Ṣùgbọ́n igi Olifi dá wọn lóhùn pé, ‘Èmi yóò ha fi òróró mi sílẹ̀ èyí tí a ń lò láti fi ọ̀wọ̀ fún àwọn ọlọ́run àti ènìyàn kí èmi sì wá ṣe olórí àwọn igi?’

10“Àwọn igi sọ fún igi ọ̀pọ̀tọ́ pé, ‘Wá jẹ ọba ní orí wa.’

11“Ṣùgbọ́n ọ̀pọ̀tọ́ dá wọn lóhùn pé, ‘Kí èmi fi èso mi tí ó dára tí ó sì dùn sílẹ̀ láti wá ṣe olórí àwọn igi?’

12“Àwọn igi sì tún sọ fún àjàrà pé, ‘Wá, kí o ṣe ọba wa.’

13“Ṣùgbọ́n àjàrà dáhùn pé, ‘Ṣé kí èmi dẹ́kun àti máa so èso wáìnì mi èyí tí ó ń mú inú Ọlọ́run àti àwọn ènìyàn dùn láti máa ṣe olórí àwọn igi?’

14“Ní ìparí gbogbo àwọn igi lọ bá igi ẹ̀gún wọ́n sì sọ fún un pé, ‘Wá kí ó ṣe ọba wa.’

15“Igi ẹ̀gún dá àwọn igi lóhùn pé, ‘Bí olóòtítọ́ ni ẹ bá fẹ́ yàn mí ní ọba yín. Ẹ sá àsálà sí abẹ́ ibòòji mi; ṣùgbọ́n tí kì í bá ṣe bẹ́ẹ̀ jẹ́ kí iná jáde láti inú igi ẹ̀gún kí ó sì jó àwọn igi kedari àti ti Lebanoni run!’

16“Báyìí tí ó bá jẹ́ pé ẹ̀yin ṣe ohun tí ó ní ọlá àti pẹ̀lú ẹ̀mí òtítọ́ ní fífi Abimeleki jẹ ọba, tí ó bá ṣe pé ohun tí ó tọ́ ni ẹ ṣe sí Jerubbaali àti ìdílé rẹ̀, bí ẹ bá san ẹ̀san tó yẹ fún un. 17Nítorí pé baba mi jà nítorí yín, ó fi ẹ̀mí rẹ̀ wéwu láti gbà yín sílẹ̀ lọ́wọ́ àwọn ará Midiani; 18ṣùgbọ́n lónìí ẹ̀yin ṣọ̀tẹ̀ sí ilé baba mi, ní orí òkúta kan ṣoṣo ni ẹ ti pa àwọn àádọ́rin ọmọ rẹ̀, ẹ̀yin sì ti fi Abimeleki ọmọ ẹrúbìnrin rẹ̀ jẹ ọba lórí àwọn ènìyàn Ṣekemu nítorí tí ó jẹ́ arákùnrin yín. 19Bí ohun tí ẹ ṣe sí Jerubbaali àti ìdílé rẹ̀ bá jẹ́ ohun tí ó yẹ, tí ẹ sì ṣe òtítọ́ inú sí i, kí ẹ ní ayọ̀ nínú Abimeleki kí òun náà sì ní ayọ̀ nínú yín. 20Ṣùgbọ́n tí kò bá ṣe bẹ́ẹ̀ jẹ́ kí iná jó jáde wá láti ọ̀dọ̀ Abimeleki kí ó sì jó yín run. Ẹ̀yin ará Ṣekemu àti ará Beti-Milo, kí iná pẹ̀lú jáde láti ọ̀dọ̀ yín wá ẹ̀yin ará Ṣekemu àti ará Beti-Milo kí ó sì jó Abimeleki run.”

21Lẹ́yìn tí Jotamu ti sọ èyí tan, ó sá àsálà lọ sí Beeri, ó sì gbé níbẹ̀ nítorí ó bẹ̀rù arákùnrin rẹ̀ Abimeleki.

22Lẹ́yìn tí Abimeleki ti ṣe àkóso Israẹli fún ọdún mẹ́ta, 23Ọlọ́run rán ẹ̀mí búburú sáàárín Abimeleki àti àwọn ará Ṣekemu, àwọn ẹni tí ó hu ìwà ọ̀tẹ̀. 24Ọlọ́run ṣe èyí láti gbẹ̀san àwọn ìwà búburú, àti ìtàjẹ̀ sílẹ̀ àwọn àádọ́rin ọmọ Jerubbaali lára Abimeleki arákùnrin wọn àti lára àwọn ènìyàn Ṣekemu, ẹni tí ó ràn án lọ́wọ́ láti pa àwọn arákùnrin rẹ̀. 25Nítorí ìkórìíra tí wọ́n ni sí àwọn olórí, ni Ṣekemu dẹ àwọn ènìyàn sí àwọn orí òkè láti máa dá àwọn ènìyàn tó ń kọjá lọ́nà, kí wọn sì máa jà wọ́n lólè, àwọn kan ló sọ èyí fún Abimeleki.

26Gaali ọmọ Ebedi àti àwọn arákùnrin rẹ̀ wá sí Ṣekemu, àwọn ará Ṣekemu sì gbẹ́kẹ̀lé wọn, wọ́n sì fi inú tán wọn. 27Lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n jáde lọ sí oko, wọ́n sì ṣa èso àjàrà wọn jọ, wọ́n fún èso àjàrà náà, wọ́n sì ṣe àjọ̀dún nínú ilé òrìṣà wọn. Nígbà tí wọ́n ń jẹ tí wọ́n ń mu wọ́n fi Abimeleki ré. 28Gaali ọmọ Ebedi dáhùn pé, “Ta ni Abimeleki tàbí ta ni Ṣekemu tí àwa ó fi sìn ín? Ọmọ Jerubbaali kọ́ ní ṣe tàbí Sebulu kọ́ ní igbákejì rẹ̀? Ẹ má sin àwọn ará Hamori baba àwọn ará Ṣekemu, èéṣe tí a ó fi sin Abimeleki? 29Ìbá se pé àwọn ènìyàn yìí wà ní abẹ́ ìṣàkóso mi ni! Èmi ìbá bọ́ àjàgà rẹ̀ kúrò ní ọrùn yín. Èmi yóò wí fún Abimeleki pé, ‘Kó gbogbo àwọn ogun rẹ jáde láti jà.’ ”

30Nígbà tí Sebulu, alákòóso ìlú náà gbọ́ ohun tí Gaali ọmọ Ebedi sọ, inú bí i gidigidi. 31Ó ránṣẹ́ sí Abimeleki pé, “Gaali ọmọ Ebedi àti àwọn arákùnrin rẹ̀ wá láti máa gbé ní Ṣekemu ṣùgbọ́n, wọ́n ń rú àwọn ènìyàn sókè láti ṣọ̀tẹ̀ sí ọ. 32Wá ní òru kí ìwọ àti àwọn ogun rẹ sá pamọ́ dè wọ́n nínú igbó. 33Ní òwúrọ̀ kùtùkùtù bí oòrùn ti ń yọ ìwọ yóò wọ inú ìlú náà lọ láti bá a jà. Yóò sì ṣe nígbà tí Gaali àti àwọn ogun rẹ̀ tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ bá jáde sí ọ láti bá ọ jà, ìwọ yóò ṣe ohunkóhun tí o bá fẹ́ sí wọn.”

34Abimeleki àti gbogbo àwọn ogun rẹ̀ sì jáde ní òru, wọ́n sì sá pamọ́ sí ọ̀nà mẹ́rin yí Ṣekemu ká. 35Gaali ọmọ Ebedi jáde síta, ó sì dúró ní ẹnu-ọ̀nà ibodè ìlú náà ní àkókò tí Abimeleki àti àwọn ọmọ-ogun rẹ̀ jáde kúrò níbi tí wọn sá pamọ́ sí.

36Nígbà tí Gaali rí àwọn ènìyàn náà, ó sọ fún Sebulu pé, “Wò ó, àwọn ènìyàn ń ti orí òkè sọ̀kalẹ̀ wá!”

Sebulu sì wí fún un pé, “Òjìji òkè wọ̀n-ọn-nì ni ìwọ rí bi ẹni pé ènìyàn.”

37Gaali ké ó ní, “Wòkè, àwọn ènìyàn ń tọ̀ wá bọ̀ láti agbede-méjì ilẹ̀ wá àti ẹ̀gbẹ́ kan sì ń ti ọ̀nà igi óákù Meonenimu wá.”

38Nígbà náà ni Sebulu dá a lóhùn pé, “Níbo ni ẹnu tí ó ń ṣe ni wà báyìí. Ṣe bí o wí pé, ‘Ta ni Abimeleki tí àwa ó fi máa sìn ín?’ Àwọn ẹni tí ó gàn án kọ́ nìyí? Jáde lọ kí o sì bá wọn jà!”

39Gaali sì síwájú àwọn ogun ará Ṣekemu lọ kọjú Abimeleki láti bá wọn jagun. 40Abimeleki sì lé e, ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ọmọ-ogun ṣubú wọ́n sì gbọgbẹ́ bí wọ́n ṣe ń sálọ, títí dé ẹnu-ọ̀nà ibùdó ìlú náà. 41Abimeleki dúró sí Aruma, nígbà tí Sebulu lé Gaali àti àwọn arákùnrin rẹ̀ kúrò ni Ṣekemu, kò sì jẹ́ kí wọ́n gbé Ṣekemu mọ́.

42Ní ọjọ́ kejì àwọn ará Ṣekemu sì jà lọ́ sí oko, ẹnìkan ló ṣe òfófó rẹ̀ fún Abimeleki. 43Ó kó àwọn ènìyàn rẹ̀, ó pín wọn sí ẹgbẹ́ mẹ́ta ó sì sá pamọ́ sí inú oko. Nígbà tí ó sì rí tí àwọn ènìyàn náà ń jáde kúrò nínú ìlú, ó dìde ó gbóguntì wọ́n. 44Abimeleki àti àwọn ọmọ-ogun tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ sáré síwájú, wọ́n gba ẹnu ibodè ìlú náà, wọ́n sì dúró níbẹ̀. Àwọn ẹgbẹ́ méjì tókù sì sáré sí àwọn tó wà ní oko wọ́n sì gbóguntì wọ́n. 45Ní gbogbo ọjọ́ náà ni Abimeleki fi bá àwọn ará ìlú náà jà, ó sì ṣẹ́gun wọn, ó sì pa àwọn ènìyàn ìlú náà ó wó ìlú náà palẹ̀ pátápátá ó sì fọ́n iyọ̀ sí i.

46Àwọn ènìyàn ilé ìṣọ́ Ṣekemu gbọ́ ohun tí ó ṣẹlẹ̀, wọ́n sálọ fún ààbò sí inú ilé ìṣọ́ òrìṣà El-Beriti. 47Nígbà tí wọ́n sọ fún Abimeleki pé gbogbo àwọn ènìyàn ilé ìṣọ́ Ṣekemu kó ara wọn jọ pọ̀. 48Abimeleki àti gbogbo àwọn ọmọ-ogun rẹ̀ gun òkè Salmoni lọ. Ó gé àwọn ẹ̀ka díẹ̀ pẹ̀lú àáké, ó gbé àwọn ẹ̀ka wọ̀nyí sí èjìká rẹ̀. Ó sọ fún àwọn ọmọ-ogun rẹ̀ pé, “Ẹ ṣe ohun tí ẹ rí tí mo ń ṣe yìí ní kíákíá.” 49Báyìí gbogbo àwọn ọkùnrin tí ó wà lọ́dọ̀ rẹ̀ gé àwọn ẹ̀ka igi wọn tẹ̀lé Abimeleki. Wọ́n kó wọn ti ilé ìṣọ́ agbára níbi tí àwọn ènìyàn sá pamọ́ sí wọ́n sì fi iná sí i, tóbẹ́ẹ̀ tí gbogbo àwọn ọkùnrin ilé ìṣọ́ Ṣekemu fi kú pẹ̀lú. Gbogbo àwọn ènìyàn náà tí ó tó ẹgbẹ̀rún (1,000) ènìyàn lọ́kùnrin àti lóbìnrin sì kú.

50Abimeleki tún lọ sí Tebesi, ó yí ìlú náà ká pẹ̀lú àwọn ọmọ-ogun, ó sì ṣẹ́gun rẹ̀. 51Ilé ìṣọ́ kan tí ó ní agbára sì wà nínú ìlú náà. Gbogbo àwọn ènìyàn ìlú náà ọkùnrin àti obìnrin sá sínú ilé ìṣọ́ náà. Wọ́n ti ara wọn mọ́ ibẹ̀ wọ́n sì sálọ sí inú àjà ilé ìṣọ́ náà. 52Abimeleki lọ sí ìsàlẹ̀ ilé ìṣọ́ náà, ó sì ń bá a jà. Ṣùgbọ́n bí ó ti súnmọ́ ẹnu-ọ̀nà ilé ìṣọ́ náà láti dáná sun ún, 53obìnrin kan sọ ọmọ ọlọ lu Abimeleki lórí, ó sì fọ́ ọ ní agbárí.

54Ní ojú kan náà ni ó pe ẹni tí ó ru àpáta rẹ̀ pé, “Yára yọ idà rẹ kí o sì pa mí, kí wọn má ba à sọ pé, ‘Obìnrin ni ó pa á.’ ” Ọ̀dọ́mọkùnrin náà sì fi ọ̀kọ̀ gún un, ó sì kú. 55Nígbà tí àwọn ará Israẹli rí i pé Abimeleki kú, olúkúlùkù wọn padà sí ilé rẹ̀.

56Báyìí ni Ọlọ́run san ẹ̀san ìwà búburú ti Abimeleki hù sí baba rẹ̀ ní ti pípa tí ó pa, àwọn àádọ́rin arákùnrin rẹ̀. 57Ọlọ́run jẹ́ kí ìwà búburú àwọn ará Ṣekemu pẹ̀lú padà sí orí wọn. Ègún Jotamu ọmọ Jerubbaali pàápàá wá sí orí wọn.

Nouă Traducere Ǝn Limba RomĆ¢nă

Judecători 9:1-57

Abimelek

1Abimelek, fiul lui Ierub-Baal, s‑a dus la Șechem, la frații mamei lui, și le‑a vorbit atât lor, cât și întregului clan al familiei tatălui mamei lui, zicând: 2„Spuneți, vă rog, în auzul tuturor locuitorilor Șechemului: «Ce este mai bine pentru voi: să stăpânească peste voi șaptezeci de bărbați, toți fii ai lui Ierub-Baal, sau să stăpânească peste voi un singur bărbat? Aduceți‑vă aminte că sunt os din oasele voastre și carne din carnea voastră!»“

3Frații mamei lui au spus pentru el toate aceste cuvinte în auzul tuturor locuitorilor Șechemului, iar inima lor s‑a îndreptat spre Abimelek, căci își ziceau: „Este fratele nostru!“ 4I‑au dat lui Abimelek șaptezeci de șecheli4 Aproximativ 0,8 kg. de argint din templul lui Baal-Berit4 Vezi nota de la 8:33., iar acesta a plătit cu ei niște bărbați de nimic și fără căpătâi, care au mers după el. 5Apoi a venit la familia tatălui său, în Ofra, și i‑a ucis pe o singură piatră pe frații lui, fii ai lui Ierub-Baal, șaptezeci de bărbați. Însă Iotam, fiul cel mai tânăr al lui Ierub-Baal, a scăpat, căci se ascunsese. 6După aceea, toți locuitorii Șechemului și toți cei din Bet‑Milo s‑au strâns laolaltă și au venit să‑l facă pe Abimelek rege lângă stejarul monumentului6 Sensul termenului ebraic este nesigur. care este în Șechem.

Pilda lui Iotam

7Când l‑au înștiințat pe Iotam de lucrul acesta, Iotam s‑a dus și s‑a așezat pe vârful muntelui Garizim. Acolo el și‑a ridicat glasul și a strigat, zicând: „Ascultați‑mă, locuitori ai Șechemului, ca și Dumnezeu să vă asculte pe voi!

8Copacii au plecat să ungă un rege peste ei și i‑au zis măslinului: «Domnește peste noi!» 9Dar măslinul le‑a răspuns: «Să‑mi părăsesc eu uleiul meu, prin care sunt onorați Dumnezeu și oamenii, și să merg să mă legăn peste copaci?»

10Apoi copacii i‑au zis smochinului: «Vino tu și domnește peste noi!» 11Dar smochinul le‑a răspuns: «Să‑mi părăsesc eu dulceața mea și roadele mele cele bune și să merg să mă legăn peste copaci?»

12După aceea copacii i‑au zis viței: «Vino tu și domnește peste noi!» 13Dar vița le‑a răspuns: «Să‑mi părăsesc eu mustul, care aduce bucurie lui Dumnezeu și oamenilor, și să merg să mă legăn peste copaci?»

14Atunci toți copacii i‑au zis spinului: «Vino tu și domnește peste noi!» 15Spinul le‑a răspuns copacilor: «Dacă vreți cu adevărat să mă ungeți ca rege al vostru, veniți și adăpostiți‑vă la umbra mea, dar dacă nu vreți, atunci să iasă foc din spin și să mistuie cedrii Libanului!»

16Oare cu credincioșie și integritate ați lucrat voi când l‑ați făcut pe Abimelek rege? V‑ați purtat voi bine cu Ierub-Baal și familia lui? Și oare i‑ați făcut voi după cum merita? 17Căci tatăl meu s‑a luptat pentru voi, și‑a riscat viața și v‑a eliberat din mâna lui Midian. 18Dar voi v‑ați ridicat astăzi împotriva familiei tatălui meu și i‑ați ucis fiii, șaptezeci de bărbați, pe o singură piatră. Apoi l‑ați făcut rege peste locuitorii Șechemului pe Abimelek, fiul slujnicei lui, pentru că este fratele vostru. 19Dacă ați lucrat astăzi cu credincioșie și integritate față de Ierub-Baal și familia lui, atunci bucurați‑vă de Abimelek și el să se bucure de voi! 20Dar dacă nu, să iasă foc din Abimelek și să‑i mistuie pe locuitorii Șechemului și pe cei din Bet‑Milo! Și să iasă foc din locuitorii Șechemului și din Bet‑Milo ca să‑l mistuie pe Abimelek!“

21Apoi Iotam a fugit, a scăpat și s‑a dus la Beer. Și a locuit acolo, departe de fața lui Abimelek, fratele său.

Dumnezeu pune capăt răutății lui Abimelek

22Abimelek domnea peste Israel de trei ani. 23Dumnezeu a trimis un duh rău între Abimelek și locuitorii Șechemului și astfel locuitorii Șechemului l‑au trădat pe Abimelek, 24pentru ca violența săvârșită față de cei șaptezeci de fii ai lui Ierub-Baal să fie răzbunată, iar sângele lor să cadă astfel asupra fratelui lor Abimelek, care i‑a ucis, precum și asupra locuitorilor Șechemului, care l‑au ajutat pe acesta să‑și ucidă frații. 25Locuitorii Șechemului au pus la pândă pe vârfurile munților niște oameni care‑i jefuiau pe drumeții ce treceau pe lângă ei. Abimelek a fost înștiințat de lucrul acesta.

26Gaal, fiul lui Ebed, a venit împreună cu frații lui și a trecut în Șechem. Locuitorii Șechemului s‑au încrezut în el. 27El și oamenii lui au ieșit la câmp, le‑au cules viile, au pus strugurii în teasc, iar apoi au dat un ospăț. Ei au intrat în templul zeului lor, au mâncat, au băut și l‑au blestemat pe Abimelek. 28Gaal, fiul lui Ebed, zicea: „Cine este Abimelek și cine este Șechem ca să‑i slujim? Nu este el fiul lui Ierub-Baal și nu este Zebul reprezentantul lui? Este mai bine să slujiți oamenilor lui Hamor, tatăl lui Șechem. De ce să‑i slujim lui Abimelek? 29Ah, dacă ar pune cineva poporul acesta în mâna mea! L‑aș răsturna pe Abimelek!“ Iar despre Abimelek zicea: „Înmulțește‑ți oștirea și ieși!“

30Zebul, conducătorul cetății, a auzit cuvintele lui Gaal, fiul lui Ebed, și s‑a aprins de mânie. 31A trimis pe ascuns niște mesageri la Abimelek, zicând: „Iată că Gaal, fiul lui Ebed, împreună cu frații săi au venit la Șechem și răscoală cetatea împotriva ta. 32Ridică‑te noaptea împreună cu poporul care este cu tine și stai la pândă în câmp. 33Apoi să te scoli dis‑de‑dimineață, înainte de răsăritul soarelui, și să te năpustești asupra cetății. Iată că Gaal și poporul care este cu el vor ieși împotriva ta. Să le faci după cum vei putea.“

34Abimelek și tot poporul care era cu el s‑au ridicat noaptea și s‑au pus la pândă în patru cete lângă Șechem. 35Când Gaal, fiul lui Ebed, a ieșit și a stat la intrarea porții cetății, Abimelek și poporul care era cu el au ieșit din ascunzătoare.

36Când a zărit poporul, Gaal i‑a zis lui Zebul:

– Iată un popor care se coboară de pe vârfurile munților.

Zebul i‑a răspuns:

– Ceea ce vezi este umbra munților, nu oameni.

37Însă Gaal a zis din nou:

– Iată, chiar este un popor care se coboară dinspre centrul țării, iar o ceată vine pe drumul dinspre Stejarul prezicătorilor.37 Practicanți ai „artei prezicerii“ (vezi nota de la Lev. 19:26).

38Atunci Zebul i‑a zis:

– Unde îți este acum curajul cu care ziceai: „Cine este Abimelek ca să‑i slujim?“ Oare nu este acesta poporul pe care l‑ai disprețuit? Ieși acum și luptă‑te cu el!

39Gaal a ieșit în fruntea locuitorilor Șechemului și s‑a luptat cu Abimelek. 40Abimelek l‑a urmărit, dar acesta a reușit să fugă dinaintea lui. Mulți au căzut răpuși până spre intrarea porții. 41Apoi Abimelek a rămas în Aruma, iar Zebul i‑a alungat pe Gaal și pe frații lui, astfel că n‑au mai rămas în Șechem.

42A doua zi, când poporul a ieșit la câmp, Abimelek a fost înștiințat de lucrul acesta. 43Și‑a luat oamenii, i‑a împărțit în trei cete și au stat la pândă în câmp. După ce s‑a uitat și a văzut că poporul ieșise din cetate, s‑a ridicat împotriva lui și l‑a atacat. 44Abimelek și cetele care erau cu el, au înaintat până la intrarea porții cetății. Două din cete s‑au năpustit asupra tuturor celor ce erau în câmp și i‑au ucis. 45Abimelek s‑a luptat împotriva cetății toată ziua aceea. După ce a cucerit‑o, a ucis poporul care era în ea, a dărâmat cetatea și a împrăștiat sare peste ea.

46Când au auzit acest lucru, toți locuitorii turnului Șechemului au intrat într‑un refugiu din templul lui El‑Berit46 El‑Berit înseamnă El al legământului, El fiind o zeitate foarte importantă în panteonul canaanit.. 47Abimelek a fost înștiințat că toți locuitorii turnului Șechemului s‑au adăpostit acolo. 48Abimelek și tot poporul care era cu el s‑au urcat pe muntele Țalmon. A luat în mână un topor, a tăiat o creangă din copac și a pus‑o pe umăr. Apoi le‑a zis oamenilor care erau cu el: „Ați văzut ce am făcut eu; faceți și voi la fel!“ 49Fiecare bărbat din popor a tăiat câte o creangă și l‑a urmat pe Abimelek. Au aruncat crengile acelea peste refugiu și i‑au dat foc atât lui, cât și oamenilor dinăuntru. Așa au murit toți oamenii din turnul Șechemului, aproape o mie de bărbați și femei.

50După aceea Abimelek a înaintat împotriva Tebețului, l‑a împresurat și l‑a cucerit. 51În mijlocul cetății era un turn fortificat. Locuitorii cetății, bărbați și femei, fugiseră acolo, se încuiaseră înăuntru și se urcaseră pe acoperișul turnului. 52Abimelek a ajuns până la turn și l‑a asediat. Când s‑a apropiat de ușa turnului ca să‑i dea foc, 53o femeie a aruncat de pe zid piatra de sus a unei mori, care a căzut pe capul lui Abimelek și i‑a crăpat craniul. 54Atunci el l‑a chemat repede pe cel care‑i purta armele și i‑a zis: „Scoate‑ți sabia și omoară‑mă, ca nu cumva să se zică despre mine: «L‑a ucis o femeie.»“ Slujitorul său l‑a străpuns, și el a murit. 55Când oamenii lui Israel au văzut că Abimelek a murit, au plecat fiecare la casele lor.

56Astfel, Dumnezeu a întors asupra lui Abimelek răul pe care acesta îl făcuse tatălui său atunci când și‑a ucis cei șaptezeci de frați. 57Și tot răul făcut de oamenii Șechemului, Dumnezeu l‑a întors asupra capului lor. În acest fel a venit asupra lor blestemul lui Iotam, fiul lui Ierub-Baal.