Onidajọ 21 – YCB & PCB

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Onidajọ 21:1-25

Àwọn aya fún àwọn ẹ̀yà Benjamini

1Àwọn ọkùnrin Israẹli ti búra ní Mispa pé: “Kò sí ẹnìkan nínú wa tí yóò fi ọmọ obìnrin rẹ̀ fún ẹ̀yà Benjamini ní ìyàwó.”

2Àwọn ènìyàn náà lọ sí Beteli: ilé Ọlọ́run, níbi tí wọ́n jókòó níwájú Ọlọ́run títí di àṣálẹ́, wọ́n gbé ohùn wọn sókè, wọ́n sì sọkún kíkorò. 3Wọ́n sọkún wí pé, “Háà! Olúwa Ọlọ́run Israẹli, èéṣe tí nǹkan yìí fi ṣẹlẹ̀ sí Israẹli? Èéṣe tí ẹ̀yà kan yóò fi run nínú Israẹli lónìí?”

4Ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì àwọn ènìyàn náà mọ pẹpẹ kan wọ́n sì rú ẹbọ sísun àti ọrẹ àlàáfíà.

5Àwọn ọmọ Israẹli sì béèrè wí pé, “Èwo nínú ẹ̀yà Israẹli ni ó kọ̀ láti péjọ síwájú Olúwa?” Torí pé wọ́n ti fi ìbúra ńlá búra pé, ẹnikẹ́ni tí ó bá kọ̀ láti péjọ níwájú Olúwa ní Mispa pípa ni àwọn yóò pa á.

6Àwọn ọmọ Israẹli sì banújẹ́ fún àwọn arákùnrin wọn, àwọn ẹ̀yà Benjamini. Wọ́n wí pé, “A ti ké ẹ̀yà kan kúrò lára Israẹli lónìí.” 7Báwo ni a yóò ṣe rí aya fún àwọn tí ó ṣẹ́kù, nítorí àwa ti fi Olúwa búra láti má fi ọ̀kankan nínú àwọn ọmọbìnrin wa fún wọn ní aya. 8Wọ́n sì béèrè wí pé, “Èwo ni nínú ẹ̀yà Israẹli ni ó kọ̀ láti bá àwọn ènìyàn péjọ níwájú Olúwa ní Mispa?” Wọ́n rí i pé kò sí ẹnikẹ́ni tí ó wa láti Jabesi Gileadi tí ó wá sí ibùdó fún àjọ náà. 9Nítorí pé nígbà tí wọ́n ka àwọn ènìyàn, wọ́n rí i pé kò sí ẹnìkankan láti inú àwọn ará Jabesi Gileadi tí ó wà níbẹ̀.

10Àwọn ìjọ ènìyàn náà sì rán ẹgbàá-mẹ́fà àwọn jagunjagun ọkùnrin, lọ sí Jabesi Gileadi wọ́n fún wọn ní àṣẹ pé, ẹ lọ fi idà kọlu gbogbo àwọn tí ó wà níbẹ̀, pẹ̀lú àwọn obìnrin àti àwọn ọmọ wẹ́wẹ́. 11Wọ́n ní, “Èyí ni ẹ̀yin yóò ṣe, ẹ pa gbogbo ọkùnrin àti gbogbo obìnrin tí kì í ṣe wúńdíá.” 12Wọ́n rí àwọn irínwó (400) ọ̀dọ́bìnrin tí kò mọ ọkùnrin rí nínú àwọn olùgbé Jabesi Gileadi, wọ́n sì mú wọn lọ sí ibùdó ní Ṣilo àwọn ará Kenaani.

13Gbogbo ìjọ àwọn ènìyàn sì ránṣẹ́ àlàáfíà sí àwọn Benjamini ní ihò àpáta Rimoni. 14Àwọn ẹ̀yà Benjamini náà sì padà ní àkókò náà, wọ́n sì fún wọn ní àwọn obìnrin Jabesi Gileadi. Ṣùgbọ́n wọn kò kárí gbogbo wọn.

15Àwọn ènìyàn náà sì káàánú nítorí ẹ̀yà Benjamini, nítorí Olúwa fi àlàfo kan sílẹ̀ nínú àwọn ẹ̀yà Israẹli. 16Àwọn olórí ìjọ àwọn ènìyàn náà wí pé, “Kí ni àwa yóò ṣe láti rí aya fún àwọn ọkùnrin tí ó kù nígbà tí a ti pa gbogbo àwọn obìnrin Benjamini run?” 17Wọ́n sì wí pé, “Àwọn tí ó ṣẹ́kù tí wọ́n là nínú àwọn ẹ̀yà Benjamini ní láti ní ogún àti àrólé, kí ẹ̀yà kan nínú Israẹli má ṣe di píparun kúrò ní orí ilẹ̀. 18Àwa kò le fi àwọn ọmọbìnrin wa fún wọn ní aya, nítorí tí àwa ọmọ Israẹli ti ṣe ìbúra yìí pé: ‘Ègún ni fún ẹnikẹ́ni tí ó fi aya fún ẹnikẹ́ni nínú ẹ̀yà Benjamini.’ ” 19Wọ́n sì wí pé, “Kíyèsi i ayẹyẹ ọlọ́dọọdún fún Olúwa wà ní Ṣilo ní ìhà àríwá Beteli àti ìhà ìlà-oòrùn òpópó náà tí ó gba Beteli kọjá sí Ṣekemu, àti sí ìhà gúúsù Lébónà.”

20Wọ́n sì fi àṣẹ fún àwọn ará Benjamini pé, “Ẹ lọ kí ẹ sì fi ara pamọ́ nínú àwọn ọgbà àjàrà 21kí ẹ sì wà ní ìmúrasílẹ̀. Nígbà tí àwọn ọmọbìnrin Ṣilo bá jáde láti lọ darapọ̀ fún ijó, kí ẹ yára jáde láti inú àwọn ọgbà àjàrà wọ̀n-ọn-nì kí ẹnìkọ̀ọ̀kan yín gbé aya kan nínú àwọn ọmọbìnrin Ṣilo kí ẹ padà sí ilẹ̀ Benjamini. 22Nígbà tí àwọn baba wọn tàbí àwọn arákùnrin wọn bá fi ẹjọ́ sùn wá, àwa yóò wí fún wọn pé, ‘Ẹ ṣe wá ní oore nípa ríràn wọ́n lọ́wọ́, nítorí àwa kò rí aya fún wọn ní àkókò ogun, ẹ̀yin kò sì ní jẹ̀bi, nítorí pé ẹ̀yin kọ́ ni ó fi àwọn ọmọbìnrin yín fún wọn bí aya.’ ”

23Èyí sì ni ohun tí àwọn ẹ̀yà Benjamini ṣe. Nígbà tí àwọn ọmọbìnrin náà ń jó lọ́wọ́, ọkùnrin kọ̀ọ̀kan mú ọmọbìnrin kọ̀ọ̀kan, wọ́n sì gbé e lọ láti di aya rẹ̀. Wọ́n sì padà sí ilẹ̀ ìní wọn, wọ́n sì tún àwọn ìlú náà kọ́, wọ́n sì tẹ̀dó sínú wọn.

24Ní àkókò náà, àwọn ọmọ Israẹli kúrò ní ibẹ̀, wọ́n lọ sí ilé àti ẹ̀yà rẹ̀ olúkúlùkù sí ilẹ̀ ìní rẹ̀.

25Ní àwọn ọjọ́ wọ̀nyí, kò sí ọba ní ilẹ̀ Israẹli; olúkúlùkù sì ń ṣe bí ó ti tọ́ ní ojú ara rẹ̀.

Persian Contemporary Bible

داوران 21:1-25

زنانی برای قبیلهٔ بنيامين

1رهبران اسرائيل وقتی در مصفه جمع شده بودند، قسم خوردند كه هرگز اجازه ندهند دختران آنها با مردان قبيلهٔ بنيامين ازدواج كنند. 2سپس به بيت‌ئيل آمده تا غروب آفتاب در حضور خدا نشستند. آنها به شدت می‌گريستند و می‌گفتند: 3«ای خداوند، خدای اسرائيل، چرا اين حادثه رخ داد و ما يكی از قبايل خود را از دست داديم؟»

4روز بعد، صبح زود برخاسته، قربانگاهی ساختند و بر روی آن قربانیهای سلامتی و سوختنی تقديم كردند. 5آنها می‌گفتند: «وقتی كه برای مشورت در حضور خداوند در مصفه جمع شديم آيا قبيله‌ای از اسرائيل بود كه به آنجا نيامده باشد؟» (در آن موقع همه با هم قسم خورده بودند كه اگر يكی از قبايل، از آمدن به حضور خداوند خودداری نمايد، حتماً بايد نابود گردد.) 6قوم اسرائيل به سبب نابود شدن قبيلهٔ بنيامين، سوگوار و غمگين بودند و پيوسته با خود می‌گفتند: «از قبايل اسرائيل يک قبيله نابود شد. 7اكنون برای آن عده‌ای كه باقيمانده‌اند از كجا زن بگيريم؟ زيرا ما به خداوند قسم خورده‌ايم كه دختران خود را به آنها ندهيم؟»

8‏-9برای اينكه معلوم شود كدام قبيله از قبايل اسرائيل از آمدن به مصفه خودداری كرده بود، آنها به شمارش قوم پرداختند. سرانجام معلوم شد كه از يابيش جلعاد هيچكس نيامده بود. 10‏-12پس اسرائيلی‌ها دوازده هزار نفر از بهترين جنگاوران خود را فرستادند تا مردم يابيش جلعاد را نابود كنند. آنها رفته، تمام مردان و زنان و بچه‌ها را كشتند و فقط دختران باكره را كه به سن ازدواج رسيده بودند باقی گذاردند. تعداد اين دختران چهارصد نفر بود كه آنها را به اردوگاه اسرائيل در شيلوه آوردند.

13آنگاه اسرائیلی‌ها نمايندگانی جهت صلح نزد بازماندگان قبيلهٔ بنيامين كه به صخرهٔ رمون گريخته بودند، فرستادند. 14مردان قبيلهٔ بنيامين به شهر خود بازگشتند و اسرائیلی‌ها آن چهارصد دختر را به ايشان دادند. ولی تعداد اين دختران برای آنها كافی نبود.

15قوم اسرائيل برای قبيلهٔ بنيامين غمگين بود، زيرا خداوند در ميان قبايل اسرائيل جدايی بوجود آورده بود. 16‏-17رهبران اسرائيل می‌گفتند: «برای بقيهٔ آنها از كجا زن بگيريم، چون همهٔ زنان قبيلهٔ بنيامين مرده‌اند؟ بايد در اين باره چاره‌ای بينديشيم تا نسل اين قبيله از بين نرود و قبيله‌ای از اسرائيل كم نشود. 18ولی ما نمی‌توانيم دختران خود را به آنها بدهيم، چون كسی را كه دختر خود را به قبيلهٔ بنيامين بدهد لعنت كرده‌ايم.» 19ولی بعد به ياد آوردند كه هر سال در شيلوه عيدی برای خداوند برگزار می‌شود. (شيلوه در سمت شرقی راهی كه از بيت‌ئيل به شكيم می‌رود در ميان لبونه و بيت‌ئيل واقع شده بود.) 20پس به مردان بنيامينی گفتند: «برويد و خود را در تاكستانها پنهان كنيد. 21وقتی دختران شيلوه برای رقصيدن بيرون آيند، شما از تاكستانها بيرون بياييد و آنها را برباييد و به خانه‌های خود ببريد تا همسران شما گردند. 22اگر پدران و برادران آنها برای شكايت نزد ما بيايند به ايشان خواهيم گفت: آنها را ببخشيد و بگذاريد دختران شما را پيش خود نگه دارند؛ زيرا در اين جنگ آنها بدون زن مانده بودند و شما نيز نمی‌توانستيد برخلاف عهد خود رفتار كرده، به آنها زن بدهيد.»

23پس مردان بنيامينی چنين كردند و از ميان دخترانی كه در شيلوه می‌رقصيدند، هر يک برای خود زنی گرفته، به سرزمين خود برد. سپس ايشان شهرهای خود را از نو بنا كرده، در آنها ساكن شدند.

24بنی‌اسرائيل پس از اين واقعه، آن مكان را ترک گفته، هر يک به قبيله و خاندان و ملک خود بازگشتند.

25در آن زمان بنی‌اسرائيل پادشاهی نداشت و هر کس هر چه دلش می‌خواست می‌كرد.