Numeri 30 – YCB & CARST

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Numeri 30:1-16

Ẹ̀jẹ́

1Mose sì sọ fún olórí àwọn ẹ̀yà ọmọ Israẹli pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa pàṣẹ, 230.2-16: De 23.21-23.30.2: Mt 5.33.nígbà tí ọkùnrin kan bá jẹ́ ẹ̀jẹ́ sí Olúwa tàbí búra láti fi de ara rẹ̀ ní ìdè kí òun má bà ba ọ̀rọ̀ rẹ̀ jẹ́ kí ó ṣe gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe sọ.

3“Nígbà tí ọmọbìnrin kan bá sì wà ní ilé baba rẹ̀ tó bá jẹ́ ẹ̀jẹ́ fún Olúwa tàbí búra láti fi de ara rẹ̀ 4tí baba rẹ̀ bá sì gbọ́ ẹ̀jẹ́ rẹ̀ tàbí ìdè rẹ̀ tí kò sì sọ nǹkan kan sí i, kí gbogbo ẹ̀jẹ́ rẹ̀ kí ó dúró àti gbogbo ìdè tí ó fi de ara rẹ̀ yóò sì dúró. 5Ṣùgbọ́n tí baba rẹ̀ bá kọ̀ fun un ní ọjọ́ tí ó gbọ́, kò sí ọ̀kan nínú ẹ̀jẹ́ rẹ̀ tàbí nínú ìdè tí ó fi de ara rẹ̀ tí yóò dúró; Olúwa yóò sì tú u sílẹ̀ nítorí baba rẹ̀ kọ̀ fún un.

6“Tí ó bá sì ní ọkọ lẹ́yìn ìgbà tí ó jẹ́ ẹ̀jẹ́ tàbí lẹ́yìn ìgbà tí ó sọ ọ̀rọ̀ kan láti ẹnu rẹ̀ jáde nínú èyí tí ó fi de ara rẹ̀ ní ìdè, 7tí ọkọ rẹ̀ sì gbọ́ nípa èyí ṣùgbọ́n tí kò sọ nǹkan kan, nígbà náà ni ẹ̀jẹ́ tàbí ìdè tí ó fi de ara rẹ̀ tó dúró. 8Ṣùgbọ́n tí ọkọ rẹ̀ bá kọ̀ nígbà tí ó gbọ́, ǹjẹ́ òun yóò mú ẹ̀jẹ́ rẹ̀ tí ó jẹ́ àti ohun tí ó ti ti ẹnu rẹ̀ jáde, èyí tí ó fi de ara rẹ̀ dasán, Olúwa yóò sì dáríjì í.

9“Ṣùgbọ́n ẹ̀jẹ́ kí ẹ̀jẹ́ tàbí ìdè kí ìdè tí opó tàbí obìnrin tí a kọ̀sílẹ̀ bá ṣe yóò wà lórí rẹ̀.

10“Bí obìnrin tí ó ń gbé pẹ̀lú ọkọ rẹ̀ bá jẹ́ ẹ̀jẹ́ tàbí de ara rẹ̀ ní ìdè lábẹ́ ìbúra, 11tí ọkọ rẹ̀ bá sì gbọ́, ṣùgbọ́n tí kò sọ̀rọ̀, tí kò sì kọ̀, nígbà náà ni ẹ̀jẹ́ rẹ̀ yóò dúró. 12Ṣùgbọ́n tí ọkọ rẹ̀ bá sọ wọ́n dasán, nígbà tí ó gbọ́, nígbà náà kò sí ẹ̀jẹ́ tàbí ìdè tí ó ti ẹnu rẹ̀ jáde tí yóò dúró, ọkọ rẹ̀ ti sọ wọ́n dasán, Olúwa yóò tú u sílẹ̀. 13Ọkọ rẹ̀ lè ṣe ìwádìí tàbí sọ ọ́ dasán ẹ̀jẹ́ tàbí ìbúra ìdè tí ó ti ṣe láti fi de ara rẹ̀. 14Ṣùgbọ́n tí ọkọ rẹ̀ kò bá sọ nǹkan kan sí í nípa rẹ̀ ní ọjọ́ dé ọjọ́, nígbà náà ni ó ṣe ìwádìí nípa ẹ̀jẹ́ àti ìbúra ìdè tí ó dè é. Kí ọkùnrin náà ṣe ìwádìí lórí rẹ̀ láìsọ nípa rẹ̀ si nígbà tí ó gbọ́ nípa rẹ̀. 15Bí ó ti wù kí ó rí, bí ọkùnrin náà bá sọ ọ́ dasán, ní àkókò kan lẹ́yìn tí ó ti gbọ́ wọn, nígbà náà ó jẹ̀bi ọ̀rọ̀ náà.”

16Èyí ni ìlànà tí Olúwa fún Mose nípa ìbátan láàrín ọkùnrin àti obìnrin àti láàrín baba àti ọ̀dọ́mọbìnrin rẹ̀ tí ó sì ń gbé ní ilé rẹ̀.

Священное Писание (Восточный перевод), версия для Таджикистана

Числа 30:1-17

Правила об обетах

1Мусо сказал исроильтянам всё, что повелел ему Вечный.

2Мусо сказал главам родов Исроила:

– Так повелел Вечный:

3Если человек даст обет Вечному или свяжет себя зароком, то пусть не нарушает своего слова, но выполняет всё, что сказал.

4Если молодая девушка, которая ещё живёт в доме отца, даст обет Вечному или свяжет себя зароком, 5а её отец услышит про этот обет или зарок, но ничего ей не скажет, то все её обеты и всякий зарок, которым она связала себя, останутся в силе. 6Но если, услышав об этом, отец запретит ей, то ни один из её обетов или зароков, которыми она связала себя, не останется в силе; Вечный простит ей, потому что ей запретил отец.

7Если она выйдет замуж, будучи связана обетом или опрометчивым словом своих уст, 8а её муж услышит об этом, но, услышав, ничего ей не скажет, то её обеты и зароки, которыми она связала себя, останутся в силе. 9Но если, услышав об этом, муж запретит ей, то он отменит обет или опрометчивое слово её уст, которыми она связала себя, и Вечный простит ей.

10Но всякий обет, которым свяжет себя вдова или разведённая женщина, остаётся в силе.

11Если женщина, живущая с мужем, даст обет или, поклявшись, свяжет себя зароком, 12а муж услышит об этом, но, услышав, ничего ей не скажет и не запретит, то все её обеты и зароки, которыми она связала себя, останутся в силе. 13Но если, услышав о них, муж отменит их, то ни один из обетов или зароков, которые сошли с её уст, не останется в силе: муж отменил их, и Вечный простит ей. 14Муж может подтвердить или отменить любой её обет или зарок смирять себя30:14 Или: «поститься».. 15Но если муж день за днём не будет ей ничего говорить, то он этим подтвердит все обеты и зароки, которыми она себя связала. Он подтверждает их, когда ничего не говорит ей, слыша о них. 16Если он отменит их через некоторое время после того, как услышит о них, то он будет в ответе за её вину.

17Таковы установления, которые Вечный дал Мусо об отношениях между мужем и женой, между отцом и молодой дочерью, которая ещё живёт в его доме.