Nahumu 1 – YCB & NRT

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Nahumu 1:1-15

1Ọ̀rọ̀-ìmọ̀ nípa Ninefe. Ìwé ìran Nahumu ará Elkoṣi.

Ìbínú Olúwa sí Ninefe

2Ọlọ́run ń jẹ owú, ó sì ń gbẹ̀san,

Olúwa ń gbẹ̀san, ó sì kún fún ìbínú.

Olúwa ń gbẹ̀san lára àwọn ọ̀tá rẹ̀.

Ìbínú rẹ̀ kò sì yí padà lórí àwọn ọ̀tá rẹ̀.

31.3: Isa 10.5-34; Sf 2.12-15.Olúwa lọ́ra láti bínú, ó sì tóbi ní agbára;

Olúwa kì yóò fi àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ sílẹ̀ láìjìyà.

Ọ̀nà rẹ̀ wà nínú afẹ́fẹ́ àti nínú ìjì,

ìkùùkuu sánmọ̀ sì ni eruku ẹsẹ̀ rẹ̀.

4Ó bá òkun wí, ó sì mú kí ó gbẹ;

Ó sìsọ gbogbo odò di gbígbẹ.

Baṣani àti Karmeli sì rọ.

Ìtànná Lebanoni sì rẹ̀ sílẹ̀.

5Àwọn òkè ńlá wárìrì níwájú rẹ̀,

àwọn òkè kéékèèké sì di yíyọ́,

ilẹ̀ ayé sì jóná níwájú rẹ̀,

àní ayé àti gbogbo àwọn tí ń gbé inú rẹ̀.

6Ta ni ó lé dúró níwájú ìbínú rẹ̀?

Ta ni ó lé faradà gbígbóná ìbínú rẹ̀?

Ìbínú rẹ̀ tú jáde bí iná;

àwọn àpáta sì fọ́ túútúú níwájú rẹ̀.

7Rere ni Olúwa,

òun ni ààbò ní ọjọ́ ìpọ́njú.

Òun sì tọ́jú àwọn tí ó gbẹ́kẹ̀lé e,

8ṣùgbọ́n pẹ̀lú ìkún omi ńlá

ní òun yóò fi ṣe ìparun láti ibẹ̀ dé òpin;

òkùnkùn yóò sì máa lépa àwọn ọ̀tá rẹ̀.

9Kí ni ẹ̀yìn ń gbìmọ̀ lòdì sí Olúwa?

Òun yóò fi òpin sí i,

ìpọ́njú kì yóò wáyé ní ìgbà kejì.

10Wọn yóò sì lọ́lù papọ̀ bí ẹ̀gún òṣùṣú

wọn yóò sì mu àmupara nínú ọtí wáìnì wọn

a ó sì run wọn gẹ́gẹ́ bi àgékù koríko gbígbẹ.

11Láti ọ̀dọ̀ rẹ, ìwọ Ninefe, ni ẹnìkan ti jáde wá

tí ó ń gbèrò ibi sí Olúwa

ti ó sì ń gbìmọ̀ búburú.

12Báyìí ni Olúwa wí:

“Bí wọ́n tilẹ̀ ni ìfọwọ́sowọ́pọ̀, tí wọ́n sì pọ̀ níye,

ṣùgbọ́n, báyìí ní a ó ké wọn lulẹ̀,

nígbà tí òun ó bá kọjá.

Bí mo tilẹ̀ ti pọ́n ọ lójú ìwọ Juda, èmi kì yóò pọ́n ọ lójúmọ́.

13Nísinsin yìí ni èmi yóò já àjàgà wọn kúrò ní ọrùn rẹ

èmi yóò já ṣẹ́kẹ́ṣẹkẹ̀ rẹ dànù.”

14Olúwa ti fi àṣẹ kan lélẹ̀ nítorí tìrẹ Ninefe:

“Ìwọ kì yóò ni irú-ọmọ láti máa jẹ́ orúkọ rẹ mọ́,

Èmi yóò pa ère fínfín àti ère dídà run

tí ó wà nínú tẹmpili àwọn ọlọ́run rẹ.

Èmi yóò wa ibojì rẹ,

nítorí ẹ̀gbin ni ìwọ.”

151.15: Isa 40.9; 52.7; Ap 10.36; Ro 10.15.Wò ó, lórí àwọn òkè,

àwọn ẹsẹ̀ ẹni tí ó mú ìròyìn ayọ̀ wá,

ẹni tí ó ń kéde àlàáfíà.

Ìwọ Juda, pa àṣẹ rẹ tí ó ní ìrònú mọ́,

kí ó sì san àwọn ẹ̀jẹ́ rẹ.

Àwọn ènìyàn búburú kì yóò sì gbóguntì ọ́ mọ́;

wọn yóò sì parun pátápátá.

New Russian Translation

Наум 1:1-15

1Пророчество о Ниневии. Книга видений Наума из Элкоша.

Гнев Господень против Ниневии

2Господь – ревнивый и мстительный Бог;

Господь мстительный и гневливый.

Господь мстит Своим врагам

и хранит гнев против Своих врагов.

3Господь долготерпелив и велик в Своем могуществе;

Господь не оставит виновных без наказания.

Его шествие – в буре и вихре,

облака – пыль от Его ног.

4Он приказывает морю, и оно высыхает,

рекам – и они иссякают.

Башан и Кармил увядают,

и блекнут цветы на Ливане.

5Сотрясаются перед Ним горы и тают холмы.

Земля трепещет перед Его лицом,

трепещет мир и все живущее в нем.

6Кто устоит перед Его негодованием?

Кто сможет выдержать Его пылающий гнев?

Подобно огню разливается Его гнев,

скалы рассыпаются перед Ним.

7Господь благ, Он – убежище в дни бедствий.

Он заботится о тех, кто в Нем ищет прибежища,

8но всепотопляющим наводнением

Он разрушит Ниневию до основания;

мрак настигнет Его врагов.

9Что бы вы ни замышляли против Господа,

Он истребит вас до конца,

и бедствие уже не повторится.

10Они запутаются в терновнике

и будут пьяны от вина,

они будут уничтожены, как сухое жнивье.

11Из тебя, Ниневия, вышел тот,

кто замышляет злое против Господа,

кто советует беззаконное.

12Так говорит Господь:

– Хотя у них есть союзники и их великое множество,

они будут уничтожены и исчезнут,

а тебя, Иудея, раньше Я отягощал,

но впредь уже не стану.

13И теперь Я сокрушу их ярмо, что на твоей шее,

и разорву твои оковы.

14Господь дал следующее повеление о тебе, Ниневия:

– Не станет у тебя потомков,

носящих твое имя.

Я разрушу твоих идолов и уничтожу истуканы,

что находятся в храмах твоих богов.

Я приготовлю тебе могилу,

потому что ты презираема.

15Смотри, идет по горам гонец,

несущий радостную весть,

провозглашающий мир!

Отмечай свои праздники, Иудея,

исполняй свои обещания.

Не вторгнется больше беззаконный в твои владения,

потому что будет полностью уничтожен.