Nahumu 1 – YCB & NIRV

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Nahumu 1:1-15

1Ọ̀rọ̀-ìmọ̀ nípa Ninefe. Ìwé ìran Nahumu ará Elkoṣi.

Ìbínú Olúwa sí Ninefe

2Ọlọ́run ń jẹ owú, ó sì ń gbẹ̀san,

Olúwa ń gbẹ̀san, ó sì kún fún ìbínú.

Olúwa ń gbẹ̀san lára àwọn ọ̀tá rẹ̀.

Ìbínú rẹ̀ kò sì yí padà lórí àwọn ọ̀tá rẹ̀.

31.3: Isa 10.5-34; Sf 2.12-15.Olúwa lọ́ra láti bínú, ó sì tóbi ní agbára;

Olúwa kì yóò fi àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ sílẹ̀ láìjìyà.

Ọ̀nà rẹ̀ wà nínú afẹ́fẹ́ àti nínú ìjì,

ìkùùkuu sánmọ̀ sì ni eruku ẹsẹ̀ rẹ̀.

4Ó bá òkun wí, ó sì mú kí ó gbẹ;

Ó sìsọ gbogbo odò di gbígbẹ.

Baṣani àti Karmeli sì rọ.

Ìtànná Lebanoni sì rẹ̀ sílẹ̀.

5Àwọn òkè ńlá wárìrì níwájú rẹ̀,

àwọn òkè kéékèèké sì di yíyọ́,

ilẹ̀ ayé sì jóná níwájú rẹ̀,

àní ayé àti gbogbo àwọn tí ń gbé inú rẹ̀.

6Ta ni ó lé dúró níwájú ìbínú rẹ̀?

Ta ni ó lé faradà gbígbóná ìbínú rẹ̀?

Ìbínú rẹ̀ tú jáde bí iná;

àwọn àpáta sì fọ́ túútúú níwájú rẹ̀.

7Rere ni Olúwa,

òun ni ààbò ní ọjọ́ ìpọ́njú.

Òun sì tọ́jú àwọn tí ó gbẹ́kẹ̀lé e,

8ṣùgbọ́n pẹ̀lú ìkún omi ńlá

ní òun yóò fi ṣe ìparun láti ibẹ̀ dé òpin;

òkùnkùn yóò sì máa lépa àwọn ọ̀tá rẹ̀.

9Kí ni ẹ̀yìn ń gbìmọ̀ lòdì sí Olúwa?

Òun yóò fi òpin sí i,

ìpọ́njú kì yóò wáyé ní ìgbà kejì.

10Wọn yóò sì lọ́lù papọ̀ bí ẹ̀gún òṣùṣú

wọn yóò sì mu àmupara nínú ọtí wáìnì wọn

a ó sì run wọn gẹ́gẹ́ bi àgékù koríko gbígbẹ.

11Láti ọ̀dọ̀ rẹ, ìwọ Ninefe, ni ẹnìkan ti jáde wá

tí ó ń gbèrò ibi sí Olúwa

ti ó sì ń gbìmọ̀ búburú.

12Báyìí ni Olúwa wí:

“Bí wọ́n tilẹ̀ ni ìfọwọ́sowọ́pọ̀, tí wọ́n sì pọ̀ níye,

ṣùgbọ́n, báyìí ní a ó ké wọn lulẹ̀,

nígbà tí òun ó bá kọjá.

Bí mo tilẹ̀ ti pọ́n ọ lójú ìwọ Juda, èmi kì yóò pọ́n ọ lójúmọ́.

13Nísinsin yìí ni èmi yóò já àjàgà wọn kúrò ní ọrùn rẹ

èmi yóò já ṣẹ́kẹ́ṣẹkẹ̀ rẹ dànù.”

14Olúwa ti fi àṣẹ kan lélẹ̀ nítorí tìrẹ Ninefe:

“Ìwọ kì yóò ni irú-ọmọ láti máa jẹ́ orúkọ rẹ mọ́,

Èmi yóò pa ère fínfín àti ère dídà run

tí ó wà nínú tẹmpili àwọn ọlọ́run rẹ.

Èmi yóò wa ibojì rẹ,

nítorí ẹ̀gbin ni ìwọ.”

151.15: Isa 40.9; 52.7; Ap 10.36; Ro 10.15.Wò ó, lórí àwọn òkè,

àwọn ẹsẹ̀ ẹni tí ó mú ìròyìn ayọ̀ wá,

ẹni tí ó ń kéde àlàáfíà.

Ìwọ Juda, pa àṣẹ rẹ tí ó ní ìrònú mọ́,

kí ó sì san àwọn ẹ̀jẹ́ rẹ.

Àwọn ènìyàn búburú kì yóò sì gbóguntì ọ́ mọ́;

wọn yóò sì parun pátápátá.

New International Reader’s Version

Nahum 1:1-15

1Here is a prophecy the Lord gave Nahum, who was from the town of Elkosh. The prophecy came in a vision and is written in a book. The prophecy is about Nineveh.

The Lord Is Angry With Nineveh

2The Lord is a jealous God who punishes people.

He pays them back for the evil things they do.

He directs his anger against them.

The Lord punishes his enemies.

He holds his anger back

until the right time to use it.

3The Lord is slow to get angry.

But he is very powerful.

The Lord will not let guilty people go

without punishing them.

When he marches out, he stirs up winds and storms.

Clouds are the dust kicked up by his feet.

4He controls the seas. He dries them up.

He makes all the rivers run dry.

Bashan and Mount Carmel dry up.

The flowers in Lebanon fade.

5He causes the mountains to shake.

The hills melt away.

The earth trembles because he is there.

The world and all those who live in it also tremble.

6Who can stand firm when his anger burns?

Who can live when he is angry?

His anger blazes out like fire.

He smashes the rocks to pieces.

7The Lord is good.

When people are in trouble,

they can go to him for safety.

He takes good care of those

who trust in him.

8But he will destroy Nineveh

with a powerful flood.

He will chase his enemies

into the place of darkness.

9The Lord will put an end

to anything they plan against him.

He won’t allow Assyria to win the battle

over his people a second time.

10His enemies will be tangled up among thorns.

Their wine will make them drunk.

They’ll be burned up like dry straw.

11Nineveh, a king has marched out from you.

He makes evil plans against the Lord.

He thinks about how he can do what is wrong.

12The Lord says,

“His army has many soldiers.

Other nations are helping them.

But they will be destroyed and pass away.

Judah, I punished you.

But I will not do it anymore.

13Now I will break Assyria’s yoke off your neck.

I will tear off the ropes that hold you.”

14Nineveh, the Lord has given an order concerning you.

He has said, “You will not have any children

to carry on your name.

I will destroy the wooden and metal statues

that are in the temple of your gods.

I will get your grave ready for you.

You are worthless.”

15Look at the mountains of Judah!

I see a messenger running to bring good news!

He’s telling us that peace has come!

People of Judah, celebrate your feasts.

Carry out your promises.

The evil Assyrians won’t attack you again.

They’ll be completely destroyed.