Mika 2 – YCB & NTLR

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Mika 2:1-13

Èrò ènìyàn àti ti Ọlọ́run

1Ègbé ni fún àwọn tí ń gbèrò àìṣedéédéé

tí wọ́n sì ń ṣiṣẹ́ ibi lórí ibùsùn wọn!

Nígbà tí ojúmọ́ bá mọ́, wọn yóò gbé e jáde

nítorí ó wà ní agbára wọn láti ṣe é.

2Wọ́n sì ń ṣe ojúkòkòrò oko, wọ́n sì fi agbára wọn gbà wọ́n,

àti àwọn ilé, wọ́n sì gbà wọ́n.

Wọ́n sì ni ènìyàn àti ilẹ̀ rẹ̀ lára

àní ènìyàn àti ohun ìní rẹ̀.

3Nítorí náà, Olúwa wí pé:

“Èmi ń gbèrò ibi sí àwọn ìdílé wọ̀nyí,

nínú èyí tí wọn kì yóò le è gba ara wọn là.

Ìwọ kì yóò sì lè máa rìn ní ìgbéraga mọ́,

nítorí yóò jẹ́ àkókò ibi.

4Ní ọjọ́ náà ni ẹnìkan yóò pa òwe kan sí yín;

wọn yóò sì pohùnréré ẹkún kíkorò pé:

‘Ní kíkó a ti kó wọn tán;

Olúwa ti pín ohun ìní àwọn ènìyàn mi;

Ó ti mú un kúrò lọ́dọ̀ mi!

Ó fi oko wa lé àwọn ọlọ̀tẹ̀ lọ́wọ́.’ ”

5Nítorí náà, ìwọ kò ní ní ẹnìkankan tí yóò ta okùn nínú ìjọ Olúwa,

tí yóò pín ilẹ̀ nípa ìbò.

Àwọn wòlíì èké

6“Ẹ má ṣe sọtẹ́lẹ̀,” ni àwọn wòlíì wọn wí.

“Ẹ má ṣe sọtẹ́lẹ̀ nípa nǹkan wọ̀nyí;

kí ìtìjú má ṣe le bá wa.”

7Ṣé kí á sọ ọ́, ìwọ ilé Jakọbu:

“Ǹjẹ́ ẹ̀mí Olúwa ha ń bínú bí?

Ǹjẹ́ iṣẹ́ rẹ ha nìwọ̀nyí?”

“Ǹjẹ́ ọ̀rọ̀ mi kò ha ń ṣe rere

fún ẹni tí ń rìn déédé bí?

8Láìpẹ́ àwọn ènìyàn mi dìde

bí ọ̀tá sí mi.

Ìwọ bọ́ aṣọ ọlọ́rọ̀

kúrò lára àwọn tí ń kọjá lọ ní àìléwu,

bí àwọn ẹni tí ó padà bọ̀ láti ojú ogun.

9Ẹ̀yin sì lé obìnrin àwọn ènìyàn mi

kúrò nínú ilé ayọ̀ wọn,

ẹ̀yin sì ti gba ògo mi,

kúrò lọ́wọ́ àwọn ọmọ wọn láéláé.

10Ẹ dìde, kí ẹ sì máa lọ!

Nítorí èyí kì í ṣe ibi ìsinmi yín,

nítorí tí a ti sọ ọ́ di àìmọ́

yóò pa yín run,

àní ìparun kíkorò.

11Tí òpùrọ́ àti ẹlẹ́tàn bá wà tí wọ́n sì wí pé,

‘Èmi yóò sọtẹ́lẹ̀ fún ọ nípa ọ̀pọ̀lọpọ̀ wáìnì àti ọtí líle,’

òun ni yóò tilẹ̀ ṣe wòlíì àwọn ènìyàn wọ̀nyí!

Ìlérí ìgbàlà

12“Èmi yóò kó gbogbo yín jọ, ìwọ Jakọbu;

Èmi yóò gbá ìyókù Israẹli jọ.

Èmi yóò kó wọn jọ pọ̀ gẹ́gẹ́ bí àgùntàn nínú agbo ẹran,

gẹ́gẹ́ bí ọ̀wọ́ ẹran nínú agbo wọn,

ibẹ̀ yóò sì pariwo nítorí ọ̀pọ̀ ènìyàn.

13Ẹni tí ó ń fọ ọ̀nà yóò lọ sókè níwájú wọn;

wọn yóò fọ láti ẹnu ibodè, wọn yóò sì jáde lọ.

Àwọn ọba wọn yóò sì kọjá lọ níwájú wọn,

Olúwa ni yóò sì ṣe olórí wọn.”

Nouă Traducere În Limba Română

Mica 2:1-13

Planurile celor răi și planurile lui Dumnezeu

1Vai de cei ce plănuiesc nelegiuire

și uneltesc răul1 Lit.: fac răul. în așternutul lor!

Chiar din zorii dimineții încep să le săvârșească,

pentru că le stă în putere.

2Poftesc ogoare, și apoi pun mâna pe ele!

Poftesc case, iar apoi și le însușesc!

Asupresc pe om și casa lui,

pe bărbat și moștenirea sa.

3De aceea, așa vorbește Domnul:

„Iată, plănuiesc împotriva acestui clan o nenorocire

de care nu vă veți putea feri cefele!

Și nu veți mai umbla plini de înfumurare,

căci vor fi vremuri grele.

4În ziua aceea, se va rosti o pildă pe seama voastră

și se va face o cântare de jale, care va zice:

«Suntem ruinați de tot!

El înstrăinează proprietatea poporului meu!

Vai cum o înlătură de la mine!

Ogoarele noastre le împarte trădătorilor4 Asirienii (vezi Is. 33:1); sau cuceritorilor; sau răzvrătiților, apostaților.!»“

5De aceea nu vei mai avea pe nimeni

care să întindă prin sorți,

în adunarea Domnului, funia de măsurat.

Falșii profeți

6„Nu mai predicați!“, vor predica ei atunci.

„Să nu mai predice aceste lucruri!

Ocările nu ne vor copleși!“

7Dar ce ar trebui să se spună, Casă a lui Iacov?7 Sau: Aceasta ar trebui să spună Casa lui Iacov?

„Se mânie chiar atât de ușor Duhul Domnului?

Acesta este felul Lui de a lucra?“

„Oare nu fac bine cuvintele Mele

celui ce umblă cu dreptate?7 Sau, cf. LXX: de a lucra? / Oare nu fac bine cuvintele Lui / celui ce umblă cu dreptate? În v. 7 avem fie cuvintele falșilor profeți, care pun niște întrebări retorice, fie cuvintele lui Mica, împotriva acestora.

8De curând, poporul Meu

s‑a ridicat ca un dușman.8 Sau: V‑ați ridicat ca un dușman / împotriva poporului Meu.

Ați smuls mantaua

de peste haină8 Sensul celor două versuri este nesigur. Sau Ați smuls mantaua celor pașnici.,

de la cei ce trec în siguranță,

cei ce se întorc de la război8 Sau: celor ce nu se gândesc de război, fie în ideea că sunt pașnici (vezi nota precedentă), fie în ideea că au certitudinea că războiul a trecut..

9Voi le alungați pe femeile poporului Meu

din casele lor plăcute

și luați de la copiii lor

pentru totdeauna măreția Mea.

10Ridicați‑vă și plecați,

căci acesta nu mai este locul vostru de odihnă10 Vezi Deut. 12:9; Is. 28:12..

Pentru că a devenit necurat,

el va fi distrus, iar distrugerea va fi cumplită!

11Dacă un mincinos și un înșelător ar veni și ar spune:

«Îți voi predica despre vin și despre băuturi tari!»11 Sau: Îți voi promite vin și băuturi tari.,

acela ar fi considerat drept predicatorul acestui popor!

Promisiunea restaurării

12Cu siguranță te voi strânge în întregime, Iacov!

Cu siguranță voi aduna rămășița lui Israel!

Îi voi pune laolaltă ca pe niște oi în țarc,

ca pe o turmă în pășunea ei;

locul acela va mișuna de oameni.

13Cel ce deschide calea se va sui înaintea lor;

ei vor pătrunde, vor intra pe poartă și vor ieși.

Împăratul lor va trece înaintea lor,

și Domnul va fi în fruntea lor.“