Marku 6 – YCB & PCB

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Marku 6:1-56

Wòlíì tí kò ní ọlá

16.1-6: Mt 13.53-58; Lk 4.16-30.Jesu fi ibẹ̀ sílẹ̀ lọ sí ìlú rẹ̀ pẹ̀lú àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀. 26.2: Mk 1.21; Mt 7.28.Nígbà tí ó di ọjọ́ ìsinmi, ó lọ sí Sinagọgu láti kọ́ àwọn ènìyàn, ẹnu sì ya àwọn ènìyàn púpọ̀ tí ó gbọ́.

Wọ́n wí pé, “Níbo ni ọkùnrin yìí gbé ti rí nǹkan wọ̀nyí? Irú ọgbọ́n kí ni èyí tí a fi fún un, tí irú iṣẹ́ ìyanu báyìí ń ti ọwọ́ rẹ̀ ṣe? 36.3: Mt 11.6.Gbẹ́nàgbẹ́nà náà kọ́ yìí? Ọmọ Maria àti arákùnrin Jakọbu àti Josẹfu, Judasi àti Simoni? Àwọn arábìnrin rẹ̀ gbogbo ha kọ́ ni ó ń bá wa gbé níhìn-ín yìí?” Wọ́n sì kọsẹ̀ lára rẹ̀.

4Nígbà náà, Jesu wí fún wọn pé, “A máa ń bu ọlá fún wòlíì níbi gbogbo àfi ní ìlú ara rẹ̀ àti láàrín àwọn ìdílé àti àwọn ẹbí òun pàápàá.” 56.5: Mk 5.23; 7.32; 8.23.Nítorí àìgbàgbọ́ wọn, òun kò lè ṣe iṣẹ́ ìyanu ńlá láàrín wọn, àfi àwọn aláìsàn díẹ̀ tí ó gbé ọwọ́ lé lórí, tí wọ́n sì rí ìwòsàn.

Jesu rán ọmọ-ẹ̀yìn méjìlá jáde

66.6: Mt 9.35.Ẹnu si yà á nítorí àìgbàgbọ́ wọn. Lẹ́yìn náà, Jesu lọ sí àárín àwọn ìletò kéékèèké, ó sì ń kọ́ wọn. 76.7-11: Mt 10.1,5,7-11; Lk 9.1-5.6.7: Lk 10.1.Ó sì pe àwọn méjìlá náà sọ́dọ̀ rẹ̀, ó bẹ̀rẹ̀ sí rán wọn lọ ní méjì méjì, Ó sì fi àṣẹ fún wọn lórí ẹ̀mí àìmọ́.

8O sọ fún wọn pé, wọn kò gbọdọ̀ mú ohunkóhun lọ́wọ́, àfi ọ̀pá ìtìlẹ̀ wọn. Wọn kò gbọdọ̀ mú oúnjẹ, àpò ìgbànú, tàbí owó lọ́wọ́. 9Wọn kò tilẹ̀ gbọdọ̀ mú ìpààrọ̀ bàtà tàbí aṣọ lọ́wọ́. 10Jesu wí pé, “Ẹ dúró sí ilé kan ní ìletò kan. Ẹ má ṣe sípò padà láti ilé dé ilé, nígbà tí ẹ bá wà ní ìlú náà. 116.11: Mt 10.14.Ẹnikẹ́ni tí kò bá sì gbà yín, tí kò sì gbọ́rọ̀ yín, nígbà tí ẹ̀yin bá jáde kúrò níbẹ̀, ẹ gbọn eruku ẹsẹ̀ yín síbẹ̀ fún ẹ̀rí fún wọn.”

126.12-13: Mt 11.1; Lk 9.6.Wọ́n jáde lọ láti wàásù ìrònúpìwàdà fún àwọn ènìyàn. 136.13: Jk 5.14.Wọ́n lé ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ẹ̀mí àìmọ́ jáde. Wọ́n sì ń fi òróró kun orí àwọn tí ara wọn kò dá, wọ́n sì mú wọn láradá.

A bẹ́ Johanu onítẹ̀bọmi lórí

146.14-16: Mt 14.1-2; Lk 9.7-9; 9.19; Mt 21.11.Láìpẹ́, ọba Herodu gbọ́ nípa Jesu, nítorí níbi gbogbo ni a ti ń sọ̀rọ̀ iṣẹ́ ìyanu rẹ̀. Ọba náà rò pé, “Johanu Onítẹ̀bọmi jíǹde kúrò nínú òkú, nítorí náà ni iṣẹ́ ìyanu ṣe ń ṣe láti ọwọ́ rẹ.”

15Àwọn mìíràn wí pé, “Elijah ní.”

Àwọn mìíràn wí pé, “Wòlíì bí ọ̀kan lára àwọn àtijọ́ tó ti kú ló tún padà sáyé.”

16Ṣùgbọ́n nígbà tí Herodu gbọ́ èyí, ó wí pé “Johanu tí mo tí bẹ́ lórí ni ó ti jíǹde kúrò nínú òkú.”

176.17-18: Mt 14.3-4; Lk 3.19-20.Herodu fúnra rẹ̀ sá ti ránṣẹ́ mú Johanu, tìkára rẹ̀ sínú túbú nítorí Herodia aya Filipi arákùnrin rẹ̀ nítorí tí ó fi ṣe aya. 18Johanu sì ti wí fún Herodu pé, “Kò tọ́ sí ọ láti fi ìyàwó arákùnrin rẹ ṣe aya.” 196.19-29: Mt 14.5-12.Nítorí náà ni Herodia ṣe ní sínú, òun sì fẹ́ pa á, ṣùgbọ́n kò le ṣe é. 206.20: Mt 21.26.Nítorí Herodu bẹ̀rù Johanu, ó sì mọ̀ ọ́n ni olóòtítọ́ ènìyàn àti ẹni mímọ́, ó sì ń tọ́jú rẹ̀. Nígbà tí Herodu ba gbọ́rọ̀ Johanu, ó máa ń dààmú síbẹ̀, ó sì fi ayọ̀ gbọ́rọ̀ rẹ̀.

21Níkẹyìn Herodia rí ààyè. Àkókò yìí ni ọjọ́ ìbí Herodu, òun sì pèsè àsè ní ààfin ọba fún àwọn olùrànlọ́wọ́ rẹ̀: àwọn balógun àti àwọn ènìyàn pàtàkì ní Galili. 22Nígbà náà, ni ọmọbìnrin Herodia wọlé láti jó. Inú Herodu àti àwọn àlejò rẹ̀ dùn tó bẹ́ẹ̀.

Ọba sọ fún ọmọbìnrin náà pé, “Béèrè ohunkóhun tí ìwọ bá fẹ́ lọ́wọ́ mi, èmi ó sì fi fún ọ.” 236.23: Es 5.3,6.Ó sì búra fún un wí pé, “Ohunkóhun tí ìwọ bá fẹ́, ìbá à ṣe ìdajì ìjọba mi ni, èmi yóò fi fún ọ.”

24Ó jáde lọ sọ fún ìyá rẹ̀ pé, “Kí ní kí ń béèrè?”

Ó dáhùn pé, “Orí Johanu Onítẹ̀bọmi.”

25Ọmọbìnrin yìí sáré padà wá sọ́dọ̀ Herodu ọba. Ó sì wí fún un pé, “Mo ń fẹ́ orí Johanu Onítẹ̀bọmi nísinsin yìí nínú àwopọ̀kọ́.”

26Inú ọba sì bàjẹ́ gidigidi, ṣùgbọ́n nítorí àwọn ìbúra rẹ, àti nítorí àwọn tí ó bá a jókòó pọ̀, kò sì fẹ́ kọ̀ fún un. 27Nítorí èyí, ọba rán ẹ̀ṣọ́ kan, ó fi àṣẹ fún un pé, kí ó gbé orí Johanu wá. Ọkùnrin náà sì lọ, ó bẹ́ Johanu lórí nínú túbú. 28Ó sì gbé orí Johanu wa nínú àwopọ̀kọ́. Ó sì gbé e fún ọmọbìnrin náà. Òun sì gbé e tọ ìyá rẹ̀ lọ. 29Nígbà tí àwọn ọmọ-ẹ̀yìn Johanu gbọ́, wọ́n wá gbé òkú rẹ̀, wọ́n sì lọ tẹ́ ẹ sínú ibojì.

Jesu bọ́ ẹgbẹ̀rún márùn-ún (5,000) ènìyàn

306.30-31: Lk 9.10; Mk 3.20.Àwọn aposteli kó ara wọn jọ sí ọ̀dọ̀ Jesu, wọ́n sí ròyìn ohun gbogbo tí wọ́n ti ṣe àti ohun gbogbo tí wọ́n ti kọ́ni. 31Nígbà tí Jesu rí i pé ọ̀pọ̀ ènìyàn ń lọ tí wọ́n sì ń bọ̀ tó bẹ́ẹ̀ tí kò sí ààyè fún wọn láti jẹun, ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ jẹ́ kí a kúrò láàrín ọ̀pọ̀ ènìyàn wọ̀nyí fún ìgbà díẹ̀, kí a sì sinmi.”

326.32-44: Mt 14.13-21; Lk 9.11-17; Jh 6.5-13; Mk 8.1-10; Mt 15.32-39.Nítorí náà, wọ́n wọ ọkọ̀ ojú omi kúrò níbẹ̀ lọ sí ibi tí ó parọ́rọ́. 33Ṣùgbọ́n ọ̀pọ̀ ènìyàn ni o rí wọn nígbà tí wọ́n ń lọ. Àwọn wọ̀nyí sì tún wá láti ìlú ńlá gbogbo wọn sáré gba etí Òkun, wọ́n ṣáájú wọn gúnlẹ̀ ní èbúté. 346.34: Mt 9.36.Bí Jesu ti ń sọ̀kalẹ̀ láti inú ọkọ̀ náà, ó bá ọ̀pọ̀ ènìyàn bí i tí àtẹ̀yìnwá, tí wọ́n ti ń dúró dè e. Ó káàánú fún wọn, nítorí wọ́n dàbí àgùntàn tí kò ní olùtọ́jú. Ó sì kọ́ wọn ni ọ̀pọ̀ nǹkan tí ó yẹ kí wọ́n mọ̀.

35Nígbà tí ọjọ́ sì ti bù lọ tán, àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ tọ̀ ọ́ wá, wọ́n wí fún un pé, ibi aṣálẹ̀ ni ìbí yìí, ọjọ́ sì bù lọ tán. 36“Rán àwọn ènìyàn wọ̀nyí láti lọ sí àwọn abúlé àti ìlú láti ra oúnjẹ fún ara wọn.”

376.37: 2Ọb 4.42-44.Ṣùgbọ́n Jesu sọ fún àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ pé, “Ẹ fún wọn ní oúnjẹ.”

Àwọn ọmọ-ẹ̀yìn wí fún pé, “Èyí yóò ná wa tó owó iṣẹ́ ọ̀yà oṣù mẹ́jọ, ṣe kí a lọ fi èyí ra àkàrà fún àwọn ọ̀pọ̀ ènìyàn yìí láti jẹ.”

38Jesu tún béèrè pé, “Ìṣù àkàrà mélòó ni ẹ̀yin ni lọ́wọ́? Ẹ lọ wò ó.”

Wọ́n padà wá jíṣẹ́ pé, “Ìṣù àkàrà márùn-ún àti ẹja méjì.”

39Nígbà náà ni Jesu sọ fún ọ̀pọ̀ ènìyàn náà kí a mú wọn jókòó lẹ́gbẹ̀ẹ̀gbẹ́ lórí koríko. 40Lẹ́sẹ̀kan náà, wọ́n bẹ̀rẹ̀ sí í jókòó, ní àádọ́ta tàbí ọgọọgọ́rùn-ún. 416.41: Mk 14.22; Lk 24.30-31.Nígbà tí ó sì mú ìṣù àkàrà márùn-ún àti ẹja méjì náà, ó gbé ojú rẹ̀ sókè ọ̀run. Ó dúpẹ́ fún oúnjẹ náà, ó bù wọ́n sí wẹ́wẹ́, ó fún àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ láti gbé e kalẹ̀ síwájú àwọn ènìyàn náà àti àwọn ẹja méjì náà ni ó pín fún gbogbo wọn. 42Gbogbo wọn sì jẹ àjẹyó. 43Àwọn ọmọ-ẹ̀yìn sì kó agbọ̀n méjìlá tí ó kún fún àjẹkù àkàrà àti ti ẹja pẹ̀lú. 44Àwọn tí ó sì jẹ́ àkàrà náà tó ìwọ̀n ẹgbẹ̀rún márùn-ún (5,000) ọkùnrin.

Jesu rìn lórí omi

456.45-52: Mt 14.22-33; Jh 6.15-21.Lẹ́sẹ̀kẹsẹ̀ lẹ́yìn èyí, Jesu pàṣẹ fún àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ láti padà sínú ọkọ̀ kí wọn sì ṣáájú rékọjá sí Betisaida. Níbẹ̀ ni òun yóò ti wà pẹ̀lú wọn láìpẹ́. Nítorí òun fúnra a rẹ̀ yóò dúró sẹ́yìn láti rí i pé àwọn ènìyàn túká lọ ilé wọn. 46Lẹ́yìn náà, ó lọ sórí òkè láti lọ gbàdúrà.

47Nígbà tí ó di alẹ́, ọkọ̀ wà láàrín Òkun, òun nìkan sì wà lórí ilẹ̀. 486.48: Mk 13.35.Ó rí i wí pé àwọn ọmọ-ẹ̀yìn wà nínú wàhálà púpọ̀ ní wíwa ọkọ̀ náà nítorí ti ìjì líle ṣe ọwọ́ òdì sí wọn, nígbà tí ó sì dì ìwọ̀n ìṣọ́ kẹrin òru, ó tọ̀ wọ́n wá, ó ń rìn lórí omi Òkun, òun sì fẹ́ ré wọn kọjá, 49ṣùgbọ́n nígbà tí wọ́n rí i tí ó ń rìn, wọ́n rò pé iwin ni. Wọ́n sì kígbe sókè lóhùn rara, 506.50: Mt 9.2.nítorí gbogbo wọn ni ó rí i, tí ẹ̀rù sì bà wọ́n.

Ṣùgbọ́n òun sọ̀rọ̀ sí wọn lẹ́sẹ̀kẹsẹ̀ pé, “Ẹ mú ọkàn le! Èmi ni. Ẹ má bẹ̀rù.” 51Nígbà náà ni ó gòkè sínú ọkọ̀ pẹ̀lú wọn, ìjì líle náà sì dáwọ́ dúró. Ẹ̀rù sì bà wọ́n rékọjá gidigidi, ẹnu sì yà wọ́n. 526.52: Mk 8.17.Wọn kò sá tó ni òye iṣẹ́ ìyanu ti ìṣù àkàrà, nítorí ti ọkàn wọn yigbì.

536.53-56: Mt 14.34-36.Lẹ́yìn tí wọ́n la Òkun náà kọjá, wọ́n gúnlẹ̀ sí Genesareti. Wọ́n sì so ọkọ̀ sí èbúté. 54Wọ́n jáde kúrò nínú ọkọ̀. Àwọn ènìyàn tó wà níbẹ̀ rí Jesu, wọ́n sì dá a mọ̀ ọ́n. 55Wéré, wọ́n ròyìn dídé rẹ̀, gbogbo àwọn ènìyàn sáré gbé gbogbo àwọn aláìsàn lórí àkéte wọn wá pàdé rẹ̀. 566.56: Mk 3.10; Mt 9.20.Ní ibi gbogbo tí ó sì dé, yálà ní abúlé, ìlú ńlá tàbí àrọ́ko, ń ṣe ni wọ́n ń kó àwọn aláìsàn pàdé rẹ̀ ní àárín ọjà. Wọ́n sì ń bẹ̀ ẹ́ kí ó jẹ́ kí wọn fi ọwọ́ kan etí aṣọ rẹ̀, gbogbo àwọn tí wọ́n sì fi ọwọ́ kàn án ni a mú láradá.

Persian Contemporary Bible

مَرقُس 6:1-56

پيامبر در شهر خود احترامی ندارد

1آنگاه عيسی از آن ديار روانه شد و همراه شاگردانش به ناصره، شهری كه در آن بزرگ شده بود، بازگشت. 2روز شنبه به كنيسه رفت تا تعليم دهد. مردم از حكمت و معجزات او غرق در شگفتی شدند، مخصوصاً كه همشهری ايشان نيز بود. آنان می‌گفتند: «مگر او چه چيز از ما بيشتر دارد؟ 3او كه همان نجّار است و مادرش مريم و برادرانش هم يعقوب و يوشا و يهودا و شمعون هستند؛ خواهرانش نيز در ميان ما زندگی می‌كنند.» و بدين ترتيب غرورشان اجازه نداد با احترام به سخنان او گوش فرا دهند.

4عيسی به ايشان فرمود: «پيامبر را همه جا گرامی می‌دارند، مگر در شهر خود و ميان خويشاوندان و خانوادهٔ خويش.» 5و او نتوانست معجزهٔ بزرگی در آن شهر انجام دهد چون مردم به او ايمان نداشتند. فقط دست خود را بر چند بيمار گذاشت و ايشان را شفا بخشيد. 6عيسی نمی‌توانست باور كند كه همشهريان او تا اين حد بی‌ايمان باشند.

مأموريت دوازده شاگرد عيسی

آنگاه عيسی به دهكده‌ها رفته، به تعليم دادن مردم پرداخت.

7او دوازده شاگرد خود را فرا خواند و ايشان را دو به دو فرستاد و به ايشان قدرت داد تا ارواح پليد را از مردم بيرون كنند. 8در ضمن به ايشان فرمود: «جز چوبدستی چيزی همراه خود نبريد. نه خوراک، نه پوشاک، نه پول در كمربند خود، 9و نه حتی كفش و لباس اضافی. 10به هر دِهی كه رسيديد، فقط در يک خانه بمانيد و تا وقتی در آن دِه هستيد محل اقامت خود را عوض نكنيد. 11اگر در جايی شما را نپذيرفتند و حاضر نبودند به سخنانتان گوش دهند، از آنجا بيرون برويد و گرد و خاكی را كه از آن ده بر پايهايتان نشسته است پاک كنيد، تا نشان دهيد كه آنان چه فرصتی را از دست داده‌اند.»

12پس ايشان رفته، همهٔ مردم را به توبه از گناهان دعوت كردند. 13ايشان روحهای ناپاک زيادی را بيرون كردند و بر سر بيماران بسياری روغن زيتون ماليده، آنان را شفا دادند.

مرگ يحيی

14طولی نكشيد كه خبر كارهای عيسی به گوش هيروديس پادشاه رسيد زيرا همه جا گفتگو دربارهٔ معجزات او بود. بعضی گمان می‌كردند عيسی همان يحيی است كه زنده شده و می‌گفتند: «برای همين است كه چنين معجزاتی می‌كند.» 15عده‌ای نيز بر اين گمان بودند كه او همان الياس پيغمبر می‌باشد كه ظهور كرده است. ديگران نيز می‌گفتند كه او پيامبری است مانند پيامبران بزرگ گذشته. 16اما هيروديس می‌گفت: «نه، اين بايد همان يحيی باشد كه من سرش را از تن جدا كردم، و حالا دوباره زنده شده است.»

17‏-18ماجرا چنين بود كه هيروديس سربازانی فرستاده، يحيی را دستگير كرده، به زندان انداخته بود، زيرا او به هيروديس می‌گفت: «ازدواج تو با هيروديا، همسر برادرت فيليپ، كار درستی نيست.» 19هيروديا از يحيی كينه به دل داشت و می‌خواست او را بكشد، اما اين كار بدون اجازهٔ هيروديس ممكن نبود. 20هيروديس به يحيی احترام می‌گذاشت چون می‌دانست كه او مرد نيک و مقدسی است؛ بنابراين، از او حمايت می‌كرد و هرگاه با يحيی گفتگو می‌نمود، وجدانش ناراحت می‌شد. با اين حال دوست می‌داشت سخنان او را بشنود.

21اما سرانجام فرصت مناسبی برای هيروديا پيش آمد. به اين ترتيب كه هيروديس در روز تولد خود، ضيافتی ترتيب داد و همهٔ درباريان و فرماندهان و بزرگان ايالت جليل را دعوت كرد. 22‏-23آنگاه دختر هيروديا وارد مجلس شد و برای مهمانان رقصيد و همه را شاد كرد. پس هيروديس پادشاه برای او قسم خورد و گفت: «هر چه می‌خواهی بگو تا به تو بدهم؛ حتی اگر نصف مملكتم را بخواهی به تو خواهم داد.» 24دختر بی‌درنگ نزد مادرش رفت تا با او مشورت كند. مادر به او گفت: «سر يحيی را درخواست كن!» 25دختر با عجله برگشت و درخواستش را به پادشاه گفت: «سر يحيی را می‌خواهم. آن را در يک سينی به من بدهيد.»

26پادشاه بسيار اندوهگين شد، ولی چون نمی‌توانست قول خود را در مقابل مهمانان زير پا بگذارد، 27يكی از جلادان را به زندان فرستاد تا سر يحيی را از تن جدا كند و برايش بياورد. 28جلاد نيز به زندان رفت و سر يحيی را بريد و آن را در يک سينی برای دختر آورد. او نيز سر بريده را نزد مادرش برد.

29هنگامی كه مريدان يحيی از ماجرا باخبر شدند، آمدند و جنازهٔ او را برده، به خاک سپردند.

غذا دادن به ۵,۰۰۰ نفر

30پس از مدتی، شاگردان عيسی از سفر برگشتند و او را از كارهايی كه كرده و تعاليمی كه داده بودند، آگاه ساختند. 31عيسی به ايشان گفت: «بياييد از غوغای جمعيت كمی دور شويم و استراحت كنيم.» رفت و آمد مردم آنقدر زياد بود كه حتی فرصت نمی‌كردند چيزی بخورند. 32پس سوار قايقی شدند تا به جای خلوتی بروند. 33وقتی مردم ديدند كه ايشان می‌روند، در كنار دريا آنقدر دويدند تا به مقصد ايشان رسيدند و پيش از آنكه عيسی و شاگردانش از قايق پياده شوند، در آن محل حاضر بودند. 34وقتی عيسی پا به ساحل گذاشت مردم طبق معمول دور او جمع شدند. او دلش به حال ايشان سوخت چون مانند گوسفندان بی‌شبان بودند. پس تعاليم بسياری به ايشان داد.

35‏-36نزديک غروب، شاگردان نزد او آمدند و گفتند: «به مردم بگوييد به دهات اطراف بروند و برای خود خوراک تهيه كنند، چون در اين جای دور افتاده، چيزی برای خوردن پيدا نمی‌شود. هوا نيز رو به تاريكی می‌رود.»

37ولی عيسی فرمود: «شما خودتان به ايشان خوراک بدهيد.»

پرسيدند: «با دست خالی؟ می‌دانی چقدر پول می‌خواهد تا بتوانيم به اين جمعيت خوراک بدهيم؟»

38عيسی فرمود: «برويد ببينيد چقدر نان داريم.»

پس از تحقيق، آمدند و گفتند كه پنج نان و دو ماهی دارند. 39‏-40آنگاه عيسی به مردم فرمود تا بر روی زمين بنشينند. طولی نكشيد كه مردم در گروه‌های پنجاه نفری و صد نفری، روی سبزه‌ها نشستند.

41عيسی آن پنج نان و دو ماهی را در دست گرفت و به سوی آسمان نگاه كرد و خدا را شكر نمود. سپس نانها را تكه‌تكه كرد و با ماهی به يارانش داد تا پيش مردم بگذارند. 42مردم آنقدر خوردند تا كاملاً سير شدند.

43‏-44تعداد كسانی كه نان و ماهی را خوردند حدود ۵,۰۰۰ مرد بود؛ با اين حال، از خرده نانها و ماهيها، دوازده سبد پر شد.

عيسی روی آب راه می‌رود

45بلافاصله پس از آن، عيسی به شاگردانش فرمود تا سوار قايق شوند و به كنارهٔ ديگر درياچه به بيت‌صيدا بروند تا خود نيز پس از روانه كردن مردم، به ايشان ملحق شود.

46پس عيسی مردم را مرخص فرمود و از تپه‌ای بالا رفت تا دعا كند. 47كم‌كم شب شد. قايق شاگردان به وسط درياچه رسيده بود و عيسی هنوز در تنهايی مشغول دعا بود. 48در اين هنگام، او ديد كه ايشان در زحمت افتاده‌اند و با باد و موج دست به گريبانند.

پس نزديک به ساعت سه بعد از نيمه شب، عيسی بر روی آب قدم زنان به سوی قايق حركت كرد و می‌خواست از ايشان بگذرد 49كه شاگردان متوجه شدند و ديدند كه چيزی روی آب راه می‌رود. به گمان اينكه روحی می‌بينند، از ترس فرياد زدند، 50چون همه او را می‌ديدند و مضطرب بودند. ولی عيسی فوری با ايشان صحبت كرده، گفت: «دلير باشيد، نترسيد، من هستم!» 51آنگاه سوار قايق شد و باد از وزيدن باز ايستاد.

شاگردان از ترس و حيرت، در جای خود خشک شده بودند. 52چون حتی بعد از آن معجزهٔ بزرگ شب پيش، هنوز نفهميده بودند او چه شخصيتی دارد، زيرا نمی‌خواستند ايمان بياورند.

53وقتی به آن كنارهٔ درياچه، به سرزمين جنيسارت رسيدند و لنگر انداخته 54از قايق بيرون آمدند، مردم فوری او را شناختند 55و در سراسر آن ناحيه خبر ورود او را پخش كردند. طولی نكشيد كه از هر طرف مريضان را روی تختها نزد او آوردند. 56عيسی هر جا قدم می‌گذاشت، چه در دهات و چه در شهرها و چه در صحرا، مردم بيماران را بر سر راه او می‌گذاشتند و خواهش می‌كردند كه لااقل اجازه دهد به لباس او دست بزنند؛ و هر مريضی كه به او دست می‌زد شفا می‌يافت.