1Ọ̀rọ̀-ìjìnlẹ̀: ọ̀rọ̀ Olúwa sí Israẹli láti ẹnu Malaki.
Ọlọ́run fẹ́ràn Jakọbu, o sì kórìíra Esau
21.2-3: Ro 9.13.1.2-5: Isa 34; 63.1-6; Jr 49.7-22; El 25.12-14; 35; Am 1.11-12.“Èmí ti fẹ́ ẹ yín,” ni Olúwa wí.
“Ṣùgbọ́n ẹ̀yin béèrè pé, ‘Báwo ni ìwọ ṣe fẹ́ wa?’
“Esau kì í ha ṣe arákùnrin Jakọbu bí?” ni Olúwa wí. “Síbẹ̀ èmi fẹ́ràn Jakọbu, 3ṣùgbọ́n Esau ni mo kórìíra, mo ti sọ àwọn òkè ńlá rẹ̀ di aṣálẹ̀, mo sì fi ìní rẹ̀ fún àwọn akátá aginjù.”
4Edomu lè wí pé, “Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé a run wá, àwa yóò padà wá, a ó sì tún ibùgbé náà kọ́.”
Ṣùgbọ́n èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí pé: “Àwọn lè kọ́, ṣùgbọ́n èmi yóò wó palẹ̀. Wọn yóò sì pè wọ́n ní ilẹ̀ búburú, àwọn ènìyàn tí wọ́n máa ń wà ní ìbínú Olúwa. 5Ẹ̀yin yóò sì fi ojú yín rí i, ẹ̀yin yóò sì wí pé, ‘Títóbi ni Olúwa, títóbi rẹ̀ tayọ kọjá agbègbè Israẹli.’
Ẹbọ àìmọ́
6“Ọmọ a máa bu ọ̀wọ̀ fún baba rẹ̀, ọmọ ọ̀dọ̀ a sì máa bu ọlá fún olúwa rẹ̀. Ǹjẹ́ bí èmí bá jẹ́ baba, ọlá tí ó tọ́ sí mi ha dà? Bí èmi bá sì jẹ́ olúwa, ẹ̀rù tí ó tọ́ sí mi dà?” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
“Ẹ̀yin ni, ẹ̀yin àlùfáà, ni ẹ ń gan orúkọ mi.
“Ṣùgbọ́n ẹ̀yin béèrè pé, ‘Báwo ni àwa ṣe gan orúkọ rẹ?’
7“Ẹ̀yin gbé oúnjẹ àìmọ́ sí orí pẹpẹ mi.
“Ẹ̀yin sì tún béèrè pé, ‘Báwo ni àwa ṣe ṣe àìmọ́ sí ọ?’
“Nípa sísọ pé tábìlì Olúwa di ẹ̀gàn. 8Nígbà tí ẹ̀yin mú afọ́jú ẹran wá fún ìrúbọ, ṣé èyí kò ha burú bí? Nígbà tí ẹ̀yin fi amúnkùn ún àti aláìsàn ẹran rú ẹbọ, ṣé èyí kò ha burú gidigidi bí? Ẹ dán an wò, ẹ fi wọ́n rú ẹbọ sí àwọn baálẹ̀ yín! Ṣé inú rẹ̀ yóò dùn sí yín? Ṣé yóò gbà yín?” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
9“Ní ìsinsin yìí, ẹ bẹ Ọlọ́run kí ó ṣàánú fún wa. Ṣùgbọ́n pẹ̀lú irú àwọn ẹbọ wọ̀nyí láti ọwọ́ yín wá, ṣé yóò gbà yín?” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
10“Hó ò! Ẹnìkan ìbá jẹ́ wà láàrín yín ti yóò sé ìlẹ̀kùn tẹmpili, pé kí ẹ má ba à ṣe dá iná asán lórí pẹpẹ mi mọ́! Èmi kò ní inú dídùn sí i yín,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, “bẹ́ẹ̀ ni èmi kì yóò gba ọrẹ kan lọ́wọ́ yín. 11Orúkọ mi yóò tóbi láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, láti ìlà-oòrùn títí ó sì fi dé ìwọ̀-oòrùn. Ní ibi gbogbo ni a ó ti mú tùràrí àti ọrẹ mímọ́ wá fún orúkọ mi, nítorí orúkọ mi tóbi láàrín àwọn orílẹ̀-èdè,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
12“Nítorí ẹ̀yin ti sọ ọ́ di àìmọ́, nínú èyí tí ẹ wí pé, ‘Tábìlì Olúwa di àìmọ́ àti èso rẹ̀,’ àní oúnjẹ rẹ̀ ni ohun ẹ̀gàn. 13Ẹ̀yin wí pẹ̀lú pé, ‘Wò ó, irú àjàgà kín ni èyí!’ Ẹ̀yin sì yínmú sí i,” ní Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
“Nígbà tí ẹ̀yin sì mú èyí tí ó fi ara pa, arọ àti ọlọkùnrùn ẹran tí ẹ sì fi rú ẹbọ, Èmi o ha gba èyí lọ́wọ́ yín?” ni Olúwa wí. 14“Ṣùgbọ́n ègún ni fún ẹlẹ́tàn náà, tí ó ni akọ nínú ọ̀wọ́ ẹran rẹ̀, tí ó sì ṣe ìlérí láti fi lélẹ̀ tí ó sì fi ẹran tó lábùkù rú ẹbọ sí Olúwa; nítorí ọba ńlá ni Èmi,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, “ẹ̀rù sì ni orúkọ mi láàrín àwọn orílẹ̀-èdè.
1اين است پيام خداوند كه بوسيلهٔ ملاكی نبی به اسرائيل داده شد.
محبت خداوند نسبت به اسرائيل
2-3خداوند میفرمايد: «من شما را هميشه دوست داشتهام!»
ولی شما میگوييد: «تو چگونه ما را دوست داشتهای؟»
خداوند میفرمايد: «من جد شما يعقوب را محبت نمودم، هر چند لايق محبت نبود، و به اين ترتيب نشان دادم كه شما را دوست دارم، ولی عيسو را كه برادرش بود رد كردم و سرزمين كوهستانی او را ويران نمودم و آن را جای شغالهای بيابان ساختم.»
4شايد ادومیها كه فرزندان عيسو هستند بگويند: «ما برمیگرديم و سرزمين ويران خود را دوباره آباد میكنيم.» ولی خداوند قادر متعال میگويد: «اگر آن را آباد كنند من دوباره ويرانش خواهم كرد. سرزمين آنها ”سرزمين شرارت“ خوانده خواهد شد و مردمشان به ”قومی كه خداوند آنها را هرگز نمیبخشد“، مشهور خواهند گرديد.»
5ای قوم اسرائيل، وقتی با چشمان خود آنچه را كه خداوند در سراسر دنيا انجام میدهد ببينيد، خواهيد گفت: «براستی كه قدرت عظيم خداوند در آن سوس مرزهای ما نيز ديده میشود.»
سرزنش كاهنان
6خداوند قادر متعال به كاهنان میفرمايد: «پسر، پدر خود را و غلام، ارباب خويش را احترام میكند. پس اگر من پدر شما هستم احترام من كجاست؟ و اگر من ارباب شما هستم، حرمت من كجاست؟ شما نام مرا بیحرمت كردهايد. میگوييد: ”ما چگونه نام تو را بیحرمت كردهايم؟“ 7شما هنگامی نام مرا بیحرمت میكنيد كه قربانیهای ناپاک روی قربانگاه من میگذاريد. بلی، با اين كارتان مرا تحقير میكنيد. 8حيوانات لنگ و كور و بيمار را برای من قربانی میكنيد. آيا اين قبيح نيست؟ اگر آن را به حاكم خود هديه میكرديد آيا او آن را میپسنديد و از شما راضی میشد؟
9«دعا میكنيد و میگوييد: ”خداوندا، بر ما رحم كن! خداوندا، لطف تو شامل حال ما بشود!“ ولی وقتی كه چنين هدايايی میآوريد، چطور انتظار داريد دعای شما را اجابت كنم؟»
10خداوند قادر متعال میفرمايد: «ای كاش يكی از شما كاهنان، درها را میبست تا چنين هدايايی روی قربانگاه من گذاشته نشود. از شما راضی نيستم و قربانیهای شما را نمیپذيرم.
11«نام من در سراسر جهان بوسيلهٔ مردم غيريهود مورد احترام قرار خواهد گرفت و آنها به احترام نام من بخور خوشبو خواهند سوزانيد و قربانیهای پاک تقديم خواهند كرد. آری آنها نام مرا با احترام فراوان ياد خواهند كرد. 12ولی شما نام مرا بیحرمت میسازيد و قربانگاه مرا نجس میكنيد، زيرا حيوانات معيوب بر آن میگذاريد. 13میگوييد: ”خدمت كردن به خداوند كار مشكل و خسته كنندهای است“، و از دستورات من سرپيچی میكنيد. حيوانات دزديده شده، لنگ و بيمار برای من قربانی میكنيد. آيا فكر میكنيد من آنها را از دست شما قبول خواهم كرد؟ 14لعنت بر كسی كه بخواهد مرا فريب دهد و با آنكه نذر كرده قوچ سالمی از گلهٔ خود هديه كند، حيوان معيوبی برای من قربانی نمايد. من پادشاه عظيم هستم و مردم دنيا بايد اسم مرا با ترس و احترام ياد كنند.»