Luku 2 – YCB & CARS

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Luku 2:1-52

Ìbí Jesu

12.1: Lk 3.1.Ó sì ṣe ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì, àṣẹ ti ọ̀dọ̀ Kesari Augustu jáde wá pé, kí a kọ orúkọ gbogbo ayé sínú ìwé. 2(Èyí ni ìkọ sínú ìwé èkínní tí a ṣe nígbà tí Kirene fi jẹ baálẹ̀ Siria.) 3Gbogbo àwọn ènìyàn sì lọ láti kọ orúkọ wọn sínú ìwé, olúkúlùkù sí ìlú ara rẹ̀.

42.4: Lk 1.27.Josẹfu pẹ̀lú sì gòkè láti Nasareti ni Galili, sí ìlú Dafidi ní Judea, tí à ń pè ní Bẹtilẹhẹmu; nítorí ti ìran àti ìdílé Dafidi ní í ṣe, 5láti kọ orúkọ rẹ̀, pẹ̀lú Maria aya rẹ̀ àfẹ́sọ́nà, tí oyún rẹ̀ ti tó bí. 6Ó sì ṣe, nígbà tí wọ́n wà níbẹ̀, ọjọ́ rẹ̀ pé tí òun yóò bí. 7Ó sì bí àkọ́bí rẹ̀ ọmọkùnrin, ó sì fi ọ̀já wé e, ó sì tẹ́ ẹ sínú ibùjẹ ẹran; nítorí tí ààyè kò sí fún wọn nínú ilé èrò.

Àwọn olùṣọ́-àgùntàn àti àwọn angẹli

8Àwọn olùṣọ́-àgùntàn ń bẹ tí wọ́n ń gbé ní ìlú náà, wọ́n ń ṣọ́ agbo àgùntàn wọn ní òru ní pápá tí wọ́n ń gbé. 92.9: Lk 1.11; Ap 5.19.Angẹli Olúwa sì yọ sí wọn, ògo Olúwa sì ràn yí wọn ká, ẹ̀rù sì bà wọ́n gidigidi. 10Angẹli náà sì wí fún wọn pé, “Má bẹ̀rù: sá wò ó, mo mú ìyìnrere ayọ̀ ńlá fún yín wá, tí yóò ṣe ti ènìyàn gbogbo. 112.11: Jh 4.42; Ap 5.31; Mt 16.16; Ap 2.36.Nítorí a ti bí Olùgbàlà fún yín lónìí ní ìlú Dafidi, tí í ṣe Kristi Olúwa. 122.12: 1Sa 2.34; 2Ọb 19.29; Isa 7.14.Èyí ni yóò sì ṣe àmì fún yín; ẹ̀yin yóò rí ọmọ ọwọ́ tí a fi ọ̀já wé, ó dùbúlẹ̀ ní ibùjẹ ẹran.”

13Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ogun ọ̀run sì darapọ̀ mọ́ angẹli náà ní òjijì, wọ́n ń yin Ọlọ́run, wí pé,

142.14: Lk 19.38; 3.22.“Ògo ni fún Ọlọ́run lókè ọ̀run,

àti ní ayé àlàáfíà, ìfẹ́ inú rere sí ènìyàn.”

15Ó sì ṣe, nígbà tí àwọn angẹli náà padà kúrò lọ́dọ̀ wọn lọ sí ọ̀run, àwọn olùṣọ́-àgùntàn náà bá ara wọn sọ pé, “Ẹ jẹ́ kí á lọ tààrà sí Bẹtilẹhẹmu, kí á lè rí ohun tí ó ṣẹ̀, tí Olúwa fihàn fún wa.”

16Wọ́n sì wá lọ́gán, wọ́n sì rí Maria àti Josẹfu, àti ọmọ ọwọ́ náà, ó dùbúlẹ̀ nínú ibùjẹ ẹran. 17Nígbà tí wọ́n sì ti rí i, wọ́n sọ ohun tí a ti wí fún wọn nípa ti ọmọ yìí. 18Ẹnu sì ya gbogbo àwọn tí ó gbọ́ sí nǹkan wọ̀nyí tí a ti wí fún wọn láti ọ̀dọ̀ àwọn olùṣọ́-àgùntàn wá. 192.19: Lk 2.51.Ṣùgbọ́n Maria pa gbogbo nǹkan wọ̀nyí mọ́, ó ń rò wọ́n nínú ọkàn rẹ̀. 20Àwọn olùṣọ́-àgùntàn sì padà lọ, wọ́n ń fi ògo fún Ọlọ́run, wọ́n sì yìn ín, nítorí ohun gbogbo tí wọ́n ti gbọ́ àti tí wọ́n ti rí, bí a ti wí i fún wọn.

A gbé Jesu kalẹ̀ nínú Tẹmpili

212.21: Lk 1.31,59; Mt 1.25.Nígbà tí ọjọ́ mẹ́jọ sì pé láti kọ ọmọ náà nílà, wọ́n pe orúkọ rẹ̀ ní Jesu, bí a ti sọ ọ́ tẹ́lẹ̀ láti ọ̀dọ̀ angẹli náà wá kí á tó lóyún rẹ̀.

222.22-24: Le 12.2-8.Nígbà tí ọjọ́ ìwẹ̀nù Maria sì pé gẹ́gẹ́ bí òfin Mose, Josẹfu àti Maria gbé Jesu wá sí Jerusalẹmu láti fi í fún Olúwa 232.23: Ek 13.2,12.(bí a ti kọ ọ́ sínú òfin Olúwa pé, “Gbogbo ọmọ ọkùnrin tí ó ṣe àkọ́bí, òun ni a ó pè ní mímọ́ fún Olúwa”), 24àti láti rú ẹbọ gẹ́gẹ́ bí èyí tí a wí nínú òfin Olúwa: “Àdàbà méjì tàbí ọmọ ẹyẹlé méjì.”

252.25: Lk 2.38; 23.51.Sì kíyèsi i, ọkùnrin kan wà ní Jerusalẹmu, orúkọ rẹ̀ a máa jẹ́ Simeoni; ọkùnrin náà sì ṣe olóòtítọ́ àti olùfọkànsìn, ó ń retí ìtùnú Israẹli, Ẹ̀mí mímọ́ sì bà lé e. 26A sì ti fihàn án láti ọ̀dọ̀ Ẹ̀mí Mímọ́ náà wá pé, òun kì yóò rí ikú, kí ó tó rí Kristi Olúwa. 27Ó sì ti ipa Ẹ̀mí wá sínú tẹmpili. Nígbà tí àwọn òbí rẹ̀ sì gbé Jesu wá, láti ṣe fún un bí ìṣe òfin. 28Nígbà náà ni Simeoni gbé e ní apá rẹ̀, ó fi ìbùkún fún Ọlọ́run, ó ní:

29“Olúwa Olódùmarè, nígbà yìí ni ó tó jọ̀wọ́ ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ lọ́wọ́ lọ,

ní àlàáfíà, gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ.

302.30: Isa 52.10; Lk 3.6.Nítorí tí ojú mi ti rí ìgbàlà rẹ ná,

31tí ìwọ ti pèsè sílẹ̀ níwájú ènìyàn gbogbo;

322.32: Isa 42.6; 49.6; Ap 13.47; 26.23.ìmọ́lẹ̀ láti mọ́ sí àwọn aláìkọlà,

àti ògo Israẹli ènìyàn rẹ̀.”

33Ẹnu sì ya Josẹfu àti ìyá rẹ̀ sí nǹkan tí a ń sọ sí i wọ̀nyí. 34Simeoni sì súre fún wọn, ó sì wí fún Maria ìyá rẹ̀ pé, “Kíyèsi i, a gbé ọmọ yìí kalẹ̀ fún ìṣubú àti ìdìde ọ̀pọ̀ ènìyàn ní Israẹli; àti fún àmì tí a ń sọ̀rọ̀-òdì sí; 35(idà yóò sì gún ìwọ náà ní ọkàn pẹ̀lú) kí á lè fi ìrònú ọ̀pọ̀ ọkàn hàn.”

362.36: Ap 21.9; Jo 19.24; 1Tm 5.9.Ẹnìkan sì ń bẹ, Anna wòlíì, ọmọbìnrin Penueli, nínú ẹ̀yà Aṣeri: ọjọ́ ogbó rẹ̀ pọ̀, ó ti bá ọkọ gbé ní ọdún méje láti ìgbà wúńdíá rẹ̀ wá; 37Ó sì ṣe opó títí ó fi di ẹni ọdún mẹ́rìnlélọ́gọ́rin, ẹni tí kò kúrò ní tẹmpili, ṣùgbọ́n ó ń fi àwẹ̀ àti àdúrà sin Ọlọ́run lọ́sàn án àti lóru. 38Ó sì wólẹ̀ ní àkókò náà, ó sì dúpẹ́ lọ́wọ́ Ọlọ́run pẹ̀lú, ó sì sọ̀rọ̀ rẹ̀ fún gbogbo àwọn tí ó ń retí ìdáǹdè Jerusalẹmu.

39Nígbà tí wọ́n sì ti ṣe nǹkan gbogbo tán gẹ́gẹ́ bí òfin Olúwa, wọ́n padà lọ sí Galili, sí Nasareti ìlú wọn. 402.40: On 13.24; 1Sa 2.26.Ọmọ náà sì ń dàgbà, ó sì ń lágbára, ó sì kún fún ọgbọ́n: oore-ọ̀fẹ́ Ọlọ́run sì ń bẹ lára rẹ̀.

Ọ̀dọ́mọkùnrin Jesu ni tẹmpili

412.41: De 16.1-8; Ek 23.15.Àwọn òbí rẹ̀ a sì máa lọ sí Jerusalẹmu ní ọdọọdún sí àjọ ìrékọjá. 42Nígbà tí ó sì di ọmọ ọdún méjìlá, wọ́n gòkè lọ sí Jerusalẹmu gẹ́gẹ́ bí ìṣe àjọ náà. 43Nígbà tí ọjọ́ wọn sì pé bí wọ́n ti ń padà bọ̀, ọmọ náà, Jesu dúró lẹ́yìn ní Jerusalẹmu; Josẹfu àti ìyá rẹ̀ kò mọ̀. 44Ṣùgbọ́n wọ́n ṣe bí ó wà ní ẹ̀gbẹ́ èrò, wọ́n rin ìrìn ọjọ́ kan; wọ́n wá a kiri nínú àwọn ará àti àwọn ojúlùmọ̀ wọn. 45Nígbà tí wọn kò sì rí i, wọ́n padà sí Jerusalẹmu, wọ́n ń wá a kiri. 46Ó sì ṣe, lẹ́yìn ọjọ́ mẹ́ta wọ́n rí i nínú tẹmpili ó jókòó ní àárín àwọn olùkọ́ni, ó ń gbọ́ tiwọn, ó sì ń bi wọ́n léèrè. 47Ẹnu sì ya gbogbo àwọn tí ó gbọ́ ọ̀rọ̀ rẹ̀ fún òye àti ìdáhùn rẹ̀. 482.48: Mk 3.31-35.Nígbà tí wọ́n sì rí i, háà ṣe wọ́n, ìyá rẹ̀ sì bi í pé, “Ọmọ, èéṣe tí ìwọ fi ṣe wá bẹ́ẹ̀? Sá wò ó, baba rẹ̀ àti èmi ti ń fi ìbànújẹ́ wá ọ kiri.”

49Ó sì dáhùn wí fún wọn pé, “Èéṣe tí ẹ̀yin fi ń wá mi kiri? Ẹ̀yin kò mọ̀ pé èmi kò lè ṣàìmá wà níbi iṣẹ́ Baba mi?” 50Ọ̀rọ̀ tí o sọ kò sì yé wọn.

512.51: Lk 2.19.Ó sì bá wọn sọ̀kalẹ̀ lọ sí Nasareti, sì fi ara balẹ̀ fún wọn, ṣùgbọ́n ìyá rẹ̀ pa gbogbo nǹkan wọ̀nyí mọ́ nínú ọkàn rẹ̀. 522.52: Lk 1.80; 2.40.Jesu sì ń pọ̀ ní ọgbọ́n, sì ń dàgbà, ó sì wà ní ojúrere ní ọ̀dọ̀ Ọlọ́run àti ènìyàn.

Священное Писание

Лука 2:1-52

Рождение Исы Масиха

1В те дни император Август2:1 Август был римским императором с 27 г. до н. э. до 14 г. н. э. издал указ о проведении переписи по всей Римской империи. 2Это была первая перепись, она проводилась в то время, когда Сирией управлял Квириний2:2 Квириний, вероятно, был римским чиновником или полководцем, который проводил эту первую перепись в Сирии, длившуюся с 11 по 4 гг. до н. э., а во время второй переписи с 6 по 9 гг. н. э. он был римским наместником.. 3Поэтому каждый отправился в свой город для регистрации. 4Юсуф тоже пошёл из галилейского города Назарета в Иудею, в город Давуда, называемый Вифлеем, потому что он был потомком царя Давуда. 5Он отправился на перепись вместе с Марьям, которая была с ним обручена и ожидала ребёнка. 6В Вифлееме у Марьям подошло время родов, 7и она родила своего первенца, запеленала Его и положила в кормушку для скота, потому что для них не нашлось места в гостинице2:7 Или: «в комнате для гостей»..

Ангелы возвещают пастухам радостную весть

8Неподалёку были пастухи, которые жили в поле и стерегли ночью своё стадо. 9Вдруг перед ними предстал ангел от Вечного, окружённый сиянием славы Вечного. Пастухи очень испугались, 10но ангел сказал им:

– Не бойтесь. Я пришёл сообщить вам весть, что принесёт великую радость всему народу! 11Сегодня в городе Давуда родился ваш Спаситель2:11 Спаситель – ср. Ис. 43:11; Ос. 13:4. – Масих2:11 Масих (переводится как «Помазанник») – праведный Царь и Освободитель, Спаситель, обещанный Всевышним ещё в Таурате, Забуре и Книге Пророков., Повелитель! 12Вот вам знак: вы найдёте младенца, запелёнатого и лежащего в кормушке.

13И вдруг к ангелу присоединилось многочисленное небесное воинство, славившее Всевышнего и восклицавшее:

14– Хвала Всевышнему в вышине небес!

А на земле мир тем людям, к которым Он благоволит!

15Когда ангелы вернулись на небеса, пастухи сказали друг другу:

– Пойдём в Вифлеем и посмотрим, что там произошло, о чём это нам объявил Вечный?

16Они поспешили туда и нашли Марьям, Юсуфа и младенца, лежащего в кормушке для скота. 17Когда они Его увидели, то рассказали всё, что им было сказано об этом младенце. 18Все, кто слушал, удивлялись рассказу пастухов, 19а Марьям всё запоминала и размышляла об этом. 20Пастухи возвратились, прославляя и восхваляя Всевышнего за всё, что они видели и слышали: всё оказалось точно так, как им и было сказано.

Обрезание, наречение имени и посвящение Исы Масиха Всевышнему

21На восьмой день, когда пришло время совершить над Ним обряд обрезания, Его назвали Иса – имя, которое ангел дал Ему ещё до того, как Он был зачат. 22Когда закончилось время очищения, предписанное Законом Мусы2:22 По Закону очищение женщины завершалось на сороковой день после рождения сына (см. Лев. 12:2-8)., Марьям и Юсуф понесли младенца в Иерусалим, чтобы посвятить Его Вечному, 23потому что в Законе Вечного написано: «Каждый первенец мужского пола должен быть посвящён Вечному»2:23 См. Исх. 13:2, 12, 15.. 24Они должны были также по Закону Вечного принести в жертву пару горлиц или двух молодых голубей2:24 См. Лев. 12:6-8..

Благословение и пророчество Шимона

25В Иерусалиме в это время был человек, которого звали Шимон. Он был праведен и благочестив и с надеждой ожидал Того, Кто принесёт утешение для Исраила, и на нём был Святой Дух. 26Святой Дух открыл ему, что он не умрёт, пока не увидит Масиха, посланного Вечным. 27Ведомый Святым Духом, Шимон пришёл в храм, и когда родители принесли младенца Ису, чтобы совершить над Ним то, что было установлено Законом, 28Шимон взял Его на руки и прославил Всевышнего, сказав:

29– Владыка! Теперь, как Ты и обещал,

Ты отпускаешь Своего раба с миром,

30потому что мои глаза увидели спасение Твоё,

31которое Ты приготовил перед лицом всех народов,

32свет откровения язычникам

и славу народа Твоего, Исраила!2:32 См. Ис. 42:6; 49:6.

33Отец и мать удивлялись тому, что было сказано об Исе. 34Потом Шимон благословил их и сказал Марьям, матери ребёнка:

– Это дитя будет причиной падения и возвышения для многих в Исраиле и станет знамением от Всевышнего, которое будет многими отвергаемо, – 35да и тебе самой меч пронзит душу. Через всё это откроются тайные мысли многих людей.

36Там находилась также пророчица Ханна, дочь Пануила, из рода Ашира. Она была в глубокой старости. Ханна прожила семь лет со своим мужем, 37а всю остальную жизнь она жила вдовой. Ей было восемьдесят четыре года2:37 Или: «Она была вдовой восемьдесят четыре года».. Она никогда не покидала храма, день и ночь служа Всевышнему постами и молитвами. 38Подойдя в этот момент к тем, кто принёс младенца, она возблагодарила Всевышнего и говорила о ребёнке всем ожидавшим избавления для Иерусалима.

39Когда родители Исы сделали всё, что предписывал Закон Вечного, они возвратились в Галилею, в свой родной город Назарет. 40Ребёнок рос и набирался сил и мудрости, и Всевышний был благосклонен к Нему.

Двенадцатилетний Иса в храме

41Каждый год на праздник Освобождения2:41 Праздник Освобождения – этот праздник отмечался исключительно в Иерусалиме в память об избавлении иудейского народа под руководством пророка Мусы из Египетского рабства (см. Исх. 12; 13:17-22; 14; Втор. 16:1-8). родители Исы ходили в Иерусалим. 42Когда Ему было двенадцать лет, они, как обычно, пошли на праздник. 43После окончания праздника, когда все возвращались домой, мальчик Иса остался в Иерусалиме, но Его родители об этом не знали. 44Полагая, что Он идёт среди других путников, они после целого дня пути стали искать Его среди родственников и знакомых. 45Не найдя, они возвратились в Иерусалим, чтобы искать там. 46Через три дня они нашли мальчика в храме. Он сидел среди учителей, слушал их и задавал вопросы. 47Все, кто Его слышал, поражались Его пониманию и Его ответам. 48Родители были изумлены, увидев Его там.

– Сынок, почему Ты так с нами поступил? – спросила Его мать. – Твой отец и я беспокоились и искали Тебя.

49– Зачем же вы Меня искали? – спросил Он. – Разве вы не знали, что Я должен быть в доме Отца Моего?

50Но они не поняли, о чём Он им говорил. 51Он возвратился с ними в Назарет и был послушен им. Но всё происшедшее Его мать хранила в своей памяти.

52Иса взрослел и становился мудрее. Его любили и люди, и Всевышний2:52 Ср. 1 Цар. 2:26..