Lefitiku 4 – YCB & NSP

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Lefitiku 4:1-35

Ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀

1Olúwa sọ fún Mose pé, 24.2-12: Nu 15.27-29.“Sọ fún àwọn ọmọ Israẹli pé, ‘Bí ẹnìkan bá ṣẹ̀ láìmọ̀, tí ó ṣe ohun tí kò yẹ kó ṣe sí ọ̀kan nínú àwọn òfin Olúwa.

3“ ‘Bí àlùfáà tí a fi òróró yàn bá ṣẹ̀, tí ó sì mú ẹ̀bi wá sórí àwọn ènìyàn, ó gbọdọ̀ mú ọmọ akọ màlúù tí kò lábùkù wá fún Olúwa gẹ́gẹ́ bí ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ fún ẹ̀ṣẹ̀ tí ó ṣẹ̀. 4Kí ó mú ọ̀dọ́ màlúù wá síwájú Olúwa ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé. Kí ó gbé ọwọ́ rẹ̀ lé e lórí, kí ó sì pa á níwájú Olúwa. 5Kí àlùfáà tí a fi òróró yàn mú díẹ̀ nínú ẹ̀jẹ̀ akọ màlúù, kí ó sì gbé e lọ sínú àgọ́ ìpàdé. 6Kí ó ti ìka bọ inú ẹ̀jẹ̀ náà kí ó sì wọ́n díẹ̀ nínú rẹ̀ ní ẹ̀ẹ̀méje níwájú Olúwa, níwájú aṣọ títa ibi mímọ́. 7Àlùfáà yóò tún mú díẹ̀ nínú ẹ̀jẹ̀ náà sórí ìwo pẹpẹ tùràrí tó wà níwájú Olúwa nínú àgọ́ ìpàdé. Kí ó da gbogbo ẹ̀jẹ̀ akọ màlúù tókù sí ìsàlẹ̀ pẹpẹ ẹbọ sísun ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé. 8Kí ó yọ gbogbo ọ̀rá tí ń bẹ nínú akọ màlúù ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ náà ọ̀rá tí ó bo nǹkan inú àti gbogbo ohun tó so mọ́ wọn. 9Kíndìnrín méjèèjì pẹ̀lú ọ̀rá wọn tí ń bẹ lẹ́bàá ìhà àti ọ̀rá tí ó bo ẹ̀dọ̀, kí ó yọ ọ́ pẹ̀lú kíndìnrín. 10Gẹ́gẹ́ bí a ṣe ń yọ ọ̀rá kúrò lára màlúù tí a fi rú ẹbọ àlàáfíà; àlùfáà yóò sì sun wọ́n lórí pẹpẹ ẹbọ sísun. 11Ṣùgbọ́n awọ màlúù àti gbogbo ara rẹ̀, àti ẹsẹ̀, gbogbo nǹkan inú àti ìgbẹ́ rẹ̀. 12Èyí túmọ̀ sí pé gbogbo ìyókù akọ màlúù náà ni kí ẹ gbé jáde síta lẹ́yìn ibùdó sí ibi tí a sọ di mímọ́ níbi tí à ń da eérú sí, kí ẹ sì sun wọ́n lórí iná igi, níbi eérú tí a kójọ.

134.13-21: Nu 15.22-26.“ ‘Bí gbogbo àpapọ̀ ènìyàn Israẹli bá ṣèèṣì ṣẹ̀, tí wọ́n sì ṣe ohun tí kò yẹ kí wọ́n ṣe sí ọ̀kan nínú àwọn òfin Olúwa, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé àpapọ̀ ènìyàn náà kò mọ̀ sí ọ̀rọ̀ náà, wọ́n jẹ̀bi. 14Nígbà tí wọ́n bá mọ̀, gbogbo ìjọ ènìyàn yóò mú akọ màlúù wá sí àgọ́ ìpàdé gẹ́gẹ́ bí ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀. 15Kí àwọn àgbàgbà ìjọ Israẹli gbé ọwọ́ lórí akọ ọmọ màlúù náà níwájú Olúwa. 16Kí àlùfáà tí a fi òróró yàn sì mú díẹ̀ lára ẹ̀jẹ̀ akọ ọmọ màlúù náà wá sínú àgọ́ ìpàdé. 17Kí ó ti ìka rẹ̀ bọ inú ẹ̀jẹ̀ náà kí ó sì wọn ní ẹ̀ẹ̀méje níwájú Olúwa níbi aṣọ títa ẹnu-ọ̀nà. 18Kí ó sì mú díẹ̀ nínú ẹ̀jẹ̀ náà sórí ìwo pẹpẹ tó wà níwájú Olúwa nínú àgọ́ ìpàdé. Ìyókù ẹ̀jẹ̀ náà ni kí ó dà sí ìsàlẹ̀ pẹpẹ ẹbọ sísun ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé. 19Kí ó yọ gbogbo ọ̀rá kúrò lára rẹ̀, kí ó sì sun ún lórí pẹpẹ. 20Kí ó sì ṣe akọ ọmọ màlúù yìí gẹ́gẹ́ bí ó ṣe ṣe akọ màlúù tó wà fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀. Báyìí ni àlùfáà yóò ṣe ṣe ètùtù fún wọn, á ó sì dáríjì wọ́n. 21Lẹ́yìn náà ni yóò sun màlúù yìí lẹ́yìn ibùdó, yóò sì sun ún gẹ́gẹ́ bó ṣe sun màlúù àkọ́kọ́. Èyí ni ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ fún gbogbo ìjọ ènìyàn Israẹli.

22“ ‘Bí olórí kan bá ṣèèṣì ṣẹ̀ láìmọ̀ tí ó sì ṣe ohun tí kò yẹ kí ó ṣe sí ọ̀kan nínú àwọn òfin Olúwa Ọlọ́run rẹ̀, ó jẹ̀bi. 23Nígbà tí a bá sì sọ ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ fún un, ó gbọdọ̀ mú akọ ewúrẹ́ tí kò ní àbùkù wá gẹ́gẹ́ bí ẹbọ rẹ̀. 24Kí ó gbé ọwọ́ rẹ̀ lórí ewúrẹ́ náà, kí ó sì pa á níbi tí wọ́n ti ń pa ẹran ẹbọ sísun níwájú Olúwa. Ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ ni. 25Lẹ́yìn èyí, kí àlùfáà ti ìka rẹ̀ bọ inú ẹ̀jẹ̀ ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ náà, kí ó fi sí orí ìwo pẹpẹ ẹbọ sísun, kí ó sì da ẹ̀jẹ̀ yòókù sí ìsàlẹ̀ pẹpẹ. 26Kí ó sun gbogbo ọ̀rá rẹ̀ lórí pẹpẹ bí ó ṣe sun ọ̀rá ọrẹ àlàáfíà. Báyìí ní àlùfáà yóò ṣe ètùtù fún ẹ̀ṣẹ̀ ọkùnrin náà, a ó sì dáríjì í.

274.27-31: Nu 15.27,28.“ ‘Bí ènìyàn nínú àwọn ará ìlú bá ṣèèṣì ṣẹ̀ láìmọ̀ tí ó sì ṣe ohun tí kò yẹ sí ọ̀kan nínú àwọn òfin Olúwa, ó jẹ̀bi. 28Nígbà tí a bá sọ ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ fún un, ó gbọdọ̀ mú abo ewúrẹ́ tí kò ní àbùkù wá gẹ́gẹ́ bí ẹbọ fún ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀. 29Kí ó gbé ọwọ́ rẹ̀ lórí ewúrẹ́ ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ náà, kí ó sì pa á níbi ẹbọ sísun. 30Àlùfáà yóò sì ti ìka rẹ̀ bọ́ ẹ̀jẹ̀ náà, yóò fi sí orí ìwo pẹpẹ ẹbọ sísun, kí ó sì da ìyókù ẹ̀jẹ̀ náà sí ìsàlẹ̀ pẹpẹ. 31Kí ó yọ gbogbo ọ̀rá ẹran náà gẹ́gẹ́ bó ṣe yọ ọ̀rá ẹran fún ọrẹ àlàáfíà. Kí àlùfáà sì sun ọ̀rá yìí lórí pẹpẹ bí òórùn dídùn sí Olúwa. Báyìí ni àlùfáà yóò ṣe ètùtù fún ẹni náà, a ó sì dáríjì í.

32“ ‘Bí ó bá mú ọ̀dọ́-àgùntàn wá gẹ́gẹ́ bí ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀, kí ó mú abo tí kò lábùkù. 33Kí ó gbé ọwọ́ rẹ̀ lé e lórí, kí ó sì pa á fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ níbi tí wọ́n ti ń pa ẹran ẹbọ sísun. 34Àlùfáà yóò sì ti ìka rẹ̀ bọ inú ẹ̀jẹ̀ ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ náà, yóò sì fi sí orí ìwo pẹpẹ ẹbọ sísun, yóò sì da ìyókù ẹ̀jẹ̀ náà sí ìsàlẹ̀ pẹpẹ. 35Kí ó yọ gbogbo ọ̀rá rẹ̀ bó ti yọ ọ̀rá lára ọ̀dọ́-àgùntàn ọrẹ àlàáfíà, àlùfáà yóò sì sun ún ní orí pẹpẹ, lórí ọrẹ tí a fi iná sun sí Olúwa. Báyìí ni àlùfáà yóò ṣe ètùtù fún ẹni náà, nítorí ẹ̀ṣẹ̀ tí ó sẹ̀, a ó sì dáríjì í.

New Serbian Translation

3. Мојсијева 4:1-35

Жртве за грех

1Господ рече Мојсију: 2„Говори Израиљцима и реци им: ’Када се неко нехотице огреши о једну од заповести Господњих чинећи што је забрањено:

3Ако згреши помазани свештеник, и тиме учини да грех падне на народ, нека за грех који је починио принесе из крда јунца без мане Господу на жртву за грех. 4Нека доведе јунца пред Господа, код улаза у Шатор од састанка; нека положи руку на јунчеву главу, те закоље јунца пред Господом. 5Онда помазани свештеник нека узме нешто јунчеве крви и донесе је у Шатор од састанка. 6Затим нека свештеник умочи прст у крв и делом крви пошкропи седам пута пред Господом испред завесе Светиње. 7Потом свештеник нека намаже нешто крви на рогове жртвеника за паљење када пред Господом, који се налази у Шатору од састанка. Сву осталу крв нека излије на подножје жртвеника за жртве свеспалнице, који је код улаза у Шатор од састанка. 8Онда нека извади све сало из јунца, жртве за грех, сало које покрива црева и све сало које је око изнутрица. 9А бубреге и сало што је око њих и на слабинама, те мрежицу што је на јетри, нека уклони заједно с бубрезима, 10као што се уклања из вола, жртве мира. Нека их затим свештеник спали на жртвенику за жртве свеспалнице. 11А јунчеву кожу са свим његовим телом, главом и ногама, утробом и балегом – 12све што остане од јунца – нека однесе изван табора на чисто место, где се просипа пепео, и нека га спали на дрвима; где се просипа пепео, тамо нека буде спаљен.

13Ако сав збор Израиљев нехотице згреши, а збору остане непознато у чему је ствар, то јест, ако прекрше коју од Господњих заповести чинећи што је забрањено, и тако постану криви, 14онда, кад се дозна за грех који су учинили, нека збор принесе из крда једног јунца на жртву за грех. Нека га доведу пред Шатор од састанка, 15а старешине заједнице, нека ту, пред Господом, положе руке на јунчеву главу, па нека закољу јунца пред Господом. 16Затим нека помазани свештеник донесе нешто јунчеве крви у Шатор од састанка. 17Онда нека свештеник умочи прст у крв и нека пошкропи седам пута пред Господом испред завесе. 18Са нешто крви нека помаже рогове жртвеника који стоји пред Господом у Шатору од састанка. Сву осталу крв нека излије на подножје жртвеника за жртве свеспалнице, који је код улаза у Шатор од састанка. 19А све сало нека извади из јунца и нека га спали на жртвенику. 20Са јунцем нека поступи онако како је поступио с јунцем жртвом за грех. Кад свештеник изврши обред откупљења над њима, биће им опроштено. 21Затим нека изнесе преосталог јунца изван табора, и нека га спали као што је спалио првог јунца. То је жртва за грех за збор.

22Ако кнез нехотице згреши и прекрши једну од заповести Господа, Бога свога, чинећи што је забрањено, и тако постане крив, 23или му укажу на грех који је учинио – нека принесе на жртву мушко јаре без мане. 24Нека положи руку на главу јарета и нека га закоље на месту где се кољу жртве свеспалнице пред Господом. То је жртва за грех. 25Затим нека свештеник узме на прст нешто крви од жртве за грех и нека је стави на рогове жртвеника за жртве свеспалнице. Сву осталу крв нека излије на подножје жртвеника за жртве свеспалнице. 26А све сало нека спали на жртвенику, као што се пали сало жртве мира. Кад свештеник изврши над њим обред откупљења, биће му опроштено.

27Ако неко из народа у земљи нехотице згреши и прекрши једну од Господњих заповести чинећи што је забрањено и тако постане крив, 28или му укажу на грех који је починио – нека за грех који је починио принесе на жртву женско јаре без мане. 29Затим нека положи руку на главу жртве за грех, и нека је закоље на месту за жртве свеспалнице. 30Онда свештеник нека узме нешто од њене крви на прст, па нека стави на рогове жртвеника за жртве свеспалнице. Сву осталу крв нека излије на подножје жртвеника. 31А све њено сало нека извади, као што се вади сало из жртве мира, а свештеник нека га спали на жртвенику на угодан мирис Господу. Кад свештеник изврши над њим обред откупљења, биће му опроштено.

32Ако доводи јагње као жртву за грех, нека доведе женско јагње без мане. 33Затим нека положи руку на главу жртве за грех и нека је закоље на месту за жртве свеспалнице. 34Тада свештеник нека узме нешто од њене крви на прст и нека је стави на рогове жртвеника за жртве свеспалнице. Сву осталу крв нека излије на подножје жртвеника. 35А све њено сало нека извади, као што се вади сало из жртве мира, а свештеник нека га спали на жртвенику поврх жртава које се пале Господу. Кад свештеник изврши над њим обред откупљења за грех који је учинио, биће му опроштено.