Gẹnẹsisi 1 – YCB & NIRV

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Gẹnẹsisi 1:1-31

Ìbẹ̀rẹ̀ dídá ayé

11.1: Jh 1.1.Ní ìbẹ̀rẹ̀ ohun gbogbo Ọlọ́run dá àwọn ọ̀run àti ayé. 2Ayé sì wà ní rúdurùdu, ó sì ṣófo, òkùnkùn sì wà lójú ibú omi, Ẹ̀mí Ọlọ́run sì ń rábàbà lójú omi.

31.3: 2Kọ 4.6.Ọlọ́run sì wí pé, “Jẹ́ kí ìmọ́lẹ̀ kí ó wà,” ìmọ́lẹ̀ sì wà. 4Ọlọ́run rí i pé ìmọ́lẹ̀ náà dára, ó sì ya ìmọ́lẹ̀ náà sọ́tọ̀ kúrò lára òkùnkùn. 5Ọlọ́run sì pe ìmọ́lẹ̀ náà ní “ọ̀sán,” àti òkùnkùn ní “òru.” Àṣálẹ́ àti òwúrọ̀ sì jẹ́ ọjọ́ kìn-ín-ní.

61.6-8: 2Pt 3.5.Ọlọ́run sì wí pé, “Jẹ́ kí òfúrufú kí ó wà ní àárín àwọn omi, láti pààlà sí àárín àwọn omi.” 7Ọlọ́run sì dá òfúrufú láti ya omi tí ó wà ní òkè òfúrufú kúrò lára omi tí ó wà ní orí ilẹ̀. Ó sì rí bẹ́ẹ̀. 8Ọlọ́run sì pe òfúrufú ní “ọ̀run.” Àṣálẹ́ àti òwúrọ̀ sì jẹ́ ọjọ́ kejì.

9Ọlọ́run sì wí pé, “Jẹ́ kí omi abẹ́ ọ̀run wọ́ papọ̀ sí ojú kan, kí ilẹ̀ gbígbẹ sì farahàn.” Ó sì rí bẹ́ẹ̀. 10Ọlọ́run sì pe ilẹ̀ gbígbẹ náà ní “ilẹ̀,” àti àpapọ̀ omi ní “òkun.” Ọlọ́run sì rí i wí pé ó dára.

11Ọlọ́run sì wí pé, “Jẹ́ kí ilẹ̀ kí ó hu ọ̀gbìn: ewéko ti yóò máa mú èso wá àti igi tí yóò máa so èso ní irú tirẹ̀, tí ó ní irúgbìn nínú.” Ó sì rí bẹ́ẹ̀. 12Ilẹ̀ sì hù ọ̀gbìn: ewéko tí ó ń so èso ní irú tirẹ̀, àti igi tí ń so èso, tí ó ní irúgbìn nínú ní irú tirẹ̀. Ọlọ́run sì ri pé ó dára. 13Àṣálẹ́ àti òwúrọ̀ sì jẹ́ ọjọ́ kẹta.

14Ọlọ́run sì wí pé, “Jẹ́ kí ìmọ́lẹ̀ kí ó wà ní ojú ọ̀run, láti pààlà sí àárín ọ̀sán àti òru, kí wọn ó sì máa wà fún àmì láti mọ àwọn àsìkò, àti àwọn ọjọ́ àti àwọn ọdún. 15Kí wọn ó jẹ́ ìmọ́lẹ̀ ní ojú ọ̀run láti tan ìmọ́lẹ̀ sí orí ilẹ̀.” Ó sì rí bẹ́ẹ̀. 16Ọlọ́run dá ìmọ́lẹ̀ ńlá ńlá méjì, ìmọ́lẹ̀ tí ó tóbi láti ṣe àkóso ọ̀sán àti ìmọ́lẹ̀ tí ó kéré láti ṣe àkóso òru. Ó sì dá àwọn ìràwọ̀ pẹ̀lú. 17Ọlọ́run sì ṣe wọ́n lọ́jọ̀ sí ojú ọ̀run láti máa tan ìmọ́lẹ̀ si orí ilẹ̀, 18láti ṣàkóso ọ̀sán àti òru àti láti pààlà sí àárín ìmọ́lẹ̀ àti òkùnkùn. Ọlọ́run sì rí i pé ó dára. 19Àṣálẹ́ àti òwúrọ̀ sì jẹ́ ọjọ́ kẹrin.

20Ọlọ́run sì wí pé, “Jẹ́ kí omi kí ó kún fún àwọn ohun alààyè, kí àwọn ẹyẹ kí ó sì máa fò ní òfúrufú.” 21Nítorí náà Ọlọ́run dá àwọn ẹ̀dá alààyè ńlá ńlá sí inú òkun, àwọn ohun ẹlẹ́mìí àti àwọn ohun tí ń rìn ní onírúurú tiwọn, àti àwọn ẹyẹ abìyẹ́ ní onírúurú tiwọn. Ọlọ́run sì rí i pé ó dára. 22Ọlọ́run súre fún wọn, ó sì wí pé, “Ẹ máa bí sí i, ẹ sì máa pọ̀ sí i, ẹ kún inú omi òkun, kí àwọn ẹyẹ náà sì máa pọ̀ sí i ní orí ilẹ̀.” 23Àṣálẹ́ àti òwúrọ̀ sì jẹ́ ọjọ́ karùn-ún.

24Ọlọ́run sì wí pé, “Kí ilẹ̀ kí ó mú ohun alààyè jáde ní onírúurú wọn: ẹran ọ̀sìn, àwọn ohun afàyàfà àti àwọn ẹran inú igbó, ọ̀kọ̀ọ̀kan ní irú tirẹ̀.” Ó sì rí bẹ́ẹ̀. 25Ọlọ́run sì dá ẹranko inú igbó àti ẹran ọ̀sìn gbogbo ní irú tirẹ̀ àti gbogbo ohun alààyè tí ń rìn ní ilẹ̀ ní irú tirẹ̀. Ọlọ́run sì rí i pé ó dára.

261.26,27: Gẹ 5.1; Mt 19.4; Mk 10.6; Kl 3.10; Jk 3.9.Lẹ́yìn náà ni Ọlọ́run wí pé, “Ẹ jẹ́ kí a dá ènìyàn ní àwòrán ara wa, gẹ́gẹ́ bí àwa ti rí, kí wọn kí ó jẹ ọba lórí ẹja òkun, ẹyẹ ojú ọ̀run, ẹran ọ̀sìn, gbogbo ilẹ̀ àti lórí ohun gbogbo tí ń rìn lórí ilẹ̀.”

271.27,28: Gẹ 5.1,2.1.27: Mt 19.4; Mk 10.6.Nítorí náà, Ọlọ́run dá ènìyàn ní àwòrán ara rẹ̀,

ní àwòrán Ọlọ́run ni ó dá a,

akọ àti abo ni ó dá wọn.

28Ọlọ́run sì súre fún wọn, Ọlọ́run sì wí fún wọn pé, “Ẹ máa bí sí i, kí ẹ sì máa pọ̀ sí i, kí ẹ sì gbilẹ̀, kí ẹ ṣe ìkápá ayé. Ẹ ṣe àkóso àwọn ẹja inú òkun, ẹyẹ ojú ọ̀run àti gbogbo ẹ̀dá alààyè tí ó ń rìn ní orí ilẹ̀.”

29Nígbà náà ni Ọlọ́run wí pé, “Mo fi gbogbo ohun ọ̀gbìn tí ń so èso fún un yín bí oúnjẹ àti àwọn igi eléso pẹ̀lú. Gbogbo rẹ̀ yóò jẹ́ oúnjẹ fún un yín. 30Àti fún àwọn ẹranko inú igbó àti ẹyẹ ojú ọ̀run àti àwọn ohun afàyàfà, gbogbo ohun tó ní èémí ìyè nínú ni mo fi ewéko fún bí oúnjẹ.” Ó sì rí bẹ́ẹ̀.

31Ọlọ́run sì rí àwọn ohun gbogbo tí ó dá, ó dára gidigidi. Àṣálẹ́ àti òwúrọ̀ sì jẹ́ ọjọ́ kẹfà.

New International Reader’s Version

Genesis 1:1-31

The Beginning

1In the beginning, God created the heavens and the earth. 2The earth didn’t have any shape. And it was empty. There was darkness over the surface of the waves. At that time, the Spirit of God was hovering over the waters.

3God said, “Let there be light.” And there was light. 4God saw that the light was good. He separated the light from the darkness. 5God called the light “day.” He called the darkness “night.” There was evening, and there was morning. It was day one.

6God said, “Let there be a huge space between the waters. Let it separate water from water.” 7And that’s exactly what happened. God made the huge space between the waters. He separated the water under the space from the water above it. 8God called the huge space “sky.” There was evening, and there was morning. It was day two.

9God said, “Let the water under the sky be gathered into one place. Let dry ground appear.” And that’s exactly what happened. 10God called the dry ground “land.” He called all the water that was gathered together “seas.” And God saw that it was good.

11Then God said, “Let the land produce plants. Let them produce their own seeds. And let there be trees on the land that grow fruit with seeds in it. Let each kind of plant or tree have its own kind of seeds.” And that’s exactly what happened. 12So the land produced plants. Each kind of plant had its own kind of seeds. And the land produced trees that grew fruit with seeds in it. Each kind of tree had its own kind of seeds. God saw that it was good. 13There was evening, and there was morning. It was day three.

14God said, “Let there be lights in the huge space of the sky. Let them separate the day from the night. Let the lights set the times for the holy celebrations and the days and the years. 15Let them be lights in the huge space of the sky to give light on the earth.” And that’s exactly what happened. 16God made two great lights. He made the larger light to rule over the day and the smaller light to rule over the night. He also made the stars. 17God put the lights in the huge space of the sky to give light on the earth. 18He put them there to rule over the day and the night. He put them there to separate light from darkness. God saw that it was good. 19There was evening, and there was morning. It was day four.

20God said, “Let the seas be filled with living things. Let birds fly above the earth across the huge space of the sky.” 21So God created the great sea creatures. He created every kind of living thing that fills the seas and moves about in them. He created every kind of bird that flies. And God saw that it was good. 22God blessed them. He said, “Have little ones so that there will be many of you. Fill the water in the seas. Let there be more and more birds on the earth.” 23There was evening, and there was morning. It was day five.

24God said, “Let the land produce every kind of living creature. Let there be livestock, and creatures that move along the ground, and wild animals.” And that’s exactly what happened. 25God made every kind of wild animal. He made every kind of livestock. He made every kind of creature that moves along the ground. And God saw that it was good.

26Then God said, “Let us make human beings so that they are like us. Let them rule over the fish in the seas and the birds in the sky. Let them rule over the livestock and all the wild animals. And let them rule over all the creatures that move along the ground.”

27So God created human beings in his own likeness.

He created them to be like himself.

He created them as male and female.

28God blessed them. He said to them, “Have children so that there will be many of you. Fill the earth and bring it under your control. Rule over the fish in the seas and the birds in the sky. Rule over every living creature that moves along the ground.”

29Then God said, “I am giving you every plant on the face of the whole earth that produces its own seeds. I am giving you every tree that has fruit with seeds in it. All of them will be given to you for food. 30I am giving every green plant as food for all the land animals and for all the birds in the sky. I am also giving the plants to all the creatures that move along the ground. I am giving them to every living thing that breathes.” And that’s exactly what happened.

31God saw everything he had made. And it was very good. There was evening, and there was morning. It was day six.