Johanu 16 – YCB & BPH

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Johanu 16:1-33

1“Nǹkan wọ̀nyí ni mo ti sọ fún yín, kí a má ba à mú yín yapa kúrò. 216.2: Jh 9.22; Ap 26.9-11; Isa 66.5.Wọ́n ó yọ yín kúrò nínú Sinagọgu: àní, àkókò ń bọ̀, tí ẹnikẹ́ni tí ó bá pa yín, yóò rò pé òun ń ṣe ìsìn fún Ọlọ́run. 3Nǹkan wọ̀nyí ni wọ́n ó sì ṣe, nítorí tí wọn kò mọ Baba, wọn kò sì mọ̀ mí. 4Ṣùgbọ́n nǹkan wọ̀nyí ni mo ti sọ fún yín, pé nígbà tí wákàtí wọn bá dé, kí ẹ lè rántí wọn pé mo ti wí fún yín. Ṣùgbọ́n èmi kò sọ nǹkan wọ̀nyí fún yín láti ìpilẹ̀ṣẹ̀ wá, nítorí tí mo wà pẹ̀lú yín.

Iṣẹ́ Ẹ̀mí Mímọ́

516.5: Jh 7.33; 14.5.“Ṣùgbọ́n nísinsin yìí èmi ń lọ sọ́dọ̀ ẹni tí ó rán mi; kò sì sí ẹnìkan nínú yín tí ó bi mí lérè pé, ‘Níbo ni ìwọ ń lọ?’ 6Ṣùgbọ́n nítorí mo sọ nǹkan wọ̀nyí fún yín, ìbìnújẹ́ kún ọkàn yín. 716.7: Jh 14.16,26; 15.26.Ṣùgbọ́n òtítọ́ ni èmi ń sọ fún yín; àǹfààní ni yóò jẹ́ fún yín bí èmi bá lọ, nítorí bí èmi kò bá lọ, Olùtùnú kì yóò tọ̀ yín wá; ṣùgbọ́n bí mo bá lọ, èmi ó rán an sí yín. 8Nígbà tí òun bá sì dé, yóò fi òye yé aráyé ní ti ẹ̀ṣẹ̀, àti ní ti òdodo, àti ní ti ìdájọ́, 916.9: Jh 15.22.ní ti ẹ̀ṣẹ̀, nítorí tí wọn kò gbà mí gbọ́; 1016.10: Ap 3.14; 7.52; 1Pt 3.18.ní ti òdodo, nítorí tí èmi ń lọ sọ́dọ̀ Baba, ẹ̀yin kò sì mọ̀ mí. 1116.11: Jh 12.31.Ní ti ìdájọ́, nítorí tí a ti ṣe ìdájọ́ ọmọ-aládé ayé yìí.

12“Mo ní ohun púpọ̀ láti sọ fún yín pẹ̀lú, ṣùgbọ́n ẹ kò lè gbà wọ́n nísinsin yìí. 13Ṣùgbọ́n nígbà tí òun, àní Ẹ̀mí òtítọ́ náà bá dé, yóò tọ́ yín sí ọ̀nà òtítọ́ gbogbo, nítorí kì yóò sọ ti ara rẹ̀; ṣùgbọ́n ohunkóhun tí ó bá gbọ́, òun ni yóò máa sọ, yóò sì sọ ohun tí ń bọ̀ fún yín. 1416.14: Jh 7.39.Òun ó máa yìn mí lógo, nítorí tí yóò gbà nínú ti èmi, yóò sì máa sọ ọ́ fún yín. 15Ohun gbogbo tí Baba ní tèmi ni, nítorí èyí ni mo ṣe wí pé, òun ó gba nínú tèmi, yóò sì sọ ọ́ fún yín.

1616.16-24: Jh 14.18-24.“Nígbà díẹ̀, ẹ̀yin kì ó sì rí mi, àti nígbà díẹ̀ si, ẹ ó sì rí mi, nítorí tí èmi ń lọ sọ́dọ̀ Baba.”

Ìbànújẹ́ àwọn ọmọ-ẹ̀yìn yóò di ayọ̀

17Nítorí náà díẹ̀ nínú àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ ń bá ara wọn sọ pé, “Kín ni èyí tí o wí fún wa yìí, ‘Nígbà díẹ̀, ẹ̀yin ó sì rí mi, àti nígbà díẹ̀ ẹ̀wẹ̀, ẹ̀yin kì yóò rí mi, àti, nítorí tí èmi ń lọ sọ́dọ̀ Baba’?” 18Nítorí náà wọ́n wí pé, kín ni, nígbà díẹ̀? Àwa kò mọ̀ ohun tí ó wí.

19Jesu sá à ti mọ̀ pé, wọ́n ń fẹ́ láti bi òun léèrè, ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ̀yin ń bi ara yín léèrè ní ti èyí tí mo wí pé, nígbà díẹ̀, ẹ̀yin kì yóò sì rí mi, àti nígbà díẹ̀ si, ẹ̀yin ó sì rí mi? 2016.20: Jh 20.20.Lóòótọ́, lóòótọ́ ni mo wí fún yín pé, ẹ̀yin yóò máa sọkún ẹ ó sì máa pohùnréré ẹkún, ṣùgbọ́n àwọn aráyé yóò máa yọ̀: ṣùgbọ́n, ìbànújẹ́ yín yóò di ayọ̀. 2116.21: Isa 13.8; Ho 13.13; Mt 4.9; 1Tẹ 5.3.Nígbà tí obìnrin bá ń rọbí, a ní ìbìnújẹ́, nítorí tí wákàtí rẹ̀ dé: ṣùgbọ́n nígbà tí ó bá ti bí ọmọ náà tán, òun kì í sì í rántí ìrora náà mọ́, fún ayọ̀ nítorí a bí ènìyàn sí ayé. 22Nítorí náà ẹ̀yin ní ìbànújẹ́ nísinsin yìí, ṣùgbọ́n èmi ó tún rí yín, ọkàn yín yóò sì yọ̀, kò sì sí ẹni tí yóò gba ayọ̀ yín lọ́wọ́ yín. 23Àti ní ọjọ́ náà ẹ̀yin kì ó bi mí lérè ohunkóhun. Lóòótọ́, lóòótọ́ ni mo wí fún yín, ohunkóhun tí ẹ̀yin bá béèrè lọ́wọ́ Baba ní orúkọ mi, òhun ó fi fún yín. 2416.24: Jh 14.14; 15.11.Títí di ìsinsin yìí ẹ kò tí ì béèrè ohunkóhun ní orúkọ mi, ẹ béèrè, ẹ ó sì rí gbà, kí ayọ̀ yín kí ó lè kún.

2516.25: Jh 10.6; Mt 13.34.“Nǹkan wọ̀nyí ni mo fi òwe sọ fún yín: ṣùgbọ́n àkókò dé, nígbà tí èmi kì yóò fi òwe bá yín sọ̀rọ̀ mọ́, ṣùgbọ́n èmi ó sọ nípa ti Baba fún yín gbangba. 26Ní ọjọ́ náà, ẹ̀yin ó béèrè ní orúkọ mi, èmi kò sì wí fún yín pé, èmi ó béèrè lọ́wọ́ Baba fún yín. 27Nítorí tí Baba tìkára rẹ̀ fẹ́ràn yín, nítorí tí ẹ̀yin ti fẹ́ràn mi, ẹ sì ti gbàgbọ́ pé, lọ́dọ̀ Ọlọ́run ni èmi ti jáde wá. 28Mo ti ọ̀dọ̀ Baba jáde wá, mo sì wá sí ayé, àti nísinsin yìí mo fi ayé sílẹ̀, mo sì lọ sọ́dọ̀ Baba.”

29Àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ wí fún un pé, “Wò ó, nígbà yìí ni ìwọ ń sọ̀rọ̀ gbangba, ìwọ kò sì sọ ohunkóhun ní òwe. 30Nígbà yìí ni àwa mọ̀ pé, ìwọ mọ̀ ohun gbogbo, ìwọ kò ní kí a bi ọ́ léèrè: nípa èyí ni àwa gbàgbọ́ pé, lọ́dọ̀ Ọlọ́run ni ìwọ ti jáde wá.”

31Jesu dá wọn lóhùn pé, “Ẹ̀yin gbàgbọ́ wàyí? 3216.32: Jh 4.23; Mk 14.27; Sk 13.7.Kíyèsi i, wákàtí ń bọ̀, àní ó dé tan nísinsin yìí, tí a ó fọ́n yín ká kiri, olúkúlùkù sí ilé rẹ̀; ẹ ó sì fi èmi nìkan sílẹ̀, ṣùgbọ́n kì yóò sì ṣe èmi nìkan, nítorí tí Baba ń bẹ pẹ̀lú mi.

3316.33: Jh 14.27; 15.18; Ro 8.37; 2Kọ 2.14; If 3.21.“Nǹkan wọ̀nyí ni mo ti sọ fún yín tẹ́lẹ̀, kí ẹ̀yin kí ó lè ní àlàáfíà nínú mi. Nínú ayé, ẹ̀yin ó ní ìpọ́njú; ṣùgbọ́n ẹ tújúká; mo ti ṣẹ́gun ayé.”

Bibelen på hverdagsdansk

Johannesevangeliet 16:1-33

1Jeg siger det, før det sker, for at I ikke skal miste troen. 2I vil blive smidt ud af synagogen, ja, det vil komme så vidt, at de, der slår jer ihjel, vil mene, at de dermed tjener Gud. 3Og det vil de gøre, fordi de hverken kender min Far eller mig. 4Men når forfølgelserne kommer, så husk på, hvad jeg nu har sagt til jer. Jeg har ikke sagt det før, for jeg har hele tiden været hos jer.

Helligåndens opgave

5Nu skal jeg snart tilbage til ham, der sendte mig, og ingen af jer spørger mig længere, hvor jeg går hen. 6I er fyldt af sorg og uro på grund af det, jeg har fortalt jer, 7men I må tro mig, når jeg siger, at det er bedst for jer, at jeg går bort. Kun hvis jeg går bort, kan Vejlederen komme til jer, og når jeg er gået bort herfra, vil jeg sende ham til jer.

8Når Helligånden kommer, vil han afsløre folks forkerte opfattelse af synd, retfærdighed og dom. 9Deres synd er, at de ikke tror på mig. 10Det er retfærdigt, at jeg går til Faderen, og I derfor ikke længere kan se mig. 11Dommen består i, at denne verdens fyrste er dømt.

12Jeg har stadig meget at sige jer, som I ikke kan forstå endnu. 13Men når sandhedens Ånd kommer, vil han vejlede jer til hele sandheden. Han vil ikke fremføre sine egne meninger, men det, han hører mig sige, vil han give videre til jer, og han vil åbenbare for jer, hvad fremtiden bringer. 14Han vil ophøje og ære mig ved at tage imod det, jeg giver ham, og derefter åbenbare det for jer. 15Alt, hvad Faderen har, er også mit. Det er derfor jeg siger, at Helligånden vil tage imod det, jeg giver ham, og åbenbare det for jer.

Sorg skal vendes til glæde

16Snart ser I mig ikke mere, men lidt senere vil I se mig igen.” 17Da spurgte disciplene hinanden: „Hvad mener han med, at vi snart ikke skal se ham mere, men at vi så lidt senere får ham at se igen? Og hvad mener han med, at han skal gå til Faderen, 18og at det skal ske snart? Vi forstår det ikke.”

19Jesus var klar over, at de ønskede at spørge ham om det, så han sagde: „I spørger hinanden, hvad jeg mener med det, jeg sagde. 20Dét siger jeg jer: Denne verden vil glæde sig over det, der skal ske med mig—men I vil sørge og græde. Bagefter vil jeres sorg blive vendt til glæde. 21En kvinde glæder sig ikke til den smerte, der er forbundet med at føde, men når barnet er født, glemmer hun smerterne af glæde over, at et lille menneskebarn er kommet til verden. 22Det samme gælder jer. I er ikke glade lige nu, men vi skal ses igen, og da skal I opleve en glæde i hjertet, som ingen kan tage fra jer. 23Når den tid kommer, skal I ikke længere bede mig om noget, for I kan gå direkte til Faderen. Det siger jeg jer: Han vil give jer, hvad som helst I beder om i mit navn. 24Endnu har I ikke prøvet at bede om noget i mit navn. Bed i mit navn, og I skal få, så I kan blive fyldt af glæde.

Jesus har sejret over verden

25Indtil nu har jeg måttet tale til jer i billeder, men den tid kommer, hvor det ikke er nødvendigt længere. Da vil jeg tale klart til jer om Faderen. 26Når det sker, kan I også gå direkte til ham i mit navn. Det er ikke nødvendigt, at jeg går i forbøn for jer hos Faderen, 27for han elsker jer, fordi I elsker mig, og fordi I tror, at jeg er kommet fra ham. 28Da jeg kom til denne verden, kom jeg fra Faderen. Nu forlader jeg så denne verden og er på vej tilbage til Faderen.”

29Disciplene udbrød: „Nu taler du klart og ikke længere i billeder. 30Og nu forstår vi, at du ved alt, og at der ikke er grund til at stille spørgsmål ved det, du siger. Derfor tror vi på, at du er kommet fra Gud.”

31„Mon I nu også tror?” sagde Jesus. 32„Om ganske kort tid vil I være spredt for alle vinde, og jeg vil stå alene tilbage. Men jeg er ikke alene, for min Far er med mig. 33Jeg har sagt jer alt det her, for at I skal søge jeres fred hos mig. I denne verden vil I blive forfulgt, men vær ved godt mod, for jeg har sejret over verden!”