Johanu 12 – YCB & CARSA

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Johanu 12:1-50

A fi àmì òróró yàn Jesu ni Betani

112.1-8: Mt 26.6-13; Mk 14.3-9; Lk 7.37-38.Nítorí náà, nígbà tí àjọ ìrékọjá ku ọjọ́ mẹ́fà, Jesu wá sí Betani, níbi tí Lasaru wà, ẹni tí ó ti kú, tí Jesu jí dìde kúrò nínú òkú. 2Wọ́n sì ṣe àsè alẹ́ fún un níbẹ̀. Marta sì ń ṣe ìránṣẹ́, ṣùgbọ́n Lasaru jẹ́ ọ̀kan nínú àwọn tí ó jókòó níbi tábìlì rẹ̀. 3Nígbà náà ni Maria mú òróró ìkunra nadi, òsùwọ̀n lita kan, àìlábùlà, olówó iyebíye, ó sì ń fi kun Jesu ní ẹsẹ̀, ó sì ń fi irun orí rẹ̀ nu ẹsẹ̀ rẹ̀ nù. Ilé sì kún fún òórùn ìkunra náà.

412.4: Jh 6.71; 13.26.Nígbà náà ni ọ̀kan nínú àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀, Judasi Iskariotu, ọmọ Simoni ẹni tí yóò fi í hàn, wí pé, 5“Èéṣe tí a kò ta òróró ìkunra yìí ní ọ̀ọ́dúnrún owó idẹ kí a sì fi fún àwọn tálákà?” 612.6: Lk 8.3.Ṣùgbọ́n ó wí èyí, kì í ṣe nítorí tí ó náání àwọn tálákà; ṣùgbọ́n nítorí tí ó jẹ́ olè, òun ni ó ni àpò, a sì máa jí ohun tí a fi sínú rẹ̀ láti fi ran ara rẹ lọ́wọ́.

712.7: Jh 19.40.Nígbà náà ni Jesu wí pé, “Ẹ fi í sílẹ̀, ó ṣe é sílẹ̀ de ọjọ́ ìsìnkú mi. 8Nígbà gbogbo ni ẹ̀yin sá à ní tálákà pẹ̀lú yín; ṣùgbọ́n èmi ni ẹ kò ní nígbà gbogbo.”

9Nítorí náà, ìjọ ènìyàn nínú àwọn Júù ni ó mọ̀ pé ó wà níbẹ̀; wọ́n sì wá, kì í ṣe nítorí Jesu nìkan, ṣùgbọ́n kí wọn lè rí Lasaru pẹ̀lú, ẹni tí ó ti jí dìde kúrò nínú òkú. 1012.10: Mk 14.1.Ṣùgbọ́n àwọn olórí àlùfáà gbìmọ̀ kí wọn lè pa Lasaru pẹ̀lú, 11nítorí pé nípasẹ̀ rẹ̀ ni ọ̀pọ̀ nínú àwọn Júù jáde lọ, wọ́n sì gbà Jesu gbọ́.

Jesu gun kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ wọ Jerusalẹmu

1212.12-15: Mt 21.4-9; Mk 11.7-10; Lk 19.35-38.Ní ọjọ́ kejì nígbà tí ọ̀pọ̀ ènìyàn tí ó wá sí àjọ gbọ́ pé, Jesu ń bọ̀ wá sí Jerusalẹmu. 1312.13: Sm 118.25; Jh 1.49.Wọ́n mú imọ̀ ọ̀pẹ, wọ́n sì jáde lọ pàdé rẹ̀, wọ́n sì ń kígbe pé,

“Hosana!”

“Olùbùkún ni ẹni tí ń bọ̀ wá ní orúkọ Olúwa!”

“Olùbùkún ni ọba Israẹli!”

14Nígbà tí Jesu sì rí ọmọ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ kan, ó gùn ún; gẹ́gẹ́ bí a ti kọ̀wé pé,

1512.15: Sk 9.9.“Má bẹ̀rù, ọmọbìnrin Sioni;

wò ó, ọba rẹ ń bọ̀ wá,

o jókòó lórí ọmọ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́.”

1612.16: Mk 9.32; Jh 2.22.Nǹkan wọ̀nyí kò tètè yé àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀, ṣùgbọ́n nígbà tí a ṣe Jesu lógo, nígbà náà ni wọ́n rántí pé, a kọ̀wé nǹkan wọ̀nyí nípa rẹ̀ sí i.

17Nítorí náà, ìjọ ènìyàn tí ó wà lọ́dọ̀ rẹ̀ nígbà tí o pé Lasaru jáde nínú ibojì rẹ̀, tí ó sì jí i dìde kúrò nínú òkú, jẹ́rìí sí i. 18Nítorí èyí ni ìjọ ènìyàn sì ṣe lọ pàdé rẹ̀, nítorí tí wọ́n gbọ́ pé ó ti ṣe iṣẹ́ àmì yìí. 19Nítorí náà àwọn Farisi wí fún ara wọn pé, “Ẹ kíyèsi bí ẹ kò ti lè borí ní ohunkóhun? Ẹ wo bí gbogbo ayé ti ń wọ́ tọ̀ ọ́!”

Jesu sọ nípa ikú rẹ̀

2012.20: Jh 7.35; Ap 11.20.Àwọn Giriki kan sì wà nínú àwọn tí ó gòkè wá láti sìn nígbà àjọ, 2112.21: Jh 1.44; 6.5.Àwọn wọ̀nyí ni ó tọ Filipi wá, ẹni tí í ṣe ará Betisaida tí Galili, wọ́n sì ń béèrè lọ́wọ́ rẹ̀, pé, “Alàgbà, àwa ń fẹ́ rí Jesu!” 22Filipi wá, ó sì sọ fún Anderu; Anderu àti Filipi wá, wọ́n sì sọ fún Jesu.

2312.23: Jh 13.1; 17.1; Mk 14.35,41.Jesu sì dá wọn lóhùn pé, “Wákàtí náà dé, tí a ó ṣe Ọmọ Ènìyàn lógo. 2412.24: 1Kọ 15.36.Lóòótọ́, lóòótọ́ ni mo wí fún yín, bí kò ṣe pé alikama bá bọ́ sí ilẹ̀, tí ó bá sì kú, ó wà ní òun nìkan; ṣùgbọ́n bí ó bá kú, yóò sì so ọ̀pọ̀lọpọ̀ èso. 2512.25: Mt 10.39; Mk 8.35; Lk 9.24; 14.26.Ẹni tí ó bá fẹ́ ẹ̀mí rẹ̀ yóò sọ ọ́ nù; ẹni tí ó bá sì kórìíra ẹ̀mí rẹ̀ láyé yìí ni yóò sì pa á mọ́ títí ó fi di ìyè àìnípẹ̀kun. 26Bí ẹnikẹ́ni bá ń sìn mí, kí ó máa tọ̀ mí lẹ́yìn, àti pe níbi tí èmi bá wà, níbẹ̀ ni ìránṣẹ́ mi yóò wà pẹ̀lú, bí ẹnikẹ́ni bá ń sìn mí, òun ni Baba yóò bu ọlá fún.

2712.27: Jh 11.33; Mt 26.38; Mk 14.34.“Ní ìsinsin yìí ni a ń pọ́n ọkàn mi lójú; kín ni èmi ó sì wí? ‘Baba, gbà mí kúrò nínú wákàtí yìí’? Rárá, ṣùgbọ́n nítorí èyí ni mo ṣe wá sí wákàtí yìí. 2812.28: Mk 1.11; 9.7.Baba, ṣe orúkọ rẹ lógo!”

Nígbà náà ni ohùn kan ti ọ̀run wá, wí pé, “Èmi ti ṣe é lógo!” 29Nítorí náà ìjọ ènìyàn tí ó dúró níbẹ̀, tí wọ́n sì gbọ́ ọ, wí pé, “Àrá ń sán.” Àwọn ẹlòmíràn wí pé, “Angẹli kan ni ó ń bá a sọ̀rọ̀.”

30Jesu sì dáhùn wí pé, “Kì í ṣe nítorí mi ni ohùn yìí ṣe wá, bí kò ṣe nítorí yín. 3112.31: Jh 16.11; 2Kọ 4.4; Ef 2.2.Ní ìsinsin yìí ni ìdájọ́ ayé yìí dé: nísinsin yìí ni a ó lé aládé ayé yìí jáde. 3212.32: Jh 3.14; 8.28.Àti èmi, bí a bá gbé mi sókè kúrò ní ayé, èmi ó fa gbogbo ènìyàn sọ́dọ̀ ara mi!” 33Ṣùgbọ́n ó wí èyí, ó ń ṣe àpẹẹrẹ irú ikú tí òun yóò kú.

3412.34: Sm 110.4; Isa 9.7; El 37.25; Da 7.14.Nítorí náà àwọn ìjọ ènìyàn dá a lóhùn pé, “Àwa gbọ́ nínú òfin pé, Kristi wà títí láéláé, ìwọ ha ṣe wí pé, ‘A ó gbé Ọmọ Ènìyàn sókè’? Ta ni ó ń jẹ́ ‘Ọmọ Ènìyàn yìí’?”

3512.35: Jh 7.33; 9.4; Ef 5.8; 1Jh 2.11.Nígbà náà ni Jesu wí fún wọn pé, “Nígbà díẹ̀ sí i ni ìmọ́lẹ̀ wà láàrín yín, ẹ máa rìn nígbà tí ẹ̀yin ní ìmọ́lẹ̀, kí òkùnkùn má ṣe bá yín, ẹni tí ó bá sì ń rìn ní òkùnkùn kò mọ ibi òun ń lọ. 3612.36: Lk 16.8; Jh 8.59.Nígbà tí ẹ̀yin ní ìmọ́lẹ̀, ẹ gba ìmọ́lẹ̀ gbọ́, kí ẹ lè jẹ́ ọmọ ìmọ́lẹ̀!” Nǹkan wọ̀nyí ni Jesu sọ, ó sì jáde lọ, ó fi ara pamọ́ fún wọn.

Àwọn Júù n tẹ̀síwájú nínú àìgbàgbọ́

37Ṣùgbọ́n bí ó ti ṣe ọ̀pọ̀lọpọ̀ iṣẹ́ àmì tó báyìí lójú wọn, wọn kò gbà á gbọ́. 3812.38: Isa 53.1; Ro 10.16.Kí ọ̀rọ̀ wòlíì Isaiah lè ṣẹ, èyí tí ó sọ pé,

“Olúwa, ta ni ó gba ìwàásù wa gbọ́

Àti ta ni a sì fi apá Olúwa hàn fún?”

39Nítorí èyí ni wọn kò fi lè gbàgbọ́, nítorí Isaiah sì tún sọ pé,

4012.40: Isa 6.10; Mt 13.14.“Ó ti fọ́ wọn lójú,

Ó sì ti sé àyà wọn le;

kí wọn má ba à fi ojú wọn rí,

kí wọn má ba à fi ọkàn wọn mọ̀,

kí wọn má ba à yípadà, kí èmi má ba à mú wọn láradá.”

4112.41: Isa 6.1; Lk 24.27.Nǹkan wọ̀nyí ni Isaiah wí, nítorí ó ti rí ògo rẹ̀, ó sì sọ̀rọ̀ rẹ̀.

4212.42: Jh 9.22; Lk 6.22.Síbẹ̀ ọ̀pọ̀ nínú àwọn olórí gbà á gbọ́ pẹ̀lú; ṣùgbọ́n nítorí àwọn Farisi wọn kò jẹ́wọ́ rẹ̀, kí a má ba à yọ wọ́n kúrò nínú Sinagọgu, 43nítorí wọ́n fẹ́ ìyìn ènìyàn ju ìyìn ti Ọlọ́run lọ.

4412.44: Mt 10.40; Jh 5.24.Jesu sì kígbe ó sì wí pé, “Ẹni tí ó bá gbà mí gbọ́, èmi kọ́ ni ó gbàgbọ́ ṣùgbọ́n ẹni tí ó rán mi. 4512.45: Jh 14.9.Ẹni tí ó bá sì rí mi, ó rí ẹni tí ó rán mi. 4612.46: Jh 1.4; 8.12; 9.5.Èmi ni ìmọ́lẹ̀ tí ó wá sí ayé, kí ẹnikẹ́ni tí ó bá gbà mí gbọ́ má ṣe wà nínú òkùnkùn.

4712.47: Jh 3.17.“Bí ẹnikẹ́ni bá sì gbọ́ ọ̀rọ̀ mi, tí kò sì pa wọ́n mọ́, èmi kì yóò ṣe ìdájọ́ rẹ̀ nítorí tí èmi kò wá láti ṣe ìdájọ́ ayé, bí kò ṣe láti gba ayé là. 4812.48: Mt 10.14-15.Ẹni tí ó bá kọ̀ mí, tí kò sì gba ọ̀rọ̀ mi, ó ní ẹnìkan tí ń ṣe ìdájọ́ rẹ̀; ọ̀rọ̀ tí mo ti sọ, òun náà ni yóò ṣe ìdájọ́ rẹ̀ ní ọjọ́ ìkẹyìn. 49Nítorí èmi kò dá ọ̀rọ̀ sọ fún ara mi, ṣùgbọ́n Baba tí ó rán mi, ni ó ti fún mi ní àṣẹ, ohun tí èmi ó sọ, àti èyí tí èmi ó wí. 50Èmi sì mọ̀ pé ìyè àìnípẹ̀kun ni òfin rẹ̀, nítorí náà, àwọn ohun tí mo bá wí, gẹ́gẹ́ bí Baba ti sọ fún mi, bẹ́ẹ̀ ni mo wí!”

Священное Писание (Восточный перевод), версия с «Аллахом»

Иохан 12:1-50

Помазание Исы аль-Масиха дорогим ароматическим маслом

(Мат. 26:6-13; Мк. 14:3-9; Лк. 7:37-39)

1За шесть дней до праздника Освобождения Иса пришёл в Вифанию, туда, где жил Элеазар, которого Он воскресил из мёртвых. 2Здесь в честь Исы был устроен обед. Марфа накрывала на стол, и Элеазар вместе с Исой и другими гостями тоже возлежал у стола. 3Марьям в это время взяла кувшин12:3 Букв.: «одна литра», что равняется примерно 330 г. чистого нардового12:3 Нард – ароматическая жидкость, получаемая из определённого растения, которое произрастает только в Индии, на Гималаях, и поэтому доставка делала нард дорогостоящим товаром. Нард смешивали с другими веществами и продавали в алебастровых кувшинах в виде масла, мази или нардовой воды. масла, которое стоило очень дорого, и вылила его на ноги Исе. Потом она стала вытирать Его ноги своими волосами. Весь дом наполнился ароматом масла. 4Иуда Искариот, один из учеников Исы, который впоследствии предал Его, возмутился:

5– Почему было не продать это масло за триста серебряных монет12:5 Букв.: «триста динариев». и не раздать деньги нищим?

6Он говорил это не потому, что заботился о нищих, а потому, что был вор. Ему был доверен ящик с общими деньгами, и он брал из него на свои нужды.

7– Оставь её, – сказал Иса, – она должна была сохранить этот бальзам на день Моего погребения. 8Нищие всегда будут с вами, а Я не всегда буду с вами.

9Тем временем множество иудеев узнало, что Иса там. Они пришли не только для того, чтобы увидеть Ису, но и посмотреть на Элеазара, которого Иса воскресил из мёртвых. 10Главные же священнослужители решили убить и Элеазара, 11потому что из-за него многие иудеи приходили к Исе и верили в Него.

Торжественный въезд в Иерусалим

(Мат. 21:4-9; Мк. 11:7-10; Лк. 19:35-38)

12На следующий день многочисленная толпа, пришедшая на праздник Освобождения, услышала о том, что Иса идёт в Иерусалим. 13Люди взяли пальмовые ветви12:13 Пальмовые ветви символизируют радость победы. и вышли Ему навстречу с возгласами:

– Хвала Царю!12:13 Хвала Царю (букв.: «Осанна» («Спаси нас»)) – выражение, ставшее возгласом хвалы.

Благословен Тот, Кто приходит во имя Вечного!12:13 Заб. 117:25, 26.

Благословен Царь Исраила!12:13 Народ здесь наделяет Ису титулами аль-Масиха.

14Иса нашёл молодого осла и сел на него, как об этом и написано:

15«Не бойся, дочь Сиона!12:15 То есть жители Иерусалима.

Вот идёт Царь твой,

сидя на ослёнке»12:15 Зак. 9:9 (см. Ис. 62:11). Иса въехал в Иерусалим на осле, как миролюбивый и смиренный царь, а не на боевом коне с мечом, как это делали цари того времени..

16Вначале ученики Исы ничего не могли понять. Только после того, как Он был прославлен, они поняли, что сбылось написанное о Нём. 17Люди, бывшие с Исой, когда Он вызвал Элеазара из могилы, воскресив его из мёртвых, продолжали рассказывать об этом случае. 18Потому и вышла встречать Ису целая толпа, что все хотели увидеть Человека, сотворившего такое знамение. 19Блюстители Закона с досадой говорили друг другу:

– Ничего не помогает. Весь мир идёт за Ним!

Иса аль-Масих говорит о Своей смерти

20Среди пришедших на праздник для поклонения было несколько греков. 21Они подошли к Филиппу, ученику Исы, который был родом из Вифсаиды в Галилее, и попросили:

– Господин, мы бы хотели увидеть Ису.

22Филипп пошёл к Андеру, и они вдвоём подошли и сказали об этом Исе. 23Иса ответил:

– Настал час прославиться Ниспосланному как Человек. 24Говорю вам истину: если пшеничное зерно не упадёт в землю и не умрёт, то оно останется одним зерном. Если же оно умрёт, то из него произойдёт много зёрен. 25Тот, кто любит свою жизнь, тот потеряет её, но кто возненавидит свою жизнь в этом мире, тот сохранит её для вечной жизни. 26Тот, кто служит Мне, должен и следовать за Мной. И где Я, там будет и Мой слуга. И Отец Мой прославит того, кто служит Мне.

27Сейчас Моя душа взволнована. Что Я могу сказать? Сказать ли: «Отец, избавь Меня от этого часа»? Но ведь для этого часа Я и пришёл! 28Отец, прославь имя Твоё!

И с небес раздался голос:

– Прославил и ещё прославлю!

29Народ, который там стоял и слышал, говорил, что это гром, но некоторые утверждали, что это ангел говорил с Ним. 30Иса сказал:

– Этот голос был не для Меня, а для вас. 31Теперь настало время суда для мира, и Шайтан, князь этого греховного мира, будет изгнан вон. 32Но когда Я буду поднят от земли, Я всех привлеку к Себе.

33Это Он сказал, давая им понять, какой смертью Он умрёт.

34Толпа ответила Ему:

– Мы слышали из Писания, что аль-Масих вечно жив12:34 См. Заб. 88:37-38; Ис. 9:6-7; Езек. 37:25; Дан. 7:13-14.. Как же Ты можешь говорить, что «Ниспосланный как Человек будет поднят»? И что тогда из Себя представляет Ниспосланный как Человек?

35Тогда Иса сказал им:

– Ещё совсем недолго Свет будет с вами. Ходите, пока есть Свет и пока вас не покрыла тьма. А тот, кто ходит во тьме, не знает, куда он идёт. 36Верьте в Свет, пока Свет есть, чтобы вам стать сынами Света.

Закончив говорить, Иса ушёл и скрылся от них.

Неверие народа и страх перед гонениями

37Даже после того как Иса сотворил перед ними столько знамений, они не верили в Него. 38Так исполнились слова пророка Исаии:

«Вечный, кто поверил слышанному от нас,

и кому открылась сила Вечного?»12:38 Ис. 53:1.

39Они потому не могли верить, что, как ещё сказал Исаия:

40«Он ослепил их глаза

и ожесточил их сердца,

чтобы они не увидели глазами,

не поняли сердцами

и не обратились, чтобы Я их исцелил»12:40 Ис. 6:10..

41Исаия сказал это потому, что он видел славу аль-Масиха и говорил о Нём12:41 См. Ис. 6:1-3. То, что Исаия говорит о Вечном, Иохан относит к Исе аль-Масиху.. 42Впрочем даже среди начальников многие поверили в Ису, хотя из боязни, что блюстители Закона отлучат их от общества, они не говорили о своей вере. 43Похвала людей была для них дороже одобрения Аллаха.

Важность принятия слов Исы ал-Масиха

44Иса воскликнул:

– Когда человек верит в Меня, он верит не только в Меня, но и в Пославшего Меня. 45Когда он смотрит на Меня, он видит Того, Кто послал Меня. 46Я – свет, и Я пришёл в мир, чтобы никто из тех, кто верит в Меня, не остался во тьме.

47Я не сужу того, кто слушает Мои слова, но не делает того, что Я говорю. Ведь Я пришёл не судить мир, а спасти его. 48Для того, кто отвергает Меня и не принимает Моих слов, есть судья; Моё слово будет судить его в Последний день. 49Я ведь не от Себя говорил, но Отец, Который послал Меня, повелел Мне, что говорить и как говорить. 50Я знаю, что Его повеление ведёт к вечной жизни. Поэтому то, что говорю, Я говорю так, как сказал Мне Отец.