Ọ̀rọ̀ di ẹran-ara
11.1: Gẹ 1.1; 1Jh 1.1; If 19.13; Jh 17.5.Ní àtètèkọ́ṣe ni Ọ̀rọ̀ wà, Ọ̀rọ̀ sì wà pẹ̀lú Ọlọ́run, Ọlọ́run sì ni Ọ̀rọ̀ náà. 2Òun ni ó sì wà pẹ̀lú Ọlọ́run ní àtètèkọ́ṣe. 31.3: Kl 1.16; 1Kọ 8.6; Hb 1.2.Nípasẹ̀ rẹ̀ ni a dá ohun gbogbo; lẹ́yìn rẹ̀ a kò sì dá ohun kan nínú ohun tí a ti dá. 41.4: Jh 5.26; 11.25; 14.6.Nínú rẹ̀ ni ìyè wà, ìyè yìí náà sì ni ìmọ́lẹ̀ aráyé, 51.5: Jh 9.5; 12.46.ìmọ́lẹ̀ náà sì ń mọ́lẹ̀ nínú òkùnkùn, òkùnkùn kò sì borí rẹ̀.
61.6: Mk 1.4; Mt 3.1; Lk 3.3; Jh 1.19-23.Ọkùnrin kan wà tí a rán láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run wá; orúkọ ẹni tí ń jẹ́ Johanu. 7Òun ni a sì rán fún ẹ̀rí, kí ó lè ṣe ẹlẹ́rìí fún ìmọ́lẹ̀ náà, kí gbogbo ènìyàn kí ó lè gbàgbọ́ nípasẹ̀ rẹ̀. 8Òun fúnrarẹ̀ kì í ṣe ìmọ́lẹ̀ náà, ṣùgbọ́n a rán an wá láti ṣe ẹlẹ́rìí fún ìmọ́lẹ̀ náà.
91.9: 1Jh 2.8.Ìmọ́lẹ̀ òtítọ́ ń bẹ tí ń tan ìmọ́lẹ̀ fún olúkúlùkù ènìyàn tí ó wá sí ayé. 10Òun sì wà ní ayé, àti pé, nípasẹ̀ rẹ̀ ni a sì ti dá ayé, ṣùgbọ́n ayé kò sì mọ̀ ọ́n. 11Ó tọ àwọn tirẹ̀ wá, àwọn tirẹ̀ kò sì gbà á. 121.12: Ga 3.26; Jh 3.18; 1Jh 5.13.Ṣùgbọ́n iye àwọn tí ó gbà á, àní àwọn náà tí ó gbà orúkọ rẹ̀ gbọ́, àwọn ni ó fi ẹ̀tọ́ fún láti di ọmọ Ọlọ́run; 131.13: Jn 3.5; 1Pt 1.23; Jk 1.18; 1Jh 3.9.Àwọn ọmọ tí kì í ṣe nípa ẹ̀jẹ̀, tàbí nípa ti ìfẹ́ ara, bẹ́ẹ̀ ni kì í ṣe nípa ìfẹ́ ti ènìyàn, bí kò ṣe láti ọwọ́ Ọlọ́run.
141.14: Ro 1.3; Ga 4.4; Fp 2.7; 1Tm 3.16; Hb 2.14; 1Jh 4.2.Ọ̀rọ̀ náà sì di ara, òun sì ń bá wa gbé. Àwa sì ti rí ògo rẹ̀, àní ògo ọmọ rẹ kan ṣoṣo, tí ó ti ọ̀dọ̀ Baba wá, ó kún fún oore-ọ̀fẹ́ àti òtítọ́.
151.15: Jh 1.30.Johanu sì jẹ́rìí nípa rẹ̀, ó kígbe, ó sì wí pé, “Èyí ni ẹni tí mo sọ̀rọ̀ rẹ̀ pé, ‘Ẹni tí ń bọ̀ lẹ́yìn mi pọ̀jù mí lọ, nítorí òun ti wà ṣáájú mi.’ ” 161.16: Kl 1.19; 2.9; Ef 1.23; Ro 5.21.Nítorí láti inú ẹ̀kúnrẹ́rẹ́ oore-ọ̀fẹ́ rẹ̀ ni gbogbo wa sì ti gba ìbùkún kún ìbùkún. 171.17: Jh 7.19.Nítorí pé nípasẹ̀ Mose ni a ti fi òfin fún ni ṣùgbọ́n òun; oore-ọ̀fẹ́ àti òtítọ́ láti ipasẹ̀ Jesu Kristi wá. 181.18: El 33.20; Jh 6.26; 1Jh 4.12; Jh 3.11.Kò sí ẹni tí ó rí Ọlọ́run rí, bí kò ṣe òun nìkan, àní ọmọ rẹ̀ kan ṣoṣo, ẹni tí òun pàápàá jẹ́ Ọlọ́run, tí ó sì wà ní ìbásepọ̀ tí ó súnmọ́ jùlọ pẹ̀lú baba, òun náà ni ó sì fi í hàn.
Johanu sọ pé òun kì í ṣe Kristi
191.19: Jh 1.6.Èyí sì ni ẹ̀rí Johanu, nígbà tí àwọn Júù rán àwọn àlùfáà àti àwọn ọmọ Lefi láti Jerusalẹmu wá láti béèrè lọ́wọ́ rẹ̀ ẹni tí òun ń ṣe. 201.20: Jh 3.28.Òun kò sì kùnà láti jẹ́wọ́, ṣùgbọ́n òun jẹ́wọ́ wọ́ọ́rọ́wọ́ pé, “Èmi kì í ṣe Kristi náà.”
211.21: Mt 11.14; 16.14; Mk 9.13; Mt 17.13; De 18.15,18.Wọ́n sì bi í léèrè pé, “Ta ha ni ìwọ? Elijah ni ìwọ bí?”
Ó sì wí pé, “Èmi kọ́.”
“Ìwọ ni wòlíì náà bí?”
Ó sì dáhùn pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́.”
22Ní ìparí wọ́n wí fún un pé, “Ta ni ìwọ í ṣe? Fún wa ní ìdáhùn kí àwa kí ó lè mú èsì padà tọ àwọn tí ó rán wa wá lọ. Kí ni ìwọ wí nípa ti ara rẹ?”
231.23: Isa 40.3; Mk 1.3; Mt 3.3; Lk 3.4.Johanu sì fi ọ̀rọ̀ wòlíì Isaiah fún wọn ní èsì pé, “Èmi ni ohùn ẹni tí ń kígbe ní ijù, ‘Ẹ ṣe ọ̀nà Olúwa ní títọ́.’ ”
24Ọ̀kan nínú àwọn Farisi tí a rán 25bi í léèrè pé, “Èéṣe tí ìwọ fi ń bamitiisi nígbà náà, bí ìwọ kì í bá ṣe Kristi, tàbí Elijah, tàbí wòlíì náà?”
261.26-27: Mk 1.7-8; Mt 3.11; Lk 3.16.Johanu dá wọn lóhùn, wí pé, “Èmi ń fi omi bamitiisi: ẹnìkan dúró láàrín yín, ẹni tí ẹ̀yin kò mọ̀; 27Òun náà ni ẹni tí ń bọ̀ lẹ́yìn mi, okùn bàtà ẹni tí èmi kò tó láti tú.”
28Àwọn nǹkan wọ̀nyí ni ó ṣẹlẹ̀ ní Betani ní òdìkejì odò Jordani, níbi tí Johanu ti ń fi omi bamitiisi.
Jesu jẹ́ Ọ̀dọ́-Àgùntàn Ọlọ́run
291.29: Jh 1.36; Isa 53.7; Ap 8.32; 1Pt 1.19; If 5.6; 1Jh 3.5.Ní ọjọ́ kejì, Johanu rí Jesu tí ó ń bọ̀ wá sí ọ̀dọ̀ rẹ̀, ó sì wí pé, “Wò ó, Ọ̀dọ́-àgùntàn Ọlọ́run, ẹni tí ó kó ẹ̀ṣẹ̀ ayé lọ! 30Èyí ni ẹni tí mo ń sọ nígbà tí mo wí pé, ‘Ọkùnrin kan tí ń bọ̀ wá lẹ́yìn mi, tí ó pọ̀jù mí lọ, nítorí tí ó ti wà ṣáájú mi.’ 31Èmi gan an kò sì mọ̀ ọ́n, ṣùgbọ́n ìdí tí mo fi wá ń fi omi ṣe ìtẹ̀bọmi ni kí a lè fi í hàn fún Israẹli.”
321.32: Mk 1.10; Mt 3.16; Lk 3.22.Nígbà náà ni Johanu jẹ́rìí sí i pé: “Mo rí Ẹ̀mí sọ̀kalẹ̀ láti ọ̀run wá bí àdàbà, tí ó sì bà lé e. 33Èmí kì bá tí mọ̀ ọ́n, bí kò ṣe pé ẹni tí ó rán mi láti fi omi bamitiisi sọ fún mi pé, ‘Ọkùnrin tí ìwọ rí tí Ẹ̀mí sọ̀kalẹ̀ tí ó bà lé lórí ni ẹni tí yóò fi Ẹ̀mí Mímọ́ bamitiisi.’ 34Èmi ti rí i, mo sì jẹ́rìí pé, èyí ni Ọmọ Ọlọ́run.”
Àwọn ọmọ-ẹ̀yìn Jesu àkọ́kọ́
351.35: Lk 7.18.Ní ọjọ́ kejì, Johanu dúró pẹ̀lú méjì nínú àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀. 36Nígbà tí ó sì rí Jesu bí ó ti ń kọjá lọ, ó wí pé, “Wò ó Ọ̀dọ́-àgùntàn Ọlọ́run!”
37Nígbà tí àwọn ọmọ-ẹ̀yìn méjì náà sì gbọ́ ohun tí ó wí yìí, wọ́n bẹ̀rẹ̀ sì í tọ Jesu lẹ́yìn. 38Nígbà náà ni Jesu yípadà, ó rí i pé wọ́n ń tọ òun lẹ́yìn, ó sì béèrè pé, “Kí ni ẹ̀yin ń wá?”
Wọ́n wí fún un pé, “Rabbi” (ìtumọ̀ èyí tí í ṣe Olùkọ́ni), “Níbo ni ìwọ ń gbé?”
39Ó wí fún wọn pé, “Ẹ wá wò ó, ẹ̀yin yóò sì rí i.”
Wọ́n sì wá, wọ́n sì rí ibi tí ó ń gbé, wọ́n sì wà ní ọ̀dọ̀ rẹ̀ ní gbogbo ọjọ́ náà. Ó jẹ́ ìwọ̀n wákàtí kẹwàá ọjọ́.
401.40-42: Mt 4.18-22; Mk 1.16-20; Lk 5.2-11.Anderu arákùnrin Simoni Peteru jẹ́ ọ̀kan nínú àwọn méjì tí ó gbọ́ ọ̀rọ̀ Johanu, tí ó sì tọ Jesu lẹ́yìn. 411.41: Da 9.25; Jh 4.25.Ohun àkọ́kọ́ tí Anderu ṣe ni láti wá Simoni arákùnrin rẹ̀, ó sì wí fún un pé, “Àwa ti rí Messia” (ẹni tí ṣe Kristi). 421.42: Jh 21.15-17; 1Kọ 15.5; Mt 16.18.Ó sì mú un wá sọ́dọ̀ Jesu.
Jesu sì wò ó, ó wí pé, “Ìwọ ni Simoni ọmọ Jona: Kefa ni a ó sì máa pè ọ” (ìtumọ̀ èyí tí ṣe Peteru).
Jesu pe Filipi àti Natanaeli
431.43: Mt 10.3; Jh 6.5; 12.21; 14.8.Ní ọjọ́ kejì Jesu ń fẹ́ jáde lọ sí Galili, ó sì rí Filipi, ó sì wí fún un pé, “Máa tọ̀ mí lẹ́yìn.”
44Filipi gẹ́gẹ́ bí i Anderu àti Peteru, jẹ́ ará ìlú Betisaida. 451.45: Lk 24.27.Filipi rí Natanaeli, ó sì wí fún un pé, “Àwa ti rí ẹni náà tí Mose kọ nípa rẹ̀ nínú òfin àti ẹni tí àwọn wòlíì ti kọ̀wé rẹ̀—Jesu ti Nasareti, ọmọ Josẹfu.”
461.46: Jh 7.41; Mk 6.2.Natanaeli béèrè pé, “Nasareti? Ohun rere kan ha lè ti ibẹ̀ jáde?”
Filipi wí fún un pé, “Wá wò ó.”
47Jesu rí Natanaeli ń bọ̀ wá sọ́dọ̀ rẹ̀, ó sì wí nípa rẹ̀ pé, “Èyí ni ọmọ Israẹli tòótọ́, nínú ẹni tí ẹ̀tàn kò sí.”
48Natanaeli béèrè pé, “Báwo ni ìwọ ti ṣe mọ̀ mí?”
Jesu sì dáhùn pé, “Èmi rí ọ nígbà tí ìwọ wà lábẹ́ igi ọ̀pọ̀tọ́ kí Filipi tó pè ọ́.”
491.49: Sm 2.7; Mk 15.32; Jh 12.13.Nígbà náà ni Natanaeli sọ ọ́ gbangba pé, “Rabbi, ìwọ ni ọmọ Ọlọ́run; Ìwọ ni ọba Israẹli.”
50Jesu sì wí fún un pé, “Ìwọ gbàgbọ́ nítorí mo wí fún ọ pé mo rí ọ lábẹ́ igi ọ̀pọ̀tọ́. Ìwọ ó rí ohun tí ó pọ̀jù ìwọ̀nyí lọ.” 511.51: Lk 3.21; Gẹ 28.12.Nígbà náà ni ó fi kún un pé, “Èmi wí fún yín nítòótọ́, ẹ̀yin yóò rí ọ̀run ṣí sílẹ̀, àwọn angẹli Ọlọ́run yóò sì máa gòkè, wọ́n ó sì máa sọ̀kalẹ̀ sórí Ọmọ Ènìyàn.”
مسيح به دنيای ما آمد
1-2در ازل، پيش از آنكه چيزی پديد آيد، «كلمه» وجود داشت و نزد خدا بود. او همواره زنده بوده، و خود او خداست. 3هر چه هست، بوسيلهٔ او آفريده شده و چيزی نيست كه آن را نيافريده باشد. 4زندگی جاويد در اوست و اين زندگی به تمام مردم نور میبخشد. 5او همان نوری است كه در تاريكی میدرخشد و تاريكی هرگز نمیتواند آن را خاموش كند.
6-7خدا يحيای پيامبر را فرستاد تا اين «نور» را به مردم معرفی كند و مردم به او ايمان آورند. 8يحيی آن نور نبود، او فقط شاهدی بود تا نور را به مردم معرفی كند. 9اما بعد، آن نور واقعی آمد تا به هر کس كه به اين دنيا میآيد، بتابد.
10گرچه جهان را او آفريده بود، اما زمانی كه به اين جهان آمد، كسی او را نشناخت. 11-12حتی در سرزمين خود و در ميان قوم خود، يهوديان، كسی او را نپذيرفت. اما او به تمام كسانی كه به او ايمان آوردند، اين حق را داد كه فرزندان خدا گردند؛ بلی، فقط كافی بود به او ايمان آورند تا نجات يابند. 13اين اشخاص تولدی نو يافتند، نه همچون تولدهای معمولی كه نتيجهٔ اميال و خواستههای آدمی است، بلكه اين تولد را خدا به ايشان عطا فرمود.
14«كلمهٔ خدا» انسان شد و بر روی اين زمين و در بين ما زندگی كرد. او لبريز از محبت و بخشش و راستی بود. ما بزرگی و شكوه او را به چشم خود ديديم، بزرگی و شكوه فرزند بینظير پدر آسمانی ما، خدا.
15يحيی او را به مردم معرفی كرد و گفت: «اين همان كسی است كه به شما گفتم بعد از من میآيد و مقامش از من بالاتر است، زيرا پيش از آنكه من باشم، او وجود داشت.»
16لطف بیپايان او به همهٔ ما رسيد و بركت در پی بركت نصيب ما شد. 17خدا احكام خود را توسط موسی به مردم داد، اما راستی و محبت را بهوسیلهٔ عيسی مسيح عطا فرمود. 18كسی هرگز خدا را نديده است؛ اما عيسی، فرزند يگانهٔ خدا، او را ديده است زيرا همواره همراه پدر خود، خدا میباشد. او هر آنچه را كه ما بايد دربارهٔ خدا بدانيم، به ما گفته است.
شهادت يحيی
19روزی سران قوم يهود از شهر اورشليم، چند تن از كاهنان و دستيارانش را نزد يحيی فرستادند تا بدانند آيا او ادعا میكند كه مسيح است يا نه.
20يحيی، صريحاً اظهار داشت: «نه، من مسيح نيستم.»
21پرسيدند: «خوب، پس كه هستيد؟ آيا الياس پيامبر هستيد؟»
جواب داد: «نه!»
پرسيدند: «آيا شما آن پيامبر نيستيد كه ما چشم به راهش میباشيم؟»
باز هم جواب داد: «نه.»
22گفتند: «پس به ما بگوييد كه هستيد تا بتوانيم برای سران قوم كه ما را به اينجا فرستادهاند، جوابی ببريم.»
23يحيی گفت: «چنانكه اشعيای نبی پيشگويی كرده، من صدای ندا كنندهای هستم كه در بيابان فرياد میزند: ای مردم، خود را برای آمدن خداوند آماده سازيد.»
24سپس، افرادی كه از طرف فرقهٔ فريسیها آمده بودند، 25از او پرسيدند: «خوب، اگر شما نه مسيح هستيد، نه الياس و نه آن پيامبر، پس چه حق داريد مردم را غسل تعميد دهيد؟»
26يحيی گفت: «من مردم را فقط با آب غسل میدهم؛ ولی همين جا در ميان اين جمعيت، كسی هست كه شما او را نمیشناسيد. 27او بزودی خدمت خود را در بين شما آغاز میكند. مقام او به قدری بزرگ است كه من حتی شايسته نيستم كفشهای او را پيش پايش بگذارم.»
28اين گفتگو در «بيتعنيا» روی داد. بيتعنيا دهی است در آن طرف رود اردن و جايی است كه يحيی، مردم را غسل تعميد میداد.
عيسی، برّه خدا
29روز بعد، يحيی، عيسی را ديد كه به سوی او میآيد. پس به مردم گفت: «نگاه كنيد! اين همان برّهای است كه خدا فرستاده تا برای آمرزش گناهان تمام مردم دنيا قربانی شود. 30اين همان كسی است كه گفتم بعد از من میآيد ولی مقامش از من بالاتر است، چون قبل از من وجود داشته است. 31من نيز او را نمیشناختم. ولی برای اين آمدم كه مردم را با آب غسل دهم تا به اين وسيله او را به قوم اسرائيل معرفی كنم.»
32سپس گفت: «من روح خدا را ديدم كه به شكل كبوتری از آسمان آمد و بر عيسی قرار گرفت. 33همانطور كه گفتم، من نيز او را نمیشناختم ولی وقتی خدا مرا فرستاد تا مردم را غسل تعميد دهم، در همان وقت به من فرمود: هرگاه ديدی روح خدا از آسمان آمد و بر كسی قرار گرفت، بدان كه او همان است كه منتظرش هستيد. اوست كه مردم را با روحالقدس تعميد خواهد داد. 34و چون من با چشم خود اين را ديدهام، شهادت میدهم كه او فرزند خداست.»
نخستين شاگردان عيسی
35فردای آن روز، وقتی يحيی با دو نفر از شاگردان خود ايستاده بود، 36عيسی را ديد كه از آنجا میگذرد، يحيی با اشتياق به او نگاه كرد و گفت: «ببينيد! اين همان برهای است كه خدا فرستاده است.» 37آنگاه دو شاگرد يحيی برگشتند و در پی عيسی رفتند.
38عيسی كه ديد دو نفر دنبال او میآيند، برگشت و از ايشان پرسيد: «چه میخواهيد؟»
جواب دادند: «آقا، كجا اقامت داريد؟»
39فرمود: «بياييد و ببينيد.»
پس همراه عيسی رفتند و از ساعت چهار بعد از ظهر تا غروب نزد او ماندند. 40(يكی از آن دو، «اندرياس» برادر «شمعون پطرس» بود.)
41اندرياس رفت و برادر خود را يافته، به او گفت: «شمعون، ما مسيح را پيدا كردهايم!» 42و او را آورد تا عيسی را ببيند.
عيسی چند لحظه به او نگاه كرد و فرمود: «تو شمعون، پسر يونا هستی. ولی از اين پس پطرس (يعنی ”صخره“) ناميده خواهی شد!»
43روز بعد، عيسی تصميم گرفت به ايالت جليل برود. در راه، «فيليپ» را ديد و به او گفت: «همراه من بيا.» 44(فيليپ نيز اهل بيتصيدا و همشهری اندرياس و پطرس بود.)
45فيليپ رفت و «نتنائيل» را پيدا كرد و به او گفت: «نتنائيل، ما مسيح را يافتهايم، همان كسی كه موسی و پيامبران خدا دربارهاش خبر دادهاند. نامش عيسی است، پسر يوسف و اهل ناصره.»
46نتنائيل با تعجب پرسيد: «گفتی اهل ناصره؟ مگر ممكن است از ناصره هم چيز خوبی بيرون آيد؟»
فيليپ گفت: «خودت بيا و او را ببين.»
47وقتی نزديک میشدند، عيسی فرمود: «ببينيد، اين شخص كه میآيد، يک مرد شريف و يک اسرائيلی واقعی است.»
48نتنائيل پرسيد: «از كجا میدانی من كه هستم؟»
عيسی فرمود: «قبل از آنكه فيليپ تو را پيدا كند، من زير درخت انجير تو را ديدم.»
49نتنائيل حيرتزده گفت: «آقا، شما فرزند خدا هستيد؛ شما پادشاه اسرائيل میباشيد!»
50عيسی گفت: «چون فقط گفتم تو را زير درخت انجير ديدم، به من ايمان آوردی؟ بعد از اين چيزهای بزرگتر خواهی ديد. 51در حقيقت همهٔ شما آسمان را خواهيد ديد كه باز شده و فرشتگان خدا نزد من میآيند و به آسمان باز میگردند.»