Jobu 6 – YCB & NVI-PT

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Jobu 6:1-30

Ìdáhùn Jobu

1Jobu sì dáhùn ó si wí pé,

2“Háà! À bá lè wọ́n ìbìnújẹ́ mi nínú òsùwọ̀n,

kí a sì le gbé ọ̀fọ̀ mi lé orí òsùwọ̀n ṣọ̀kan pọ̀!

3Ǹjẹ́ nísinsin yìí, ìbá wúwo jú iyanrìn òkun lọ,

nítorí náà ni ọ̀rọ̀ mi ṣe ń tàsé.

4Nítorí pé ọfà Olódùmarè wọ̀ mi nínú,

oró èyí tí ọkàn mi mú;

ìpayà-ẹ̀rù Ọlọ́run dúró tì mí.

5Ǹjẹ́ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ igbó á máa dún nígbà tí ó bá ní koríko,

tàbí ọ̀dá màlúù a máa dún lórí ìjẹ rẹ̀?

6A ha lè jẹ ohun tí kò ní adùn ní àìní iyọ̀,

tàbí adùn ha wà nínú funfun ẹyin?

7Ohun ti ọ̀kan mi kọ̀ láti tọ́wò,

òun ni ó dàbí oúnjẹ tí ó mú mi ṣàárẹ̀.

8“Háà! èmi ìbá lè rí ìbéèrè mi gbà;

àti pé, kí Ọlọ́run lè fi ohun tí èmi ṣàfẹ́rí fún mi.

9Àní Ọlọ́run ìbá jẹ́ pa mí run,

tí òun ìbá jẹ́ ṣíwọ́ rẹ̀ kì ó sì ké mi kúrò.

10Nígbà náà ní èmi ìbá ní ìtùnú síbẹ̀,

àní, èmi ìbá mú ọkàn mi le nínú ìbànújẹ́ mi ti kò dá ni sí:

nítorí èmi kò fi ọ̀rọ̀ ẹni mímọ́ ni sin rí.

11“Kí ní agbára mi tí èmi ó fi retí?

Kí sì ní òpin mi tí èmi ó fi ní sùúrù?

12Agbára mi ha ṣe agbára òkúta bí?

Ẹran-ara mi í ṣe idẹ?

13Ìrànlọ́wọ́ mi kò ha wà nínú mi:

ọgbọ́n kò ha ti sálọ kúrò lọ́dọ̀ mi bí?

14“Ẹni tí àyà rẹ̀ yọ́ dànù, ta ni a bá máa ṣàánú fún láti ọ̀dọ̀ ọ̀rẹ́ rẹ̀ wá,

kí ó má ba à kọ ìbẹ̀rù Olódùmarè sílẹ̀?

15Àwọn ará mi dàbí odò tí kò ṣe gbẹ́kẹ̀lé

bí ìṣàn omi odò, wọ́n sàn kọjá lọ.

16Tí ó dúdú nítorí omi dídì,

àti níbi tí yìnyín dídì gbé di yíyọ́.

17Nígbàkígbà tí wọ́n bá gbóná wọn a sì yọ́ sàn lọ,

nígbà tí oòrùn bá mú, wọn a sì gbẹ kúrò ni ipò wọn.

18Àwọn oníṣòwò yà kúrò ní ọ̀nà wọn,

wọ́n gòkè sí ibi asán, wọ́n sì run.

19Ẹgbẹ́ oníṣòwò Tema ń wá omi,

àwọn oníṣòwò Ṣeba ń dúró dè wọ́n ní ìrètí.

20Wọ́n káàárẹ̀, nítorí tí wọ́n gbẹ́kẹ̀ wọn lé e;

wọ́n dé bẹ̀, wọ́n sì dààmú.

21Ǹjẹ́ nísinsin yìí, ẹ̀yin dàbí wọn;

ẹ̀yin rí ìrẹ̀sílẹ̀ mi àyà sì fò mí.

22Èmi ó ha wí pé, ‘Ẹ mú ohun fún mi wá,

tàbí pé ẹ fún mi ní ẹ̀bùn nínú ohun ìní yín?

23Tàbí, ẹ gbà mí lọ́wọ́ ọ̀tá ni,

tàbí, ẹ rà mí padà kúrò lọ́wọ́ alágbára nì’?

24“Ẹ kọ́ mi, èmi ó sì pa ẹnu mi mọ́

kí ẹ sì mú mi wòye níbi tí mo gbé ti ṣìnà.

25Wò ó! Bí ọ̀rọ̀ òtítọ́ ti lágbára tó

ṣùgbọ́n kí ni àròyé ìbáwí yín jásí?

26Ẹ̀yin ṣè bí ẹ tún ọ̀rọ̀ mi ṣe

àti ohùn ẹnu tí ó dàbí afẹ́fẹ́ ṣe àárẹ̀.

27Àní ẹ̀yin ṣe gẹ́gẹ́ bí aláìní baba,

ẹ̀yin sì da iye lé ọ̀rẹ́ yín.

28“Nítorí náà, kí èyí kí ó tó fún yín.

Ẹ má wò mi! Nítorí pé ó hàn gbangba pé,

ní ojú yín ni èmi kì yóò ṣèké.

29Èmi ń bẹ̀ yín, ẹ padà, kí ó má sì ṣe jásí ẹ̀ṣẹ̀;

àní, ẹ sì tún padà, àre mi ń bẹ nínú ọ̀rọ̀ yìí.

30Àìṣedéédéé ha wà ní ahọ́n mi?

Ǹjẹ́ ìtọ́wò ẹnu mi kò kúkú le mọ ohun ti ó burú jù?

Nova Versão Internacional

Jó 6:1-30

1Então Jó respondeu:

2“Se tão somente pudessem pesar a minha aflição

e pôr na balança a minha desgraça!

3Veriam que o seu peso é maior que o da areia dos mares.

Por isso as minhas palavras são tão impetuosas.

4As flechas do Todo-poderoso estão cravadas em mim,

e o meu espírito suga delas o veneno;

os terrores de Deus me assediam.

5Zurra o jumento selvagem se tiver capim?

Muge o boi se tiver forragem?

6Come-se sem sal uma comida insípida?

E a clara do ovo, tem algum sabor?

7Recuso-me a tocar nisso;

esse tipo de comida causa-me repugnância.

8“Se tão somente fosse atendido o meu pedido,

se Deus me concedesse o meu desejo,

9se Deus se dispusesse a esmagar-me,

a soltar a mão protetora e eliminar-me!

10Pois eu ainda teria o consolo, minha alegria

em meio à dor implacável,

de não ter negado as palavras do Santo.

11“Que esperança posso ter, se já não tenho forças?

Como posso ter paciência, se não tenho futuro?

12Acaso tenho a força da pedra?

Acaso a minha carne é de bronze?

13Haverá poder que me ajude

agora que os meus recursos se foram?

14“Um homem desesperado deve receber a compaixão de seus amigos,

muito embora ele tenha abandonado o temor do Todo-poderoso.

15Mas os meus irmãos enganaram-me como riachos temporários,

como os riachos que transbordam

16quando o degelo os torna turvos

e a neve que se derrete os faz encher,

17mas que param de fluir no tempo da seca

e no calor desaparecem dos seus leitos.

18As caravanas se desviam de suas rotas;

sobem para lugares desertos e perecem.

19Procuram água as caravanas de Temá,

olham esperançosos os mercadores de Sabá.

20Ficam tristes, porque estavam confiantes;

lá chegaram tão somente para sofrer decepção.

21Pois agora vocês de nada me valeram;

contemplam minha temível situação e se enchem de medo.

22Alguma vez pedi a vocês que me dessem alguma coisa?

Ou que da sua riqueza pagassem resgate por mim?

23Ou que me livrassem das mãos do inimigo?

Ou que me libertassem das garras de quem me oprime?

24“Ensinem-me, e eu me calarei;

mostrem-me onde errei.

25Como doem as palavras verdadeiras!

Mas o que provam os argumentos de vocês?

26Vocês pretendem corrigir o que digo e tratar como vento

as palavras de um homem desesperado?

27Vocês seriam capazes de pôr em sorteio o órfão

e de vender um amigo por uma bagatela!

28“Mas agora, tenham a bondade de olhar para mim.

Será que eu mentiria na frente de vocês?

29Reconsiderem a questão, não sejam injustos;

tornem a analisá-la,

pois a minha integridade está em jogo6.29 Ou minha retidão ainda está firme.

30Há alguma iniquidade em meus lábios?

Será que a minha boca não consegue discernir a maldade?