Jobu 41 – YCB & AKCB

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Jobu 41:1-34

Ọlọ́run ń tẹ̀síwájú láti pe Jobu níjà

1“Ǹjẹ́ ìwọ le è fi ìwọ̀ fa Lefitani jáde?

Tàbí ìwọ lè fi okùn so ahọ́n rẹ̀ mọ́lẹ̀?

2Ìwọ lè fi okùn bọ̀ ọ́ ní í mú,

tàbí fi ìwọ̀ ẹ̀gún gun ní ẹ̀rẹ̀kẹ́?

3Òun ha jẹ́ bẹ ẹ̀bẹ̀ fún àánú lọ́dọ̀

rẹ ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ bí òun ha bá ọ sọ̀rọ̀ pẹ̀lẹ́?

4Òun ha bá ọ dá májẹ̀mú bí?

Ìwọ ó ha máa mú ṣe ẹrú láéláé bí?

5Ìwọ ha lè ba sáré bí ẹni pé ẹyẹ ni,

tàbí ìwọ ó dè é fún àwọn ọmọbìnrin ìránṣẹ́ rẹ̀?

6Ẹgbẹ́ àwọn apẹja yóò ha máa tà á bí?

Wọn ó ha pín láàrín àwọn oníṣòwò?

7Ìwọ ha lè fi ọ̀kọ̀-irin gun awọ rẹ̀,

tàbí orí rẹ̀ pẹ̀lú ọ̀kọ̀ ìpẹja.

8Fi ọwọ́ rẹ lé e lára,

ìwọ ó rántí ìjà náà, ìwọ kì yóò sì ṣe bẹ́ẹ̀ mọ́.

9Kíyèsi, ìgbìyànjú láti mú un ní asán;

ní kìkì ìrí rẹ̀ ara kì yóò ha rọ̀ ọ́ wẹ̀sì?

10Kò sí ẹni aláyà lílé tí ó lè ru sókè.

Ǹjẹ́ ta ni ó lè dúró níwájú mi.

11Ta ni ó kọ́kọ́ ṣe fún mi, tí èmi ìbá fi san án fún un?

Ohunkóhun ti ń bẹ lábẹ́ ọ̀run gbogbo, tèmi ni.

12“Èmi kì yóò fi ẹ̀yà ara Lefitani,

tàbí ipá rẹ, tàbí ìhámọ́ra rẹ tí ó ní ẹwà pamọ́.

13Ta ni yóò lè rídìí aṣọ àpáta rẹ̀?

Tàbí ta ni ó lè súnmọ́ ọ̀nà méjì eyín rẹ̀?

14Ta ni ó lè ṣí ìlẹ̀kùn iwájú rẹ̀?

Àyíká ẹ̀yin rẹ ni ìbẹ̀rù ńlá.

15Ìpẹ́ lílé ní ìgbéraga rẹ̀;

ó pàdé pọ̀ tímọ́tímọ́ bí àmì èdìdì.

16Èkínní fi ara mọ́ èkejì tó bẹ́ẹ̀

tí afẹ́fẹ́ kò lè wọ àárín wọn.

17Èkínní fi ara mọ́ èkejì rẹ̀;

wọ́n lè wọ́n pọ̀ tí a kò lè mọ̀ wọ́n.

18Nípa sí sin rẹ̀ ìmọ́lẹ̀ á mọ́,

ojú rẹ̀ a sì dàbí ìpéǹpéjú òwúrọ̀.

19Láti ẹnu rẹ ni ọ̀wọ́-iná ti jáde wá,

ìpẹ́pẹ́ iná a sì ta jáde.

20Láti ihò imú rẹ ni èéfín ti jáde wá,

bí ẹni pé láti inú ìkòkò tí a fẹ́ iná ìfèéfèé lábẹ́ rẹ̀.

21Èémí rẹ̀ tiná bọ ẹ̀yin iná,

ọ̀wọ́-iná sì ti ẹnu rẹ̀ jáde.

22Ní ọrùn rẹ̀ ní agbára kù sí,

àti ìbànújẹ́ àyà sì padà di ayọ̀ níwájú rẹ̀.

23Jabajaba ẹran rẹ̀ dìjọ pọ̀,

wọ́n múra gírí fún ara wọn, a kò lè sí wọn ní ipò.

24Àyà rẹ̀ dúró gbagidi bí òkúta,

àní, ó le bi ìyá ọlọ.

25Nígbà tí ó bá gbé ara rẹ̀ sókè, àwọn alágbára bẹ̀rù;

nítorí ìbẹ̀rù ńlá, wọ́n dààmú.

26Ọ̀kọ̀ tàbí idà, tàbí ọfà,

ẹni tí ó ṣá a kò lè rán an.

27Ó ká irin sí ibi koríko gbígbẹ

àti idẹ si bi igi híhù.

28Ọfà kò lè mú un sá;

òkúta kànnakánná lọ́dọ̀ rẹ̀ dàbí àgékù koríko.

29Ó ka ẹṣin sí bí àgékù ìdì koríko;

ó rẹ́rìn-ín sí mímì ọ̀kọ̀.

30Òkúta mímú ń bẹ nísàlẹ̀ abẹ́ rẹ̀,

ó sì tẹ́ ohun mímú ṣóńṣó sórí ẹrẹ̀.

31Ó mú ibú omi hó bí ìkòkò;

ó sọ̀ agbami òkun dàbí kólòbó ìkunra.

32Ó mú ipa ọ̀nà tan lẹ́yìn rẹ̀;

ènìyàn a máa ka ibú sí ewú arúgbó.

33Lórí ilẹ̀ ayé kò sí ẹni tí ó dàbí rẹ̀,

tí a dá láìní ìbẹ̀rù.

34Ó bojú wo ohun gíga gbogbo,

ó sì nìkan jásí ọba lórí gbogbo àwọn ọmọ ìgbéraga.”

Akuapem Twi Contemporary Bible

Hiob 41:1-34

1“So wubetumi de darewa atwe ɔdɛnkyɛmmirampɔn

anaa wubetumi de hama akyekyere ne tɛkrɛma?

2So wubetumi de hama afa ne hwenem,

anaasɛ wubetumi de darewa aso nʼabogye mu?

3Ɔbɛkɔ so asrɛ wo sɛ hu no mmɔbɔ ana?

Ɔne wo bɛkasa brɛoo ana?

4Ɔbɛpene ne wo ayɛ apam

ama wode no ayɛ wʼakoa afebɔɔ ana?

5Wubetumi de no ayɛ abɛbɛ te sɛ anomaa

anaa wubetumi asa no hama de no ama wo mmabea?

6So aguadifo bɛpɛ sɛ wode no bedi nsesagua?

Wɔbɛkyekyɛ ne mu ama aguadifo ana?

7Wubetumi de mpeaw awowɔ ne were mu

anaasɛ wode mpataa mpɛmɛ bɛwowɔ ne ti ho?

8Wode wo nsa ka no a,

wobɛkae sɛnea ɔbɛwosow ne ho, nti worenyɛ saa bio!

9Ɔkwan biara nni hɔ a wobɛfa so akyere no;

ani a ɛbɔ ne so kɛkɛ no ma nnipa dwudwo.

10Obiara ntumi nsi ne bo nhwanyan no.

Afei hena na obetumi ne me adi asi?

11Hena na mede no ka a ɛsɛ sɛ mitua?

Biribiara a ɛhyɛ ɔsoro ase no yɛ me de.

12“Me werɛ remfi sɛ mɛka nʼakwaa,

nʼahoɔden ne ne bɔbea fɛfɛ no ho asɛm.

13Hena na obetumi aworɔw ne ho ahama,

na hena na ɔde nnareka bɛkɔ ne ho?

14Hena na obetumi abue nʼabogye,

a ɛse a ɛyɛ hu ayɛ no ma no?

15Nʼakyi wɔ bona a ɛsesa so,

ɛtetare so a ɔkwan nna mu koraa;

16sɛnea ɛtetare so fa no nti,

mframa biara mfa ntam.

17Ɛtoatoa mu denneennen a

emu ntumi ntetew.

18Sɛ ɔnwansi a, ɛpepa gya;

nʼaniwa aba te sɛ adekyeenim hann.

19Agyatɛn turuw fi nʼanom

na nsramma turuturuw fi mu.

20Wusiw sen fi ne hwene mu

te sɛ ɔsɛn a esi gya so.

21Ne home ma gyabiriw ano sɔ,

na ogyaframa tu fi nʼanom.

22Ne kɔn mu wɔ ahoɔden ankasa;

wɔn a wohu no no aba mu bu.

23Ne were a abubu agu so no yɛ peperee;

ayɛ pemee a ɛnka ne ho.

24Ne koko so yɛ den sɛ ɔbotan

ɛyɛ den sɛ awiyammo.

25Sɛ ɔsɔre a, ahoɔdenfo bɔ huboa;

sɛ ɔwosow ne ho a woguan.

26Afoa wɔ no a, ɛnka no,

peaw, pɛmɛ ne agyan nso saa ara.

27Ɔfa dade sɛ wura bi

na kɔbere mfrafrae te sɛ dua a awu bi ma no.

28Agyan mma no nguan;

ahwimmo mu aboa yɛ ntɛtɛ ma no.

29Kontibaa te sɛ sare wɔ nʼani so;

na ɔserew pɛmɛ nnyigyei.

30Abon a ano yɛ nnam tuatua ne yafunu so.

Ɔtwe ne ho ase wɔ fam fa dontori mu a, eyiyi akam.

31Ɔma bun mu huru sɛ nsu a ɛwɔ ɛsɛn mu

na onunu po mu sɛ srade a ɛwɔ kuku mu.

32Nea ɔbɛfa no, ɛhɔ nsu no pa yerɛw yerɛw;

na obi besusuw sɛ po bun adan ayɛ dwen.

33Asase so biribiara ne no nsɛ.

Ɔyɛ abɔde a onsuro hwee.

34Ommu wɔn a wɔyɛ ahantan no mu biara;

ɔyɛ wɔn a wɔyɛ ahomaso no nyinaa so hene.”