Jobu 33 – YCB & CARSA

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Jobu 33:1-33

Elihu bá Jobu sọ̀rọ̀

1“Ǹjẹ́ nítorí náà, Jobu, èmí bẹ̀ ọ,

gbọ́ ọ̀rọ̀ mi kí o sì fetísí ọ̀rọ̀ mi!

2Kíyèsi i nísinsin yìí, èmí ya ẹnu mi,

ahọ́n mi sì sọ̀rọ̀ ní ẹnu mi.

3Ọ̀rọ̀ mi yóò sì jásí ìdúró ṣinṣin ọkàn mi,

ètè mi yóò sì sọ ìmọ̀ mi jáde dájúdájú.

4Ẹ̀mí Ọlọ́run ni ó tí dá mi,

àti ìmísí Olódùmarè ni ó ti fún mi ní ìyè.

5Bí ìwọ bá le dá mi lóhùn,

tò ọ̀rọ̀ rẹ̀ lẹ́sẹẹsẹ níwájú mi;

6kíyèsi i, bí ìwọ ṣe jẹ́ ti Ọlọ́run, bẹ́ẹ̀ ni èmi náà;

láti amọ̀ wá ni a sì ti dá mi pẹ̀lú.

7Kíyèsi i, ẹ̀rù ńlá mi kì yóò bà ọ;

bẹ́ẹ̀ ni ọwọ́ mi kì yóò wúwo sí ọ lára.

8“Nítòótọ́ ìwọ sọ ní etí mi,

èmí sì gbọ́ ọ̀rọ̀ rẹ̀ wí pé,

9‘Èmi mọ́, láìní ìrékọjá, aláìṣẹ̀ ní èmi;

bẹ́ẹ̀ àìṣedéédéé kò sí ní ọwọ́ mi.

10Kíyèsi i, Ọlọ́run ti rí àìṣedéédéé pẹ̀lú mi;

ó kà mí sì ọ̀tá rẹ̀.

11Ó kan ẹ̀ṣẹ̀ mi sínú àbà;

o kíyèsi ipa ọ̀nà mi gbogbo.’

12“Kíyèsi i, nínú èyí ìwọ ṣìnà!

Èmi ó dá ọ lóhùn pé, Ọlọ́run tóbi jù ènìyàn lọ!

13Nítorí kí ni ìwọ ṣe ń bá a jà, wí pé,

òun kò ní sọ ọ̀rọ̀ kan nítorí iṣẹ́ rẹ̀?

14Nítorí pe Ọlọ́run sọ̀rọ̀ lẹ́ẹ̀kan,

àní, lẹ́ẹ̀kejì, ṣùgbọ́n ènìyàn kò róye rẹ̀.

15Nínú àlá, ní ojúran òru,

nígbà tí orun èjìká bá kùn ènìyàn lọ,

ní sísùn lórí ibùsùn,

16nígbà náà ni ó lè sọ̀rọ̀ ní etí wọn,

yóò sì dẹ́rùbà wọ́n pẹ̀lú ìbáwí,

17kí ó lè fa ènìyàn sẹ́yìn kúrò nínú ètè rẹ̀;

kí ó sì pa ìgbéraga mọ́ kúrò lọ́dọ̀ ènìyàn;

18Ó sì fa ọkàn rẹ̀ padà kúrò nínú isà òkú,

àti ẹ̀mí rẹ̀ láti ṣègbé lọ́wọ́ idà.

19“A sì nà án lórí ibùsùn ìrora rẹ̀;

pẹ̀lúpẹ̀lú a fi ìjà egungun rẹ̀ ti ó dúró pẹ́ nà án,

20bẹ́ẹ̀ ni ẹ̀mí rẹ kọ oúnjẹ,

ọkàn rẹ̀ sì kọ oúnjẹ dídùn.

21Ẹran-ara rẹ̀ run, títí a kò sì fi lè rí i mọ́

egungun rẹ̀ tí a kò tí rí sì ta jáde.

22Àní, ọkàn rẹ̀ sì súnmọ́ isà òkú,

ẹ̀mí rẹ̀ sì súnmọ́ ọ̀dọ̀ àwọn ìránṣẹ́ ikú.

23Bí angẹli kan ba wà lọ́dọ̀ rẹ̀,

ẹni tí ń ṣe alágbàwí,

ọ̀kan nínú ẹgbẹ̀rún (1,000) láti fi ọ̀nà pípé hàn ni,

24nígbà náà ni ó ṣe oore-ọ̀fẹ́ fún un ó sì wí pé,

gbà á kúrò nínú lílọ sínú isà òkú;

èmi ti rà á padà.

25Ara rẹ̀ yóò sì di ọ̀tun bí i ti ọmọ kékeré,

yóò sì tún padà sí ọjọ́ ìgbà èwe rẹ̀;

26Ó gbàdúrà sọ́dọ̀ Ọlọ́run, òun sì ṣe ojúrere rẹ̀,

o sì rí ojú rẹ̀ pẹ̀lú ayọ̀,

òhun o san òdodo rẹ̀ padà fún ènìyàn.

27Ó wá sọ́dọ̀ ènìyàn ó sì wí pé,

‘Èmi ṣẹ̀, kò sì ṣí èyí tí o tọ́, mo sì ti yí èyí tí ó tọ́ po,

a kò sì san ẹ̀san rẹ̀ fún mi;

28Ọlọ́run ti gba ọkàn mi kúrò nínú lílọ sínú ihò,

ẹ̀mí mi yóò wà láti jẹ adùn ìmọ́lẹ̀ ayé.’

29“Wò ó! Nǹkan wọ̀nyí ni Ọlọ́run

máa ń ṣe fún ènìyàn nígbà méjì àti nígbà mẹ́ta,

30láti mú ọkàn rẹ padà kúrò nínú isà òkú,

láti fi ìmọ́lẹ̀ alààyè han sí i.

31“Jobu, kíyèsi i gidigidi, kí o sì fetí sí mi;

pa ẹnu rẹ mọ́, èmi ó sì máa sọ ọ́.

32Bí ìwọ bá sì ní ohun wí, dá mi lóhùn;

máa sọ, nítorí pé èmi fẹ́ dá ọ láre.

33Bí bẹ́ẹ̀ kọ́, gbọ́ tèmi;

pa ẹnu rẹ mọ́, èmi ó sì kọ́ ọ ní ọgbọ́n.”

Священное Писание (Восточный перевод), версия с «Аллахом»

Аюб 33:1-33

1Так выслушай, Аюб, речи мои

и внимай всем моим словам.

2Вот я уже открываю уста,

говорит мой язык в гортани моей.

3Слова мои исходят от чистого сердца;

скажут честно, что знают уста мои.

4Дух Аллаха создал меня,

и дыхание Всемогущего животворит меня.

5Ответь же мне, если сможешь,

приготовься и возрази мне.

6Мы равны с тобой перед Аллахом –

из той же глины я взят.

7Страх передо мной тебя не смутит,

и рука моя тебе тяжела не будет.

8Ты при мне говорил,

и я слышал, как ты утверждал:

9«Я чист, и греха на мне нет.

Я невинен и непорочен.

10Но Аллах отыскал за мною вину

и считает меня врагом.

11Он ноги мои в колодки забил

и за всеми путями моими следит».

12Но я говорю тебе: ты не прав,

потому что Аллах выше смертного.

13Для чего тебе состязаться с Ним,

говоря, что на слова человека Он не отвечает?

14Ведь Аллах говорит разными путями,

хотя человек и не понимает.

15Во сне и в ночном видении,

когда смертных объемлет глубокий сон,

когда они дремлют на ложах своих,

16тогда Он открывает человеку слух

и страшит его Своими видениями,

17чтобы отвернуть его от зла

и удержать его от гордости,

18чтобы сберечь его душу от бездны

и не дать ему перейти реку смерти.

19Или вразумляет человека на ложе недуг,

и непрестанная боль в его костях,

20так что его внутренность гнушается хлебом,

а душа – лакомой пищей.

21Истощается его плоть, её и не видно,

выпирают его кости, скрытые прежде.

22Его душа приближается к бездне,

и жизнь – к ангелам смерти.

23Но если есть ангел на его стороне,

заступник, один из тысячи,

наставляющий человека на прямой путь,

24Аллах33:24 Согласно другому толкованию здесь жалеет и говорит не Аллах, а ангел-заступник из ст. 23. пожалеет его и скажет:

«Избавь его, пусть не сойдёт он в бездну;

за него Я выкуп нашёл»,

25то плоть его станет как у младенца,

и вернутся к нему его юные дни.

26Он помолится Аллаху и найдёт милость;

он увидит лицо Аллаха и возликует.

Аллах вернёт ему его праведность.

27Тогда он воспоёт перед людьми и скажет:

«Я согрешил, искажал правду,

но пользы мне это не принесло.

28Он искупил мою душу от бездны,

и я опять вижу свет».

29Истинно, всё это делает Аллах

со смертным два-три раза,

30чтобы душу его отвести от бездны,

чтобы свет живых на него просиял.

31Внимай мне, Аюб, и слушай меня;

молчи, и я буду говорить.

32Если есть, что сказать, то ответь мне;

говори, я хочу тебя оправдать.

33А если нет, то меня послушай;

молчи, и я научу тебя мудрости.