Jobu 20 – YCB & BPH

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Jobu 20:1-29

Ìdáhùn Sofari

1Ìgbà náà ní Sofari, ará Naama dáhùn, ó sì wí pé,

2“Nítorí náà ní ìrò inú mi dá mi lóhùn,

àti nítorí èyí náà ní mo sì yára si gidigidi.

3Mo ti gbọ́ ẹ̀san ẹ̀gàn mi,

ẹ̀mí òye mi sì dá mi lóhùn.

4“Ìwọ kò mọ̀ èyí rí ní ìgbà àtijọ́,

láti ìgbà tí a sọ ènìyàn lọ́jọ̀ sílé ayé,

5pé, orin ayọ̀ ènìyàn búburú, ìgbà kúkúrú ni,

àti pé, ní ìṣẹ́jú kan ní ayọ̀ àgàbàgebè?

6Bí ọláńlá rẹ̀ tilẹ̀ gòkè dé ọ̀run,

ti orí rẹ̀ sì kan àwọsánmọ̀;

7ṣùgbọ́n yóò ṣègbé láéláé bí ìgbẹ́ ara rẹ̀;

àwọn tí ó ti rí i rí yóò wí pé, ‘Òun ha dà?’

8Yóò fò lọ bí àlá, a kì yóò sì rí i,

àní a ó lé e lọ bi ìran òru.

9Ojú tí ó ti rí i rí kì yóò sì rí i mọ́,

bẹ́ẹ̀ ni ibùjókòó rẹ̀ kì yóò sì ri i mọ́.

10Àwọn ọmọ rẹ̀ yóò máa wá àti rí ojúrere lọ́dọ̀ tálákà,

ọwọ́ rẹ̀ yóò sì kó ọrọ̀ wọn padà.

11Egungun rẹ̀ kún fún agbára ìgbà èwe rẹ̀,

tí yóò bá a dùbúlẹ̀ nínú erùpẹ̀.

12“Bí ìwà búburú tilẹ̀ dún ní ẹnu rẹ̀,

bí ó tilẹ̀ pa á mọ́ nísàlẹ̀ ahọ́n rẹ̀,

13bí ó tilẹ̀ dá a sì, tí kò si kọ̀ ọ́ sílẹ̀,

tí ó pa á mọ́ síbẹ̀ ní ẹnu rẹ̀,

14ṣùgbọ́n oúnjẹ rẹ̀ nínú ikùn rẹ̀ ti yípadà,

ó jásí òróró paramọ́lẹ̀ nínú rẹ̀;

15Ó ti gbé ọrọ̀ mì, yóò sì tún bí i jáde;

Ọlọ́run yóò pọ̀ ọ́ yọ jáde láti inú rẹ̀ wá.

16Ó ti fà oró paramọ́lẹ̀ mú;

ahọ́n ejò olóró ní yóò pa á.

17Kì yóò rí odò wọ̀n-ọn-nì,

ìṣàn omi, odò tí ń ṣàn fún oyin àti ti òrí-àmọ́.

18Ohun tí ó ṣiṣẹ́ fún ni yóò mú un padà, kí yóò sì gbé e mì;

gẹ́gẹ́ bí ọrọ̀ tí ó ní, kì yóò sì ìgbádùn nínú rẹ̀.

19Nítorí tí ó fi owó rẹ̀ ni tálákà lára, ó sì ti pẹ̀yìndà si wọ́n;

nítorí ti ó fi agbára gbé ilé tí òun kò kọ́.

20“Nítorí òun kò mọ̀ ìwà pẹ̀lẹ́ nínú ara rẹ̀,

kì yóò sì gbà nínú èyí tí ọkàn rẹ̀ fẹ́ sílẹ̀.

21Ohun kan kò kù fún jíjẹ́ rẹ̀;

nítorí náà ọ̀rọ̀ rẹ̀ kì yóò dúró pẹ́.

22Nínú ànító rẹ̀, ìdààmú yóò dé bá a;

àwọn ènìyàn búburú yóò dáwọ́jọ lé e lórí.

23Yóò sì ṣe, nígbà tí ó bá fẹ́ jẹun,

Ọlọ́run yóò fà ríru ìbínú rẹ̀ sí í lórí, nígbà tó bá ń jẹun lọ́wọ́,

yóò sì rọ òjò ìbínú rẹ̀ lé e lórí.

24Bi o tilẹ̀ sá kúrò lọ́wọ́ ohun ìjà ìrìn;

ọrun akọ irin ní yóò ta a po yọ.

25O fà á yọ, ó sì jáde kúrò lára;

idà dídán ní ń jáde láti inú òróòro wá.

Ẹ̀rù ńlá ń bẹ ní ara rẹ̀;

26òkùnkùn biribiri ní a ti pamọ́ fún ìṣúra rẹ̀.

Iná ti a kò fẹ́ ní yóò jó o run

yóò sì jẹ èyí tí ó kù nínú àgọ́ rẹ̀ run.

27Ọ̀run yóò fi ẹ̀ṣẹ̀ rẹ hàn,

ayé yóò sì dìde dúró sí i.

28Ìbísí ilé rẹ̀ yóò kọjá lọ,

àti ohun ìní rẹ̀ yóò sàn dànù lọ ni ọjọ́ ìbínú Ọlọ́run.

29Èyí ni ìpín ènìyàn búburú láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run wá,

àti ogún tí a yàn sílẹ̀ fún un láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run.”

Bibelen på hverdagsdansk

Jobs Bog 20:1-29

Zofars anden tale til Job

1Derefter tog Zofar til genmæle:

2„Jeg bliver nødt til at sætte dig på plads,

for det, du siger, er oprørende.

3Det er nemt nok at anklage os,

men jeg ved, hvordan jeg skal svare dig.

4Ved du ikke, at fra tidernes morgen,

så længe der har været mennesker til,

5har de gudløses triumf været kort,

og deres glæde kun varet et øjeblik?

6Selv om deres selvglæde når til himlen,

og de går med næsen i sky,

7bliver de kastet bort som affald,

og deres venner spørger, hvor de blev af.

8De forsvinder som en drøm, når man vågner,

fordufter, som var det hele et synsbedrag.

9Deres venner ser dem ikke mere,

aldrig vender de tilbage til deres hjemby.

10Børnene må levere tilbage, hvad deres fædre har stjålet,

for de svage skal have det igen, som blev taget fra dem.

11De gudløse dør og bliver lagt i graven,

selv om de stadig var unge og stærke.

12De elsker smagen af synd,

nyder den i fulde drag,

13lader den smelte langsomt på tungen,

synker den med stort velbehag.

14Men i maven giver den voldsomme smerter,

som var det slangegift, de havde slugt.

15Gud sørger for, at de kaster den op,

den velstand de guffede i sig, kommer op igen.

16Men giften har gjort sin virkning,

de går til som bidt af en slange.

17De kan ikke længere skumme fløden

eller nyde en overflod af honning.

18De må aflevere deres uretmæssige bytte,

får ikke glæde af det, de har ranet.

19For de knuste ubarmhjertigt de hjælpeløse,

overtog huse, som ikke var deres.

20Altid skrabede de til sig,

men intet af det får de gavn af.

21De stjal, hvad de kunne få fat i,

men den slags rigdom varer ikke ved.

22Midt i velstanden rammes de af ulykken,

katastroferne regner ned over dem.

23Mens de sidder i fred og spiser,

rammes de af Guds vrede,

han lader slagene hagle ned over dem.

24De prøver at flygte for sværdet,

men bliver ramt i ryggen af en pil.

25Når de trækker pilen ud,

drypper spidsen af galde.

Dødens rædsler står malet i deres ansigter,

26deres skatte ender i glemslens mørke.

Guds ild fortærer dem,

opbrænder alle deres ejendele.

27Himlens magter straffer dem for deres synd,

jorden vidner imod dem.

28Guds vrede regner ned over dem,

deres huse skylles væk af en flodbølge.

29Sådan er de gudløses skæbne.

Det er Gud selv, der straffer dem.”