Jobu 14 – YCB & HOF

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Jobu 14:1-22

Jobu tẹ̀síwájú nínú àròyé rẹ̀

1“Ènìyàn tí a bí nínú obìnrin,

ọlọ́jọ́ díẹ̀ ni, ó sì kún fún ìpọ́njú.

2Ó jáde wá bí ìtànná ewéko, a sì ké e lulẹ̀;

ó sì ń fò lọ bí òjìji, kò sì dúró pẹ́.

3Ìwọ sì ń síjú rẹ wò irú èyí ni?

Ìwọ sì mú mi wá sínú ìdájọ́ pẹ̀lú rẹ?

4Ta ni ó lè mú ohun mímọ́ láti inú àìmọ́ jáde wá?

Kò sí ẹnìkan!

5Ǹjẹ́ a ti pinnu ọjọ́ rẹ̀,

iye oṣù rẹ̀ ń bẹ ní ọwọ́ rẹ,

ìwọ ti pààlà rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ní òun kò le kọjá rẹ̀.

6Yípadà kúrò lọ́dọ̀ rẹ̀, kí ó lè sinmi,

títí yóò fi pé ọjọ́ rẹ̀ bí alágbàṣe.

7“Nítorí pé ìrètí wà fún igi, bí a bá

ké e lulẹ̀, pé yóò sì tún sọ,

àti pé ẹ̀ka rẹ̀ tuntun kì yóò gbẹ.

8Bí gbòǹgbò rẹ̀ tilẹ̀ di ogbó nínú ilẹ̀,

tí kùkùté rẹ̀ si kú ni ilẹ̀,

9síbẹ̀ nígbà tí ó bá gbóòórùn omi,

yóò sọ, yóò sì yọ ẹ̀ka jáde bí irúgbìn.

10Ṣùgbọ́n ènìyàn kú, a sì dàánù,

àní ènìyàn jọ̀wọ́ ẹ̀mí rẹ̀ lọ́wọ́: Òun kò sì sí mọ́.

Àgékúrú ọjọ́ ọmọ ènìyàn

11“Bí omi ti í tán nínú ipa odò,

àti bí odò ṣì tí í fà tí sì gbẹ,

12bẹ́ẹ̀ ni ènìyàn dùbúlẹ̀ tí kò sì dìde mọ́;

títí ọ̀run kì yóò fi sí mọ́,

wọ́n kì yóò jí, a kì yóò jí wọn kúrò lójú oorun wọn.

13“Háà! ìwọ ìbá fi mí pamọ́ ní ipò òkú,

kí ìwọ kí ó fi mí pamọ́ ní ìkọ̀kọ̀,

títí ìbínú rẹ yóò fi rékọjá,

ìwọ ìbá lànà ìgbà kan sílẹ̀ fún mi, kí ó si rántí mi!

14Bí ènìyàn bá kú yóò sì tún yè bí?

Gbogbo ọjọ́ ìgbà tí a là sílẹ̀

fún mi ni èmi dúró dè, títí àmúdọ̀tún mi yóò fi dé.

15Ìwọ ìbá pè, èmi ìbá sì dá ọ lóhùn;

ìwọ ó sì ní ìfẹ́ sì iṣẹ́ ọwọ́ rẹ.

16Ṣùgbọ́n nísinsin yìí ìwọ ń kaye ìṣísẹ̀ mi;

ìwọ kò fa ọwọ́ rẹ kúrò nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mi?

17A fi èdìdì di ìrékọjá mi sínú àpò,

ìwọ sì rán àìṣedéédéé mi pọ̀.

18“Àti nítòótọ́ òkè ńlá tí ó ṣubú, ó dasán,

a sì ṣí àpáta kúrò ní ipò rẹ̀.

19Omi a máa yinrin òkúta, ìwọ a sì

mú omi sàn bo ohun tí ó hù jáde lórí ilẹ̀,

ìwọ sì sọ ìrètí ènìyàn dí òfo.

20Ìwọ ṣẹ́gun rẹ̀ láéláé, òun sì kọjá lọ!

Ìwọ pa awọ ojú rẹ̀ dà, o sì rán an lọ kúrò.

21Àwọn ọmọ rẹ̀ bọ́ sí ipò ọlá, òun kò sì mọ̀;

wọ́n sì rẹ̀ sílẹ̀, òun kò sì kíyèsi i lára wọn.

22Ṣùgbọ́n ẹran-ara rẹ̀ ni yóò rí ìrora

ọkàn rẹ̀ ni yóò sì máa ní ìbìnújẹ́ nínú rẹ̀.”

Hoffnung für Alle

Hiob 14:1-22

Gott, versteck mich doch bei den Toten!

1»Wie vergänglich ist der Mensch!

Wie kurz sind seine Jahre!

Wie mühsam ist sein Leben!

2Er blüht auf wie eine Blume –

und verwelkt;

er verschwindet wie ein Schatten –

und fort ist er!

3Und doch verlierst du ihn nicht aus den Augen

und stellst ihn vor dein Gericht!

4Du musst doch wissen, dass aus Unreinheit nichts Reines entsteht.

Wie sollte da ein Mensch vollkommen sein? Alle sind mit Schuld beladen!14,4 Wörtlich: Wie könnte ein Reiner vom Unreinen kommen? Nicht einer! – Vgl. »rein/unrein« in den Sacherklärungen.

5Die Jahre eines jeden Menschen sind gezählt;

die Dauer seines Lebens hast du festgelegt.

Du hast ihm eine Grenze gesetzt,

die er nicht überschreiten kann.

6So schau jetzt weg von ihm,

damit er Ruhe hat und seines Lebens noch froh wird,

wie ein Arbeiter am Feierabend!

7Für einen Baum gibt es immer noch Hoffnung,

selbst wenn man ihn gefällt hat;

aus dem Stumpf wachsen wieder frische Triebe nach.

8Auch wenn seine Wurzeln im Erdreich absterben

und der Stumpf langsam im Boden vertrocknet,

9erwacht er doch zu neuem Leben,

sobald er Wasser bekommt.

Neue Triebe schießen empor wie bei einer jungen Pflanze.

10Aber wenn ein Mensch gestorben ist,

dann ist er dahin.

Er hat sein Leben ausgehaucht. Wo ist er nun?

11Wie Wasser, das aus einem See ausläuft,

und wie ein Flussbett, das vertrocknet,

12so ist der Mensch, wenn er stirbt:

Er legt sich nieder und steht nie wieder auf.

Ja, die Toten werden niemals erwachen,

solange der Himmel besteht!

Nie wieder werden sie aus ihrem Schlaf erweckt!

13O Gott, versteck mich doch bei den Toten!

Schließ mich für eine Weile dort ein,

bis dein Zorn verflogen ist!

Aber setz dir eine Frist und denk dann wieder an mich! –

14Meinst du, ein Mensch wird wieder lebendig,

wenn er gestorben ist? –

Dann könnte ich trotz meiner Qualen auf bessere Zeiten hoffen

wie ein Zwangsarbeiter, der die Tage bis zu seiner Entlassung zählt.

15Denn dann wirst du mich rufen, und ich werde dir antworten.

Du wirst dich nach mir sehnen,

weil du selbst mich geschaffen hast.

16Meine Wege siehst du auch dann noch,

aber meine Sünden hältst du mir nicht mehr vor.

17Was immer ich begangen habe,

verschließt du wie in einem Beutel,

meine Schuld löschst du für immer aus.

18Doch selbst Berge stürzen und zerfallen,

Felsen rutschen zu Tal.

19Wasser zermahlt die Steine zu Sand,

und Sturzbäche reißen den Erdboden fort.

Genauso zerstörst du jede Hoffnung des Menschen.

20Du überwältigst ihn, zwingst ihn zu Boden;

mit entstelltem Gesicht liegt er da und stirbt.

Du schickst ihn fort – er kommt nie wieder.

21Ob seine Kinder einst berühmt sind

oder ob man sie verachtet,

er weiß nichts davon.

Ihre Zukunft bleibt ihm völlig verborgen.

22Er fühlt nur die eigenen Schmerzen

und trauert nur über sich selbst.«