Jobu 11 – YCB & ASCB

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Jobu 11:1-20

Sofari fi ẹ̀sùn irọ́ pípa àti àìṣòótọ́ kan Jobu

1Ìgbà náà ni Sofari, ará Naama, dáhùn, ó sì wí pé,

2“A ha lè ṣe kí a máa dáhùn sí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọ̀rọ̀?

A ha lè fi gbogbo ọ̀rọ̀ wọ̀nyí da ènìyàn láre?

3Ṣé àmọ̀tán rẹ le mú ènìyàn pa ẹnu wọn mọ́ bí?

Ṣé ẹnikẹ́ni kò ní bá ọ wí bí ìwọ bá yọ ṣùtì sí ni?

4Ìwọ sá à ti wí fún Ọlọ́run pé, ‘Ìṣe mi jẹ́ aláìléérí,

èmi sì mọ́ ní ojú rẹ.’

5Ṣùgbọ́n Ọlọ́run ìbá jẹ́ sọ̀rọ̀,

kí ó sì ya ẹnu rẹ̀ sí ọ

6kí ó sì fi àṣírí ọgbọ́n hàn ọ́ pé, ó pọ̀ ju òye ènìyàn lọ,

nítorí náà, mọ̀ pé Ọlọ́run ti

gbàgbé àwọn ẹ̀ṣẹ̀ rẹ kan.

7“Ìwọ ha le ṣe àwárí ohun ìjìnlẹ̀ Ọlọ́run bí?

Ìwọ ha le ṣe àwárí ibi tí Olódùmarè dé bi?

8Ó ga ju àwọn ọ̀run lọ; kí ni ìwọ le è ṣe?

Ó jìn ju jíjìn isà òkú lọ; kí ni ìwọ le mọ̀?

9Ìwọ̀n rẹ̀ gùn ju ayé lọ,

ó sì ní ibú ju òkun lọ.

10“Bí òun bá rékọjá, tí ó sì sé ọnà

tàbí tí ó sì mú ni wá sí ìdájọ́, ǹjẹ́, ta ni ó lè dí i lọ́wọ́?

11Òun sá à mọ ẹlẹ́tàn ènìyàn;

àti pé ṣé bí òun bá rí ohun búburú, ṣé òun kì i fi iyè sí i?

12Ṣùgbọ́n òmùgọ̀ ènìyàn ki yóò di ọlọ́gbọ́n

bi ko ti rọrùn fún ọmọ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ igbó láti bí ènìyàn.

13“Bí ìwọ bá fi ọkàn rẹ fún un,

tí ìwọ sì na ọwọ́ rẹ sí ọ̀dọ̀ rẹ̀,

14bí ìwọ bá gbé ẹ̀ṣẹ̀ tí ń bẹ ní ọwọ́ rẹ jù sọnù

tí ìwọ kò sì jẹ́ kí aburú gbé nínú àgọ́ rẹ,

15nígbà náà ni ìwọ ó gbé ojú rẹ sókè láìní àbàwọ́n,

àní ìwọ yóò dúró ṣinṣin, ìwọ kì yóò sì bẹ̀rù.

16Nítorí pé ìwọ ó gbàgbé ìṣòro rẹ;

ìwọ ó sì rántí rẹ̀ bí omi tí ó ti sàn kọjá lọ.

17Ọjọ́ ayé rẹ yóò sì mọ́lẹ̀ ju ọ̀sán gangan lọ,

bí òkùnkùn tilẹ̀ bò ọ́ mọ́lẹ̀ nísinsin yìí, ìwọ ó dàbí òwúrọ̀.

18Ìwọ ó sì wà láìléwu, nítorí pé ìrètí wà;

àní ìwọ ó rin ilé rẹ wò, ìwọ ó sì sinmi ní àlàáfíà.

19Ìwọ ó sì dùbúlẹ̀ pẹ̀lú, kì yóò sì sí ẹni tí yóò dẹ́rùbà ọ́,

àní ènìyàn yóò máa wá ojúrere rẹ.

20Ṣùgbọ́n ojú ìkà ènìyàn yóò mófo;

gbogbo ọ̀nà àbáyọ ni yóò nù wọ́n,

ìrètí wọn a sì dàbí ẹni tí ó jọ̀wọ́ ẹ̀mí rẹ̀ lọ́wọ́.”

Asante Twi Contemporary Bible

Hiob 11:1-20

Sofar Mmuaeɛ A Ɛdi Ɛkan

1Na Naamani Sofar buaa sɛ,

2“Ɛnsɛ sɛ wɔyi saa nsɛm yi ano anaa?

Ɛsɛ sɛ wɔbu saa ɔkasafoɔ yi bem anaa?

3Wo nsɛm hunu no bɛma nnipa ayɛ komm anaa?

Sɛ wodi fɛ a obiara renka wʼanim anaa?

4Woka kyerɛ Onyankopɔn sɛ, ‘Me gyidie ho nni asɛm

na meyɛ pɛ wɔ wʼani so.’

5Ao, anka mepɛ sɛ Onyankopɔn kasa,

anka ɔnkasa ntia wo

6na ɔmmue nyansa mu ahintasɛm so nkyerɛ wo,

ɛfiri sɛ nyansa turodoo yɛ afanu.

Hunu yei sɛ, Onyankopɔn werɛ afiri wo bɔne no bi mpo.

7“Wobɛtumi ate Onyankopɔn anwanwadeɛ ase anaa?

Wobɛtumi abɔre ahunu deɛ Otumfoɔ no tumi kɔpem anaa?

8Ɛkorɔn sene ɔsoro, ɛdeɛn na wobɛtumi ayɛ?

Emu dɔ sene damena ase tɔnn, ɛdeɛn na wobɛtumi ahunu?

9Ne nsusuiɛ mu ware sene asase

na ɛtrɛ sene ɛpo.

10“Sɛ ɔba na ɔde wo to nneduadan mu

ansa na wasi nkonnwa a, hwan na ɔbɛtumi asi no ɛkwan?

11Ampa ara ɔhyɛ nnipa nnaadaafoɔ nso;

na sɛ ɔhunu amumuyɛ a, ɔnhyɛ ne nso anaa?

12Nanso ogyimifoɔ rentumi nyɛ onyansafoɔ

sɛdeɛ wɔrentumi nwo afunumu ba sɛ onipa no.

13“Na sɛ wode wʼakoma ma no

na wopagya wo nsa kyerɛ no,

14sɛ wogyaa bɔne a wokura no mu

na woamma amumuyɛ antena wo ntomadan mu a,

15ɛnneɛ, wobɛpagya wo ti a womfɛre;

wobɛgyina pintinn a wonsuro.

16Wo werɛ bɛfiri wʼahokyere,

na ɛbɛyɛ wo sɛ nsuo a asene korɔ.

17Wʼabrabɔ bɛhyerɛn asene owigyinaeɛ,

na esum bɛyɛ sɛ adekyeɛ hann.

18Wobɛnya banbɔ, ɛfiri sɛ anidasoɔ wɔ hɔ;

wobɛhwɛ wo ho ahyia, na wahome asomdwoeɛ mu.

19Wobɛda ahome, na obi renhunahuna wo,

na bebree bɛhwehwɛ mmoa afiri wo nkyɛn.

20Amumuyɛfoɔ ani bɛfira,

wɔrentumi nnwane;

na wɔn anidasoɔ bɛdane owuo ahomeguo.”