Joẹli 2 – YCB & NVI-PT

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Joẹli 2:1-32

Àwọn jagunjagun eṣú

1Ẹ fun ìpè ní Sioni,

ẹ sì fún ìpè ìdágìrì ní òkè mímọ́ mi.

Jẹ́ kí àwọn ará ilẹ̀ náà wárìrì,

nítorí tí ọjọ́ Olúwa ń bọ̀ wá,

nítorí ó kù sí dẹ̀dẹ̀.

2Ọjọ́ òkùnkùn àti ìrọ́kẹ̀kẹ̀,

ọjọ́ ìkùùkuu àti òkùnkùn biribiri.

Bí ọyẹ́ òwúrọ̀ ti í la bo orí àwọn òkè ńlá:

àwọn ènìyàn ńlá àti alágbára; ya dé,

ti kó ti ì sí irú rẹ̀ rí,

bẹ́ẹ̀ ni irú rẹ̀ kì yóò sí mọ́ lẹ́yìn rẹ̀, títí dé ọdún ìran dé ìran.

3Iná ń jó níwájú wọ́n;

ọwọ́ iná sì ń jó lẹ́yìn wọn.

Ilẹ̀ náà dàbí ọgbà Edeni níwájú wọn,

àti lẹ́yìn wọn bí ahoro ijù;

nítòótọ́, kò sì sí ohun tí yóò bọ́ lọ́wọ́ wọn.

42.4-5: If 9.7,9.Ìrí wọn dàbí ìrí àwọn ẹṣin;

wọ́n ń sáré lọ bí àwọn ẹlẹ́ṣin ogun.

5Bí ariwo kẹ̀kẹ́ ogun ni

wọn ń fo ní orí òkè

bí ariwo ọ̀wọ́-iná tí ń jó koríko gbígbẹ,

bí akọni ènìyàn tí a kójọ fún ogun.

6Ní ojú wọn, àwọn ènìyàn yóò jẹ ìrora púpọ̀:

gbogbo ojú ní yóò ṣú dudu.

7Wọn yóò sáré bi àwọn alágbára;

wọn yóò gùn odi bí ọkùnrin ológun;

olúkúlùkù wọn yóò sì rìn lọ ní ọ̀nà rẹ̀,

wọn kì yóò sì yà kúrò ni ọ̀nà wọn.

8Bẹ́ẹ̀ ni ẹnìkan kì yóò kọlu ẹnìkejì rẹ̀;

olúkúlùkù wọn yóò rìn ní ọ̀nà rẹ̀,

nígbà tí wọn bá sì ṣubú lù idà

wọn kì yóò gbọgbẹ́.

9Wọn yóò sáré síwá sẹ́yìn ní ìlú;

wọn yóò súré lórí odi,

wọn yóò gùn orí ilé;

wọn yóò gbà ojú fèrèsé wọ̀ inú ilé bí olè.

102.10: If 9.2.Ayé yóò mì níwájú wọn;

àwọn ọ̀run yóò wárìrì;

oòrùn àti òṣùpá yóò ṣókùnkùn,

àwọn ìràwọ̀ yóò sì fà ìmọ́lẹ̀ wọn sẹ́yìn.

112.11: If 6.17.Olúwa yóò sì bú ramúramù

jáde níwájú ogun rẹ̀:

nítorí ibùdó rẹ̀ tóbi gidigidi;

nítorí alágbára ní òun, tí n mú ọ̀rọ̀ rẹ̀ ṣẹ;

nítorí ọjọ́ Olúwa tóbi ó sì ní ẹ̀rù gidigidi;

ara ta ni ó lè gbà á?

Fa ọkàn rẹ ya

12“Ǹjẹ́ nítorí náà nísinsin yìí,” ni Olúwa wí,

“Ẹ fi gbogbo ọkàn yín yípadà sí mi,

àti pẹ̀lú àwẹ̀, àti pẹ̀lú ẹkún, àti pẹ̀lú ọ̀fọ̀.”

13Ẹ sì fa ọkàn yín ya,

kì í sì í ṣe aṣọ yín,

ẹ sì yípadà sí Olúwa Ọlọ́run yín,

nítorí tí o pọ̀ ní oore-ọ̀fẹ́,

ó sì kún fun àánú, ó lọ́ra láti bínú,

ó sì ṣeun púpọ̀, ó sì ronúpìwàdà láti ṣe búburú.

14Ta ni ó mọ̀ bí òun yóò yípadà, kí o sì ronúpìwàdà,

kí ó sì fi ìbùkún sílẹ̀ lẹ́yìn rẹ̀—

àní ọrẹ-jíjẹ àti ọrẹ mímu

fún Olúwa Ọlọ́run yín?

15Ẹ fún ìpè ní Sioni,

ẹ ya àwẹ̀ kan sí mímọ́,

ẹ pe àjọ tí ó ni ìrònú.

16Ẹ kó àwọn ènìyàn jọ,

ẹ ya ìjọ sí mímọ́;

ẹ pe àwọn àgbàgbà jọ,

ẹ kó àwọn ọmọdé jọ,

àti àwọn tí ń mú ọmú,

jẹ kí ọkọ ìyàwó kúrò nínú ìyẹ̀wù rẹ̀.

Kí ìyàwó sì kúrò nínú iyàrá rẹ̀.

17Jẹ́ kí àwọn àlùfáà, àwọn ìránṣẹ́ Olúwa,

sọkún láàrín ìloro àti pẹpẹ.

Sí jẹ́ kí wọn wí pé, “Dá àwọn ènìyàn rẹ sí, Olúwa.

Má sì ṣe fi ìní rẹ fun ẹ̀gàn,

tí yóò sì di òwe ní àárín àwọn kèfèrí.

Èéṣe tí wọn yóò fi wí láàrín àwọn ènìyàn pé,

‘Ọlọ́run wọn ha da?’ ”

Olúwa ra Juda padà

18Nígbà náà ní Olúwa yóò jowú fún ilẹ̀ rẹ̀,

yóò sì káàánú fún ènìyàn rẹ̀.

19Nítòótọ́, Olúwa yóò dá wọn lóhùn, yóò sì wí fun àwọn ènìyàn rẹ̀ pé:

“Wò ó èmi yóò rán ọkà, àti ọtí wáìnì tuntun, àti òróró sí i yín,

a ó sì fi wọn tẹ́ yín lọ́rùn;

Èmi kì yóò sì fi yín ṣe ẹ̀gàn mọ́

láàrín àwọn aláìkọlà.

20“Ṣùgbọ́n èmi yóò lé ogun àríwá jìnnà réré kúrò lọ́dọ̀ yín,

èmi yóò sì lé e lọ sí ilẹ̀ tí ó ṣá, tí ó sì di ahoro,

pẹ̀lú ojú rẹ̀ sí Òkun ìlà-oòrùn,

àti ẹ̀yìn rẹ̀ sí ìwọ̀-oòrùn Òkun.

Òórùn rẹ̀ yóò sì gòkè,

òórùn búburú rẹ̀ yóò sì gòkè.”

Nítòótọ́ ó ti ṣe ohun ńlá.

21Má bẹ̀rù, ìwọ ilẹ̀;

jẹ́ kí inú rẹ̀ dùn kí o sì yọ̀,

nítorí Olúwa ti ṣe ohun ńlá.

22Ẹ má bẹ̀rù, ẹranko igbó,

nítorí pápá oko aginjù ń rú.

Nítorí igi ń so èso rẹ̀,

igi ọ̀pọ̀tọ́ àti àjàrà ń so èso ọ̀rọ̀ wọn.

23Ẹ jẹ́ kí inú yín dùn, ẹ̀yin ọmọ Sioni,

ẹ sì yọ̀ nínú Olúwa Ọlọ́run yín,

nítorí ó ti fi àkọ́rọ̀ òjò fún yín bí ó ti tọ́,

Òun ti mú kí òjò rọ̀ sílẹ̀ fún un yín,

àkọ́rọ̀ àti àrọ̀kúrò òjò ní oṣù kìn-ín-ní.

24Àwọn ilẹ̀ ìpakà yóò kún fún ọkà;

àti ọpọ́n wọn nì yóò sàn jáde

pẹ̀lú ọtí wáìnì tuntun àti òróró.

25“Èmi yóò sì mú ọdún wọ̀nyí ti eṣú jẹ run padà fún un yín.

Èyí tí eṣú agénijẹ àti eṣú jewéjewé

ọwọ́ eṣú agénijẹ àti kòkòrò ajẹnirun mìíràn ti fi jẹ

àwọn ogun ńlá mi tí mo rán sí àárín yín.

26Ẹ̀yin yóò ni ọ̀pọ̀lọpọ̀ láti jẹ, títí ẹ̀yin yóò fi yó

ẹ ó sì yín orúkọ Olúwa Ọlọ́run yín,

ẹni tí ó fi ìyanu bá yín lò;

ojú kì yóò sì ti àwọn ènìyàn mi láéláé.

27Ẹ̀yin yóò sì mọ̀ pé, èmi wà láàrín Israẹli,

àti pé; Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín,

àti pé kò sí ẹlòmíràn,

ojú kì yóò sì ti àwọn ènìyàn mí láéláé.

Ọjọ́ Olúwa

282.28-32: Ap 2.17-21.“Yóò sì ṣe níkẹyìn ọjọ́,

èmi yóò tú nínú Ẹ̀mí mí sí ara ènìyàn gbogbo;

àwọn ọmọ yín ọkùnrin àti àwọn ọmọ yín obìnrin yóò máa sọtẹ́lẹ̀,

àwọn arúgbó yín yóò máa lá àlá,

àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin yín yóò máa ríran.

29Àti pẹ̀lú sí ara àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ ọkùnrin,

àti sí ara àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ obìnrin,

ní èmi yóò tú ẹ̀mí mí jáde ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì.

30Èmi yóò sì fi iṣẹ́ ìyanu hàn ní ọrun

àti ní ayé,

ẹ̀jẹ̀ àti iná, àti ọ̀wọ́n èéfín.

312.31: If 6.12.A á sọ oòrùn di òkùnkùn,

àti òṣùpá di ẹ̀jẹ̀,

kí ọjọ́ ńlá àti ọjọ́ ẹ̀rù Olúwa tó dé.

322.32: Ro 10.13.Yóò sí ṣe, ẹnikẹ́ni tí ó ba ké pè

orúkọ Olúwa ní a ó gbàlà,

nítorí ní òkè Sioni àti ní Jerusalẹmu

ní ìgbàlà yóò gbé wà,

Olúwa ti wí,

àti nínú àwọn

ìyókù tí Olúwa yóò pè.

Nova Versão Internacional

Joel 2:1-32

O Dia do Senhor se Aproxima

1Toquem a trombeta em Sião;

deem o alarme no meu santo monte.

Tremam todos os habitantes do país,

pois o dia do Senhor está chegando.

Está próximo!

2É dia de trevas e de escuridão,

dia de nuvens e negridão.

Assim como a luz da aurora

se estende pelos montes,

um grande e poderoso exército se aproxima,

como nunca antes se viu

nem jamais se verá nas gerações futuras.

3Diante deles o fogo devora,

atrás deles arde uma chama.

Diante deles a terra é como o jardim do Éden,

atrás deles, um deserto arrasado;

nada lhes escapa.

4Eles têm a aparência de cavalos;

como cavalaria, atacam galopando.

5Com um barulho semelhante ao de carros

saltam sobre os cumes dos montes

como um fogo crepitante

que consome o restolho,

como um exército poderoso

em posição de combate.

6Diante deles povos se contorcem angustiados;

todos os rostos ficam pálidos de medo.

7Eles atacam como guerreiros;

escalam muralhas como soldados.

Todos marcham em linha,

sem desviar-se do curso.

8Não empurram uns aos outros;

cada um marcha sempre em frente.

Avançam por entre os dardos2.8 Ou pela passagem de água

sem desfazer a formação.

9Lançam-se sobre a cidade;

correm ao longo da muralha.

Sobem nas casas;

como ladrões entram pelas janelas.

10Diante deles a terra treme,

os céus estremecem,

o sol e a lua escurecem

e as estrelas param de brilhar.

11O Senhor levanta a sua voz

à frente do seu exército.

Como é grande o seu exército!

Como são poderosos os que obedecem à sua ordem!

Como é grande o dia do Senhor!

Como será terrível!

Quem poderá suportá-lo?

Chamado ao Arrependimento

12“Agora, porém”, declara o Senhor,

“voltem-se para mim de todo o coração,

com jejum, lamento e pranto.”

13Rasguem o coração e não as vestes.

Voltem-se para o Senhor, o seu Deus,

pois ele é misericordioso e compassivo,

muito paciente e cheio de amor;

arrepende-se e não envia a desgraça.

14Talvez ele volte atrás, arrependa-se,

e ao passar deixe uma bênção.

Assim vocês poderão fazer ofertas de cereal

e ofertas derramadas

para o Senhor, o seu Deus.

15Toquem a trombeta em Sião,

decretem jejum santo,

convoquem uma assembleia sagrada.

16Reúnam o povo,

consagrem a assembleia;

ajuntem os anciãos,

reúnam as crianças,

mesmo as que mamam no peito.

Até os recém-casados

devem deixar os seus aposentos.

17Que os sacerdotes, que ministram perante o Senhor,

chorem entre o pórtico do templo e o altar, orando:

“Poupa o teu povo, Senhor.

Não faças da tua herança objeto de zombaria

e de chacota entre as nações.

Por que se haveria de dizer pelos povos:

‘Onde está o Deus deles?’ ”

A Resposta do Senhor

18Então o Senhor mostrou zelo por sua terra

e teve piedade do seu povo.

19O Senhor respondeu2.18,19 Ou o Senhor mostrará zelo… e terá piedade… 19 O Senhor responderá ao seu povo:

“Estou enviando para vocês trigo,

vinho novo e azeite, o bastante

para satisfazê-los plenamente;

nunca mais farei de vocês

objeto de zombaria para as nações.

20“Levarei o invasor que vem do norte

para longe de vocês,

empurrando-o para uma terra seca e estéril,

a vanguarda para o mar oriental2.20 Isto é, o mar Morto.

e a retaguarda para o mar ocidental2.20 Isto é, o Mediterrâneo..

E a sua podridão subirá;

o seu mau cheiro se espalhará”.

Ele tem feito coisas grandiosas!

21Não tenha medo, ó terra;

regozije-se e alegre-se.

O Senhor tem feito coisas grandiosas!

22Não tenham medo, animais do campo,

pois as pastagens estão ficando verdes.

As árvores estão dando os seus frutos;

a figueira e a videira estão carregadas.

23Ó povo de Sião, alegre-se

e regozije-se no Senhor, o seu Deus,

pois ele dá a vocês as chuvas de outono,

conforme a sua justiça2.23 Ou no tempo certo.

Ele envia a vocês muitas chuvas,

as de outono e as de primavera, como antes fazia.

24As eiras ficarão cheias de trigo;

os tonéis transbordarão de vinho novo e de azeite.

25“Vou compensá-los pelos anos de colheitas

que os gafanhotos destruíram:

o gafanhoto peregrino,

o gafanhoto devastador,

o gafanhoto devorador

e o gafanhoto cortador,

o meu grande exército

que enviei contra vocês.

26Vocês comerão até ficarem satisfeitos,

e louvarão o nome do Senhor, o seu Deus,

que fez maravilhas em favor de vocês;

nunca mais o meu povo será humilhado.

27Então vocês saberão que eu estou no meio de Israel.

Eu sou o Senhor, o seu Deus,

e não há nenhum outro;

nunca mais o meu povo será humilhado.

O Dia do Senhor

28“E, depois disso,

derramarei do meu Espírito sobre todos os povos.

Os seus filhos e as suas filhas profetizarão,

os velhos terão sonhos,

os jovens terão visões.

29Até sobre os servos e as servas

derramarei do meu Espírito naqueles dias.

30Mostrarei maravilhas no céu e na terra:

sangue, fogo e nuvens de fumaça.

31O sol se tornará em trevas,

e a lua em sangue,

antes que venha o grande e temível dia do Senhor.

32E todo aquele que invocar

o nome do Senhor será salvo,

pois, conforme prometeu o Senhor,

no monte Sião e em Jerusalém

haverá livramento

para os sobreviventes,

para aqueles a quem o Senhor chamar.