Joṣua 1 – YCB & CARS

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Joṣua 1:1-18

Olúwa pàṣẹ fún Joṣua

1Lẹ́yìn ikú u Mose ìránṣẹ́ Olúwa, Olúwa sọ fún Joṣua ọmọ Nuni, olùrànlọ́wọ́ ọ Mose, 2“Mose ìránṣẹ́ mi ti kú. Nísinsin yìí, ìwọ àti gbogbo àwọn ènìyàn wọ̀nyí, ẹ múra láti kọjá odò Jordani lọ sí ilẹ̀ tí Èmi ó fi fún wọn fún àwọn ará Israẹli. 3Èmi yóò fún un yín ní gbogbo ibi tí ẹ bá fi ẹsẹ̀ ẹ yín tẹ̀, gẹ́gẹ́ bí mo ti ṣe ìlérí fún Mose. 4Ilẹ̀ ẹ yín yóò fẹ̀ láti aginjù Lebanoni, àti láti odò ńlá, ti Eufurate—gbogbo orílẹ̀-èdè Hiti títí ó fi dé Òkun Ńlá ní ìwọ̀-oòrùn. 51.5: Hb 13.5.Kì yóò sí ẹnikẹ́ni tí yóò le è dúró níwájú rẹ ní ọjọ́ ayé è rẹ gbogbo. Bí mo ti wà pẹ̀lú u Mose, bẹ́ẹ̀ ni Èmi yóò wà pẹ̀lú rẹ, Èmi kì yóò fi ọ́ sílẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni Èmi kì yóò kọ̀ ọ́.

6“Jẹ́ alágbára kí o sì mú àyà le, nítorí ìwọ ni yóò ṣe amọ̀nà àwọn ènìyàn wọ̀nyí, láti lè jogún ilẹ̀ tí mo ti búra fún àwọn baba ńlá a wọn láti fi fún wọn. 7Jẹ́ alágbára, kí o sì mú àyà le gidigidi. Kí o sì ṣọ́ra láti pa gbogbo òfin tí Mose ìránṣẹ́ mi fún ọ mọ́, má ṣe yà kúrò nínú u rẹ̀ sí ọ̀tún tàbí sí òsì, kí ìwọ kí ó lè ṣe rere níbikíbi tí ìwọ bá ń lọ. 8Má ṣe jẹ́ kí ìwé òfin yìí kúrò ní ẹnu rẹ, máa ṣe àṣàrò nínú u rẹ̀ ní ọ̀sán àti ní òru, kí ìwọ kí ó lè ṣọ́ra láti ṣe gbogbo nǹkan tí a kọ sí inú u rẹ̀. Nígbà náà ni yóò dára fún ọ, ìwọ yóò sì ní àṣeyọrí. 9Èmi kò ha ti pàṣẹ fún ọ bí? Jẹ́ alágbára kí o sì mú àyà le. Má ṣe bẹ̀rù, má sì ṣe rẹ̀wẹ̀sì, nítorí pé Olúwa à rẹ yóò wà pẹ̀lú rẹ ní ibikíbi tí ìwọ bá ń lọ.”

10Báyìí ni Joṣua pàṣẹ fún olórí àwọn ènìyàn rẹ̀, 11“Ẹ la ibùdó já, kí ẹ sì sọ fún àwọn ènìyàn, ‘Ẹ pèsè oúnjẹ yín sílẹ̀. Ní ìwòyí ọ̀túnla, ẹ̀yin yóò la Jordani yìí kọjá, láti gba ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run yín fi fún un yín láti ní.’ ”

121.12-18: Jo 22.1-34; Nu 32.4-22.Ṣùgbọ́n Joṣua sọ fún àwọn ará a Reubeni, àwọn ará Gadi àti fún ìdajì ẹ̀yà Manase pé, 13“Rántí àṣẹ tí Mose ìránṣẹ́ Olúwa pa fún yín: ‘Olúwa Ọlọ́run yín á fún yin ní ìsinmi, òun yóò sì fún un yín ní ilẹ̀ yìí.’ 14Àwọn ìyàwó yín, àwọn ọmọ yín àti àwọn ẹran ọ̀sìn yín lè dúró ní ilẹ̀ tí Mose fún un yin ní ìlà-oòrùn Jordani; ṣùgbọ́n gbogbo àwọn jagunjagun un yín, pẹ̀lú ìhámọ́ra ogun gbọdọ̀ kọjá síwájú àwọn arákùnrin yín. Ẹ̀yin yóò sì rán àwọn arákùnrin yín lọ́wọ́ 15títí Olúwa yóò fi fún wọn ní ìsinmi, gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe fún un yín, àti títí tí àwọn pẹ̀lú yóò fi gba ilẹ̀ náà tí Olúwa Ọlọ́run yín fi fún wọn. Lẹ́yìn náà, ẹ̀yin lè padà sí ilẹ̀ ìní in yín, tí Mose ìránṣẹ́ Olúwa fi fún un yin ní agbègbè ìlà-oòrùn ti Jordani.”

16Nígbà náà ni wọ́n dá Joṣua lóhùn pé, “Ohunkóhun tí ìwọ pàṣẹ fún wa ni àwa yóò ṣe, ibikíbi tí ìwọ bá rán wa ni àwa yóò lọ. 17Gẹ́gẹ́ bí àwa ti gbọ́rọ̀ sí Mose nínú ohun gbogbo, bẹ́ẹ̀ ni àwa yóò máa gbọ́ tìrẹ. Kí Olúwa Ọlọ́run rẹ wà pẹ̀lú rẹ, gẹ́gẹ́ bí ó ṣe wà pẹ̀lú u Mose. 18Ẹnikẹ́ni tí ó bá tàpá sí ọ̀rọ̀ rẹ, tí kò sì ṣe ìgbọ́ràn sí ọ̀rọ̀ rẹ nínú ohun gbogbo tí ìwọ yóò pàṣẹ fún wọn, pípa ni a ó pa á. Kí ìwọ sá à ṣe gírí, kí ó sì mú àyà le!”

Священное Писание

Иешуа 1:1-18

Вечный повелевает Иешуа завоевать Ханаан

1После смерти Мусы, раба Вечного1:1 Вечный – на языке оригинала: «Яхве». Под этим именем Всевышний открылся Мусе и народу Исраила (см. Исх. 3:13-15). См. пояснительный словарь., Вечный сказал Иешуа, сыну Нуна, помощнику Мусы:

2– Мой раб Муса умер. Итак, приготовься вместе со всем этим народом переправиться через реку Иордан в землю, которую Я даю им – исраильтянам. 3Я отдам вам всякое место, на которое ступит ваша нога, как Я обещал Мусе. 4Ваша земля будет простираться от пустыни до Ливана, от великой реки Евфрат (включая всю землю хеттов) до Средиземного моря1:4 Букв.: «до Великого моря». на западе. 5Никто не сможет противостоять тебе во все дни твоей жизни. Как Я был с Мусой, так буду и с тобой. Я никогда тебя не оставлю и никогда не покину.

6Будь твёрд и мужествен, потому что ты поведёшь этих людей, чтобы им унаследовать землю, которую Я клялся дать их предкам. 7Будь твёрд и очень мужествен. Тщательно исполняй весь Закон, который дал тебе Мой раб Муса. Не уклоняйся от него ни вправо, ни влево, чтобы тебе иметь успех везде, куда бы ты ни пошёл. 8Пусть слова Таурата, книги Закона, всегда будут у тебя на устах, размышляй над ними день и ночь, чтобы в точности исполнять всё, что написано. Тогда ты будешь иметь успех в своих делах и поступать благоразумно. 9Итак, Я повелеваю тебе: будь твёрд и мужествен. Не бойся и не падай духом, потому что Вечный, твой Бог, будет с тобой, куда бы ты ни пошёл.

10И приказал Иешуа вождям народа:

11– Пройдите по лагерю и скажите народу: «Запаситесь едой, потому что через три дня вы переправитесь здесь через Иордан, чтобы пойти и завладеть землёй, которую Вечный, ваш Бог, даёт вам во владение».

12Но родам Рувима, Гада и половине рода Манассы Иешуа сказал:

13– Помните повеление, которое дал вам Муса, раб Вечного: «Вечный, ваш Бог, дал вам покой и даровал эту землю». 14Ваши жёны, дети и скот могут остаться в земле, которую Муса дал вам к востоку от Иордана, но все ваши воины в полном вооружении должны переправиться впереди ваших братьев. Вы должны помогать вашим братьям, 15пока Вечный не даст им покой, как Он сделал это для вас самих, и пока они тоже не завладеют землёй, которую Вечный, ваш Бог, даёт им. После этого вы сможете вернуться и занять свою землю, которую Муса, раб Вечного, дал вам к востоку от Иордана.

16Они ответили Иешуа:

– Всё, что бы ты ни приказал нам, мы исполним, и куда бы ты ни направил нас, мы пойдём. 17Как мы слушались Мусу, так будем слушаться и тебя. Только пусть Вечный, твой Бог, будет с тобой, как Он был с Мусой. 18Всякий, кто воспротивится твоему приказу и не послушается твоих слов – что бы ты ни приказал, будет предан смерти. Только будь твёрд и мужествен!