Jeremiah 8 – YCB & CARSA

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Jeremiah 8:1-22

1“ ‘Ní ìgbà náà ni Olúwa wí pé, wọn yóò mú egungun àwọn ọba Juda àti egungun àwọn ìjòyè, egungun àwọn àlùfáà àti egungun àwọn wòlíì àti egungun àwọn olùgbé Jerusalẹmu kúrò nínú ibojì. 2A ó yọ wọ́n síta fún oòrùn àti òṣùpá àti gbogbo àwọn ìràwọ̀ ojú ọ̀run tí wọ́n ti fẹ́ràn tí wọ́n sì ti sìn, àti àwọn tí wọ́n ti tọ̀ lẹ́yìn tí wọ́n ti wá tí wọ́n sì ti foríbalẹ̀ fún. Kì yóò ṣà wọ́n jọ tàbí sìn wọ́n, wọn yóò dàbí ìdọ̀tí tó wà lórí ilẹ̀. 3Níbikíbi tí mo bá lé wọn lọ, gbogbo àwọn ìyókù wọn yóò fẹ́ ikú ju ìyè lọ ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.’

Ẹ̀ṣẹ̀ àti ìjìyà

4“Wí fún wọn pé, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa wí:

“ ‘Bí ènìyàn bá ṣubú lulẹ̀, wọn kì í padà dìde bí?

Nígbà tí ènìyàn bá yà kúrò ní ọ̀nà rẹ, kì í yí padà bí?

5Èéṣe nígbà náà àwọn ènìyàn wọ̀nyí fi yà kúrò lọ́nà rẹ̀?

Kí ló dé tí Jerusalẹmu fi yà kúrò ní gbogbo ìgbà?

Wọ́n rọ̀ mọ́ ẹ̀tàn;

wọ́n kọ̀ láti yípadà.

6Mo ti fetísílẹ̀ dáradára,

wọn kò sọ ohun tí ó tọ́.

Kò sí ẹnìkan tó ronúpìwàdà nínú ìwà búburú rẹ̀,

kí ó wí pé, “Kí ni mo ṣe?”

Olúkúlùkù ń tọ ọ̀nà rẹ̀

gẹ́gẹ́ bí ẹṣin tó ń lọ sójú ogun.

7Kódà, ẹyẹ àkọ̀ ojú ọ̀run

mọ ìgbà tirẹ̀,

àdàbà, alápáǹdẹ̀dẹ̀ àti lékèélékèé

mọ àkókò ìṣípò padà wọn.

Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn mi kò mọ

ohun tí Olúwa wọn fẹ́.

8“ ‘Báwo ni ẹ̀yin ṣe lè wí pé, “Àwa gbọ́n,

nítorí a ní òfin Olúwa,”

nígbà tí ó jẹ́ pé kálámù èké àwọn akọ̀wé

ti àwọn sọ ọ́ di ẹ̀tàn.

9Ojú yóò ti àwọn ọlọ́gbọ́n,

a ó dà wọ́n láàmú, wọn yóò sì kó sí ìgbèkùn.

Nítorí wọ́n ti kọ ọ̀rọ̀ Olúwa,

irú ọgbọ́n wo ló kù tí wọ́n ní?

10Nítorí náà, èmi yóò fi ìyàwó wọn fún àwọn ọkùnrin mìíràn

àti ilẹ̀ wọn fún àwọn ẹlòmíràn.

Láti èyí tó kéré jù dé èyí tó dàgbà jù,

gbogbo wọn ni èrè àjẹjù ń jẹ lógún;

àwọn wòlíì àti àwọn àlùfáà

pẹ̀lú ń hùwà ẹ̀tàn.

11Wọ́n tọ́jú ọgbẹ́ àwọn ènìyàn mi

gẹ́gẹ́ bí èyí tí kò jinlẹ̀.

“Àlàáfíà, àlàáfíà,” ni wọ́n ń wí,

nígbà tí kò sí àlàáfíà.

12Ǹjẹ́ wọ́n tijú fún ìṣe ìríra wọn?

Bẹ́ẹ̀ kọ́, wọn kò ní ìtìjú rárá;

wọn kò tilẹ̀ mọ bí wọ́n ti ṣe ń tì jú.

Nítorí náà wọn yóò ṣubú pẹ̀lú àwọn tó ti ṣubú,

a ó sì wó wọ́n lulẹ̀ nígbà tí a bá bẹ̀ wọ́n wò,

ni Olúwa wí.

13“ ‘Èmi yóò mú ìkórè wọn kúrò,

ni Olúwa wí.

Kì yóò sí èso lórí igi àjàrà.

Kì yóò sí ọ̀pọ̀tọ́ lórí igi,

ewé wọn yóò sì rẹ̀ sílẹ̀.

Ohun tí mo ti fi fún wọn

ni à ó gbà kúrò.’ ”

14“Èéṣe tí àwa fi jókòó ní ibí yìí?

A kó ara wa jọ!

Jẹ́ kí a sálọ sí ìlú olódi

kí a sì ṣègbé síbẹ̀.

Nítorí tí Olúwa Ọlọ́run wa ti pinnu pé a ó ṣègbé.

Yóò sì fún wa ní omi onímájèlé mu,

nítorí àwa ti ṣẹ̀ sí i.

15Àwa ń retí àlàáfíà

kò sí ìre kan,

tí ó wá ní ìgbà ìmúláradá

bí kò ṣe ìpayà nìkan.

16Ìró ìfọn imú ẹṣin àwọn ọlọ̀tẹ̀

là ń gbọ́ láti Dani,

yíyan àwọn akọ ẹṣin

mú gbogbo ilẹ̀ wárìrì.

Wọ́n wá láti pa ilẹ̀ náà run,

gbogbo ohun tó wà níbẹ̀,

ìlú náà àti gbogbo olùgbé ibẹ̀.

17“Wò ó, èmi yóò rán àwọn ejò olóró sí àárín yín,

paramọ́lẹ̀ tí ẹ kò lè pa oró wọn,

yóò sì bù yín jẹ,”

ni Olúwa wí.

18Olùtùnú mi, nígbà tí ìbànújẹ́ ọkàn mi,

rẹ̀wẹ̀sì nínú mi.

19Fetí sí ẹkún àwọn ènìyàn mi

láti ilẹ̀ jíjìnnà wá:

Olúwa kò ha sí ní Sioni bí?

Ọba rẹ̀ kò sí níbẹ̀ mọ́ ni?”

“Èéṣe tí wọ́n fi mú mi bínú pẹ̀lú ère wọn,

pẹ̀lú àwọn òrìṣà àjèjì tí wọn kò níláárí?”

20“Ìkórè ti rékọjá,

ìgbà ẹ̀ẹ̀rùn ti parí,

síbẹ̀ a kò gbà wá là.”

21Níwọ́n ìgbà tí a pa àwọn ènìyàn mi run, èmi náà run pẹ̀lú,

èmi ṣọ̀fọ̀, ìrora sì mú mi káká.

22Kò ha sí ìkunra ní Gileadi bí?

Kò ha sí àwọn oníṣègùn níbẹ̀?

Kí ló ha dé tí kò fi sí ìwòsàn

fún ọgbẹ́ àwọn ènìyàn mi?

Священное Писание (Восточный перевод), версия с «Аллахом»

Иеремия 8:1-22

1В то время, – возвещает Вечный, – кости царей и правителей Иудеи, кости священнослужителей, пророков и жителей Иерусалима будут выброшены из могил. 2Их раскидают под солнцем, луной и звёздами, которые они любили, которым служили и следовали, которые вопрошали и которым поклонялись. Их не соберут и не захоронят; они будут, как отбросы, валяться на земле. 3Куда бы Я ни изгнал всех уцелевших из этого злого народа, они смерть предпочтут жизни, – возвещает Вечный, Повелитель Сил.

Грех и наказание

4– Скажи им: Так говорит Вечный:

«Разве те, кто упал, не пытаются встать?

Разве те, кто сбился с пути, не возвращаются?

5Почему же этот народ отвернулся от Меня?

Почему же Иерусалим всегда отворачивается от Меня?

Они крепко держатся за ложь

и отказываются вернуться.

6Я внимал и слушал,

но они не говорят правды.

Никто не кается в беззаконии,

говоря: „Что я сделал?“

Каждый держится своего пути,

точно конь, мчащийся на битву.

7Даже аист в небе

знает свои сроки,

и горлица, и ласточка, и журавль

знают время перелёта.

Но Мой народ не знает

Закона Вечного.

8Как вы можете говорить: „Мы мудры,

и Закон Вечного у нас“,

когда на самом деле в ложь превращает его

лживое перо писарей?

9Опозорятся мудрецы,

ужаснутся и запутаются в силках.

Если они отвергли слово Вечного,

то в чём же их мудрость?

10За это Я отдам их жён другим

и их поля – новым владельцам.

Все они, от малого до великого,

жаждут наживы;

от пророка и до священнослужителя –

все поступают лживо.

11Лечат серьёзную рану Моего народа так,

как будто это простая царапина.

„Мир, мир“, – говорят,

а мира нет.

12Не стыдно ли им за их мерзости?

Нет, им ни капли не стыдно,

и они не краснеют.

За это падут они среди павших,

будут повержены, когда Я накажу их, –

говорит Вечный. –

13Я уничтожу их урожай, –

возвещает Вечный. –

Ни гроздьев не останется на лозе,

ни плодов – на инжире,

и увянут их листья.

То, что Я дал им,

будет у них отобрано».

14Что же мы сидим?

Собирайтесь!

Побежим в укреплённые города;

там и погибнем!

Вечный, наш Бог, обрёк нас на погибель

и поит нас водой отравленной,

потому что мы согрешили против Него.

15Ждём мы мира,

а ничего доброго нет;

ждём времени исцеления,

а вместо этого – ужасы.

16Уже в Дане слышен

храп вражьих коней;

от ржания их жеребцов

содрогается земля.

Враг пришёл разрушить

страну и всё, что в ней есть,

город и всех, кто живёт в нём.

17– Вот Я насылаю на вас гадюк,

ядовитых змей, против которых нет заклинаний,

и они будут вас жалить, –

возвещает Вечный.

18Нет мне утешения в скорби,

изнемогает сердце моё.

19Слышен вопль моего народа

из далёкой страны:

«Неужели Вечный не на Сионе?

Неужели там больше нет Царя?»

– Зачем они досаждали Мне своими идолами,

ничтожными, чужеземными? – говорит Вечный.

20– Жатва прошла,

кончилось лето,

а мы всё не спасены.

21Из-за страданий моего народа я страдаю;

я скорблю, и объял меня ужас.

22Неужели нет бальзама в Галааде?8:22 Галаад славился своим целебным бальзамом из смолы мастикового дерева.

Неужели там нет врача?

Так почему же не исцеляются

раны моего народа?