Jeremiah 52 – YCB & NTLR

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Jeremiah 52:1-34

Ìṣubú Jerusalẹmu

1Sedekiah jẹ́ ọmọ ọdún mọ́kànlélógún nígbà tí ó jẹ ọba. Ọdún mọ́kànlá ló fi jẹ ọba ní Jerusalẹmu. Orúkọ ìyá rẹ̀ ni Hamutali ọmọ Jeremiah; láti Libina ló ti wá. 252.2: 2Ọb 24.18–25.30; 2Ki 36.11-13.Ó ṣe búburú ní ojú Olúwa gẹ́gẹ́ bí Jehoiakimu ti ṣe 3Nítorí ìbínú Olúwa ni gbogbo èyí ṣe ṣẹlẹ̀ sí Jerusalẹmu àti Juda àti ní ìkẹyìn. Ó sì gbà wọ́n gbọ́ ní iwájú rẹ̀.

Sedekiah ṣọ̀tẹ̀ sí ọba Babeli.

4Nígbà tí ó di ọdún kẹsànán ti Sedekiah tí ń ṣe ìjọba ní ọjọ́ kẹwàá, oṣù kẹwàá Nebukadnessari ọba Babeli sì lọ sí Jerusalẹmu pẹ̀lú gbogbo àwọn ọmọ-ogun rẹ̀, wọ́n pàgọ́ sí ẹ̀yìn odi ìlú náà; wọ́n sì mọ odi yíká rẹ̀. 5Ìlú náà sì wá lábẹ́ ìhámọ́ títí di ọdún kọkànlá ọba Sedekiah.

6Ní ọjọ́ kẹsànán, oṣù mẹ́rin ìyàn ìlú náà sì ti burú dé ibi pé kò sí oúnjẹ kankan mọ́ fún àwọn ènìyàn láti jẹ. 7Bákan náà, odi ìlú náà ti ya àwọn ọmọ-ogun sì tí sálọ. Wọn fi ìlú náà sílẹ̀ ní òru nípa ojú ọ̀nà tó wà láàrín odi méjèèjì lẹ́bàá ọgbà ọba. Bí ó tilẹ̀ jẹ́ wí pé, Àwọn ará Babeli yìí yí ìlú náà ká. Wọ́n sá gba aginjù lọ. 8Ṣùgbọ́n àwọn ọmọ-ogun Babeli lépa ọba Sedekiah wọ́n sì le bá ni pẹ̀tẹ́lẹ̀ Jeriko. Gbogbo àwọn ọmọ-ogun sì pínyà, kúrò ní ọ̀dọ̀ rẹ̀ wọ́n sì túká. 9Wọ́n sì mu ní ìgbèkùn.

Wọn mú un lọ sí ọ̀dọ̀ ọba Babeli, ní Ribla ní ilẹ̀ Hamati níbẹ̀ ni ó ti ṣe ìdájọ́ lórí rẹ̀. 10Ní Ribla ni ọba Babeli ti pa ọmọkùnrin Sedekiah lójú rẹ̀; ó sì tún pa gbogbo àwọn aláṣẹ Juda. 11Lẹ́yìn náà, ọba Babeli yọ Sedekiah ní ojú, o sì fi ẹ̀wọ̀n dè é, ó sì gbe e lọ sí Babeli níbi tí ó ti fi sínú ọgbà ẹ̀wọ̀n títí di ọjọ́ ikú rẹ̀.

12Ní ọjọ́ kẹwàá oṣù karùn-ún, tí ó jẹ́ ọdún kọkàn-dínlógún Nebukadnessari ọba Babeli, ni Nebusaradani balógun ìṣọ́ wá sí Jerusalẹmu. 13Ó dáná sun pẹpẹ Olúwa, ààfin ọba àti gbogbo àwọn ilé Jerusalẹmu. Ó sì dáná sun gbogbo àwọn ilé ńláńlá. 14Gbogbo àwọn ogun Babeli, tí ó wà lọ́dọ̀ olórí ẹ̀ṣọ́, wó ògiri tí ó yí Jerusalẹmu ká lulẹ̀. 15Nebusaradani balógun ìṣọ́ kó gbogbo àwọn tálákà àti gbogbo àwọn tí ó kù ní ìlú, ní ìgbèkùn lọ sí Babeli, pẹ̀lú àwọn tí ó ya lọ, tí ó sì ya tọ ọba Babeli lọ, àti ìyókù àwọn ènìyàn náà. 16Ṣùgbọ́n Nebusaradani, balógun ìṣọ́ fi àwọn tálákà tó kú ní ilẹ̀ náà sílẹ̀ láti máa ṣiṣẹ́ nínú ọgbà àjàrà àti ro oko.

17Àwọn ará Babeli fọ́ ọ̀wọ̀n idẹ wọ̀n-ọn-nì àti àwọn ìjókòó wọ̀n-ọn-nì, àti agbada idẹ títóbi wọ̀n-ọn-nì tí ń bẹ ní ilé Olúwa, àwọn ará Babeli fọ́ túútúú, Wọ́n sì kó gbogbo idẹ náà lọ sí Babeli. 18Bákan náà, wọ́n tún kó àwọn ìkòkò wọ̀n-ọn-nì, ọkọ́ wọ̀n-ọn-nì àti ọ̀pá fìtílà wọ̀n-ọn-nì, àwọn ọpọ́n wọ̀n-ọn-nì, ṣíbí wọ̀n-ọn-nì àti gbogbo ohun èlò idẹ tí wọ́n ń lò níbi pẹpẹ lọ. 19Balógun ìṣọ́ náà kó àwokòtò wọ̀n-ọn-nì, ohun ìfọnná wọ̀n-ọn-nì, ọpọ́n wọ̀n-ọn-nì, ìkòkò wọ̀n-ọn-nì, ọ̀pá fìtílà wọ̀n-ọn-nì, ṣíbí wọ̀n-ọn-nì àti ago wáìnì wọ̀n-ọn-nì; èyí tí a fi wúrà àti fàdákà ṣe lọ.

20Àwọn ọ̀wọ́n méjì, agbada ńlá kan àti àwọn màlúù idẹ méjìlá tí ó wà lábẹ́ ìjókòó alágbéká tí Solomoni ọba ṣe fún ilé Olúwa, idẹ ni gbogbo ohun èlò wọ̀nyí, ó ju èyí tí a lè wọ́n lọ. 21Ọ̀kọ̀ọ̀kan nínú àwọn ọ̀wọ́n yìí ni ga ní ìwọ̀n ìgbọ̀nwọ́ méjì-dínlógún; okùn ìgbọ̀nwọ́ méjìlá sì yí i ká. Ọ̀kọ̀ọ̀kan nípọn tó ìka mẹ́rin, wọ́n sì ní ihò nínú. 22Ọ̀nà orí idẹ kan tó ìgbọ̀nwọ́ márùn-ún ní gíga, wọ́n sì fi èso pomegiranate ṣe ọ̀ṣọ́ sí i lára yíká. Ọ̀wọ́n kejì sì wà pẹ̀lú èso pomegiranate tí ó jọra. 23Pomegiranate mẹ́rìn-dínlọ́gọ́rùn-ún ni ó wà ní àwọn ẹ̀gbẹ́ rẹ̀. Àpapọ̀ gbogbo pomegiranate sì jẹ́ ọgọ́rùn-ún kan.

24Balógun àwọn ẹ̀ṣọ́ mu Seraiah olórí àwọn àlùfáà àti Sefaniah àlùfáà kejì àti àwọn olùṣọ́ ìloro mẹ́ta. 25Nínú àwọn tí ó kù ní ilẹ̀ náà, ó mú ìwẹ̀fà kan, tí ó wà ní ìtọ́jú àwọn ológun, àti àwọn olùdámọ̀ràn ọba méje. Bákan náà, ó tún mu akọ̀wé olórí ogun tí ó wà ní ìtọ́jú títo àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà, àti ọgọ́ta nínú àwọn ọkùnrin rẹ̀ tí wọ́n rí ní ìlú náà. 26Nebusaradani, balógun ìṣọ́ kó gbogbo wọn, ó sì mú wọn tọ ọba Babeli wá ní Ribla. 27Ọba Babeli sì kọlù wọ́n, ó sì pa wọ́n ní Ribla ni ilẹ̀ Hamati.

Báyìí ni a mú Juda kúrò ní ilẹ̀ rẹ̀.

28Èyí ni iye àwọn ènìyàn tí Nebukadnessari kó lọ sí ilẹ̀ àjèjì.

Ní ọdún keje ẹgbẹ̀ẹ́dógún ó-lé-mẹ́tàlélógún (3,023) ará Juda.

29Ní ọdún kejì-dínlógún Nebukadnessari

o kó ẹgbẹ̀rún ó-lé-méjì-dínlọ́gbọ̀n láti Jerusalẹmu.

30Ní ọdún kẹtàlélógún àwọn Júù

tí Nebusaradani kó lọ sí ilẹ̀ àjèjì jẹ́ ọ̀tà-dínlẹ́gbẹ̀rin-ó-dín-márùn-ún (745).

Gbogbo ènìyàn tí ó kó lápapọ̀ jẹ́ ẹgbẹ̀tàlélógún.

Ìtúsílẹ̀ Jehoiakimu

31Ní ọdún kẹtà-dínlógójì ti Jehoiakini ọba Juda ni Efili-Merodaki di ọba Babeli. Ó gbé orí Jehoiakini ọba Juda sókè, ó sì tú sílẹ̀ nínú túbú ní ọjọ́ kẹẹdọ́gbọ̀n oṣù kejìlá. 32Ó ń sọ̀rọ̀ rere fún un, ó sì gbé ìtẹ́ rẹ̀ ga ju ìtẹ́ àwọn ọba tókù lọ tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ ní Babeli. 33Nítorí náà, Jehoiakini pàrọ̀ aṣọ túbú rẹ̀, ó sì ń jẹun ní gbogbo ìgbà ní iwájú rẹ̀ ní gbogbo ọjọ́ ayé rẹ̀. 34Ní ojoojúmọ́ ni ọba Babeli ń fún Jehoiakini ní ìpín tirẹ̀ bí ó tí ń bẹ láààyè, títí di ọjọ́ kú rẹ̀.

Nouă Traducere În Limba Română

Ieremia 52:1-34

Căderea Ierusalimului

(2 Regi 24:18–25:21; 2 Cron. 36:11-20; Ier. 39:1-10)

1Zedechia era în vârstă de douăzeci și unu de ani când a devenit rege și a domnit la Ierusalim timp de unsprezece ani. Mama sa se numea Hamutal și era fiica lui Ieremia din Libna. 2El a făcut ce este rău în ochii Domnului, tot așa cum făcuse și Iehoiachim. 3Din cauza mâniei Domnului s‑au întâmplat aceste lucruri în Ierusalim și în Iuda, pe care, în cele din urmă, le‑a izgonit din prezența Sa.

Zedechia s‑a răsculat împotriva împăratului Babilonului.

4În al nouălea an al domniei lui Zedechia, în a zecea zi a lunii a zecea, Nebucadnețar, împăratul Babilonului, a venit împotriva Ierusalimului cu toată armata sa. Ei și‑au așezat tabăra înaintea cetății și au zidit întărituri de jur împrejurul ei. 5Cetatea a fost în stare de asediu până în cel de‑al unsprezecelea an al regelui Zedechia.

6În ziua a noua a lunii a patra, foametea din cetate a devenit atât de mare, încât poporul țării nu mai avea nimic de mâncare. 7Atunci s‑a pătruns în cetate, astfel că toți războinicii au fugit. Ei au ieșit din cetate noaptea, pe drumul porții dintre cele două ziduri, de lângă grădina regelui, în timp ce caldeenii înconjurau cetatea. Ei au luat‑o pe drumul spre Araba7 Vezi nota de la 39:4., 8însă armata caldeenilor l‑a urmărit pe regele Zedechia și l‑a ajuns în câmpiile Ierihonului. Toată armata lui se împrăștiase de lângă el. 9Ei l‑au capturat pe rege și l‑au dus la împăratul Babilonului, la Ribla, în țara Hamatului. Acesta a rostit o sentință împotriva lui. 10Acolo, la Ribla, împăratul Babilonului i‑a înjunghiat pe fiii lui Zedechia înaintea ochilor lui. De asemenea, i‑a înjunghiat și pe toți conducătorii lui Iuda. 11Apoi împăratul Babilonului i‑a scos ochii lui Zedechia, l‑a legat cu lanțuri de bronz și l‑a dus în Babilon, unde a stat în temniță până în ziua morții lui.

12În ziua a zecea12 În textul paralel din 2 Regi 25:8 se face referire la ziua a șaptea. a lunii a cincea, în al nouăsprezecelea an al împăratului Nebucadnețar, împăratul Babilonului, Nebuzaradan, căpetenia gărzilor, care era în slujba împăratului Babilonului, a pătruns în Ierusalim. 13El a dat foc Casei Domnului, palatului regelui și tuturor caselor din Ierusalim. A dat foc tuturor caselor mari. 14Toată armata caldeenilor, care era împreună cu căpetenia gărzilor, a dărâmat toate zidurile din jurul Ierusalimului. 15Nebuzaradan, căpetenia gărzilor, a dus în captivitate o parte din cei mai săraci oameni, poporul15 Sau: artizanii; sau: populația. care mai rămăsese în cetate, dezertorii care fugiseră la împăratul Babilonului și restul mulțimii. 16Totuși, Nebuzaradan, căpetenia gărzilor, a lăsat în țară câțiva oameni săraci ca să lucreze viile și câmpurile.

17Caldeenii au sfărâmat stâlpii de bronz care erau în Casa Domnului, precum și piedestalele și „marea“17, 20 Vezi nota de la 27:19. din bronz care erau în Casa Domnului și au dus tot bronzul la Babilon. 18Au luat vasele, lopețile, mucarnițele, potirele, farfuriile și toate uneltele de bronz cu care preoții făceau slujba. 19Căpetenia gărzilor a mai luat și ligheanele, fărașele pentru cărbuni, cupele, oalele, sfeșnicele, lingurile și bolurile – tot ce era de aur sau de argint.

20Cei doi stâlpi, „marea“, cei doisprezece boi de bronz care erau sub mare și piedestalele, toate aceste obiecte de bronz pe care le făcuse regele Solomon pentru Casa Domnului, aveau o greutate care nu se putea cântări. 21În ce privește stâlpii, un stâlp avea o înălțime de optsprezece coți21 Aproximativ 9 m., iar circumferința lui se putea măsura cu un fir de doisprezece coți21 Aproximativ 6 m.; grosimea lui era de patru degete și era gol pe dinăuntru. 22Fiecare avea deasupra un capitel de bronz. Înălțimea unui capitel era de cinci coți22 Aproximativ 2,5 m., capitelul având de jur împrejur o rețea și rodii, toate din bronz. Al doilea stâlp, cu rodiile lui, era la fel. 23Erau nouăzeci și șase de rodii pe fiecare parte; toate rodiile aflate de jur împrejurul rețelei erau în număr de o sută.

24Căpetenia gărzilor i‑a luat prizonieri pe Seraia, preotul conducător, pe Țefania, următorul preot în rang și pe cei trei paznici ai porții. 25Din cetate a luat un demnitar care avea în subordine războinici și încă șapte oameni dintre sfetnicii regelui, care, de asemenea, fuseseră găsiți în cetate. L‑a mai luat pe scribul conducătorului oștirii, care recruta bărbați din poporul țării, și pe încă șaizeci de bărbați din poporul țării, care fuseseră găsiți tot în cetate. 26Nebuzaradan, căpetenia gărzilor, i‑a luat și i‑a dus la împăratul Babilonului, la Ribla. 27Acolo, la Ribla, în țara Hamat, împăratul Babilonului i‑a lovit și i‑a omorât.

Astfel, Iuda a fost dus în captivitate, departe de țara lui. 28Acesta este poporul pe care l‑a dus Nebucadnețar în captivitate:

în al șaptelea an: trei mii douăzeci și trei de iudei;

29în al optsprezecelea an al lui Nebucadnețar,

a dus în captivitate din Ierusalim opt sute treizeci și doi de oameni;

30iar în al douăzeci și treilea an al lui Nebucadnețar,

Nebuzaradan, căpetenia gărzilor, a mai dus în captivitate șapte sute patruzeci și cinci de iudei.

În total, au fost duși în captivitate patru mii șase sute de oameni.

Eliberarea lui Iehoiachin din temniță

(2 Regi 25:27-30)

31În al treizeci și șaptelea an de captivitate a lui Iehoiachin, regele lui Iuda, în a douăzeci și cincea zi a lunii a douăsprezecea, Evil-Merodak31 Numit și Amel-Marduk. [562–560 î.Cr.], împăratul Babilonului, în primul an al domniei lui, i‑a înălțat capul lui Iehoiachin, regele lui Iuda, și l‑a scos din temniță. 32I‑a vorbit cu bunătate și i‑a dat un loc de cinste mai presus decât cel al regilor care erau cu el în Babilon. 33Iehoiachin și‑a schimbat hainele de întemnițat și pentru tot restul vieții sale a mâncat la masa împăratului. 34Împăratul Babilonului s‑a îngrijit necurmat de hrana zilnică a lui Iehoiachin în toate zilele vieții lui, până în ziua morții acestuia.