Jeremiah 42 – YCB & CARST

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Jeremiah 42:1-22

1Nígbà náà ní gbogbo àwọn olórí ogun àti Johanani ọmọkùnrin Karea àti Jesaniah ọmọkùnrin Hoṣaiah àti kékeré títí dé orí ẹni ńlá wá. 2Sí ọ̀dọ̀ Jeremiah wòlíì náà, wọ́n sì sọ fún un pé, “Jọ̀wọ́ gbọ́ ẹ̀bẹ̀ wa, kí o sì gbàdúrà sí Olúwa Ọlọ́run rẹ fún gbogbo ìyókù yìí. Nítorí gẹ́gẹ́ bi ìwọ ṣe rí i nísinsin yìí pé a pọ̀ níye nígbà kan rí; ṣùgbọ́n báyìí àwa díẹ̀ la ṣẹ́kù. 3Gbàdúrà pé kí Olúwa Ọlọ́run rẹ sọ ibi tí àwa yóò lọ fún wa àti ohun tí àwa yóò ṣe.”

4Wòlíì Jeremiah sì dáhùn wí pé, “Mo ti gbọ́. Èmi yóò gbàdúrà sí Olúwa Ọlọ́run yín gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yin ṣe béèrè. Èmi yóò sọ gbogbo ohun tí Olúwa bá sọ fún un yín, ń kò sì ní fi ohunkóhun pamọ́ fún un yín.”

5Nígbà náà ni wọ́n sọ fún Jeremiah wí pé, “Kí Olúwa ṣe ẹlẹ́rìí òtítọ́ àti òdodo láàrín wa, bí àwa kò bá ṣe gẹ́gẹ́ bí gbogbo ohun tí Olúwa Ọlọ́run rẹ bá rán ọ láti sọ fún wa. 6Ìbá à ṣe rere, ìbá à ṣe búburú, àwa yóò gbọ́rọ̀ sí Olúwa Ọlọ́run wa, èyí tí àwa ń rán ọ sí, kí ó ba à lè dára fún wa. Nítorí pé àwa yóò gbọ́rọ̀ sí Olúwa Ọlọ́run wa.”

7Lẹ́yìn ọjọ́ mẹ́wàá, ọ̀rọ̀ Olúwa tọ Jeremiah wá, 8O sì pe Johanani ọmọkùnrin Karea àti gbogbo àwọn olórí ogun tí wọ́n wà pẹ̀lú rẹ̀; àti gbogbo àwọn ènìyàn láti orí ẹni tí ó kéré dé orí ẹni ńlá. 9Ó sì wí fún wọn pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run àwọn Israẹli wí: ‘Èyí ni ẹni tí ẹ̀yin ti rán láti gbé ẹ̀bẹ̀ yín lọ síwájú mi. 10Bí ẹ̀yin bá gbé ní ilẹ̀ yìí, èmi yóò gbé e yín ró, n kò sí ní fà yín lulẹ̀, èmi yóò gbìn yín, n kì yóò fà yín tu nítorí wí pé èmi yí ọkàn padà ní ti ibi tí mo ti ṣe sí i yín. 11Ẹ má ṣe bẹ̀rù ọba Babeli tí ẹ̀yin ń bẹ̀rù, báyìí ẹ má ṣe bẹ̀rù rẹ̀ ni Olúwa wí; nítorí tí èmi wà pẹ̀lú yín láti pa yín mọ́ àti láti gbà yín ní ọwọ́ rẹ̀. 12Èmi yóò fi àánú hàn sí i yín, kí ó lè ṣàánú fún un yín, kí ó sì mú un yín padà sí ilẹ̀ yín.’

13“Ṣùgbọ́n sá, bí ẹ̀yin bá wí pé, ‘Àwa kò ní gbé ilẹ̀ yìí,’ ẹ̀yin ti ṣe àìgbọ́ràn sí Olúwa Ọlọ́run yín. 14Àti pé bí ẹ̀yin bá wí pé, ‘Bẹ́ẹ̀ kọ́, àwa yóò lọ gbé ní Ejibiti; níbi tí àwa kì yóò rí ìró ogunkógun, tí a kì yóò sì gbọ́ ìró fèrè, tí ebi oúnjẹ kì yóò sì pa wá, níbẹ̀ ni àwa ó sì máa gbé,’ 15nítorí náà, ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa ẹ̀yin ìyókù Juda èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun Israẹli wí: ‘Bí ẹ̀yin bá pinnu láti lọ sí Ejibiti láti lọ ṣe àtìpó níbẹ̀. 16Yóò sì ṣe, idà tí ẹ̀yin bẹ̀rù yóò sì lé e yín bá níbẹ̀; àti ìyanu náà tí ẹ̀yin ń bẹ̀rù yóò sì tẹ̀lé yín lọ sí Ejibiti àti pé ibẹ̀ ni ẹ̀yin yóò kú sí. 17Nítorí náà, gbogbo àwọn tí ó ti pinnu láti ṣe àtìpó ní Ejibiti ni yóò ti ipa idà kú, ìyàn àti àjàkálẹ̀-ààrùn kò sì ní jẹ́ kí ẹnikẹ́ni nínú wọn yè tàbí sá àsálà nínú ibi tí èmi yóò mú wá sórí wọn.’ 18Báyìí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run Israẹli wí: ‘Gẹ́gẹ́ bí èmi ti da ìbínú àti ìrunú síta sórí àwọn tí ó ń gbé ní Jerusalẹmu, bẹ́ẹ̀ ni ìrunú mi yóò dà síta sórí yín, nígbà tí ẹ̀yin bá lọ sí Ejibiti. Ẹ̀yin ó sì di ẹni ègún àti ẹni ẹ̀gàn àti ẹ̀sín, ẹ̀yin kì yóò sì rí ibí yìí mọ́.’

19“Ẹ̀yin yòókù Juda, Olúwa ti sọ fún un yín pé, ‘Kí ẹ má ṣe lọ sí Ejibiti.’ Ẹ mọ èyí dájú, èmi kìlọ̀ fún un yín lónìí, 20pé àṣìṣe ńlá gbá à ni ẹ̀yin ṣe nígbà tí ẹ̀yin rán mi sí Olúwa Ọlọ́run yín pé, ‘Gbàdúrà sí Olúwa Ọlọ́run wa fún wa; sọ fún wa gbogbo ohun tí ó bá sọ, àwa yóò sì ṣe é.’ 21Mo ti sọ fún un yín lónìí, ṣùgbọ́n síbẹ̀ ẹ̀yin kò tí ì gbọ́ ohùn Olúwa Ọlọ́run yín, àti gbogbo ohun tí ó rán mi láti sọ fún un yín. 22Ǹjẹ́ nísinsin yìí ẹ mọ èyí dájú pé, ẹ̀yin yóò kú nípa idà, ìyàn àti àjàkálẹ̀-ààrùn níbikíbi tí ẹ̀yin bá fẹ́ lọ láti ṣe àtìpó.”

Священное Писание (Восточный перевод), версия для Таджикистана

Иеремия 42:1-22

1Все полководцы вместе с Иохананом, сыном Кареаха, и Иезанией42:1 В других рукописях: «Азарией» (ср. 43:1). Возможно, что Иезания было вторым именем Азарии., сыном Гошаи, и весь народ, от малого до великого, подошли 2к пророку Иеремии и сказали ему:

– Просим тебя, выслушай нашу просьбу и помолись Вечному, твоему Богу, за всех этих уцелевших. Ведь ты сам видишь, как нас, некогда многочисленных, осталось мало. 3Помолись, чтобы Вечный, твой Бог, сказал, куда нам идти и что делать.

4– Хорошо, – ответил пророк Иеремия. – Я помолюсь Вечному, вашему Богу, как вы просили, и всё, что скажет мне Вечный, я перескажу вам, ничего не утаив.

5А они сказали Иеремии:

– Пусть Вечный будет истинным и верным свидетелем против нас, если мы не сделаем всего, что Вечный, твой Бог, посылает тебя сказать нам. 6Будь то нам во благо или во зло – мы будем послушны Вечному, нашему Богу, к Которому мы посылаем тебя, чтобы нам обрести благо за то, что мы будем слушаться Вечного, нашего Бога.

7Спустя десять дней к Иеремии было слово Вечного. 8Он созвал Иоханана, сына Кареаха, всех полководцев, которые были при нём, и весь народ, от малого до великого.

9Он сказал им:

– Так говорит Вечный, Бог Исроила, к Которому вы посылали меня со своей просьбой: 10«Если вы останетесь в этой стране, Я буду созидать вас, а не разрушать; Я насажу вас, а не искореню, – ведь Я скорблю о зле, которое Я вам причинил. 11Не бойтесь царя Вавилона, которого вы страшитесь. Не бойтесь его, – возвещает Вечный, – потому что Я с вами, и Я спасу вас и избавлю от него. 12Я помилую вас, и он явит вам милость и вернёт вас в вашу землю».

13Но если вы скажете: «Мы не останемся в этой стране» – и ослушаетесь Вечного, вашего Бога, 14если вы скажете: «Нет, мы уйдём и будем жить в Египте, где не увидим войны, не услышим зова рога и не будем голодать», 15то слушайте слово Вечного, вы, остаток Иудеи. Так говорит Вечный, Повелитель Сил, Бог Исроила: «Если вы решите идти в Египет и пойдёте, чтобы поселиться там, 16то меч, которого вы боитесь, настигнет вас там, а голод, которого вы боитесь, устремится за вами в Египет, и там вы умрёте. 17Так будет: все, кто решит идти в Египет, чтобы поселиться там, умрут от меча, голода и мора; никто из них не уцелеет и не спасётся от беды, которую Я на них нашлю».

18Так говорит Вечный, Повелитель Сил, Бог Исроила: «Как Мой гнев и негодование обрушились на тех, кто жил в Иерусалиме, так Мой гнев обрушится и на вас, когда вы войдёте в Египет. Вы будете проклятием и ужасом, порицанием и презрением, и вы никогда больше не увидите этой страны».

19Вечный говорит вам, остаток Иудеи: «Не ходите в Египет». Будьте уверены в том, что сегодня я вас предупредил: 20вы совершили страшную ошибку, когда вы сами послали меня к Вечному, нашему Богу, сказав: «Помолись о нас Вечному, нашему Богу, и перескажи нам всё, что Вечный, наш Бог, скажет, и мы это исполним». 21Сегодня я всё пересказал вам, но вы всё-таки ослушались Вечного, вашего Бога, во всём, что Он послал меня сказать вам. 22Так знайте же: вы умрёте от меча, голода и мора в том краю, куда вы хотите идти, чтобы поселиться.