Jeremiah 22 – YCB & SNC

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Jeremiah 22:1-30

Ìdájọ́ fún àwọn ọba búburú

1Báyìí ni Olúwa wí, “Sọ̀kalẹ̀ lọ sí ààfin ọba Juda, kí o sì sọ ọ̀rọ̀ yìí níbẹ̀: 2‘Gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa ìwọ ọba Juda, tí ó jókòó ní ìtẹ́ Dafidi, ìwọ, àwọn ènìyàn rẹ àti àwọn ìránṣẹ́ rẹ, tí ó wọlé láti ẹnu ibodè wọ̀nyí. 3Báyìí ni Olúwa wí: Ṣé ohun tí ó jẹ́ òtítọ́ tí ó sì yẹ, kí o sì gba ẹni tí a fi ẹ̀tọ́ rẹ̀ dù ú kúrò lọ́wọ́ aninilára. Kí ó má ṣe fi agbára àti ìkà lé àlejò, aláìní baba, tàbí opó, ìwọ kò sì gbọdọ̀ ta ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ sílẹ̀ níbí yìí. 4Nítorí bí ẹ̀yin bá tẹ̀lé àṣẹ wọ̀nyí, nígbà náà ni àwọn ọba tí ó jókòó lórí ìtẹ́ Dafidi yóò gba inú ààfin láti ẹnu-ọ̀nà, wọn yóò gun kẹ̀kẹ́ àti ẹṣin, àwọn àti ìránṣẹ́ wọn àti àwọn ènìyàn wọn. 5Ṣùgbọ́n bí ẹ̀yin kò bá tẹ̀lé àṣẹ wọ̀nyí, mo búra fúnra mi pé ààfin yìí yóò di ìparun ni Olúwa wí.’ ”

6Nítorí báyìí ni Olúwa wí, nípa ààfin ọba Juda,

“Bí ó tilẹ̀ jẹ́ wí pé ìwọ dàbí Gileadi sí mi,

gẹ́gẹ́ bí góńgó òkè Lebanoni,

dájúdájú Èmi yóò sọ ọ́ di aṣálẹ̀,

àní gẹ́gẹ́ bí ìlú tí a kò gbé inú wọn.

7Èmi ó ya àwọn apanirun sọ́tọ̀ fún ọ,

olúkúlùkù ọkùnrin pẹ̀lú ohun ìjà rẹ̀,

wọn yóò sì gé àṣàyàn igi kedari rẹ lulẹ̀,

wọn ó sì kó wọn jù sínú iná.

8“Àwọn ènìyàn láti ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè yóò rékọjá lẹ́bàá ìlú yìí wọn yóò sì máa bi ara wọn léèrè pé, ‘Èéṣe tí Olúwa ṣe irú èyí sí ìlú ńlá yìí?’ 9Ìdáhùn wọn yóò sì jẹ́: ‘Nítorí tí wọ́n ti kọ májẹ̀mú Olúwa Ọlọ́run wọn sílẹ̀, wọn ti ń fi orí balẹ̀ fún ọlọ́run mìíràn, wọ́n sì sìn wọ́n.’ ”

10Nítorí náà má ṣe sọkún nítorí ọba tí ó ti kú tàbí ṣọ̀fọ̀ fún àdánù rẹ̀,

ṣùgbọ́n ẹ sọkún kíkorò fún ẹni tí a lé kúrò nílùú

nítorí kì yóò padà wá mọ́

tàbí fi ojú rí ilẹ̀ tí a ti bí i.

11Nítorí báyìí ni Olúwa wí, nípa Ṣallumu ọmọ Josiah ọba Juda tí ó jẹ ọba lẹ́yìn baba rẹ̀, ṣùgbọ́n tí ó jáde kúrò níhìn-ín: “Òun kì yóò padà wá mọ́. 12Yóò kú ni ibi tí a mú u ní ìgbèkùn lọ, kì yóò sì rí ilẹ̀ yìí mọ́.”

13“Ègbé ni fún ẹni tí a kọ́ ààfin rẹ̀ lọ́nà àìṣòdodo,

àti àwọn yàrá òkè rẹ̀ lọ́nà àìtọ́

tí ó mú kí àwọn ará ìlú rẹ ṣiṣẹ́ lásán

láìsan owó iṣẹ́ wọn fún wọn.

14Ó wí pé, ‘Èmi ó kọ́ ààfin ńlá fún ara mi

àwọn yàrá òkè tí ó fẹ̀,

ojú fèrèsé rẹ̀ yóò tóbi.’

A ó sì fi igi kedari bò ó,

a ó fi ohun aláwọ̀ pupa ṣe é ní ọ̀ṣọ́.

15“Ìwọ ó ha jẹ ọba

kí ìwọ kí ó lè ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ igi kedari?

Baba rẹ kò ha ní ohun jíjẹ àti mímu?

Ó ṣe ohun tí ó tọ́ àti òdodo,

nítorí náà ó dára fún un.

16Ó gbèjà òtòṣì àti aláìní,

ohun gbogbo sì dára fún un.

Bí a ti mọ̀ mí kọ́ ni èyí?”

ni Olúwa wí.

17“Ṣùgbọ́n ojú rẹ àti ọkàn rẹ

wà lára èrè àìṣòótọ́

láti ta ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ sílẹ̀

ìnilára àti ìlọ́nilọ́wọ́gbà.”

18Nítorí náà báyìí ni Olúwa wí, nípa Jehoiakimu ọmọ Josiah ọba Juda:

“Wọn kì yóò ṣọ̀fọ̀ fún un:

wí pé, ‘Ó ṣe, arákùnrin mi! Ó ṣe, arábìnrin mi!’

Wọn kì yóò ṣọ̀fọ̀ fún un:

wí pé, ‘Ó ṣe, olúwa tàbí ó ṣe ọlọ́lá!’

19A ó sin òkú rẹ̀ bí i kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́

tí a wọ́ sọnù láti ẹnu ibodè

Jerusalẹmu.”

20“Gòkè lọ sí Lebanoni, kígbe síta,

kí a sì gbọ́ ohùn rẹ ní Baṣani,

kí o kígbe sókè láti Abarimu,

nítorí a ti ṣẹ́ gbogbo olùfẹ́ rẹ túútúú.

21Èmi ti kìlọ̀ fún ọ nígbà tí o rò pé kò séwu,

ṣùgbọ́n o sọ pé, ‘Èmi kì yóò fetísílẹ̀!’

Èyí ni iṣẹ́ rẹ láti ìgbà èwe rẹ,

ìwọ kò fìgbà kan gba ohùn mi gbọ́.

22Ẹ̀fúùfù yóò lé gbogbo àwọn olùṣọ́-àgùntàn rẹ̀ lọ,

gbogbo àwọn olùfẹ́ rẹ yóò lọ sí ìgbèkùn,

nígbà náà ni a ó kẹ́gàn rẹ, ojú yóò tì ọ́

nítorí gbogbo ìwà búburú rẹ.

23Ìwọ tí ń gbé ‘Lebanoni,’

tí ó tẹ́ ìtẹ́ sí orí igi kedari,

ìwọ yóò ti kérora pẹ́ tó, nígbà tí ìrora bá dé bá ọ,

ìrora bí i ti obìnrin tí ń rọbí!

24“Dájúdájú bí èmi ti wà láààyè,” ni Olúwa wí, “Bí Koniah ọmọ Jehoiakimu ọba Juda tilẹ̀ jẹ́ òrùka èdìdì lọ́wọ́ ọ̀tún mi, síbẹ̀ èmi ó fà ọ́ tu kúrò níbẹ̀. 25Èmi ó sì fà ọ́ lé ọwọ́ àwọn tí ó ń wá ẹ̀mí rẹ, àwọn tí ìwọ bẹ̀rù, àní lé ọwọ́ Nebukadnessari, ọba Babeli àti ọwọ́ àwọn ará Babeli. 26Èmi ó fi ìwọ àti ìyá tí ó bí ọ sọ̀kò sí ilẹ̀ mìíràn, níbi tí a kò bí ẹnikẹ́ni nínú yín sí. Níbẹ̀ ni ẹ̀yin méjèèjì yóò kú sí. 27Ẹ̀yin kì yóò padà sí ilẹ̀ tí ẹ̀yin fẹ́ mọ́ láéláé.”

28Ǹjẹ́ Jehoiakini ẹni ẹ̀gàn yàtọ̀ sí ìkòkò òfìfo,

ohun èlò tí ẹnìkan kò fẹ́?

Èéṣe tí a fi òun àti àwọn ọmọ rẹ̀ sókè

sí ilẹ̀ tí wọn kò mọ̀.

29Ìwọ ilẹ̀, ilẹ̀, ilẹ̀,

gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa!

30Báyìí ni Olúwa wí:

“Kọ àkọsílẹ̀ ọkùnrin yìí sínú ìwé gẹ́gẹ́ bí aláìlọ́mọ,

ẹni tí kì yóò ṣe rere ní ọjọ́ ayé rẹ̀;

nítorí ọ̀kan nínú irú-ọmọ rẹ̀ kì yóò ṣe rere,

èyíkéyìí wọn kì yóò jókòó lórí ìtẹ́ Dafidi

tàbí jẹ ọba ní Juda mọ́.”

Slovo na cestu

Jeremjáš 22:1-30

1Takto řekl Hospodin: Sejdi do domu krále Judského, a mluv tam slovo toto, 2A rci: Slyš slovo Hospodinovo, králi Judský, kterýž sedíš na stolici Davidově, ty i služebníci tvoji i lid tvůj, kteříž chodíte skrze brány tyto. 3Takto praví Hospodin: Konejte soud a spravedlnost, a vychvacujte obloupeného z ruky násilníka; příchozímu tolikéž, sirotku, ani vdově nečiňte křivdy, aniž jich utiskujte, a krve nevinné nevylévejte na místě tomto. 4Nebo budete-li to pilně vykonávati, jistě že poberou se skrze brány domu tohoto králové, sedící místo Davida na stolici jeho, jezdíce na vozích, neb na koních, král s služebníky svými i s lidem svým. 5Jestliže pak neuposlechnete slov těchto, skrze sebe přisahám, dí Hospodin, že poušť bude dům tento. 6Nebo takto praví Hospodin o domu krále Judského: Byl jsi mi jako Galád a vrch Libánský, ale obrátím tě jistotně v poušť jako města, v nichž se bydliti nemůže. 7A přistrojím na tebe zhoubce, jednoho každého se zbrojí jeho, kteřížto zpodtínají nejvýbornější cedry tvé, a vmecí na oheň. 8A když půjdou národové mnozí mimo město toto, a řekne jeden druhému: Proč tak učinil Hospodin městu tomuto velikému? 9Tedy řeknou: Proto že opustili smlouvu Hospodina Boha svého, a klaněli se bohům cizím a sloužili jim. 10Neplačtež mrtvého, aniž ho litujte, ale ustavičně plačte příčinou toho, kterýž odchází; neboť se nenavrátí více, aby pohleděl na zemi, v níž se narodil. 11Nebo takto praví Hospodin o Sallumovi synu Joziáše, krále Judského, kterýž kraluje místo Joziáše otce svého: Když vyjde z místa tohoto, nenavrátí se sem více. 12Ale tam v tom místě, kamž jej zastěhují, umře, a tak země této neuzří více. 13Běda tomu, kdož staví dům svůj s útiskem, a paláce své s křivdou, kterýž bližního svého v službu podrobuje darmo, mzdy pak jeho nedává jemu; 14Kterýž říká: Vystavím sobě dům veliký a paláce prostranné, kterýž prolamuje sobě okna, a tafluje cedrovím, a maluje barvou. 15Zdaliž kralovati budeš, že se pleteš v to cedrové stavení? Otec tvůj zdaliž nejídal a nepíjel? Když konal soud a spravedlnost, tedy dobře bylo jemu. 16Když soudíval při chudého a nuzného, tedy dobře bylo. Zdaliž mně to není známé? dí Hospodin. 17Ale oči tvé i srdce tvé nehledí než lakomství tvého, a abys krev nevinnou proléval, a nátisk a křivdu činil. 18Protož takto praví Hospodin o Joakimovi synu Joziáše, krále Judského: Nebudouť ho kvíliti: Ach, bratře můj, aneb ach, sestro. Nebudou ho kvíliti: Ach, pane, aneb ach, kdež důstojnost jeho? 19Pohřbem osličím pohřben bude, vyvlečen a vyvržen jsa za brány Jeruzalémské. 20Vstup na Libán a křič, i na hoře Bázan vydej hlas svůj; křič také přes brody, když potříni budou všickni milovníci tvoji. 21Mluvíval jsem s tebou v největším štěstí tvém, říkávalas: Nebuduť poslouchati. Tať jest cesta tvá od dětinství tvého; neuposlechlas zajisté hlasu mého. 22Všecky pastýře tvé zpase vítr, a milovníci tvoji v zajetí půjdou. Tehdáž jistě hanbiti a styděti se budeš za všelikou nešlechetnost svou. 23Ó ty, kteráž jsi usadila se na Libánu, jenž se hnízdíš na cedroví, jak milostná budeš, když na tě přijdou svírání a bolest jako rodičky! 24Živť jsem já, dí Hospodin, že byť pak byl Koniáš syn Joakima, krále Judského, prstenem pečetním na mé ruce pravé, však tě i odtud strhnu. 25A vydám tě v ruku těch, kteříž hledají bezživotí tvého, a v ruku těch, jejichž ty se oblíčeje lekáš, totiž v ruku Nabuchodonozora krále Babylonského, a v ruku Kaldejských. 26A hodím tebou i matkou tvou, kteráž tě porodila, do země cizí, tam, kdež jste se nezrodili, a tam zemřete. 27Do země pak, po níž toužiti budete, abyste se navrátili tam, tam se nenavrátíte. 28Zdaliž modlou ničemnou, kteráž roztřískána bývá, bude muž tento Koniáš? Zdali nádobou, v níž není žádné líbosti? Proč by vyházíni byli on i símě jeho, a uvrženi do země, o níž nevědí? 29Ó země, země, země, slyš slovo Hospodinovo. 30Takto praví Hospodin: Zapište to, že muž tento bez dětí bude, a že se jemu nepovede šťastně za dnů jeho. Anobrž nepovede se šťastně i tomu muži, kterýž by z semene jeho seděl na stolici Davidově, a panoval ještě nad Judou.