Jeremiah 22 – YCB & PCB

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Jeremiah 22:1-30

Ìdájọ́ fún àwọn ọba búburú

1Báyìí ni Olúwa wí, “Sọ̀kalẹ̀ lọ sí ààfin ọba Juda, kí o sì sọ ọ̀rọ̀ yìí níbẹ̀: 2‘Gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa ìwọ ọba Juda, tí ó jókòó ní ìtẹ́ Dafidi, ìwọ, àwọn ènìyàn rẹ àti àwọn ìránṣẹ́ rẹ, tí ó wọlé láti ẹnu ibodè wọ̀nyí. 3Báyìí ni Olúwa wí: Ṣé ohun tí ó jẹ́ òtítọ́ tí ó sì yẹ, kí o sì gba ẹni tí a fi ẹ̀tọ́ rẹ̀ dù ú kúrò lọ́wọ́ aninilára. Kí ó má ṣe fi agbára àti ìkà lé àlejò, aláìní baba, tàbí opó, ìwọ kò sì gbọdọ̀ ta ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ sílẹ̀ níbí yìí. 4Nítorí bí ẹ̀yin bá tẹ̀lé àṣẹ wọ̀nyí, nígbà náà ni àwọn ọba tí ó jókòó lórí ìtẹ́ Dafidi yóò gba inú ààfin láti ẹnu-ọ̀nà, wọn yóò gun kẹ̀kẹ́ àti ẹṣin, àwọn àti ìránṣẹ́ wọn àti àwọn ènìyàn wọn. 5Ṣùgbọ́n bí ẹ̀yin kò bá tẹ̀lé àṣẹ wọ̀nyí, mo búra fúnra mi pé ààfin yìí yóò di ìparun ni Olúwa wí.’ ”

6Nítorí báyìí ni Olúwa wí, nípa ààfin ọba Juda,

“Bí ó tilẹ̀ jẹ́ wí pé ìwọ dàbí Gileadi sí mi,

gẹ́gẹ́ bí góńgó òkè Lebanoni,

dájúdájú Èmi yóò sọ ọ́ di aṣálẹ̀,

àní gẹ́gẹ́ bí ìlú tí a kò gbé inú wọn.

7Èmi ó ya àwọn apanirun sọ́tọ̀ fún ọ,

olúkúlùkù ọkùnrin pẹ̀lú ohun ìjà rẹ̀,

wọn yóò sì gé àṣàyàn igi kedari rẹ lulẹ̀,

wọn ó sì kó wọn jù sínú iná.

8“Àwọn ènìyàn láti ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè yóò rékọjá lẹ́bàá ìlú yìí wọn yóò sì máa bi ara wọn léèrè pé, ‘Èéṣe tí Olúwa ṣe irú èyí sí ìlú ńlá yìí?’ 9Ìdáhùn wọn yóò sì jẹ́: ‘Nítorí tí wọ́n ti kọ májẹ̀mú Olúwa Ọlọ́run wọn sílẹ̀, wọn ti ń fi orí balẹ̀ fún ọlọ́run mìíràn, wọ́n sì sìn wọ́n.’ ”

10Nítorí náà má ṣe sọkún nítorí ọba tí ó ti kú tàbí ṣọ̀fọ̀ fún àdánù rẹ̀,

ṣùgbọ́n ẹ sọkún kíkorò fún ẹni tí a lé kúrò nílùú

nítorí kì yóò padà wá mọ́

tàbí fi ojú rí ilẹ̀ tí a ti bí i.

11Nítorí báyìí ni Olúwa wí, nípa Ṣallumu ọmọ Josiah ọba Juda tí ó jẹ ọba lẹ́yìn baba rẹ̀, ṣùgbọ́n tí ó jáde kúrò níhìn-ín: “Òun kì yóò padà wá mọ́. 12Yóò kú ni ibi tí a mú u ní ìgbèkùn lọ, kì yóò sì rí ilẹ̀ yìí mọ́.”

13“Ègbé ni fún ẹni tí a kọ́ ààfin rẹ̀ lọ́nà àìṣòdodo,

àti àwọn yàrá òkè rẹ̀ lọ́nà àìtọ́

tí ó mú kí àwọn ará ìlú rẹ ṣiṣẹ́ lásán

láìsan owó iṣẹ́ wọn fún wọn.

14Ó wí pé, ‘Èmi ó kọ́ ààfin ńlá fún ara mi

àwọn yàrá òkè tí ó fẹ̀,

ojú fèrèsé rẹ̀ yóò tóbi.’

A ó sì fi igi kedari bò ó,

a ó fi ohun aláwọ̀ pupa ṣe é ní ọ̀ṣọ́.

15“Ìwọ ó ha jẹ ọba

kí ìwọ kí ó lè ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ igi kedari?

Baba rẹ kò ha ní ohun jíjẹ àti mímu?

Ó ṣe ohun tí ó tọ́ àti òdodo,

nítorí náà ó dára fún un.

16Ó gbèjà òtòṣì àti aláìní,

ohun gbogbo sì dára fún un.

Bí a ti mọ̀ mí kọ́ ni èyí?”

ni Olúwa wí.

17“Ṣùgbọ́n ojú rẹ àti ọkàn rẹ

wà lára èrè àìṣòótọ́

láti ta ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ sílẹ̀

ìnilára àti ìlọ́nilọ́wọ́gbà.”

18Nítorí náà báyìí ni Olúwa wí, nípa Jehoiakimu ọmọ Josiah ọba Juda:

“Wọn kì yóò ṣọ̀fọ̀ fún un:

wí pé, ‘Ó ṣe, arákùnrin mi! Ó ṣe, arábìnrin mi!’

Wọn kì yóò ṣọ̀fọ̀ fún un:

wí pé, ‘Ó ṣe, olúwa tàbí ó ṣe ọlọ́lá!’

19A ó sin òkú rẹ̀ bí i kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́

tí a wọ́ sọnù láti ẹnu ibodè

Jerusalẹmu.”

20“Gòkè lọ sí Lebanoni, kígbe síta,

kí a sì gbọ́ ohùn rẹ ní Baṣani,

kí o kígbe sókè láti Abarimu,

nítorí a ti ṣẹ́ gbogbo olùfẹ́ rẹ túútúú.

21Èmi ti kìlọ̀ fún ọ nígbà tí o rò pé kò séwu,

ṣùgbọ́n o sọ pé, ‘Èmi kì yóò fetísílẹ̀!’

Èyí ni iṣẹ́ rẹ láti ìgbà èwe rẹ,

ìwọ kò fìgbà kan gba ohùn mi gbọ́.

22Ẹ̀fúùfù yóò lé gbogbo àwọn olùṣọ́-àgùntàn rẹ̀ lọ,

gbogbo àwọn olùfẹ́ rẹ yóò lọ sí ìgbèkùn,

nígbà náà ni a ó kẹ́gàn rẹ, ojú yóò tì ọ́

nítorí gbogbo ìwà búburú rẹ.

23Ìwọ tí ń gbé ‘Lebanoni,’

tí ó tẹ́ ìtẹ́ sí orí igi kedari,

ìwọ yóò ti kérora pẹ́ tó, nígbà tí ìrora bá dé bá ọ,

ìrora bí i ti obìnrin tí ń rọbí!

24“Dájúdájú bí èmi ti wà láààyè,” ni Olúwa wí, “Bí Koniah ọmọ Jehoiakimu ọba Juda tilẹ̀ jẹ́ òrùka èdìdì lọ́wọ́ ọ̀tún mi, síbẹ̀ èmi ó fà ọ́ tu kúrò níbẹ̀. 25Èmi ó sì fà ọ́ lé ọwọ́ àwọn tí ó ń wá ẹ̀mí rẹ, àwọn tí ìwọ bẹ̀rù, àní lé ọwọ́ Nebukadnessari, ọba Babeli àti ọwọ́ àwọn ará Babeli. 26Èmi ó fi ìwọ àti ìyá tí ó bí ọ sọ̀kò sí ilẹ̀ mìíràn, níbi tí a kò bí ẹnikẹ́ni nínú yín sí. Níbẹ̀ ni ẹ̀yin méjèèjì yóò kú sí. 27Ẹ̀yin kì yóò padà sí ilẹ̀ tí ẹ̀yin fẹ́ mọ́ láéláé.”

28Ǹjẹ́ Jehoiakini ẹni ẹ̀gàn yàtọ̀ sí ìkòkò òfìfo,

ohun èlò tí ẹnìkan kò fẹ́?

Èéṣe tí a fi òun àti àwọn ọmọ rẹ̀ sókè

sí ilẹ̀ tí wọn kò mọ̀.

29Ìwọ ilẹ̀, ilẹ̀, ilẹ̀,

gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa!

30Báyìí ni Olúwa wí:

“Kọ àkọsílẹ̀ ọkùnrin yìí sínú ìwé gẹ́gẹ́ bí aláìlọ́mọ,

ẹni tí kì yóò ṣe rere ní ọjọ́ ayé rẹ̀;

nítorí ọ̀kan nínú irú-ọmọ rẹ̀ kì yóò ṣe rere,

èyíkéyìí wọn kì yóò jókòó lórí ìtẹ́ Dafidi

tàbí jẹ ọba ní Juda mọ́.”

Persian Contemporary Bible

ارميا 22:1‏-30

پيام خدا به خاندان سلطنتی

1‏-3خداوند فرمود كه به قصر پادشاه يهودا بروم و به او كه بر تخت پادشاهی داوود نشسته و به تمام درباريان و به اهالی اورشليم، بگويم كه خداوند چنين می‌فرمايد:

«عدل و انصاف را بجا آوريد و داد مظلومان را از ظالمان بستانيد؛ به غريبان، يتيمان و بيوه‌زنان ظلم نكنيد و خون بی‌گناهان را نريزيد. 4اگر آنچه می‌گويم انجام دهيد، اجازه خواهم داد كه همواره پادشاهانی از نسل داوود بر تخت سلطنت تكيه بزنند و با درباريان و همهٔ قوم در سعادت و آسايش روزگار بگذرانند.

5«ولی اگر اين حكم را اطاعت نكنيد، به ذات خود قسم كه اين قصر به ويرانه تبديل خواهد شد. 6اگرچه اين قصر در نظرم مثل سرزمين حاصلخيز جلعاد و مانند کوههای سرسبز لبنان زيبا می‌باشد، اما آن را ويران و متروک خواهم ساخت تا كسی در آن زندگی نكند؛ 7افرادی ويرانگر را همراه با تبرهایشان خواهم فرستاد تا تمام ستونها و تيرهای چوبی آن را كه از بهترين سروهای آزاد تهيه شده، قطع كنند و در آتش بسوزانند. 8آنگاه مردم سرزمینهای ديگر وقتی از كنار خرابه‌های اين شهر عبور كنند، از يكديگر خواهند پرسيد: ”چرا خداوند با اين شهر بزرگ چنين كرد؟“ 9در پاسخ خواهند شنيد: ”چون اهالی اينجا خداوند، خدای خود را فراموش كردند و عهد و پيمانی را كه او با ايشان بسته بود، شكستند و بت‌پرست شدند.“»

كلام خدا دربارهٔ يهوآحاز

10‏-12خداوند می‌فرمايد: «برای يوشيای پادشاه كه در جنگ كشته شده، گريه نكنيد، بلكه برای پسرش يهوآحاز ماتم بگيريد كه به اسيری برده خواهد شد22‏:10‏-12 يهوآحاز به مصر به اسيری برده شد (دوم پادشاهان 23‏:31‏-34).‏؛ چون او در سرزمينی بيگانه خواهد مرد و ديگر وطنش را نخواهد ديد.»

كلام خداوند دربارهٔ يهوياقيم

13خداوند می‌فرمايد: «وای بر تو ای يهوياقيم پادشاه، كه قصر با شكوهت را با بهره‌كشی از مردم می‌سازی؛ از در و ديوار قصرت ظلم و بی‌عدالتی می‌بارد، چون مزد كارگران را نمی‌پردازی. 14می‌گويی: ”قصر باشكوهی می‌سازم كه اتاقهای بزرگ و پنجره‌های زيادی داشته باشد؛ سقف آن را با چوب سرو آزاد می‌پوشانم و بر آن رنگ قرمز می‌زنم.“ 15آيا فكر می‌كنی با ساختن كاخهای پرشكوه، سلطنتت پايدار می‌ماند؟ چرا سلطنت پدرت يوشيا آنقدر دوام يافت؟ چون او عادل و با انصاف بود. به همين علت هم در همهٔ كارهايش كامياب می‌شد. 16او از فقيران و نيازمندان دستگيری می‌كرد، بنابراين هميشه موفق بود. اين است معنی خداشناسی! 17ولی تو فقط به دنبال ارضای حرص و آز خود هستی؛ خون بی‌گناهان را می‌ريزی و بر قوم خود با ظلم و ستم حكومت می‌كنی.

18«بنابراين ای يهوياقيم پادشاه، پسر يوشيا، پس از مرگت هيچكس حتی خانواده‌ات برايت ماتم نخواهند كرد؛ قومت نيز به مرگ تو اهميتی نخواهند داد؛ 19جنازهٔ تو را از اورشليم كشان‌كشان بيرون برده، مانند لاشهٔ الاغ به گوشه‌ای خواهند افكند!»

پيام دربارهٔ سرنوشت يهودا

20ای مردم اورشليم به لبنان برويد و در آنجا گريه كنيد؛ در باشان فرياد برآوريد؛ بر کوههای موآب ناله سر دهيد، چون همهٔ دوستان و همدستانتان از بين رفته‌اند! 21زمانی كه در سعادت و خوشبختی به سر می‌برديد، خدا با شما سخن گفت، ولی گوش فرا نداديد؛ شما هرگز نخواستيد او را اطاعت نماييد؛ عادت شما هميشه همين بوده است! 22حال وزش باد خشم خدا تمام رهبرانتان را نابود خواهد ساخت؛ همپيمانانتان نيز به اسارت خواهند رفت؛ و سرانجام به سبب شرارتهايتان، شرمسار و سرافكنده خواهيد گشت.

23ای كسانی كه در كاخهای مزين به چوب سرو لبنان زندگی می‌كنيد، بزودی دردی جانكاه همچون درد زايمان، شما را فرو خواهد گرفت؛ آنگاه همه برای شما دلسوزی خواهند كرد.

داوری يهوياكين

24‏-25خداوند به يهوياكين، پسر يهوياقيم، پادشاه يهودا چنين می‌فرمايد: «تو حتی اگر انگشتر خاتم بر دست راستم بودی، تو را از انگشتم بيرون می‌آوردم و به دست كسانی می‌دادم كه به خونت تشنه‌اند و تو از ايشان وحشت داری، يعنی به دست نبوكدنصر، پادشاه بابل و سپاهيان او! 26تو و مادرت را به سرزمينی بيگانه خواهم افكند تا در همانجا بميريد. 27شما هرگز به اين سرزمين كه آرزوی ديدنش را خواهيد داشت، باز نخواهيد گشت.»

28خداوندا، آيا اين مرد يعنی يهوياكين، مانند ظرف شكسته‌ای شده كه كسی به آن نيازی ندارد؟ آيا به همين دليل است كه خود و فرزندانش به سرزمينی بيگانه به اسارت می‌روند؟

29ای زمين، ای زمين، ای زمين! كلام خداوند را بشنو. 30خداوند می‌فرمايد: «نام اين مرد (يعنی يهوياكين) را جزو افراد بی‌اولاد بنويس، جزو كسانی كه هرگز كامياب نخواهند شد؛ چون هيچيک از فرزندان او بر تخت سلطنت داوود تكيه نخواهد زد و بر يهودا فرمانروايی نخواهد كرد!»