Jakọbu 2 – YCB & SNC

Yoruba Contemporary Bible

Jakọbu 2:1-26

Ojúsàájú jẹ́ èèwọ̀

1Ẹ̀yin ará mi, gẹ́gẹ́ bí onígbàgbọ́ nínú ògo Olúwa wá Jesu Kristi, ẹ máa ṣe ojúsàájú ẹnikẹ́ni. 2Nítorí bí ọkùnrin kan bá wá sí ìpéjọpọ̀ yín, pẹ̀lú òrùka wúrà àti aṣọ dáradára, tí tálákà kan sì wá pẹ̀lú nínú aṣọ èérí; 3tí ẹ̀yin sì bu ọlá fún ẹni tí ó wọ aṣọ dáradára tí ẹ sì wí pé, “Ìwọ jókòó níhìn-ín yìí ní ibi dáradára” tí ẹ sì wí fún tálákà náà pé, “Ìwọ dúró níbẹ̀” tàbí “jókòó níhìn-ín lábẹ́ àpótí ìtìsẹ̀ mi,” 4ẹyin kò ha ń dá ara yín sí méjì nínú ara yín, ẹ̀yin kò sì di onídàájọ́ tí ó ní èrò búburú bí?

5Ẹ fi etí sílẹ̀, ẹ̀yin ará mi olùfẹ́: Ọlọ́run kò ha ti yan àwọn tálákà ayé yìí láti jẹ́ ọlọ́rọ̀ nínú ìgbàgbọ́, àti ajogún ìjọba náà, tí ó ti ṣe ìlérí fún àwọn tí ó fẹ́ ẹ? 6Ṣùgbọ́n ẹ̀yin ti bu tálákà kù. Àwọn ọlọ́rọ̀ kò ha ń pọ́n yin lójú bí; wọn kò ha sì ń wọ́ yín lọ sílé ẹjọ́? 7Wọn kò ha ń sọ ọ̀rọ̀-òdì sí orúkọ rere nì tí a fi ń pè yín bí?

82.8: Le 19.18.Ṣùgbọ́n bí ẹ̀yin bá ń mú olú òfin nì ṣẹ gẹ́gẹ́ bí Ìwé mímọ́, èyí tí ó wí pé, “Ìwọ fẹ́ ẹni kejì rẹ gẹ́gẹ́ bí ara rẹ,” ẹ̀yin ń ṣe dáradára. 9Ṣùgbọ́n bí ẹ̀yin bá ń ṣe ojúsàájú ènìyàn, ẹ̀yin ń dẹ́ṣẹ̀, a sì ń dá yín lẹ́bi nípa òfin bí arúfin. 10Nítorí ẹnikẹ́ni tí ó bá pa gbogbo òfin mọ́, tí ó sì rú ọ̀kan, ó jẹ̀bi rírú gbogbo rẹ̀. 112.11: Ek 20.13-14; De 5.17-18.Nítorí ẹni tí ó wí pé, “Ìwọ kò gbọdọ̀ ṣe panṣágà,” òun ni ó sì wí pé, “Ìwọ kò gbọdọ̀ pànìyàn.” Ǹjẹ́ bí ìwọ kò ṣe panṣágà, ṣùgbọ́n tí ìwọ pànìyàn, ìwọ jásí arúfin.

12Ẹ máa sọ̀rọ̀, ẹ sì máa hùwà, bí àwọn tí a ó fi òfin òmìnira dá lẹ́jọ́. 13Nítorí ẹni tí kò ṣàánú, ni a ó ṣe ìdájọ́ fún láìsí àánú; àánú ń ṣògo lórí ìdájọ́.

Ìgbàgbọ́ àti àwọn iṣẹ́

14Èrè kí ni ó jẹ́, ará mi, bí ẹni kan wí pé òun ní ìgbàgbọ́, ṣùgbọ́n tí kò ní àwọn iṣẹ́ láti fihan? Ìgbàgbọ́ náà lè gbà á là bí? 15Bí arákùnrin tàbí arábìnrin kan bá wà ní àìní aṣọ, tí ó sì ṣe àìní oúnjẹ òòjọ́, 16Tí ẹni kan nínú yín sì wí fún pé, “Máa lọ ní àlàáfíà, kí ara rẹ kí ó má ṣe tutù, kí ó sì yó,” ṣùgbọ́n ẹ kò fi nǹkan wọ̀n-ọn-nì ti ara ń fẹ́ fún wọn; èrè kí ni ó jẹ́? 17Bẹ́ẹ̀ sì ni ìgbàgbọ́, bí kò bá ní iṣẹ́ rere, ó kú nínú ara rẹ̀.

18Ṣùgbọ́n ẹnìkan lè wí pé, “Ìwọ ní ìgbàgbọ́, èmi sì ní iṣẹ́:”

Fi ìgbàgbọ́ rẹ hàn mí ní àìsí iṣẹ́, èmi ó sì fi ìgbàgbọ́ mi hàn ọ́ nípa iṣẹ́ rere mi. 19Ìwọ gbàgbọ́ pé Ọlọ́run kan ní ó ń bẹ; ó dára! Àwọn ẹ̀mí èṣù pẹ̀lú gbàgbọ́ bẹ́ẹ̀, wọ́n sì wárìrì.

20Ṣùgbọ́n, ìwọ aláìmòye ènìyàn, ìwọ ha fẹ́ ní ìdánilójú pé, ìgbàgbọ́ ní àìsí iṣẹ́ rere asán ni? 212.21: Gẹ 22.1-14.Kí ha í ṣe nípa iṣẹ́ ni a dá Abrahamu baba wa láre, nígbà tí ó fi Isaaki ọmọ rẹ̀ rú ẹbọ lórí pẹpẹ? 22Ìwọ rí i pé ìgbàgbọ́ rẹ bá iṣẹ́ rìn, àti pé nípa iṣẹ́ rere ni a sọ ìgbàgbọ́ di pípé. 232.23: Gẹ 15.6; Isa 41.8; 2Ki 20.7.Ìwé Mímọ́ sì ṣẹ́ tí ó wí pé, “Abrahamu gba Ọlọ́run gbọ́, a sì kà á sí òdodo fún un,” a sì pè é ní ọ̀rẹ́ Ọlọ́run. 24Ǹjẹ́ ẹ̀yin rí i pé nípa iṣẹ́ rere ni à ń dá ènìyàn láre, kì í ṣe nípa ìgbàgbọ́ nìkan.

252.25: Jo 2.1-21.Gẹ́gẹ́ bẹ́ẹ̀ pẹ̀lú kí a dá Rahabu panṣágà láre nípa iṣẹ́ bí, nígbà tí ó gba àwọn ayọ́lẹ̀wò, tí ó sì rán wọn jáde gba ọ̀nà mìíràn? 26Nítorí bí ara ní àìsí ẹ̀mí ti jẹ́ òkú, bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ pẹ̀lú ni ìgbàgbọ́ ní àìsí iṣẹ́ jẹ́ òkú.

Czech Living New Testament

Jakubův 2:1-26

Pravá víra

1Bratři, jestliže věříte v Ježíše Krista, který je slavným Pánem všech, nemůžete měřit lidi podle kabátu.

2Představte si, že do vašeho shromáždění přijde bohatě oblečený host se zlatým prstenem na ruce a hned za ním obyčejný člověk v obnošených šatech. 3K prvnímu budete samá pozornost a uvedete ho na pěkné místo, zatímco druhého si ani nevšimnete a necháte ho někde stát. 4Čeho jste se dopustili? Udělali jste rozdíl mezi lidmi, a navíc podle zvrácených měřítek.

5Nezapomeňte, že Bůh si často z bezvýznamných lidí vírou dělá osobnosti a otevírá dveře do svého království těm, kdo ho milují, ne těm, kdo na to mají. 6A vy byste s takovým člověkem pohrdli! Copak vás právě vlivní lidé nepronásledují a nevláčejí po soudech? 7Vždyť právě oni se tak často posmívají jménu toho, který je pro vás vším!

8Korunou Božích přikázání je láska. Jednáte správně, posloucháte-li příkaz Písma: „Miluj svého bližního právě tak, jako miluješ sebe!“ 9Nadržovat jednomu a přehlížet druhého je podle tohoto zákona hřích.

10Člověk, který chce přísně dodržovat Boží zákon, ale v jedné věci se od něho odchyluje, je vinen právě tak jako ten, kdo porušuje celý zákon. 11Bůh, který řekl „Nezabiješ!“ řekl také „Nezcizoložíš!“. A tak i když jsi nikoho nezabil, ale porušil jsi nevěrou manželství, stejně jsi porušil zákon.

12Každý z vás bude souzen podle toho, zda se ve svém životě řídil či neřídil Božím zákonem lásky. Proto dávejte pozor na to, co říkáte a jak jednáte. 13Kdo jedná nemilosrdně, hrozí mu přísný soud. Milosrdenství však soud převažuje.

14Co by vám byla platná víra, bratři, kdybyste podle ní nežili? Myslíte, že vás taková víra spasí? 15Řekněme, že někdo z vašich přátel bude hladovět a nebude mít co na sebe. 16Řeknete-li mu: „Tak se měj dobře, ať nenachladneš a nemáš hlad!“ a sami mu nedáte ani jídlo ani oblečení, jakou to má cenu?

17Víra, která se neprojevuje činy, je sama o sobě mrtvá a bezcenná. 18Máte-li jen takovou víru, pak vám může někdo namítnout: „Ty mluvíš o své víře. Dokaž ji svými činy. A o mně říkáš, že víru nemám. O mé víře svědčí činy.“

19Věříš, že je Bůh. To je dobře. Ale nezapomeň, že v Boha věří i ďábel, ale nic mu to nepomůže. Chvěje se před Božím soudem. 20Vy bláhoví, ještě chcete, abych vás přesvědčoval o bezcennosti víry, která není dokázána skutky?

21Čím projevil Abraham svou víru? Tím, že byl ochoten i k takovému činu, jako obětovat Bohu svého syna Izáka. 22U něho šla víra ruku v ruce s činem a dozrála poslušností. 23O takovou víru jde v Písmu, když čteme: „Abraham uvěřil Bohu, Bůh se k němu přiznal a nazval ho svým přítelem.“ 24Vidíte, že Bůh může přijmout člověka jen tehdy, když svou víru dokazuje skutky. 25Poslušný čin víry zachránil i prostitutku Rachab, když ukryla izraelské zvědy a umožnila jim útěk. 26Víra bez činů je jako tělo bez duše.