1Ìwọ ìbá fa ọ̀run ya kí o sì sọ̀kalẹ̀ wá,
tí àwọn òkè ńlá yóò fi wárìrì níwájú rẹ!
2Gẹ́gẹ́ bí ìgbà tí iná mú ẹ̀ka igi jó
tí ó sì mú kí omi ó hó,
sọ̀kalẹ̀ wá kí orúkọ rẹ le di mí mọ̀ fún àwọn ọ̀tá rẹ
kí o sì jẹ́ kí àwọn orílẹ̀-èdè kí ó wárìrì níwájú rẹ!
3Nítorí nígbà tí o bá ṣe àwọn ohun ẹ̀rù tí àwa kò nírètí,
o sọ̀kalẹ̀ wá, àwọn òkè ńlá sì wárìrì níwájú rẹ̀.
464.4: 1Kọ 2.9.Láti ìgbà àtijọ́ kò sí ẹni tí ó gbọ́ rí
kò sí etí kan tí ó gbọ́ ọ,
kò sí ojú tí ó tí ì rí Ọlọ́run mìíràn lẹ́yìn rẹ,
tí ó máa ń ṣe nǹkan lórúkọ àwọn tí ó dúró dè é.
5Ìwọ a máa wá fún ìrànlọ́wọ́ àwọn tí wọn
ń fi ayọ̀ ṣe ohun tó tọ́,
tí ó rántí ọ̀nà rẹ.
Ṣùgbọ́n nígbà tí a bẹ̀rẹ̀ sí dẹ́ṣẹ̀ sí wọn,
inú bí ọ.
Báwo ni a ó ṣe gbà wá là?
6Gbogbo wa ti dàbí ẹnìkan tí ó jẹ́ aláìmọ́,
gbogbo òdodo wa sì dàbí èkísà ẹlẹ́gbin;
gbogbo wa kákò bí ewé,
àti bí afẹ́fẹ́, ẹ̀ṣẹ̀ wa ti gbá wa lọ kúrò.
7Ẹnikẹ́ni kò pe orúkọ rẹ
tàbí kí ó gbìyànjú láti dì ẹ́ mú;
nítorí ìwọ ti fi ojú rẹ pamọ́ fún wa
ó sì jẹ́ kí àwa ṣòfò dànù nítorí àwọn ẹ̀ṣẹ̀ wa.
8Síbẹ̀síbẹ̀, Olúwa, ìwọ ni Baba wa.
Àwa ni amọ̀, ìwọ ni amọ̀kòkò;
gbogbo wa jẹ́ iṣẹ́ ọwọ́ rẹ.
9Má ṣe bínú kọjá ààlà, ìwọ Olúwa,
má ṣe rántí gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ wa títí láé.
Jọ̀wọ́, bojú wò wá, ni a gbàdúrà,
nítorí ènìyàn rẹ ni gbogbo wa.
10Àwọn ìlú mímọ́ rẹ ti di aṣálẹ̀;
Sioni pàápàá di aṣálẹ̀, Jerusalẹmu di ahoro.
11Tẹmpili mímọ́ ológo wa, níbi tí àwọn baba wa ti yìn ọ́,
ni a ti fi iná sun,
àti ohun gbogbo tí í ṣe ìṣúra wa ti dahoro.
12Lẹ́yìn gbogbo nǹkan wọ̀nyí, Olúwa, ìwọ ó ha sì tún fi ara rẹ pamọ́ bí?
Ìwọ ó ha dákẹ́ kí o sì fìyà jẹ wá kọjá ààlà bí?
1Comme le feu ╵consume les taillis
et fait bouillonner l’eau,
ainsi tu ferais connaître ton nom ╵à tous tes adversaires,
et tous les peuples ╵trembleraient devant toi.
2Si tu accomplissais ╵des actes redoutables
que nous n’attendons pas,
oui, si tu descendais,
devant toi, les montagnes ╵s’effondreraient.
3Jamais on n’a appris, ╵ni jamais entendu,
jamais un œil n’a vu
qu’un autre dieu que toi
ait agi en faveur ╵de qui compte sur lui64.3 Allusion en 1 Co 2.9..
4Tu viens à la rencontre
de celui qui pratique ╵la justice avec joie,
et tient compte de toi ╵pour suivre les chemins ╵que tu prescris.
Mais tu t’es irrité ╵car nous avons péché.
C’est sur ces chemins de toujours ╵que nous serons sauvés64.4 Hébreu peu clair. Autre traduction : Au regard des péchés auxquels nous nous adonnons depuis toujours, pourrions-nous encore être sauvés ?.
5Nous sommes tous semblables ╵à des êtres impurs,
toute notre « justice » ╵est comme des linges souillés.
Nous sommes tous flétris ╵comme un feuillage,
nos fautes nous emportent ╵comme le vent.
6Personne ne t’invoque,
personne ne se ressaisit ╵pour s’attacher à toi.
Car tu t’es détourné de nous
et tu nous as fait défaillir
sous le poids de nos fautes.
7Et pourtant, Eternel, ╵toi, tu es notre père.
Nous, nous sommes l’argile,
et tu es le potier ╵qui nous a façonnés :
nous sommes tous l’ouvrage ╵que tes mains ont formé.
8Ne sois pas courroucé ╵à l’excès, Eternel.
Ne nous tiens pas rigueur ╵à toujours de nos fautes !
Et daigne porter tes regards ╵sur nous tous qui sommes ton peuple !
9Voici : tes villes saintes ╵sont dépeuplées.
Sion est un désert,
Jérusalem est désolée,
10notre saint temple, ╵qui était magnifique
où nos ancêtres te louaient,
est devenue la proie des flammes,
et tout ce qui nous était cher ╵est désormais en ruine.
11Face à tant de misères, ╵peux-tu, ô Eternel, ╵demeurer sans rien faire
et garder le silence ?
Vas-tu nous humilier encore ╵au-delà de toute mesure ?